< John 8 >

1 Jesu sì lọ sí orí òkè olifi.
Dar Isus s-a dus pe Muntele Măslinilor.
2 Ó sì tún padà wá sí tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gbogbo ènìyàn sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì jókòó, ó ń kọ́ wọn.
Și, dis-de-dimineață, a intrat din nou în Templu și tot poporul a venit la El. El a șezut jos și i-a învățat.
3 Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi sì mú obìnrin kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, tí a mú nínú ṣíṣe panṣágà; wọ́n sì mú un dúró láàrín.
Cărturarii și fariseii au adus o femeie prinsă în adulter. După ce au așezat-o la mijloc,
4 Wọ́n sì wí fún un pé, “Olùkọ́, a mú obìnrin yìí nínú ìṣe panṣágà.
i-au spus: “Învățătorule, am găsit-o pe această femeie în adulter, chiar în flagrant.
5 Ǹjẹ́ nínú òfin, Mose pàṣẹ fún wa láti sọ irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ ní òkúta, ṣùgbọ́n ìwọ ha ti wí?”
Or, în legea noastră, Moise ne-a poruncit să ucidem cu pietre astfel de femei. Ce spui, așadar, despre ea?”
6 Èyí ni wọ́n wí, láti dán án wò, kí wọn ba à lè rí ẹ̀sùn kan kà sí i lọ́rùn. Ṣùgbọ́n Jesu bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ń fi ìka rẹ̀ kọ̀wé ní ilẹ̀.
Ei au spus aceasta punându-l la încercare, ca să aibă de ce să-l acuze. Dar Isus s-a aplecat și a scris cu degetul pe pământ.
7 Nígbà tí wọ́n ń bi í léèrè lemọ́lemọ́, ó gbe orí rẹ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Jẹ́ kí ẹni tí ó wà láìní ẹ̀ṣẹ̀ nínú yín kọ́kọ́ sọ òkúta lù ú.”
Dar, când ei continuau să-L întrebe, El și-a ridicat privirea și le-a zis: “Cine dintre voi este fără de păcat, să arunce primul cu piatra în ea.”
8 Ó sì tún bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó ń kọ̀wé ní ilẹ̀.
Și iarăși s-a aplecat și a scris cu degetul pe pământ.
9 Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, wọ́n sì jáde lọ lọ́kọ̀ọ̀kan, bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbà títí dé àwọn tí ó kẹ́yìn; a sì fi Jesu nìkan sílẹ̀, àti obìnrin náà láàrín, níbi tí ó wà.
Când au auzit, ei, încredințați de conștiința lor, au ieșit unul câte unul, începând de la cel mai bătrân până la cel din urmă. Isus a rămas singur cu femeia acolo unde era, în mijloc.
10 Jesu sì dìde, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, àwọn olùfisùn rẹ dà? Kò sí ẹnìkan tí ó dá ọ lẹ́bi?”
Isus, ridicându-se în picioare, a văzut-o și a zis: “Femeie, unde sunt acuzatorii tăi? Nu te-a condamnat nimeni?”.
11 Ó wí pé, “Kò sí ẹnìkan, Olúwa.” Jesu wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni èmi náà kò dá ọ lẹ́bi, máa lọ, láti ìgbà yìí lọ, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́.”
Ea a răspuns: “Nimeni, Doamne.” Isus a spus: “Nici Eu nu vă condamn. Mergeți pe drumul vostru. De acum încolo, să nu mai păcătuiești”.
12 Jesu sì tún sọ fún wọn pé, “Èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé, ẹni tí ó bá tọ̀ mí lẹ́yìn kì yóò rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n yóò ní ìmọ́lẹ̀ ìyè.”
Isus le-a vorbit din nou, zicând: “Eu sunt lumina lumii. Cine Mă urmează pe Mine nu va umbla în întuneric, ci va avea lumina vieții."
13 Nítorí náà àwọn Farisi wí fún un pé, “Ìwọ ń jẹ́rìí ara rẹ; ẹ̀rí rẹ kì í ṣe òtítọ́.”
Fariseii I-au zis: “Tu mărturisești despre tine însuți. Mărturia ta nu este valabilă”.
14 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo tilẹ̀ ń jẹ́rìí fún ara mi, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi: nítorí tí mo mọ ibi tí mo ti wá, mo sì mọ ibi tí mo ń lọ; ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò lè mọ ibi tí mo ti wá, àti ibi tí mo ń lọ.
Isus le-a răspuns: “Chiar dacă mărturisesc despre mine însumi, mărturia mea este adevărată, căci eu știu de unde am venit și unde mă duc; dar voi nu știți de unde am venit și unde mă duc.
15 Ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ nípa ti ara; èmi kò ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni.
Voi judecați după trup. Eu nu judec pe nimeni.
16 Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì ṣe ìdájọ́, òtítọ́ ni, nítorí èmi nìkan kọ́, ṣùgbọ́n èmi àti Baba tí ó rán mi.
Chiar dacă judec, judecata mea este adevărată, pentru că nu sunt singur, ci sunt cu Tatăl care m-a trimis.
17 A sì kọ ọ́ pẹ̀lú nínú òfin pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí ènìyàn méjì.
De asemenea, este scris în legea voastră că mărturia a doi oameni este valabilă.
18 Èmi ni ẹni tí ń jẹ́rìí ara mi, Baba tí ó rán mi sì ń jẹ́rìí mi.”
Eu sunt cel care mărturisește despre mine însumi, iar Tatăl care m-a trimis mărturisește despre mine.”
19 Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Níbo ni Baba rẹ wà?” Jesu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ mí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò mọ Baba mi, ìbá ṣe pé ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá sì ti mọ Baba mi pẹ̀lú.”
Și I-au zis: “Unde este Tatăl Tău?” Isus a răspuns: “Nu Mă cunoașteți nici pe Mine, nici pe Tatăl Meu. Dacă M-ați cunoaște pe Mine, L-ați cunoaște și pe Tatăl Meu.”
20 Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Jesu sọ níbi ìṣúra, bí ó ti ń kọ́ni ní tẹmpili, ẹnikẹ́ni kò sì mú un; nítorí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
Isus a rostit aceste cuvinte în vistierie, în timp ce învăța în templu. Dar nimeni nu l-a arestat, pentru că nu venise încă ceasul lui.
21 Nítorí náà ó tún wí fún wọn pé, “Èmi ń lọ, ẹ̀yin yóò sì wá mi, ẹ ó sì kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá.”
Isus le-a spus deci din nou: “Mă duc, și voi mă veți căuta și veți muri în păcatele voastre. Unde Mă duc Eu, voi nu puteți veni”.
22 Nítorí náà àwọn Júù wí pé, “Òun ó ha pa ara rẹ̀ bí? Nítorí tí ó wí pé, ‘Ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá’?”
Iudeii ziceau: “Oare se va omorî El însuși, pentru că zice: “Unde Mă duc Eu, voi nu puteți veni”?”
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ìsàlẹ̀ wá; èmi ti òkè wá; ẹ̀yin jẹ́ ti ayé yìí; èmi kì í ṣe ti ayé yìí.
El le-a zis: “Voi sunteți de jos. Eu sunt de sus. Voi sunteți din lumea aceasta. Eu nu sunt din lumea aceasta.
24 Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, nítorí bí kò ṣe pé ẹ bá gbàgbọ́ pé èmi ni, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
De aceea v-am spus că veți muri în păcatele voastre; căci, dacă nu credeți că Eu sunt, veți muri în păcatele voastre.”
25 Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ jẹ́?” Jesu sì wí fún un pé, “Èmi ni èyí tí mo ti wí fún yín ní àtètèkọ́ṣe.
Și I-au zis: “Cine ești Tu?” Isus le-a spus: “Exact ceea ce v-am spus de la început.
26 Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ, àti láti ṣe ìdájọ́ nípa yín, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ohun tí èmi sì ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, wọ̀nyí ni èmi ń sọ fún aráyé.”
Am multe lucruri de spus și de judecat cu privire la voi. Totuși, cel care m-a trimis este adevărat; și lucrurile pe care le-am auzit de la el, acestea le spun lumii.”
27 Kò yé wọn pé ti Baba ni ó ń sọ fún wọn.
Ei nu înțelegeau că El le vorbea despre Tatăl.
28 Lẹ́yìn náà Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ mọ̀ pé, nígbà tí ẹ bá gbé Ọmọ Ènìyàn sókè, nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ pé èmi ni àti pé èmi kò dá ohunkóhun ṣe fún ara mi, ṣùgbọ́n bí Baba ti kọ́ mi, èmí ń sọ nǹkan wọ̀nyí.
Isus le-a zis deci: “Când veți ridica pe Fiul Omului, atunci veți cunoaște că Eu sunt El și nu fac nimic de la mine însumi, ci spun aceste lucruri așa cum M-a învățat Tatăl Meu.
29 Ẹni tí ó rán mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, kò fi mí sílẹ̀ ní èmi nìkan; nítorí tí èmi ń ṣe ohun tí ó wù ú nígbà gbogbo.”
Cel care m-a trimis este cu mine. Tatăl nu m-a lăsat singur, pentru că eu fac întotdeauna lucrurile care îi sunt plăcute.”
30 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn gbà á gbọ́.
Pe când vorbea El aceste lucruri, mulți au crezut în El.
31 Nítorí náà Jesu wí fún àwọn Júù tí ó gbà á gbọ́, pé, “Bí ẹ bá tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ mi ẹ ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi nítòótọ́.
Isus a zis deci iudeilor care crezuseră în El: “Dacă rămâneți în cuvântul Meu, sunteți cu adevărat ucenicii Mei.
32 Ẹ ó sì mọ òtítọ́, òtítọ́ yóò sì sọ yín di òmìnira.”
Veți cunoaște adevărul și adevărul vă va face liberi.”
33 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Irú-ọmọ Abrahamu ni àwa jẹ́, àwa kò sì ṣe ẹrú fún ẹnikẹ́ni rí láé; ìwọ ha ṣe wí pé, ‘Ẹ ó di òmìnira’?”
Ei i-au răspuns: “Noi suntem urmașii lui Avraam și n-am fost niciodată robi nimănui. Cum spui tu: “Veți fi liberi”?”
34 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Isus le-a răspuns: “Adevărat vă spun că oricine săvârșește un păcat este robul păcatului.
35 Ẹrú kì í sì í gbé ilé títí láé, ọmọ ní ń gbé ilé títí láé. (aiōn g165)
O roabă nu locuiește în casă pentru totdeauna. Un fiu rămâne pentru totdeauna. (aiōn g165)
36 Nítorí náà, bí Ọmọ bá sọ yín di òmìnira ẹ ó di òmìnira nítòótọ́.
Așadar, dacă Fiul vă face liberi, veți fi cu adevărat liberi.
37 Mo mọ̀ pé irú-ọmọ Abrahamu ni ẹ̀yin jẹ́; ṣùgbọ́n ẹ ń wá ọ̀nà láti pa mí nítorí ọ̀rọ̀ mi kò rí ààyè nínú yín. Jesu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ nípa ara rẹ̀.
Știu că sunteți urmașii lui Avraam, dar voi căutați să mă omorâți, pentru că cuvântul meu nu-și găsește locul în voi.
38 Ohun tí èmi ti rí lọ́dọ̀ Baba ni mo sọ, ẹ̀yin pẹ̀lú sì ń ṣe èyí tí ẹ̀yin ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ baba yín.”
Eu spun lucrurile pe care le-am văzut la Tatăl meu, iar voi faceți și voi lucrurile pe care le-ați văzut la tatăl vostru.”
39 Wọ́n dáhùn, wọ́n sì wí fún un pé, “Abrahamu ni baba wa!” Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ìbá ṣe iṣẹ́ Abrahamu.
Ei i-au răspuns: “Tatăl nostru este Avraam.” Isus le-a zis: “Dacă ați fi copiii lui Avraam, ați face faptele lui Avraam.
40 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń wá ọ̀nà láti pa mí, ẹni tí ó sọ òtítọ́ fún yín, èyí tí mo ti gbọ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, Abrahamu kò ṣe èyí.
Dar acum căutați să Mă omorâți pe Mine, un om care v-a spus adevărul pe care l-am auzit de la Dumnezeu. Avraam nu a făcut asta.
41 Ẹ̀yin ń ṣe iṣẹ́ baba yín.” Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “a kò bí wa nípa panṣágà, a ní Baba kan, èyí sì ni Ọlọ́run.”
Voi faceți faptele tatălui vostru.” Ei i-au spus: “Noi nu ne-am născut din imoralitate sexuală. Noi avem un singur Tată, Dumnezeu”.
42 Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé Ọlọ́run ni Baba yín, ẹ̀yin ìbá fẹ́ràn mi, nítorí tí èmi ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run jáde, mo sì wá; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n òun ni ó rán mi.
Isus le-a zis: “Dacă Dumnezeu ar fi tatăl vostru, M-ați iubi, căci Eu am ieșit și am venit de la Dumnezeu. Căci nu am venit de la mine însumi, ci el m-a trimis.
43 Èéṣe tí èdè mi kò fi yé yín? Nítorí ẹ kò lè gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
De ce nu înțelegeți vorbirea mea? Pentru că nu puteți auzi cuvântul meu.
44 Ti èṣù baba yin ni ẹ̀yin jẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ baba yín ni ẹ sì ń fẹ́ ṣe. Apànìyàn ni òun jẹ́ láti àtètèkọ́ṣe, kò sì dúró nínú òtítọ́; nítorí tí kò sí òtítọ́ nínú rẹ̀. Nígbà tí ó bá ń ṣèké, nínú ohun tirẹ̀ ni ó ń sọ nítorí èké ni, àti baba èké.
Voi sunteți de la tatăl vostru, diavolul, și vreți să împliniți dorințele tatălui vostru. El a fost ucigaș de la început și nu stă în adevăr, pentru că nu este adevăr în el. Când vorbește o minciună, vorbește de unul singur, căci este un mincinos și tatăl minciunii.
45 Ṣùgbọ́n nítorí tí èmi ń sọ òtítọ́ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbà mí gbọ́.
Dar pentru că spun adevărul, voi nu mă credeți.
46 Ta ni nínú yín tí ó ti dá mi lẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀? Bí mo bá ń ṣọ òtítọ́, èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà mí gbọ́?
Care dintre voi mă convinge de păcat? Dacă spun adevărul, de ce nu mă credeți?
47 Ẹni tí ń ṣe ti Ọlọ́run, a máa gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, nítorí èyí ni ẹ̀yin kò ṣe gbọ́, nítorí ẹ̀yin kì í ṣe ti Ọlọ́run.”
Cine este de la Dumnezeu ascultă cuvintele lui Dumnezeu. De aceea voi nu auziți, pentru că nu sunteți din Dumnezeu.”
48 Àwọn Júù dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò wí nítòótọ́ pé, ará Samaria ni ìwọ jẹ́, àti pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù?”
Atunci Iudeii I-au răspuns: “Nu spunem noi bine că ești samaritean și că ai un demon?”
49 Jesu sì dáhùn pé, “Èmi kò ní ẹ̀mí èṣù, ṣùgbọ́n èmi ń bu ọlá fún Baba mi, ẹ̀yin kò sì bu ọlá fún mi.
Isus a răspuns: “Eu nu am niciun demon, dar Eu Îl cinstesc pe Tatăl Meu, iar voi Mă necinstiți.
50 Èmi kò wá ògo ara mi, ẹnìkan ń bẹ tí ó ń wá a tí yóò sì ṣe ìdájọ́.
Dar eu nu caut gloria mea. Există cineva care caută și judecă.
51 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò rí ikú láéláé.” (aiōn g165)
Mai mult ca sigur, vă spun că, dacă o persoană respectă cuvântul meu, nu va vedea niciodată moartea.” (aiōn g165)
52 Àwọn Júù wí fún un pé, “Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù. Abrahamu kú, àti àwọn wòlíì; ìwọ sì wí pé, ‘Bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò tọ́ ikú wò láéláé.’ (aiōn g165)
Atunci iudeii i-au zis: “Acum știm că ai un demon. Avraam a murit, ca și profeții, iar tu spui: “Dacă un om păzește cuvântul Meu, nu va gusta niciodată moartea”. (aiōn g165)
53 Ìwọ ha pọ̀ ju Abrahamu Baba wa lọ, ẹni tí ó kú? Àwọn wòlíì sì kú, ta ni ìwọ ń fi ara rẹ pè?”
Ești tu mai mare decât tatăl nostru Avraam, care a murit? Profeții au murit. Cine te dai tu drept cine ești?”.
54 Jesu dáhùn wí pé, “Bí mo bá yin ara mi lógo, ògo mi kò jẹ́ nǹkan, Baba mi ni ẹni tí ń yìn mí lógo, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, Ọlọ́run yín ní i ṣe.
Isus a răspuns: “Dacă mă slăvesc pe mine însumi, slava mea nu este nimic. Cel care mă slăvește pe mine este Tatăl meu, despre care voi spuneți că este Dumnezeul nostru.
55 Ẹ kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, bí mo bá sì wí pé, èmi kò mọ̀ ọ́n, èmi yóò di èké gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, mo sì pa ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́.
Voi nu L-ați cunoscut, dar Eu Îl cunosc. Dacă aș spune: “Nu-l cunosc”, aș fi ca voi, un mincinos. Dar eu îl cunosc și îi respect cuvântul.
56 Abrahamu baba yín yọ̀ láti rí ọjọ́ mi, ó sì rí i, ó sì yọ̀.”
Tatăl vostru Avraam s-a bucurat să vadă ziua mea. A văzut-o și s-a bucurat”.
57 Nítorí náà, àwọn Júù wí fún un pé, “Ọdún rẹ kò ì tó àádọ́ta, ìwọ sì ti rí Abrahamu?”
Și Iudeii i-au zis: “Nu ești încă în vârstă de cincizeci de ani! L-ai văzut tu pe Avraam?”
58 Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kí Abrahamu tó wà, èmi ti wa.”
Isus le-a zis: “Adevărat vă spun că, înainte ca Avraam să fi existat, EU SUNT.”
59 Nítorí náà wọ́n gbé òkúta láti sọ lù ú, ṣùgbọ́n Jesu fi ara rẹ̀ pamọ́, ó sì jáde kúrò ní tẹmpili.
Și au luat pietre ca să arunce în El; dar Isus S-a ascuns și a ieșit din templu, trecând prin mijlocul lor, și a trecut pe lângă ei.

< John 8 >