< John 7 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
A potem chodził Jezus po Galilei; bo się nie chciał bawić w ziemi Judzkiej, przeto że Żydowie szukali, aby go zabili.
2 Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
I było blisko święto żydowskie kuczek.
3 Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
Tedy rzekli do niego bracia jego: Odejdź stąd, a idź do Judzkiej ziemi, żeby uczniowie twoi widzieli sprawy twoje, które czynisz.
4 Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
Albowiem żaden nic w skrytości nie czyni, kto chce być widziany; przetoż ty, jeźli takie rzeczy czynisz, objaw się światu.
5 Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
Bo i bracia jego nie wierzyli weń.
6 Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
I rzekł im Jezus: Czas mój jeszcze nie przyszedł; ale czas wasz zawsze jest w pogotowiu.
7 Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
Nie możeć was świat nienawidzieć, ale mnie nienawidzi; bo ja świadczę o nim, iż sprawy jego złe są.
8 Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
Idźcież wy na to święto, jać jeszcze nie pójdę na to święto; bo mój czas jeszcze się nie wypełnił.
9 Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
A to im powiedziawszy, został w Galilei.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
A gdy poszli bracia jego, tedy i on szedł na święto, nie jawnie, ale jakoby potajemnie.
11 Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
A Żydowie szukali go w święto i mówili: Gdzież on jest?
12 Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
I było o nim wielkie szemranie między ludem; bo jedni mówili: Że jest dobry; a drudzy mówili: Nie, ale zwodzi lud.
13 Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
Wszakże o nim żaden jawnie nie mówił, dla bojaźni żydowskiej.
14 Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
A gdy już było w pół święta, wstąpił Jezus do kościoła i uczył.
15 Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
I dziwowali się Żydowie, mówiąc: Jakoż ten umie Pismo, gdyż się nie uczył?
16 Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
Odpowiedział im Jezus i rzekł: Nauka moja nie jestci moja, ale tego, który mię posłał.
17 Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
Jeźliby kto chciał czynić wolę jego, ten będzie umiał rozeznać, jeźli ta nauka jest z Boga, czyli ja sam od siebie mówię.
18 Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
Ktoć z samego siebie mówi, chwały własnej szuka; ale kto szuka chwały tego, który go posłał, ten jest prawdziwy, a nie masz w nim niesprawiedliwości.
19 Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
Izali wam Mojżesz nie dał zakonu? a żaden z was nie przestrzega zakonu. Przeczże szukacie, abyście mię zabili?
20 Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
Odpowiedział lud i rzekł: Dyjabelstwo masz; któż cię szuka zabić?
21 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
Odpowiedział Jezus i rzekł im: Jedenem uczynek uczynił, a wszyscy się temu dziwujecie!
22 Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
Wszak Mojżesz wydał wam obrzezkę, (nie iżby była z Mojżesza, ale z ojców), a w sabat obrzezujecie człowieka.
23 Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
Ponieważ człowiek przyjmuje obrzezkę w sabat, aby nie był zgwałcony zakon Mojżeszowy, przecz się na mię gniewacie, żem całego człowieka uzdrowił w sabat?
24 Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
Nie sądźcie według widzenia, ale sprawiedliwy sąd sądźcie.
25 Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
Mówili tedy niektórzy z Jeruzalemczyków: Izali to nie jest ten, którego szukają zabić?
26 Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
A oto jawnie mówi, a nic mu nie mówią. Izali prawdziwie poznali książęta, iż ten jest prawdziwie Chrystus?
27 Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
Ale o tym wiemy, skąd jest: ale gdy Chrystus przyjdzie, nikt nie będzie wiedział, skąd by był.
28 Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
Wołał tedy Jezus w kościele ucząc a mówiąc: I mnie znacie, i skądem jest, wiecie; a nie przyszedłem sam od siebie, ale jest prawdziwy, który mię posłał, którego wy nie znacie.
29 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
Lecz go ja znam; bom od niego jest, a on mię posłał.
30 Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
I szukali, jakoby go pojmać; ale żaden nie ściągnął nań ręki; bo jeszcze nie przyszła godzina jego.
31 Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
A wiele ich z ludu uwierzyli weń i mówili: Chrystus gdy przyjdzie, izaż więcej cudów uczyni nad te, które ten uczynił?
32 Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
A słyszeli Faryzeuszowie, iż to lud o nim szemrał; i posłali Faryzeuszowie i przedniejsi kapłani sługi, aby go pojmali.
33 Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
Rzekł im tedy Jezus: Jeszcze na mały czas jestem z wami; potem odejdę do tego, który mię posłał.
34 Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
Szukać mię będziecie, ale nie znajdziecie; a gdzie ja będę, wy przyjść nie możecie.
35 Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
Mówili tedy Żydowie między sobą: Dokądże ten pójdzie, że my go nie znajdziemy? czyli do rozproszonych poganów pójdzie i będzie uczył pogany?
36 Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
Cóż to za mowa, którą wyrzekł: Szukać mię będziecie, ale nie znajdziecie, i gdzie ja będę, wy przyjść nie możecie?
37 Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
A w on ostateczny dzień wielki święta onego stanął Jezus i wołał mówiąc: Jeźli kto pragnie, niech do mnie przyjdzie, a pije.
38 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
Kto wierzy w mię, jako mówi Pismo, rzeki wody żywej popłyną z żywota jego.
39 Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
(A to mówił o Duchu, którego wziąć mieli wierzący weń; albowiem jeszcze nie był dany Duch Święty, przeto że jeszcze Jezus nie był uwielbiony.)
40 Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
Wiele ich tedy z owego ludu słysząc te słowa, mówili: Tenci jest prawdziwie on prorok.
41 Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
A drudzy mówili: Ten jest Chrystus; ale niektórzy mówili: Azaż z Galilei przyjdzie Chrystus?
42 Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
Azaż nie mówi Pismo, iż z nasienia Dawidowego i z Betlehemu miasteczka, gdzie był Dawid, przyjdzie Chrystus?
43 Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
A tak stało się rozerwanie dla niego między ludem.
44 Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
I chcieli go niektórzy z nich pojmać; ale żaden nie ściągnął nań rąk swoich.
45 Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
Przyszli tedy słudzy do przedniejszych kapłanów i do Faryzeuszów; którzy im rzekli: Przeczżeście go nie przywiedli?
46 Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
Odpowiedzieli oni słudzy: Nigdy tak nie mówił człowiek jako ten człowiek.
47 Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
I odpowiedzieli im Faryzeuszowie: Alboście i wy zwiedzeni?
48 Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
Izali kto uwierzył weń z książąt albo z Faryzeuszów?
49 Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
Tylko ten gmin, który nie zna zakonu; przeklęci są.
50 Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
I rzekł do nich Nikodem, który był przyszedł w nocy do niego, będąc jeden z nich:
51 “Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
Izali zakon nasz sądzi człowieka, jeźliby pierwej nie słyszał od niego i nie poznałby, co czyni?
52 Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
A oni mu odpowiedzieli i rzekli: Izaliś i ty Galilejczyk? Badajże się, a obacz, żeć prorok z Galilei nie powstał.
53 Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
I poszedł każdy do domu swego.