< John 1 >
1 Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
B'resheet ·In the beginning of the beginning· was ha D'var ·the Word·, and ha D'var ·the Word· was with God, and ha D'var ·the Word· was God.
2 Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
The same was in the beginning with God.
3 Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
All things came to be through him and without him nothing made had being.
4 Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
In him was life, and the life was the light of men.
5 ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
The light shines in the darkness, and the darkness has not overcome it.
6 Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
There came a man, sent from God, whose name was John [Yah is gracious].
7 Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
The same came as a witness, that he might testify about the light, that all might trust through him.
8 Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
He was not the light, but was sent that he might testify about the light.
9 Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
The true light that enlightens everyone was coming into the world.
10 Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
He was in the world, and the world was made through him, and the world didn’t recognize him.
11 Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
He came to his own, and those who were his own didn’t receive him.
12 Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
But as many as received him, to them he gave the right to become God’s children, to those who trust in his name:
13 Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
who were born not of blood, nor of the will of the flesh, nor of the will of man, but of God.
14 Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
Ha D'var ·The Word· became flesh, and tabernacled among us. We saw his shekhinah ·manifest weighty glory and presence of God·, such shekhinah ·manifest weighty glory and presence of God· as of the one and only Son of the Abba ·Father·, full of grace and truth.
15 Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
John [Yah is gracious] testified about him. He cried out, saying, “This was he of whom I said, ‘He who comes after me has surpassed me, for he was before me.’”
16 Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
From his fullness we all received grace upon grace.
17 Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
For the Torah ·Teaching· was given through Moses [Drawn out]; grace and truth came through Yeshua Messiah [Salvation Anointed one].
18 Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
No one has seen God at any time. The one and only Son, who is in the bosom of Abba ·Father familiar, Dear Dad·, he has declared him.
19 Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
This is John [Yah is gracious]’s testimony, when the Jews sent priests and Levites [Descendants of United with] from Jerusalem [City of peace] to ask him, “Who are you?”
20 Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
He declared, and didn’t deny, but he declared, “I am not the Messiah [Anointed one].”
21 Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
They asked him, “What then? Are you Elijah [My God Yah]?” He said, “I am not.” “Are you the prophet (promised Messiah)?” He answered, “No.”
22 Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
They said therefore to him, “Who are you? Give us an answer to take back to those who sent us. What do you say about yourself?”
23 Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
He said, “I am the voice of one crying in the wilderness, ‘Make straight the way of MarYah [Master Yahweh],’ as Isaiah [Salvation of Yah] the prophet said.”
24 Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
The ones who had been sent were from the Pharisees [Separated].
25 bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
They asked him, “Why then do you mikvah ·baptise·, if you are not the Messiah [Anointed one], nor Elijah [My God Yah], nor the prophet (promised Messiah)?”
26 Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
John [Yah is gracious] answered them, “I mikvah ·baptise· in water, but among you stands one whom you don’t know.
27 Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
He is the one who comes after me, who is preferred before me, whose sandal strap I’m not worthy to loosen.”
28 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
These things were done in Bethany [House of affliction] beyond the Jordan [Descender], where John [Yah is gracious] was baptizing.
29 Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
The next day, he saw Yeshua [Salvation] coming to him, and said, “Behold, the Lamb of God, who takes away the abstract sin ·miss the mark· of the world!
30 Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
This is he of whom I said, ‘After me comes a man who is preferred before me, for he was before me.’
31 Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
I didn’t know him, but for this reason I came baptizing in water: that he would be revealed to Israel [God prevails].”
32 Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
John [Yah is gracious] testified, saying, “I have seen haRuach [the Spirit, Breath] descending like a dove out of heaven, and it remained on him.
33 Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
I didn’t recognize him, but he who sent me to mikvah ·baptise· in water, he said to me, ‘On whomever you will see haRuach [the Spirit, Breath] descending, and remaining on him, the same is he who does mikvah ·baptise· in Ruach haKodesh [Spirit, Breath of the Holiness].’
34 Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
I have seen, and have testified that this is the Ben-Elohim ·Son of Elohim God·.”
35 Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Again, the next day, John [Yah is gracious] was standing with two of his disciples,
36 Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
and he looked at Yeshua [Salvation] as he walked, and said, “Behold, the Lamb of God!”
37 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
The two disciples heard him speak, and they followed Yeshua [Salvation].
38 Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
Yeshua [Salvation] turned, and saw them following, and said to them, “What are you looking for?” They said to him, “Rabbi!” (Which is to say, being interpreted, ·Teacher·). “Where are you staying?”
39 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
He said to them, “Come, and see.” They came and saw where he was staying, and they stayed with him that day. It was about four o'clock in the afternoon.
40 Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
One of the two who heard John [Yah is gracious], and followed him, was Andrew [Manly], Simeon Peter [Hearing Rock]’s brother.
41 Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
He first found his own brother, Simeon [Hearing], and said to him, “We have found the Messiah [Anointed one]!” (which is, being interpreted, Moshiach ·Anointed one·).
42 Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
He brought him to Yeshua [Salvation]. Yeshua [Salvation] looked at him, and said, “You are Simeon [Hearing] the son of Jonah [Dove]. You shall be called Cephas” (which is by interpretation, Peter [Rock]).
43 Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
On the next day, he was determined to go out into Galilee [District, Circuit], and he found Philip [Loves horses]. Yeshua [Salvation] said to him, “Follow me.”
44 Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
Now Philip [Loves horses] was from Bethsaida, of the city of Andrew [Manly] and Peter [Rock].
45 Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
Philip [Loves horses] found Nathanael [Given by God], and said to him, “We have found the one that Moses [Drawn out] wrote about in the Torah ·Teaching·, and the Prophets— it is Yeshua [Salvation] son of Joseph [May he add] from Nazareth [Branch, Separated one].”
46 Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
Nathanael [Given by God] said to him, “Can any good thing come out of Nazareth [Branch, Separated one]?” Philip [Loves horses] said to him, “Come and see.”
47 Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
Yeshua [Salvation] saw Nathanael [Given by God] coming to him, and said about him, “Behold, an Israelite [Descendant of God prevails] indeed, in whom is no deceit!”
48 Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
Nathanael [Given by God] said to him, “How do you know me?” Yeshua [Salvation] answered him, “Before Philip [Loves horses] called you, when you were under the fig tree, I saw you.”
49 Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
Nathanael [Given by God] answered him, “Rabbi ·Teacher·, you are the Ben-Elohim ·Son of Elohim God·! You are Melek Isra'el [King of God prevails]!”
50 Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
Yeshua [Salvation] answered him, “Because I told you, ‘I saw you underneath the fig tree,’ do you trust? You will see greater things than these!”
51 Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”
He said to him, “Most certainly, I tell you, hereafter you will see heaven opened, and the angels of God ascending and descending on the Son of Man.”