< Jonah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona ọmọ Amittai wá, wí pé:
A HIKI mai ka olelo a Iehova ia Iona, ke keiki a Amitai, i mai la,
2 “Dìde lọ sí ìlú ńlá Ninefe kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”
E ku oe, e hele i Nineva, i kela kulanakauhale nui, e kahea aku ia ia; no ka mea, ua pii mai ko lakou hewa imua o'u.
3 Ṣùgbọ́n Jona dìde kúrò láti sálọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Joppa, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tarṣiṣi: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa.
Aka, ku ae la o Iona e holo i Taresisa, mai ke alo aku o Iehova, a iho aku la i Iopa; a loaa ia ia ka moku e holo ana i Taresisa: a haawi aku ia i ka uku, a komo iho la ia iloko ona e holo pu me lakou i Taresisa mai ke alo aku o Iehova.
4 Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú Òkun, ìjì líle sì wà nínú Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́.
A hoouna mai o Iehova i ka makani nui ma ke kai, a he ino nui ma ke kai, a aneane nahaha ka moku.
5 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú Òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́. Ṣùgbọ́n Jona sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra.
Alaila, makau iho la na hooholo moku, a kahea aku kela kanaka keia kanaka i kona akua, a hoolei ka waiwai ma ka moku iloko o ke kai, e hoomama i ka moku no ia mau mea. A ua iho o Iona ilalo i ka aoao hope o ka moku, a moe iho, a ua pauhia i ka hiamoe.
6 Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóòórùn? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”
A hele aku ke kahu moku ia ia, a i aku la ia ia, Heaha kau, e ka mea hiamoe? e ala, e hea aku i kou Akua, malia paha e manao mai ke Akua ia kakou i make ole ai kakou.
7 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jona.
A olelo ae la lakou, kela mea keia mea i kona hoa, Ina kakou e hailona, i ike ai kakou i ka mea nona i hiki mai ai keia ino maluna o kakou. A hailona lakou, a lilo ka hailona no Iona.
8 Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”
Alaila, i aku la lakou ia ia, Ke noi aku nei makou, e hai mai oe ia makou i ka mea nona i hiki mai ai keia ino maluna o kakou? Heaha kau oihana? Mai hea mai oe? Owai kou aina? a no ka lahuikanaka hea oe?
9 Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Heberu ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”
I mai la oia ia lakou, He Hebera no wau; a ke makau nei au ia Iehova ke Akua o ka lani, nana i hana ke kai, a me ka aina maloo.
10 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀).
Alaila, makau iho la na kanaka i ka makau nui, a i aku la ia ia, No ke aha la oe i hana mai ai i keia? No ka mea, ua ike na kanaka, ua holo ia mai ke alo aku o Iehova, no ka mea, ua hai mai kela ia lakou.
11 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó ṣe sí ọ kí Òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí Òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.
Alaila, i aku la lakou ia ia, Heaha ka makou e hana aku ai ia oe, i malie iho ai ke kai no kakou? no ka mea, ua nui ae ka inoino o ke kai.
12 Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú Òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”
A i mai la kela ia lakou, E lawe oukou ia'u, a e kiola ia'u iloko o ke kai, a e malie iho ke kai ia oukou: no ka mea, ua ike au, no'u nei i hiki mai ai keia ino nui maluna o oukou.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà gbìyànjú gidigidi láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí Òkun túbọ̀ ru sí i, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn.
A hoe ikaika aku la na kanaka e hoi hou i ka aina; aole lakou e hiki: no ka mea, ua nui ae ka inoino o ke kai ia lakou.
14 Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.”
No ia mea, kahea aku la lakou ia Iehova, i aku la, Ke noi aku nei makou ia oe, e Iehova, ke noi aku nei makou, mai lukuia makou no ke ola o keia kanaka, a mai hoopai ia makou i ke koko hala ole: no ka mea, ua hana mai oe, e Iehova, e like me kou makemake.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jona, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú Òkun, Òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀.
Nolaila, kaikai ae la lakou ia Iona a kiola aku la ia ia iloko o ke kai: e malie iho la ke kai mai kona kupikipikio ana.
16 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.
Alaila, makau nui loa iho la na kanaka ia Iehova, a kaumaha aku lakou i mohai ia Iehova, a hoohiki i na hoohiki ana.
17 Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèsè ẹja ńlá kan láti gbé Jona mì. Jona sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.
A ua hoomakaukau o Iehova i ia nui e ale iho ia Iona. A ekolu ao, a ekolu po o Iona ileko o ka opu o ka ia.

< Jonah 1 >