< John 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
Pamande ye mambo ega oYesu asafiliye eshi hu Galilaya, afuatanaje sagaasongwelwe abhala huu Yahudi afwatanaje huuyahudi wapangaga ahubude.
2 Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
Eshi eshikulukulu sha Yahudi, eshi kulukulu ye Vibanda, ya pepee.
3 Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
Aholo wakwe nkabhozya, “Sogala apantu epa obhale hu Yahudi, abhanafunzi bhaho bhagalole amambo gobhomba.
4 Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
Nomo wabhomba lyolyonti hu shi siri nkashe omwene yoyo ahwanza ajulihane pazelu. Nkashe obhomba ega, hwilanje wewe hwabha munsi.”
5 Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
Hata bhaholo bhakwe sebhamwetesheye.
6 Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
O Yesu nkabhabhozya, “Insiku zyane sezifishile bado, ila ensiku zyenyu kila muda zihweli.
7 Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
Abhamunsi sebhawezizye abhavitwe amwe, ila bhamvitwa ane afuatane embahakikisya aje ambombo zyao mbibhi.
8 Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
Zubhaji abhale hu shikulukulu; ane sembala hu shikulukulu afuatanaje omuda gwane guli seele afishe.”
9 Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
Nayanga enongwa izyo hwa bhahala, asageye hu Galilaya.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
Hata sheshi, aholo bhakwe na bhabhalile hushikulukulu wope nkahabhala, sio apazelu bali pasirisiri.
11 Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
Ayahudi bhali bhahufuata hushikulukulu naje, “Ali hwii?”
12 Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
Hwali no luyangano lwinji muhati mlubhongano ahusu omwene. Wamo bhajile, “Muntu mwinza.” Bhamwabho wajile, “Ndadi abhatezya olubhongano.”
13 Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
Hata sheshi nomo wayanjile pazelu ahusu omwahale afuatanaje bhabhogope Ayahudi.
14 Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
Ensiku zye shikulukulu nazyahali katikati, oYesu azubhile abhale mshibhanza na hwande asambelezye.
15 Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
Ayahudi bhaswigaga na nayanje, “Huu namna wele omuntu amanye enongwa enyinji? Sasambeleye nkahashe.”
16 Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
O Yesu ayanga naje, “Emanyizyo zyane se zyaline, ila zyoola wantumile.
17 Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
Nkashe wawonti anzasongwe abhombe olusongwo lwakwe omwene, anzamanye emanyizyo ezi, aje zifuma hwa Ngolobhe, au aje eyanga afume huline nene.
18 Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
Shila wayanga gagafuma hwa mwene yoyo ahwenza umwamu wakwe, na shila wahwanza oumwamu wakwe omwene wantumile, omuntu omuntu oyo we lyoli, na muhati yakwe nahumo abhombeshe zye malenka.
19 Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
O Musa sagabhapiye amwe endajizyo? Ila nomo hata weka hulimwe wabhomba endajizyo. Yenyu muhwanza ambude?
20 Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
Amabhongano gayanga, “Aje oli na mapepo. Wenu wahanza ahubude?”
21 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
O Yesu wayanga wagaa, “Ombombile embombo yeeka, namwe mwenti muswijile afuatanajenesho.
22 Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
O Musa abhapiye etohara (sio aje efuma hwa Musa, ila efuma hwa daada), na hu Sabato mhutahiri omuntu.
23 Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
Nkashe omuntu anzaposhele etohara hwi siku lye Sabato aje endajizyo zya Musa zinganje nankanywe, yeenu munvitwa ane afwatanaje ebheshele omuntu abhe mwinza kabisa hu Sabato?
24 Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
Mganje alonje alengane sha mlola, ila alonje hulyoli.
25 Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
Bhamo bhamo uYelusalemu bhaga, “Seyayono wabhahu mwanza ahude?
26 Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
Enya, oyanga pazelu, na sebhayanga hahonti alengane no mwene. Sawezizye aje egabha aje alongozi bhamenye elyoli aje ono yo Kilisiti, ewezizye abhe?
27 Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
Timenye aje omuntu ono afumila hwii. O Kilisti lwayenza, atasheshii, nomo wailola aje afuma hwii.”
28 Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
O Yesu afumiaga izu lyakwe mwibhanza, asambele zyaga naje, “Amwe mwenti mumenye ane na mumeenye hwe fuma. Senamenye hubele gwane, ila omwene wantumile welyoli, semumenye omwene.
29 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
Emenye omwene afuatanaje enfumile hwa mwene na antumile.”
30 Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
Bhalenga ahaate, ila nomo ata omo wabhosezye okhono gwakwe ahusu omwene afuatanaje esaa yakwe yaali seele afishe.
31 Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
Hata sheshi bhinji mubhongano bhamwetesheye. Bhajile, “Kilisiti lwa yeenza, aibhomba embombo nyinji ashile zyabhombile omuntu ono?”
32 Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
Amafarisayo bhabhonvwezye amawongano wakwepelena enongwa ezi eshi oYesu, na agosi bha dimi na Mafarisayo bhatumile amaafisa aje ahukhate.
33 Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
O Yesu nkayanga, “Ali seele insiku ndodo embabhe pandwemo namwe, napamande naibhala hwa mwene wantumile.
34 Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
Munanza ila semubhandole; hula hwembala, semubhawezye ahwenze.”
35 Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
Abhayaudi bhayangama bhene hu bhene, “Omuntu ono anzabhale hwii aje tipotwe ahulole? Anzabhale hwa bhabhanyampene mhati ya yunanu bhamanyinzye Ayunani?
36 Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
Nongwa bhole ene yayanjile, 'Mwainanza nantele semwainaga; hula hwembala semwaiwezya ahwenze'?”
37 Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
Esalezi hunsiku zya mwisho, isiku igosi lye shikulukulu, pYesu ahemeleye azurizwe izu ajile, “Nkashe wa wonti ali ne sshomelwa, ayenze huline amwele.
38 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
Omwene waneteshe ane, nanshi amazu shagayanjile, afume mhati yakwe ganza hwiteshe amasoho gemenze gewomi.”
39 Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
Ila ayanji ega alengane hushi Roho, afuatanaje bhala bhabhamwetesheye bhayihuposhela; Ompempo ali seele safumiziwe alengane naje oYesu ali samwamihwe.
40 Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
Bhamo bhelubhongano, nabhahomvwezye enongwa eezi, bhajile, “Yoli ono kuwaa.”
41 Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
Bhamo bhayanjile, “Ono Kilisiti.” Ila bhamo bhamo bhajile, “yenu, oKilisiti awezya afume hu Galilaya?
42 Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
Amaazu segayanga aje oKilisiti aifuma hushikholo sha Daudi na afume hubenselehemu, hushi jiji shahali oDaudi?
43 Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
Shesho, pala pabhoha olugabhano mhati yelubhongamo alengane no mwahale.
44 Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
Bhamo mhati yabho handabhakhete, ila nomo wagolosezye okhono gwakwe hwa mwene.
45 Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
Bhala ofisa bhawela hwa gosi adimi na Mafarisayo, bhope bhabhabhozya, “Yenu semletile?”
46 Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
Amaofisa bhajile, “Nomo omunti wawayile ayanje nanshi ono haani.”
47 Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
Amafarisayo nkabhahaga, “Namwe nantele mtejile?
48 Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
Ahweli omuntu wawonti hwa gosi wahumweteha, au wawonti hwa Mafarisayo?
49 Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
Ila ebha amabhongano bhasebhemenye endwajizyo - wapete amakhosi.”
50 Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
O Nikodemo abhabhozya (omwene wabhaliye oYesu imwaha, ali pamo na Mafarisayo),
51 “Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
“Aje endajizyo zyetu ziholonga omuntu ila atejezewe na soti na amanye habhomba?”
52 Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
Bhayanjile na hubhozye, “Ivi nawe ofumila hu Galilaya? Anza na oyenye aje nomo okuwaa wafumila hu Galilaya.”
53 Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
Pamande shila munti ahabhala akhaya yakwe.

< John 7 >