< John 9 >
1 Bí ó sì ti ń kọjá lọ, ó rí ọkùnrin kan tí ó fọ́jú láti ìgbà ìbí rẹ̀ wá.
Conforme Jesus caminhava, ele viu um homem que havia nascido cego.
2 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi í léèrè, pé, “Rabbi, ta ní ó dẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin yìí tàbí àwọn òbí rẹ̀, tí a fi bí i ní afọ́jú?”
Os seus discípulos lhe perguntaram: “Rabi, por que este homem nasceu cego? Foi ele quem pecou ou foram os pais dele?”
3 Jesu dáhùn pé, “Kì í ṣe nítorí pé ọkùnrin yìí dẹ́ṣẹ̀, tàbí àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n kí a ba à lè fi iṣẹ́ Ọlọ́run hàn lára rẹ̀.
Jesus respondeu: “Isso não aconteceu porque ele ou os pais dele pecaram. Mas para que o poder de Deus se manifeste na vida dele.
4 Èmi ní láti ṣe iṣẹ́ ẹni tí ó rán mi, níwọ̀n ìgbà tí ó bá ti jẹ́ ọ̀sán, òru ń bọ̀ wá nígbà tí ẹnìkan kì yóò lè ṣe iṣẹ́.
Nós precisamos continuar fazendo o trabalho daquele que me enviou enquanto ainda é dia. Está chegando a noite, quando ninguém pode trabalhar.
5 Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé.”
Enquanto estou no mundo, eu sou a luz do mundo.”
6 Nígbà tí ó ti wí bẹ́ẹ̀ tan, ó tutọ́ sílẹ̀, ó sì fi itọ́ náà ṣe amọ̀, ó sì fi amọ̀ náà ra ojú afọ́jú náà.
Após dizer isso, Jesus cuspiu no chão e fez um pouco de lama com a saliva. Ele, então, pegou a lama e a colocou nos olhos do cego.
7 Ó sì wí fún un pé, “Lọ wẹ̀ nínú adágún Siloamu!” (Ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ yìí ni “rán”). Nítorí náà ó gba ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó wẹ̀, ó sì dé, ó ń ríran.
Depois, Jesus lhe disse: “Vá e lave o rosto no Tanque de Siloé” (que significa “enviado”). O homem foi, lavou o rosto e voltou vendo.
8 Ǹjẹ́ àwọn aládùúgbò àti àwọn tí ó rí i nígbà àtijọ́ pé alágbe ni ó jẹ́, wí pé, “Ẹni tí ó ti ń jókòó ṣagbe kọ́ yìí?”
Os vizinhos dele e as pessoas que o viam pedindo esmola, perguntaram: “Este não é o homem que costumava se sentar e pedir esmola?”
9 Àwọn kan wí pé òun ni. Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ó jọ ọ́ ni.” Ṣùgbọ́n òun wí pé, “Èmi ni.”
Algumas pessoas diziam que era ele, enquanto outras diziam: “Não, é apenas alguém que se parece com ele.” Mas, o homem continuava dizendo: “Sou eu!”
10 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Bá wo ni ojú rẹ ṣe là?”
Eles perguntaram: “Então, como você conseguiu enxergar?”
11 Ó dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Jesu ni ó ṣe amọ̀, ó sì fi kun ojú mí, ó sì wí fún mi pé, Lọ sí adágún Siloamu, kí o sì wẹ̀, èmi sì lọ, mo wẹ̀, mo sì ríran.”
Ele respondeu: “Um homem, chamado Jesus, fez um pouco de lama, colocou-a em meus olhos e me disse: ‘Vá e lave o rosto no Tanque de Siloé.’ Então, fiz o que ele me disse e agora eu consigo enxergar.”
12 Wọ́n sì wí fún un pé, “Òun náà ha dà?” Ó sì wí pé, “Èmi kò mọ̀.”
As pessoas perguntaram: “Onde ele está?” E o homem respondeu: “Eu não sei!”
13 Wọ́n mú ẹni tí ojú rẹ̀ ti fọ́ rí wá sọ́dọ̀ àwọn Farisi.
Eles levaram o homem que tinha sido cego aos fariseus.
14 Ọjọ́ ìsinmi ni ọjọ́ náà nígbà tí Jesu ṣe amọ̀, tí ó sì là á lójú.
Jesus tinha feito a lama e aberto os olhos do homem cego em um dia de sábado.
15 Nítorí náà àwọn Farisi pẹ̀lú tún bi í léèrè, bí ó ti ṣe ríran. Ọkùnrin náà fèsì, “Ó fi amọ̀ lé ojú mi, mo sì wẹ̀, báyìí mo sì ríran.”
Então, os fariseus também perguntaram ao homem como ele conseguiu enxergar. Ele falou para os fariseus: “Ele colocou a lama em meus olhos. Então, eu fui, lavei meu rosto e agora eu consigo enxergar.”
16 Nítorí náà àwọn kan nínú àwọn Farisi wí pé, “Ọkùnrin yìí kò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, nítorí tí kò pa ọjọ́ ìsinmi mọ́.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Ọkùnrin tí í ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò ha ti ṣe lè ṣe irú iṣẹ́ àmì wọ̀nyí?” Ìyapa sì wà láàrín wọn.
Alguns fariseus disseram: “O homem que fez isso não pode ser de Deus, pois ele não respeita a lei do sábado.” Mas, outros perguntaram: “Como poderia um pecador fazer tais milagres?” Assim, houve uma divisão de opiniões no grupo dos fariseus.
17 Nítorí náà, wọ́n sì tún wí fún afọ́jú náà pé, “Kí ni ìwọ ní wí nípa rẹ̀, nítorí tí ó là ọ́ lójú?” Ó sì wí pé, “Wòlíì ní í ṣe.”
Então, eles continuaram perguntando ao homem: “Qual é a sua opinião sobre ele, já que foram os seus olhos que ele curou?” O homem respondeu: “Ele é um profeta!”
18 Nítorí náà àwọn Júù kò gbàgbọ́ nípa rẹ̀ pé ojú rẹ̀ ti fọ́ rí, àti pé ó sì tún ríran, títí wọ́n fi pe àwọn òbí ẹni tí a ti là lójú.
Os líderes judeus não acreditaram que o homem, antes cego, agora pudesse enxergar. Então, eles chamaram os pais do homem.
19 Wọ́n sì bi wọ́n léèrè wí pé, “Ǹjẹ́ èyí ni ọmọ yín, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, a bí ní afọ́jú? Báwo ni ó ṣe ríran nísinsin yìí?”
Eles perguntaram aos pais dele: “Este homem é o filho de vocês, que dizem ter nascido cego? Então, como é possível que agora ele consiga enxergar?”
20 Àwọn òbí rẹ̀ dá wọn lóhùn wí pé, “Àwa mọ̀ pé ọmọ wa ni èyí, àti pé a bí i ní afọ́jú,
Os pais do homem responderam: “Nós reconhecemos que este é o nosso filho que nasceu cego.
21 ṣùgbọ́n bí ó tí ṣe ń ríran nísinsin yìí àwa kò mọ̀, ẹni tí ó là á lójú, àwa kò mọ̀, ẹni tí ó ti dàgbà ni òun; ẹ bi í léèrè, yóò wí fúnra rẹ̀.”
Mas, não temos ideia de como ele consegue enxergar agora, ou quem o curou. Por que vocês não perguntam a ele? Afinal, ele tem idade o bastante para responder por si mesmo.”
22 Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn òbí rẹ̀ sọ, nítorí tí wọ́n bẹ̀rù àwọn Júù: nítorí àwọn Júù ti fohùn ṣọ̀kan pé bí ẹnìkan bá jẹ́wọ́ pé Kristi ni, wọn ó yọ ọ́ kúrò nínú Sinagọgu.
O motivo dos pais dele dizerem isso era porque tinham medo do que os líderes judeus fariam. Os líderes judeus já haviam anunciado que qualquer pessoa que declarasse que Jesus era o Messias seria expulso da sinagoga.
23 Nítorí èyí ni àwọn òbí rẹ̀ fi wí pé, “Ẹni tí ó dàgbà ni òun, ẹ bi í léèrè.”
Por isso os pais do homem disseram: “Perguntem a ele; afinal, ele tem idade o bastante.”
24 Nítorí náà, wọ́n pe ọkùnrin afọ́jú náà lẹ́ẹ̀kejì, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ògo fún Ọlọ́run, àwa mọ̀ pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọkùnrin yìí jẹ́.”
Uma vez mais eles chamaram o homem que tinha sido cego e lhe disseram: “Dê a glória a Deus! Nós sabemos que esse homem é um pecador.”
25 Nítorí náà, ó dáhùn ó sì wí pé, “Bí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni, èmi kò mọ̀, Ohun kan ni mo mọ̀, pé mo tí fọ́jú rí, nísinsin yìí mo ríran.”
O homem respondeu: “Se ele é um pecador ou não, eu não sei. Tudo o que eu sei é que eu era cego e agora posso enxergar.”
26 Nítorí náà, wọ́n wí fún un pé, “Kí ni ó ṣe ọ́? Báwo ni ó ṣe là ọ́ lójú.”
Então, eles perguntaram ao homem: “O que ele fez para você? Como ele curou os seus olhos?”
27 Ó dá wọn lóhùn wí pé, “Èmi ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, ẹ̀yin kò sì gbọ́, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe ń fẹ́ tún gbọ́? Ẹ̀yin pẹ̀lú ń fẹ́ ṣe ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bí?”
Ele respondeu: “Eu já disse a vocês. Vocês não estavam me escutando? Por que vocês querem ouvir isso novamente? Vocês, por acaso, querem ser discípulos dele também?”
28 Wọ́n sì fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ni ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n ọmọ-ẹ̀yìn Mose ni àwa.
Eles o xingaram e disseram: “Discípulo dele é você!
29 Àwa mọ̀ pé Ọlọ́run bá Mose sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti eléyìí, àwa kò mọ ibi tí ó ti wá.”
Nós somos discípulos de Moisés. Nós sabemos que Deus falou com Moisés, mas quanto a esse homem, não sabemos nem mesmo de onde ele é.”
30 Ọkùnrin náà dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ohun ìyanu sá à ni èyí, pé ẹ̀yin kò mọ ibi tí ó tí wá, ṣùgbọ́n òun sá à ti là mí lójú.
O homem, então, respondeu: “É incrível! Vocês não sabem de onde ele é, mas ele curou os meus olhos.
31 Àwa mọ̀ pé Ọlọ́run kì í gbọ́ ti ẹlẹ́ṣẹ̀; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣe olùfọkànsìn sí Ọlọ́run, tí ó bá sì ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀, Òun ni ó ń gbọ́ tirẹ̀.
Nós sabemos que Deus não ouve pecadores, mas, sim, ouve qualquer um que o louve e que faça a sua vontade.
32 Láti ìgbà tí ayé ti ṣẹ̀, a kò ì tí ì gbọ́ pé ẹnìkan la ojú ẹni tí a bí ní afọ́jú rí. (aiōn )
Desde que o mundo existe, nunca se ouviu dizer que alguém tenha curado alguém que nasceu cego. (aiōn )
33 Ìbá ṣe pé ọkùnrin yìí kò ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, kì bá tí lè ṣe ohunkóhun.”
Se esse homem não tivesse vindo de Deus, ele não poderia fazer nada.”
34 Sí èyí, wọ́n fèsì pé, “Láti ìbí ni o tì jíngírí nínú ẹ̀ṣẹ̀, ìwọ ha fẹ́ kọ́ wa bí?” Wọ́n sì tì í sóde.
Eles responderam: “Você nasceu cheio de pecado e ainda quer nos ensinar?” E o expulsaram da sinagoga.
35 Jesu gbọ́ pé, wọ́n ti tì í sóde; nígbà tí ó sì rí i, ó wí pe, “Ìwọ gba Ọmọ Ọlọ́run, gbọ́ bí?”
Quando Jesus ouviu o que os líderes judeus tinham feito com o homem, foi encontrá-lo e lhe perguntou: “Você crê no Filho do Homem?”
36 Òun sì dáhùn wí pé, “Ta ni, Olúwa, kí èmi lè gbà á gbọ́?”
O homem respondeu: “Diga-me quem ele é, senhor, assim posso crer nele.”
37 Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti rí i, Òun náà sì ni ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí.”
“Você já o viu. Ele é quem está falando com você neste exato momento”, Jesus lhe disse.
38 Ó sì wí pé, “Olúwa, mo gbàgbọ́,” ó sì wólẹ̀ fún un.
“Eu creio em você, Senhor!”, ele disse. Então, se ajoelhou diante de Jesus e o adorou.
39 Jesu sì wí pé, “Nítorí ìdájọ́ ni mo ṣe wá sí ayé yìí, kí àwọn tí kò ríran lè ríran; àti kí àwọn tí ó ríran lè di afọ́jú.”
Depois, Jesus lhe disse: “Eu vim ao mundo para julgar, para que os cegos possam ver e os que veem fiquem cegos.”
40 Nínú àwọn Farisi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa pẹ̀lú fọ́jú bí?”
Alguns fariseus que estavam lá com Jesus lhe perguntaram: “Por acaso, nós também somos cegos?”
41 Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé ẹ̀yin fọ́jú, ẹ̀yin kì bá tí lẹ́sẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa ríran,’ nítorí náà ẹ̀ṣẹ̀ yín wà síbẹ̀.
Jesus respondeu: “Se vocês fossem cegos, não seriam culpados. Mas, agora que vocês dizem que podem ver, a culpa de vocês permanece.”