< Jonah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona ọmọ Amittai wá, wí pé:
Perwerdigarning sözi Amittayning oghli Yunusqa yétip kélip mundaq déyildi: —
2 “Dìde lọ sí ìlú ńlá Ninefe kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”
«Ornungdin tur, derhal Ninewe dégen ashu büyük sheherge bérip, awazingni kötürüp u yerdikilerni agahlandurghin; chünki ularning rezillikliri Méning közümge qadilip turidu».
3 Ṣùgbọ́n Jona dìde kúrò láti sálọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Joppa, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tarṣiṣi: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa.
Biraq Yunus ornidin turup Perwerdigarning yüzidin özini qachurush üchün Tarshish dégen yurtqa ketmekchi boldi. Shunga u Yoppa shehirige bérip, Tarshishqa baridighan kéme tépip, kirasini tölep uninggha chüshti we kémichiler bilen birlikte Tarshishqa bérip, Perwerdigarning yüzidin özini qachurmaqchi boldi.
4 Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú Òkun, ìjì líle sì wà nínú Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́.
Perwerdigar bolsa zor bir boranni déngizgha tashlidi; shunga déngizda dehshetlik qara boran chiqip, kéme parchilinip ketkili tas qaldi.
5 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú Òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́. Ṣùgbọ́n Jona sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra.
Kémichiler bolsa bek qorqup kétip, herqaysisi öz ilahlirigha xitab qilip dua qilishti; ular kémini yéniklisun dep uningdiki yük-taqlarni déngizgha tashliwetti. Biraq Yunus bolsa, kémining asti qewitige chüshüwélip, shu yerde ölüktek uxlawatqanidi.
6 Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóòórùn? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”
Kéme bashliqi uning yénigha kélip uninggha: «Ey, uxlawatqan kishi, bu qandaq qilighining? Ornungdin tur, ilahingni séghinip nida qil! Kim bilidu, ilahingning neziri chüshüp bizni halakettin qutquzup qalamdu téxi?» — dédi.
7 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jona.
Ular bir-birige: — Kélinglar, bu külpetning kimning wejidin béshimizgha chüshkenlikini békitish üchün chek tashlayli, — déyishti. Shundaq qilip ular chek tashlashti; axirda chekte Yunus chiqip qaldi.
8 Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”
Ular uningdin: — Qéni, éyt, béshimizgha chüshken bu külpet kimning sewebidin boluwatidu? Séning tirikchiliking néme? Nedin kelding? Qaysi el, qaysi millettin sen? — dep soridi.
9 Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Heberu ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”
U ulargha: — Men bolsam ibraniy millitidin, ershlerdiki Xudadin, yeni déngizni, yer-zéminni yaratqan Perwerdigardin qorqquchimen, dédi.
10 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀).
Bu söz ularni intayin qorqutiwetti. Ular: «Sen zadi néme ish qilghan?» — dep soridi [chünki ular uning Perwerdigarning yüzidin qachqanliqini bilgenidi, chünki ular buni uning öz aghzidin anglighanidi].
11 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó ṣe sí ọ kí Òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí Òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.
Ular uningdin: — Emdi biz séni qandaq qilsaq déngiz biz üchün tinchlinidu? — dep soridi; chünki déngiz dolquni barghanséri ewj élip kétiwatatti.
12 Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú Òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”
U ulargha: — Méni kötürüp déngizgha tashliwétinglar, shu chaghda déngiz siler üchün tinchlinidu; chünki bilimenki, bu zor boran méning sewebimdin silerge chüshti, — dédi.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà gbìyànjú gidigidi láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí Òkun túbọ̀ ru sí i, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn.
Biraq bu ademler küchep palaq urup qirghaqqa yétishke tirishti; emma yételmidi, chünki déngiz qérishqandek téximu dolqunlap kétiwatatti.
14 Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.”
Ular Perwerdigargha iltija qilip peryad kötürüp: — Ah Perwerdigar, Sendin ötünimiz, bu ademning jénini alghanliqimizni bizdin körmigeysen! Bigunah bir ademning qénini töküshning gunahini üstimizge qoymighaysen! Chünki Sen Perwerdigar Özüngning xalighiningni qilding! — dep nida qildi.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jona, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú Òkun, Òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀.
Shuning bilen ular Yunusni kötürüp élip déngizgha tashliwetti; déngiz dolqunlinishtin shuan toxtidi.
16 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.
Shuning bilen bu ademler Perwerdigardin qattiq qorqti; ular Perwerdigargha atap qurbanliq qilip qesem ichishti.
17 Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèsè ẹja ńlá kan láti gbé Jona mì. Jona sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.
Biraq Perwerdigar Yunusni yutuwélishqa yoghan bir béliqni ewetkenidi. Yunus bolsa bu béliqning qarnida üch kéche-kündüz turdi.

< Jonah 1 >