< John 1 >
1 Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
Akcük ma säiha Ngthu a na veki; Ngthu cun Mhnam am atänga veki, Ngthu cun Mhnama kyaki.
2 Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
Ngthu cun akcük ma säih üngkhyüh Mhnam am a na veki.
3 Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
Ahmäi naküt ani üngkhyüh Pamhnam naw a mhnüna kyaki; mhnünmceng naküt üng ani am ngpüikia mhnün i pi am ve.
4 Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
Ngthu cun xünnaka phungnua kyaki; acuna xünnak naw khyangea vei akvai lawpüiki.
5 ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
Akvai cun anghmüpnaka vai law se, nghmüp naw am näng mkhüt.
6 Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
Pamhnam naw a ngsä mat a tüih law, a ngming cun Johana kyaki.
7 Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
Ani naw khyangea veia akvaia mawng cun pyen se, khyange naw ngja u lü ami jumei law vai ua phäha kyaki.
8 Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
Amät cun akvai am ni, akvaia mawng pyen khaia lawki.
9 Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
Ani cun akvai kcang, khawmdek khana law lü khyang naküta khana vaiki.
10 Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
Ngthu cun khawmdek khana veki, khawmdek cun ani üngkhyüh mhnünmcenga kyaki. Acunsepi khawmdek naw ani am ksing.
11 Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
Amäta khyangea veia lawki. Acunsepi, amäta khyange naw am dokhamei u.
12 Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
Acunsepi, avang naw doei lü jumei u se, Pamhnama caea thawn theinak a jah pet.
13 Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
Acun he cun nghngicima mtisa thithaü üngkhyüh cawmbei lawkie am ni. Khyanga pasang üngka naw ngtüi lawkie pi am ni u, amimia pa ta Pamhnam ni.
14 Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
Ngthu cun nghngicima ngtüi lawki; bäkhäknak ja ngthungtak am be lü mi ksunga veki. Paa ca mat däka hlüngtainaka kba, a hlüngtainak cun mi hmuhki.
15 Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
Johan naw ania mawng a pyen ta, ‘Ka pyen khawi cen ani ni, “Ani cun ka hnua law kyaw sepi ka maa a na ve pängki ni” a ti.
16 Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
Kümceikia ania bäkhäknak am dawkyanaka thea dawkyanak mi van naw mi yahki.
17 Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
Thum cun Mosia kut üngkhyüh Pamhnam naw a jah peta kyaki. Acunsepi, bäkhäknak ja ngthungtak ta Jesuh Khritaw üngkhyüh a jah peta kyaki.
18 Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
U naw pi Pamhnam am hmuh khawi. Pamhnam am täng lü, Paa peia veki, a Capa mat däk naw paa mawng jah ksingsak pängki.
19 Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
Jerusalema veki Judah ngvaie naw, “Nang u ni?” ti lü, kthäh acun hea ktaiyü he ja Levihe Johana veia ami jah tüih.
20 Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
Johan naw käh mjih lü, “Kei Mesijah am ni ngü,” ti lü a jah msang.
21 Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
Amimi naw, “Nang u ni? Nang Elijah aw?” ti lü ami kthäh. Johan naw, “Am ni ngü” a ti. “Nang Sahma aw?” ami ti. Johan naw, “Am ni ngü” ti lü, a jah msang.
22 Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
Amimi naw, “Acunüng nang u ni, jah mtheha? jah tüih lawkie kami jah mthehnak be vai ami ti. Namäta mawng hin ihawkba na pyenki ni?” ti lü ami kthäh betü u.
23 Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
Johan naw, “Sahma Hesajah naw a pyena mäiha, ‘Bawipaa lawnak vai lam ngsungsak u,’ ti lü khawmkyanga ngpyangki kthaia ka kyaki ni,” a ti.
24 Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
Pharisee naw ami jah tüiha khyange cun naw,
25 bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
“Mesijah am ni, Elijah am ni, sahmaa pi am na ni üng, ise Baptican na jah peki ni?” ti u lü ami kthäh betü u.
26 Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
Johan naw, “Kei naw tui am Baptican ka jah pe khawiki, nami ksunga khyang mat am nami ksing ngdüiki.
27 Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
Ani cun ka hnua law sepi, a khawdawk yüi suh pet khaia pi am nglawi ngü” ti lü, a jah msang.
28 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
Ahin avan cun Johan naw baptican a jah petnaka hnün Jordan mliktui pei Bethaniha thawnhlawkia kyaki.
29 Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
Angawi üng Johan naw Jesuh a veia law se hmuh lü, “Khawmdeka mkhyekatnak cehpüiki Pamhnama Toca teng u!
30 Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
Acan ni, ‘Keia kthaka dämduh bawki, ka hnua lawki kyaw, cunüngpi ka maa a na ve päng kungki ni,’ ka ti cen ani ni.
31 Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
Akcüka ani am ksing ngü, cunsepi, Isarele naw ani ami ksing law vaia, kei naw law lü tui am Baptican ka jah peki,” a ti.
32 Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
Johan naw a mawng pyen lü, “Ngmüimkhya cun müma mäiha khankhaw üngka naw kyum law lü a khana ngawki ka hmuh.
33 Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
“Akcüka ta ani ni ti am ksing ngü. Cunsepi, tui am Baptican ka jah pe khaia na tüih lawki Pamhnam naw, ‘Ngmüimkhya a khana kyum law lü a ngawhnaka khyang na hmuh üng, ani cun Ngmüimkhya Ngcim am Baptican jah pe khaia Khyang ni’ ti lü a na mtheh.
34 Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
Johan naw “Ani ka hmuh pängki, ani Pamhnama Capaa kyaki tia ka ning jah mthehki,” a ti.
35 Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Angawi betü üng, Johan naw axüisaw xawi nghngih am ngdüi lü,
36 Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
Jesuh law se hmuh lü, “Acan ni Pamhnama Toca,” a ti.
37 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
Axüisaw xawi naw a pyen ngja ni lü, Jesuh läki xawi.
38 Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
Jesuh naw ani veia nghlat lü läk law ni se a jah hmuh üng, “I nani suiki” ti lü, a jah kthäh. Anini naw, ‘Rabbi (Saja tinak), hawia na veki?” ani ti.
39 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
Jesuh naw, “Law ni lü nani hmuh khai,” a ti. Cit ni lü a venak ani hmuh, acuna mhnüp cun a hlawnga veeiki xawi; acun cun mülama (Naji kphyü bang) kyaki.
40 Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
Johana ngthu pyen ngja ni lü, Jesuh läki nghngih üngka mat cun Sihmon Pita a na Andrua kyaki.
41 Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
Andru naw akcüka a be Sihmon hmuh lü, “Mesijah hmuh ve ung” ti lü, a mtheh (Mesijah ti cun Khritaw tinak ni).
42 Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
Acunüng, Sihmon cun Jesuha veia a lawpüi. Jesuh naw teng lü, “Nang hin Johana capa Sihmon na ngmingnaki, Kephaa ning sui khaie,” a ti (Acun cun Pita üng täng lü, “Lung” tinaka kyaki).
43 Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
Angawi üng Jesuh Kalile khawa cit khaia a ngtün üng, Philip hmuh lü, “Na läk lawa” a ti. (
44 Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
Philip cun Bethsaida mlüha kaa kyaki, acun cun Andru ja Pitaa ani venaka mlüha kyaki.)
45 Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
Philip naw Natanelah hmuh lü, “Mosi naw ania mawng Thum üng a yuk, sahma he naw pi a mawng ami yuk, Nazaret üngka, Josepa capa Jesuh, kami hmuhkie” ti lü a mtheh.
46 Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
Natanelah naw, “Nazaret mlüha cimvaiki ve khai aw?” a ti. Philip naw, “Law lü, teng lawa” a ti be.
47 Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
Jesuh naw, Natanelah a veia law se hmuh lü, “A mkhyenak lang am vekia Isarel khyang kcang, teng ua” ti lü, a pyen.
48 Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
Natanelah naw, “Nang naw ihawkba na na ksing ni?” a ti. Jesuh naw, “Philip naw am a ning khü ham lü, Fikdung phunga na ve üng ka ning hmuh päng ni” a ti be.
49 Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
Natanelah naw, “Rabbi, nang Pamhnama Capa ni, Isarelea Sangpuxanga pi kya veki,” a ti.
50 Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
Jesuh naw, “Fikdung phunga na ve üng ka ning hmuh päng ni’ ka tia phäha na na kcangnaki aw? Ahina kthaka dämduh bawki na hmuh law khai,” a ti.
51 Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”
Jesuh bä naw, “Akcanga ka ning jah mthehki. Tuha khankhaw nghmawng lü Pamhnama khankhawngsäe Khyanga Capaa khana ju kyum jeng kai u se nami jah hmuh law khai,” a ti.