< John 8 >
1 Jesu sì lọ sí orí òkè olifi.
A Jezus poszedł na Górę Oliwną.
2 Ó sì tún padà wá sí tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, gbogbo ènìyàn sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì jókòó, ó ń kọ́ wọn.
Potem znowu wcześnie rano przyszedł do świątyni, a cały lud zszedł się do niego. I siadłszy, nauczał ich.
3 Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi sì mú obìnrin kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, tí a mú nínú ṣíṣe panṣágà; wọ́n sì mú un dúró láàrín.
I przyprowadzili do niego uczeni w Piśmie i faryzeusze kobietę przyłapaną na cudzołóstwie, a postawiwszy ją pośrodku;
4 Wọ́n sì wí fún un pé, “Olùkọ́, a mú obìnrin yìí nínú ìṣe panṣágà.
Powiedzieli do niego: Nauczycielu, tę kobietę przyłapano na uczynku cudzołóstwa.
5 Ǹjẹ́ nínú òfin, Mose pàṣẹ fún wa láti sọ irú àwọn obìnrin bẹ́ẹ̀ ní òkúta, ṣùgbọ́n ìwọ ha ti wí?”
W prawie Mojżesz nakazał nam takie kamienować. A ty co mówisz?
6 Èyí ni wọ́n wí, láti dán án wò, kí wọn ba à lè rí ẹ̀sùn kan kà sí i lọ́rùn. Ṣùgbọ́n Jesu bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ń fi ìka rẹ̀ kọ̀wé ní ilẹ̀.
A mówili to, wystawiając go na próbę, aby mogli go oskarżyć. Jezus zaś, schyliwszy się, pisał palcem po ziemi.
7 Nígbà tí wọ́n ń bi í léèrè lemọ́lemọ́, ó gbe orí rẹ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Jẹ́ kí ẹni tí ó wà láìní ẹ̀ṣẹ̀ nínú yín kọ́kọ́ sọ òkúta lù ú.”
A gdy nie przestawali go pytać, podniósł się i powiedział do nich: Kto z was jest bez grzechu, niech pierwszy rzuci w nią kamieniem.
8 Ó sì tún bẹ̀rẹ̀ sílẹ̀, ó ń kọ̀wé ní ilẹ̀.
I znowu schyliwszy się, pisał po ziemi.
9 Nígbà tí wọ́n gbọ́ èyí, wọ́n sì jáde lọ lọ́kọ̀ọ̀kan, bẹ̀rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn àgbà títí dé àwọn tí ó kẹ́yìn; a sì fi Jesu nìkan sílẹ̀, àti obìnrin náà láàrín, níbi tí ó wà.
A gdy oni to usłyszeli, będąc przekonani przez sumienie, odchodzili jeden po drugim, począwszy od starszych aż do ostatnich. Pozostał tylko sam Jezus i ta kobieta stojąca pośrodku.
10 Jesu sì dìde, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, àwọn olùfisùn rẹ dà? Kò sí ẹnìkan tí ó dá ọ lẹ́bi?”
A Jezus podniósł się i nie widząc nikogo oprócz tej kobiety, powiedział do niej: Kobieto, gdzież są ci, którzy cię oskarżali? Nikt cię nie potępił?
11 Ó wí pé, “Kò sí ẹnìkan, Olúwa.” Jesu wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni èmi náà kò dá ọ lẹ́bi, máa lọ, láti ìgbà yìí lọ, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́.”
Ona odpowiedziała: Nikt, Panie. A Jezus powiedział do niej: I ja ciebie nie potępiam. Idź i już więcej nie grzesz.
12 Jesu sì tún sọ fún wọn pé, “Èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé, ẹni tí ó bá tọ̀ mí lẹ́yìn kì yóò rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n yóò ní ìmọ́lẹ̀ ìyè.”
Jezus znowu powiedział do nich: Ja jestem światłością świata. Kto idzie za mną, nie będzie chodził w ciemności, ale będzie miał światłość życia.
13 Nítorí náà àwọn Farisi wí fún un pé, “Ìwọ ń jẹ́rìí ara rẹ; ẹ̀rí rẹ kì í ṣe òtítọ́.”
Powiedzieli więc do niego faryzeusze: Ty świadczysz sam o sobie, a twoje świadectwo nie jest prawdziwe.
14 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo tilẹ̀ ń jẹ́rìí fún ara mi, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi: nítorí tí mo mọ ibi tí mo ti wá, mo sì mọ ibi tí mo ń lọ; ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò lè mọ ibi tí mo ti wá, àti ibi tí mo ń lọ.
Odpowiedział im Jezus: Chociaż ja świadczę sam o sobie, [jednak] moje świadectwo jest prawdziwe, bo wiem, skąd przyszedłem i dokąd idę. Lecz wy nie wiecie, skąd przyszedłem i dokąd idę.
15 Ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ nípa ti ara; èmi kò ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni.
Wy sądzicie według ciała, ale ja nie sądzę nikogo.
16 Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì ṣe ìdájọ́, òtítọ́ ni, nítorí èmi nìkan kọ́, ṣùgbọ́n èmi àti Baba tí ó rán mi.
A choćbym i sądził, mój sąd jest prawdziwy, bo nie jestem sam, ale [jestem] ja i Ojciec, który mnie posłał.
17 A sì kọ ọ́ pẹ̀lú nínú òfin pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí ènìyàn méjì.
A w waszym Prawie jest napisane, że świadectwo dwóch ludzi jest prawdziwe.
18 Èmi ni ẹni tí ń jẹ́rìí ara mi, Baba tí ó rán mi sì ń jẹ́rìí mi.”
Ja jestem tym, który świadczy sam o sobie i świadczy o mnie Ojciec, który mnie posłał.
19 Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Níbo ni Baba rẹ wà?” Jesu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ mí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò mọ Baba mi, ìbá ṣe pé ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá sì ti mọ Baba mi pẹ̀lú.”
Wtedy zapytali go: Gdzie jest twój Ojciec? Jezus odpowiedział: Nie znacie ani mnie, ani mego Ojca. Gdybyście mnie znali, znalibyście i mego Ojca.
20 Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni Jesu sọ níbi ìṣúra, bí ó ti ń kọ́ni ní tẹmpili, ẹnikẹ́ni kò sì mú un; nítorí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
Te słowa mówił Jezus w skarbcu, nauczając w świątyni, a nikt go nie schwytał, bo jeszcze nie nadeszła jego godzina.
21 Nítorí náà ó tún wí fún wọn pé, “Èmi ń lọ, ẹ̀yin yóò sì wá mi, ẹ ó sì kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá.”
Wówczas Jezus znowu powiedział do nich: Ja odchodzę, a wy będziecie mnie szukać i umrzecie w swoim grzechu. Gdzie ja idę, wy przyjść nie możecie.
22 Nítorí náà àwọn Júù wí pé, “Òun ó ha pa ara rẹ̀ bí? Nítorí tí ó wí pé, ‘Ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò lè wá’?”
Wtedy Żydzi mówili: Czyż sam się zabije, skoro mówi: Gdzie ja idę, wy przyjść nie możecie?
23 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ìsàlẹ̀ wá; èmi ti òkè wá; ẹ̀yin jẹ́ ti ayé yìí; èmi kì í ṣe ti ayé yìí.
I powiedział do nich: Wy jesteście z niskości, a ja jestem z wysoka. Wy jesteście z tego świata, ja zaś nie jestem z tego świata.
24 Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, nítorí bí kò ṣe pé ẹ bá gbàgbọ́ pé èmi ni, ẹ ó kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
Dlatego wam powiedziałem, że umrzecie w swoich grzechach. Bo jeśli nie uwierzycie, że ja jestem, umrzecie w swoich grzechach.
25 Nítorí náà wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ jẹ́?” Jesu sì wí fún un pé, “Èmi ni èyí tí mo ti wí fún yín ní àtètèkọ́ṣe.
Wtedy zapytali go: Kim ty jesteś? I odpowiedział im Jezus: Tym, kim wam od początku mówię.
26 Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ, àti láti ṣe ìdájọ́ nípa yín, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ohun tí èmi sì ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, wọ̀nyí ni èmi ń sọ fún aráyé.”
Wiele mam o was do powiedzenia i do sądzenia. Ale ten, który mnie posłał, jest prawdziwy, a ja mówię na świecie to, co od niego słyszałem.
27 Kò yé wọn pé ti Baba ni ó ń sọ fún wọn.
Nie zrozumieli jednak, że mówił im o Ojcu.
28 Lẹ́yìn náà Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà tí ẹ mọ̀ pé, nígbà tí ẹ bá gbé Ọmọ Ènìyàn sókè, nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ pé èmi ni àti pé èmi kò dá ohunkóhun ṣe fún ara mi, ṣùgbọ́n bí Baba ti kọ́ mi, èmí ń sọ nǹkan wọ̀nyí.
Dlatego Jezus powiedział do nich: Gdy wywyższycie Syna Człowieczego, wtedy poznacie, że ja jestem, a nie czynię nic sam od siebie, ale mówię to, czego mnie nauczył mój Ojciec.
29 Ẹni tí ó rán mí sì ń bẹ pẹ̀lú mi, kò fi mí sílẹ̀ ní èmi nìkan; nítorí tí èmi ń ṣe ohun tí ó wù ú nígbà gbogbo.”
A ten, który mnie posłał, jest ze mną. Ojciec nie zostawił mnie samego, bo ja zawsze czynię [to], co mu się podoba.
30 Bí ó ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí, ọ̀pọ̀ ènìyàn gbà á gbọ́.
Gdy to mówił, wielu uwierzyło w niego.
31 Nítorí náà Jesu wí fún àwọn Júù tí ó gbà á gbọ́, pé, “Bí ẹ bá tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ mi ẹ ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi nítòótọ́.
Wtedy Jezus mówił do tych Żydów, którzy mu uwierzyli: Jeśli będziecie trwać w moim słowie, będziecie prawdziwie moimi uczniami.
32 Ẹ ó sì mọ òtítọ́, òtítọ́ yóò sì sọ yín di òmìnira.”
I poznacie prawdę, a prawda was wyzwoli.
33 Wọ́n dá a lóhùn pé, “Irú-ọmọ Abrahamu ni àwa jẹ́, àwa kò sì ṣe ẹrú fún ẹnikẹ́ni rí láé; ìwọ ha ṣe wí pé, ‘Ẹ ó di òmìnira’?”
Odpowiedzieli mu: My jesteśmy potomstwem Abrahama i nigdy nie służyliśmy nikomu. Jakże [możesz] mówić: Będziecie wolni?
34 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ ni.
Jezus im odpowiedział: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam, że każdy, kto popełnia grzech, jest sługą grzechu.
35 Ẹrú kì í sì í gbé ilé títí láé, ọmọ ní ń gbé ilé títí láé. (aiōn )
A sługa nie mieszka w domu na wieki, [lecz] Syn mieszka na wieki. (aiōn )
36 Nítorí náà, bí Ọmọ bá sọ yín di òmìnira ẹ ó di òmìnira nítòótọ́.
Jeśli więc Syn was wyzwoli, będziecie prawdziwie wolni.
37 Mo mọ̀ pé irú-ọmọ Abrahamu ni ẹ̀yin jẹ́; ṣùgbọ́n ẹ ń wá ọ̀nà láti pa mí nítorí ọ̀rọ̀ mi kò rí ààyè nínú yín. Jesu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ nípa ara rẹ̀.
Wiem, że jesteście potomstwem Abrahama, lecz usiłujecie mnie zabić, bo moje słowo nie znajduje w was miejsca.
38 Ohun tí èmi ti rí lọ́dọ̀ Baba ni mo sọ, ẹ̀yin pẹ̀lú sì ń ṣe èyí tí ẹ̀yin ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ baba yín.”
Ja mówię to, co widziałem u mego Ojca, a wy też robicie to, co widzieliście u waszego ojca.
39 Wọ́n dáhùn, wọ́n sì wí fún un pé, “Abrahamu ni baba wa!” Jesu wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ìbá ṣe iṣẹ́ Abrahamu.
Odpowiedzieli mu: Naszym ojcem jest Abraham. Jezus im powiedział: Gdybyście byli synami Abrahama, spełnialibyście uczynki Abrahama.
40 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ń wá ọ̀nà láti pa mí, ẹni tí ó sọ òtítọ́ fún yín, èyí tí mo ti gbọ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, Abrahamu kò ṣe èyí.
Lecz teraz usiłujecie mnie zabić, człowieka, który wam mówił prawdę, którą słyszał od Boga. Tego Abraham nie robił.
41 Ẹ̀yin ń ṣe iṣẹ́ baba yín.” Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “a kò bí wa nípa panṣágà, a ní Baba kan, èyí sì ni Ọlọ́run.”
Wy spełniacie uczynki waszego ojca. Wtedy powiedzieli mu: My nie jesteśmy spłodzeni z nierządu. Mamy jednego Ojca – Boga.
42 Jesu wí fún wọn pé, “Ìbá ṣe pé Ọlọ́run ni Baba yín, ẹ̀yin ìbá fẹ́ràn mi, nítorí tí èmi ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run jáde, mo sì wá; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n òun ni ó rán mi.
Jezus im powiedział: Gdyby Bóg był waszym Ojcem, miłowalibyście mnie, gdyż ja od Boga wyszedłem i przyszedłem, a nie przyszedłem sam od siebie, ale on mnie posłał.
43 Èéṣe tí èdè mi kò fi yé yín? Nítorí ẹ kò lè gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.
Dlaczego nie pojmujecie tego, co mówię? Dlatego że nie możecie słuchać mojego słowa.
44 Ti èṣù baba yin ni ẹ̀yin jẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ baba yín ni ẹ sì ń fẹ́ ṣe. Apànìyàn ni òun jẹ́ láti àtètèkọ́ṣe, kò sì dúró nínú òtítọ́; nítorí tí kò sí òtítọ́ nínú rẹ̀. Nígbà tí ó bá ń ṣèké, nínú ohun tirẹ̀ ni ó ń sọ nítorí èké ni, àti baba èké.
Wy jesteście z [waszego] ojca – diabła i chcecie spełniać pożądliwości waszego ojca. On był mordercą od początku i nie został w prawdzie, bo nie ma w nim prawdy. Gdy mówi kłamstwo, mówi od siebie, bo jest kłamcą i ojcem kłamstwa.
45 Ṣùgbọ́n nítorí tí èmi ń sọ òtítọ́ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbà mí gbọ́.
A ponieważ ja mówię prawdę, nie wierzycie mi.
46 Ta ni nínú yín tí ó ti dá mi lẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀? Bí mo bá ń ṣọ òtítọ́, èéṣe tí ẹ̀yin kò fi gbà mí gbọ́?
Któż z was obwini mnie o grzech? Jeśli mówię prawdę, dlaczego mi nie wierzycie?
47 Ẹni tí ń ṣe ti Ọlọ́run, a máa gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, nítorí èyí ni ẹ̀yin kò ṣe gbọ́, nítorí ẹ̀yin kì í ṣe ti Ọlọ́run.”
Kto jest z Boga, słucha słów Bożych. Wy dlatego nie słuchacie, że nie jesteście z Boga.
48 Àwọn Júù dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò wí nítòótọ́ pé, ará Samaria ni ìwọ jẹ́, àti pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù?”
Wtedy Żydzi mu odpowiedzieli: Czy nie dobrze mówimy, że jesteś Samarytaninem i masz demona?
49 Jesu sì dáhùn pé, “Èmi kò ní ẹ̀mí èṣù, ṣùgbọ́n èmi ń bu ọlá fún Baba mi, ẹ̀yin kò sì bu ọlá fún mi.
Jezus odpowiedział: Ja nie mam demona, ale czczę mego Ojca, a wy mnie znieważacie.
50 Èmi kò wá ògo ara mi, ẹnìkan ń bẹ tí ó ń wá a tí yóò sì ṣe ìdájọ́.
Ja nie szukam swojej chwały. Jest ktoś, kto szuka i sądzi.
51 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò rí ikú láéláé.” (aiōn )
Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Jeśli ktoś będzie zachowywał moje słowa, nigdy nie ujrzy śmierci. (aiōn )
52 Àwọn Júù wí fún un pé, “Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé ìwọ ní ẹ̀mí èṣù. Abrahamu kú, àti àwọn wòlíì; ìwọ sì wí pé, ‘Bí ẹnìkan bá pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, kì yóò tọ́ ikú wò láéláé.’ (aiōn )
Wtedy Żydzi powiedzieli do niego: Teraz wiemy, że masz demona. Abraham umarł i prorocy, a ty mówisz: Jeśli ktoś będzie zachowywał moje słowa, nigdy nie skosztuje śmierci. (aiōn )
53 Ìwọ ha pọ̀ ju Abrahamu Baba wa lọ, ẹni tí ó kú? Àwọn wòlíì sì kú, ta ni ìwọ ń fi ara rẹ pè?”
Czy ty jesteś większy od naszego ojca Abrahama, który umarł? I prorocy poumierali. Kim ty się czynisz?
54 Jesu dáhùn wí pé, “Bí mo bá yin ara mi lógo, ògo mi kò jẹ́ nǹkan, Baba mi ni ẹni tí ń yìn mí lógo, ẹni tí ẹ̀yin wí pé, Ọlọ́run yín ní i ṣe.
Jezus odpowiedział: Jeśli ja sam siebie chwalę, moja chwała jest niczym. Mój Ojciec jest [tym], który mnie chwali, o którym wy mówicie, że jest waszym Bogiem.
55 Ẹ kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, bí mo bá sì wí pé, èmi kò mọ̀ ọ́n, èmi yóò di èké gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin, ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, mo sì pa ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́.
Lecz nie znacie go, a ja go znam. I jeślibym powiedział, że go nie znam, byłbym podobnym do was kłamcą. Ale znam go i zachowuję jego słowa.
56 Abrahamu baba yín yọ̀ láti rí ọjọ́ mi, ó sì rí i, ó sì yọ̀.”
Abraham, wasz ojciec, z radością pragnął ujrzeć mój dzień. I ujrzał, i radował się.
57 Nítorí náà, àwọn Júù wí fún un pé, “Ọdún rẹ kò ì tó àádọ́ta, ìwọ sì ti rí Abrahamu?”
Wówczas Żydzi powiedzieli do niego: Pięćdziesięciu lat jeszcze nie masz, a Abrahama widziałeś?
58 Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kí Abrahamu tó wà, èmi ti wa.”
Jezus im odpowiedział: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Zanim Abraham był, ja jestem.
59 Nítorí náà wọ́n gbé òkúta láti sọ lù ú, ṣùgbọ́n Jesu fi ara rẹ̀ pamọ́, ó sì jáde kúrò ní tẹmpili.
Wtedy porwali kamienie, aby w niego rzucać. Jezus jednak ukrył się i wyszedł ze świątyni, przechodząc między nimi, i tak odszedł.