< Jonah 2 >
1 Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá,
И помолися Иона ко Господу Богу своему от чрева китова
2 Ó sì wí pé: “Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa, òun sì gbọ́ ohùn mi. Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́, ìwọ sì gbọ́ ohùn mi. (Sheol )
и рече: возопих в скорби моей ко Господу Богу моему, и услыша мя из чрева адова вопль мой, услышал еси глас мой: (Sheol )
3 Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú, ní àárín Òkun, ìṣàn omi sì yí mi káàkiri; gbogbo bíbì omi àti rírú omi rékọjá lórí mi.
отвергл мя еси во глубины сердца морскаго, и реки обыдоша мя вся высоты Твоя и волны Твоя мне преидоша.
4 Nígbà náà ni mo wí pé, ‘A ta mí nù kúrò níwájú rẹ; ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’
И аз рех: отринуся от очию Твоею: еда приложу призрети ми ко храму святому Твоему?
5 Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn; ibú yí mi káàkiri, a fi koríko odò wé mi lórí.
Возлияся на мя вода до души моея, бездна обыде мя последняя, понре глава моя в разселины гор,
6 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá; ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí: ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá, Olúwa Ọlọ́run mi.
снидох в землю, еяже вереи ея заклепи вечнии: и да взыдет из истления живот мой к Тебе, Господи Боже мой.
7 “Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi, èmi rántí rẹ, Olúwa, àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.
Внегда скончаватися от мене души моей, Господа помянух, и да приидет к Тебе молитва моя ко храму святому Твоему.
8 “Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké kọ àánú ara wọn sílẹ̀.
Хранящии суетная и ложная милость свою оставиша:
9 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ. Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́. ‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’”
аз же со гласом хваления и исповедания пожру Тебе, елика обещах, воздам Тебе во спасение мое Господеви.
10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.
И повеле Господь китови, и изверже Иону на сушу.