< Jonah 2 >
1 Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá,
Youna e menabo hagomo ganodini esala. E da ea Hina Godema sia: ne gadoi.
2 Ó sì wí pé: “Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa, òun sì gbọ́ ohùn mi. Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́, ìwọ sì gbọ́ ohùn mi. (Sheol )
E amane sia: i, “Hina Gode! Na da se bagadedafa nababeba: le, Dima wele sia: ne gadoi. Amola Dia na sia: ne gadobe amo nabalu, dabe i. Na da soge wadela: i ganodini esalu, amo da dunu bogogia: su soge diala, amola na Dia fidima: ne di. Amola na dibi amo di nabi dagoi. (Sheol )
3 Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú, ní àárín Òkun, ìṣàn omi sì yí mi káàkiri; gbogbo bíbì omi àti rírú omi rékọjá lórí mi.
Dia na hano lugududafaga ha: digi amola da hano gafului amoea na huluane dedebosa.
4 Nígbà náà ni mo wí pé, ‘A ta mí nù kúrò níwájú rẹ; ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’
Na agoane dawa: i, Dia da na fisi dagoi, amola na da Dia hadigi Debolo diasu noga: idafa bu hamedafa ba: mu dawa: i galu.
5 Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn; ibú yí mi káàkiri, a fi koríko odò wé mi lórí.
Hano misini na dedeboi, amola hano wayabo misini na da: i huluanedafa dedeboi amola hano gadula: me da na da: i busa: gi amola huluane lala: gili dedeboi dagoi.
6 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá; ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí: ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá, Olúwa Ọlọ́run mi.
Na amo hano haguduga goumi, dabua gadonini dala gududafa doaga: i, amo soge amoea, na masunu gogolele, logo ga: si dialu. Be amomane Hina Gode Bagade, Di da na Godedafa, Dia na bu laiba: le. Amola, luguduga lale, na esaleawane bu walesi.
7 “Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi, èmi rántí rẹ, Olúwa, àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.
Hina Gode! Na dawa: loba, na da bogomu gadenei agoai ba: i. Be amomane, na Dima dafawane dawa: i. Amola na Hina Gode, Dima sia: ne gadoiba: le, Di da Dia hadigi Debolo Diasu ganodini nabi.
8 “Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké kọ àánú ara wọn sílẹ̀.
Dunu fifi asi gala amo da loboga hahamoi ogogosu ‘gode’ma sia: ne gadosa, amo ilia da Dima fa: no bobogesu hou yolesi dagoi.
9 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ. Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́. ‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’”
Be na da Dima hahawane gesami hea: su hamomu. Na Dima gobele salasu hou hamomu, amola ni ilegele sia: i defele hamomu. Be gaga: su houdafa da Dima fawane maha, na Hina Gode!”
10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.
Amanoba Hina Gode da menaboma isoma: ne sia: beba: le, menabo da Youna e boso da: iya, isole ligisi.