< John 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
A potem Jezus chodził po Galilei. Nie chciał bowiem przebywać w Judei, bo Żydzi szukali [sposobności], aby go zabić.
2 Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
I zbliżało się żydowskie święto Namiotów.
3 Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
Wtedy jego bracia powiedzieli do niego: Odejdź stąd i idź do Judei, żeby twoi uczniowie widzieli dzieła, których dokonujesz.
4 Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
Nikt bowiem nie czyni nic w ukryciu, jeśli chce być znany. Dlatego ty, jeśli takie rzeczy czynisz, objaw się światu.
5 Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
Bo nawet jego bracia nie wierzyli w niego.
6 Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
I powiedział do nich Jezus: Mój czas jeszcze nie nadszedł, ale wasz czas zawsze jest w pogotowiu.
7 Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
Świat nie może was nienawidzić, ale mnie nienawidzi, bo ja świadczę o nim, że jego uczynki są złe.
8 Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
Wy idźcie na święto, ja jeszcze nie pójdę na to święto, bo mój czas jeszcze się nie wypełnił.
9 Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
Powiedziawszy im to, pozostał w Galilei.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
A gdy jego bracia poszli, wtedy i on poszedł na święto, nie jawnie, ale jakby potajemnie.
11 Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
A Żydzi szukali go podczas święta i mówili: Gdzie on jest?
12 Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
I wiele szemrało się o nim wśród ludzi, bo jedni mówili: Jest dobry. A inni mówili: Przeciwnie, zwodzi ludzi.
13 Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
Nikt jednak nie mówił o nim jawnie z obawy przed Żydami.
14 Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
A gdy już minęła połowa święta, Jezus wszedł do świątyni i nauczał.
15 Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
I dziwili się Żydzi, mówiąc: Skąd on zna Pismo, skoro się nie uczył?
16 Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
Odpowiedział im Jezus: Moja nauka nie jest moją, ale tego, który mnie posłał.
17 Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
Jeśli ktoś chce wypełniać jego wolę, ten będzie umiał rozeznać, czy ta nauka jest od Boga, czy ja mówię sam od siebie.
18 Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
Kto mówi z samego siebie, szuka własnej chwały. Kto zaś szuka chwały tego, który go posłał, ten jest prawdziwy i nie ma w nim niesprawiedliwości.
19 Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
Czy Mojżesz nie dał wam prawa? A żaden z was nie przestrzega prawa. Dlaczego chcecie mnie zabić?
20 Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
Odpowiedzieli ludzie: Masz demona. Kto chce cię zabić?
21 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
Jezus im odpowiedział: Jeden uczynek spełniłem, a wszyscy się temu dziwicie.
22 Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
Przecież Mojżesz dał wam obrzezanie (nie jakoby było od Mojżesza, ale od ojców), a w szabat obrzezujecie człowieka.
23 Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
Jeśli człowiek przyjmuje obrzezanie w szabat, aby nie było złamane Prawo Mojżesza, to [dlaczego] gniewacie się na mnie, że w szabat całkowicie uzdrowiłem człowieka?
24 Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
Nie sądźcie po pozorach, ale sądźcie sprawiedliwym sądem.
25 Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
Wtedy niektórzy z mieszkańców Jerozolimy mówili: Czy to nie jest ten, którego chcą zabić?
26 Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
A oto jawnie przemawia i nic mu nie mówią. Czy przełożeni rzeczywiście poznali, że to jest prawdziwie Chrystus?
27 Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
Ale wiemy, skąd on pochodzi, lecz gdy Chrystus przyjdzie, nikt nie będzie wiedział, skąd jest.
28 Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
Wtedy Jezus, nauczając w świątyni, wołał: I znacie mnie, i wiecie, skąd jestem. A ja nie przyszedłem sam od siebie, ale prawdziwy jest ten, który mnie posłał, którego wy nie znacie.
29 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
Lecz ja go znam, bo od niego jestem i on mnie posłał.
30 Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
I usiłowali go schwytać, ale nikt nie podniósł na niego ręki, bo jeszcze nie nadeszła jego godzina.
31 Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
A wielu z ludu uwierzyło w niego i mówiło: Gdy Chrystus przyjdzie, czyż uczyni więcej cudów, niż on uczynił?
32 Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
Faryzeusze słyszeli, że tak ludzie o nim szemrali. I faryzeusze i naczelni kapłani posłali sługi, aby go schwytać.
33 Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
Wtedy Jezus powiedział im: Jeszcze krótki czas jestem z wami, potem odejdę do tego, który mnie posłał.
34 Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
Będziecie mnie szukać, ale nie znajdziecie, a gdzie ja będę, wy przyjść nie możecie.
35 Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
Wówczas Żydzi mówili między sobą: Dokąd on pójdzie, że go nie znajdziemy? Czy pójdzie do rozproszonych [wśród] pogan i będzie nauczał pogan?
36 Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
Cóż to za słowo, które wypowiedział: Będziecie mnie szukać, ale nie znajdziecie, a gdzie ja będę, wy przyjść nie możecie?
37 Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
A w ostatnim, wielkim dniu tego święta, Jezus stanął i wołał: Jeśli ktoś pragnie, niech przyjdzie do mnie i pije.
38 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
Kto wierzy we mnie, jak mówi Pismo, rzeki wody żywej popłyną z jego wnętrza.
39 Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
A to mówił o Duchu, którego mieli otrzymać wierzący w niego. Duch Święty bowiem jeszcze nie był [dany], ponieważ Jezus nie został jeszcze uwielbiony.
40 Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
Wielu więc z tych ludzi, słysząc te słowa, mówiło: To jest prawdziwie ten prorok.
41 Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
A inni mówili: To jest Chrystus. Lecz niektórzy mówili: Czyż Chrystus przyjdzie z Galilei?
42 Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
Czyż Pismo nie mówi, że Chrystus przyjdzie z potomstwa Dawida i z miasteczka Betlejem, gdzie mieszkał Dawid?
43 Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
I tak z jego powodu nastąpił rozłam wśród ludu.
44 Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
I niektórzy z nich chcieli go schwytać, ale nikt nie podniósł na niego ręki.
45 Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
Wtedy słudzy wrócili do naczelnych kapłanów i do faryzeuszy, którzy ich zapytali: Dlaczego go nie przyprowadziliście?
46 Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
Słudzy odpowiedzieli: Nikt nigdy nie mówił tak, jak ten człowiek.
47 Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
I odpowiedzieli im faryzeusze: Czy i wy jesteście zwiedzeni?
48 Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
Czy ktoś z przełożonych albo z faryzeuszy uwierzył w niego?
49 Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
A to pospólstwo, które nie zna prawa, jest przeklęte.
50 Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
Jeden z nich, Nikodem, ten, który przyszedł w nocy do niego, powiedział im:
51 “Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
Czy nasze prawo potępia człowieka, zanim go najpierw nie wysłucha i nie zbada, co czyni?
52 Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
A oni mu odpowiedzieli: Czy i ty jesteś Galilejczykiem? Zbadaj i zobacz, że [żaden] prorok nie powstał z Galilei.
53 Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
I poszedł każdy do swego domu.

< John 7 >