< John 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲀ ⲚⲀⲒ ⲚⲀϤⲘⲞϢⲒ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲚⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲈⲘⲞϢⲒ ϦⲈⲚϮⲒⲞⲨⲆⲈⲀ ϪⲈ ⲚⲀⲨⲔⲰϮ ⲚⲤⲰϤ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲈϦⲞⲐⲂⲈϤ.
2 Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
ⲃ̅ⲚⲀϤϦⲈⲚⲦ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠϢⲀⲒ ⲚⲦⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ϮⲤⲔⲎⲚⲞⲠⲎⲄⲒⲀ.
3 Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
ⲅ̅ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ⲞⲨⲚ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲤⲚⲎⲞⲨ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲐⲂⲈⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲦⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈϮⲒⲞⲨⲆⲈⲀ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲚⲈⲔⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲚⲀⲨ ⲈⲚⲈⲔϨⲂⲎⲞⲨⲒ ⲈⲦⲈⲔⲒⲢⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
4 Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
ⲇ̅ⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲘⲠⲀⲢⲈ ϨⲖⲒ ⲈⲢϨⲰⲂ ϦⲈⲚⲠⲈⲦϨⲎⲠ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤⲔⲰϮ ⲚⲤⲰϤ ϦⲈⲚⲠⲈⲐⲞⲨⲰⲚϨ ⲒⲤϪⲈ ⲬⲚⲀⲈⲢ ⲚⲀⲒ ⲞⲨⲞⲚϨⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ.
5 Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
ⲉ̅ⲞⲨⲆⲈ ⲄⲀⲢ ⲚⲈϤⲔⲈⲤⲚⲎⲞⲨ ⲚⲀⲨⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚ ⲠⲈ.
6 Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
ⲋ̅ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲚ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲀⲤⲎⲞⲨ ⲀⲚⲞⲔ ⲘⲠⲀⲦⲈϤⲒ ⲠⲈⲦⲈⲚⲤⲎⲞⲨ ⲆⲈ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ϤⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
7 Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
ⲍ̅ⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲘⲈⲤⲦⲈ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ϤⲘⲞⲤϮ ⲘⲘⲞⲒ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϪⲈ ⲚⲈϤϨⲂⲎⲞⲨⲒ ⲤⲈϨⲰⲞⲨ.
8 Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
ⲏ̅ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲆⲈ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲠϢⲀⲒ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲚϮⲚⲀⲒ ⲀⲚ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲠⲒϢⲀⲒ ϪⲈ ⲘⲠⲀⲦⲈ ⲠⲀⲤⲎⲞⲨ ⲀⲚⲞⲔ ϪⲰⲔ ⲈⲂⲞⲖ.
9 Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
ⲑ̅ⲚⲀⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤϪⲞⲦⲞⲨ ⲚⲐⲞϤ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ.
10 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
ⲓ̅ϨⲞⲦⲈ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲠϢⲀⲒ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲤⲚⲎⲞⲨ ⲦⲞⲦⲈ ⲚⲐⲞϤ ϨⲰϤ ⲀϤⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲞⲨⲰⲚϨ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ϨⲰⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲬⲰⲠ.
11 Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
ⲓ̅ⲁ̅ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲞⲨⲚ ⲚⲀⲨⲔⲰϮ ⲚⲤⲰϤ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲠϢⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀϤⲐⲰⲚ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.
12 Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲬⲢⲈⲘⲢⲈⲘ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲎϢ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϨⲀⲚⲞⲨⲞⲚ ⲘⲈⲚ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲀⲄⲀⲐⲞⲤ ⲠⲈ ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲀϤⲤⲰⲢⲈⲘ ⲘⲠⲒⲘⲎϢ.
13 Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
ⲓ̅ⲅ̅ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ⲘⲈⲚⲦⲞⲒ ⲤⲀϪⲒ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϦⲈⲚⲞⲨⲞⲨⲰⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲐⲂⲈ ⲦϨⲞϮ ⲚⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ.
14 Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
ⲓ̅ⲇ̅ϨⲎⲆⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲀ ⲠⲒϢⲀⲒ ⲈⲢⲪⲀϢⲒ ⲀϤⲒ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϮⲤⲂⲰ ⲠⲈ.
15 Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
ⲓ̅ⲉ̅ⲚⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲞⲨⲚ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲰⲤ ⲪⲀⲒ ⲤⲰⲞⲨⲚ ⲚⲤϦⲀⲒ ⲘⲠⲈϤⲤⲀⲂⲞ.
16 Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
ⲓ̅ⲋ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲦⲀⲤⲂⲰ ⲀⲚⲞⲔ ⲐⲰⲒ ⲀⲚ ⲦⲈ.
17 Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
ⲓ̅ⲍ̅ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲈⲢⲪⲞⲨⲰϢ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲈϤⲈⲤⲞⲨⲈⲚ ⲦⲀⲤⲂⲰ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲚⲞⲨϮ ⲦⲈ ϢⲀⲚ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ.
18 Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
ⲓ̅ⲏ̅ⲪⲎ ⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲀϤⲔⲰϮ ⲚⲤⲀⲠⲈϤⲰⲞⲨ ⲘⲘⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲪⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲔⲰϮ ⲚⲤⲀⲠⲰⲞⲨ ⲘⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞϤ ⲪⲀⲒ ⲞⲨⲐⲘⲎⲒ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲆⲒⲔⲒⲀ ⲚϦⲎ ⲦϤ.
19 Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
ⲓ̅ⲑ̅ⲘⲎ ⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲀⲚ ⲀϤϮ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲘⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈϤⲒⲢⲒ ⲘⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲈϦⲞⲐⲂⲈⲦ.
20 Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
ⲕ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲒⲘⲎϢ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲀⲔ ⲚⲒⲘ ⲠⲈⲦⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲔ ⲈϦⲞⲐⲂⲈⲔ.
21 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
ⲕ̅ⲁ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲞⲨϨⲰⲂ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲠⲈⲦⲀⲒⲀⲒϤ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲢϢⲪⲎ ⲢⲒ ⲦⲎⲢⲞⲨ
22 Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
ⲕ̅ⲃ̅ⲈⲐⲂⲈⲪⲀⲒ ⲀⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ϮⲚⲰⲦⲈⲚ ⲘⲠⲒⲤⲈⲂⲒ ⲞⲨⲬ ⲞⲦⲒ ϪⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲠⲈ ⲠⲒⲤⲈⲂⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲒⲞϮ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲈⲂⲒ ⲚⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ϦⲈⲚⲠⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ
23 Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
ⲕ̅ⲅ̅ⲒⲤϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲀϬⲒ ⲘⲠⲒⲤⲈⲂⲒ ϦⲈⲚⲠⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ ϨⲒⲚⲀ ϪⲈ ⲚⲚⲈϤⲂⲰⲖ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲦⲈⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲒⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚϪⲰⲚⲦ ⲈⲢⲞⲒ ϪⲈ ⲀⲒⲐⲢⲈ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲦⲎⲢϤ ⲞⲨϪⲀⲒ ϦⲈⲚⲠⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ.
24 Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
ⲕ̅ⲇ̅ⲘⲠⲈⲢϮϨⲀⲠ ⲔⲀⲦⲀ ϨⲞ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀϨⲀⲠ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲀⲠ ⲘⲘⲎⲒ.
25 Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
ⲕ̅ⲉ̅ⲚⲀⲨϪⲰ ⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲞⲨⲞⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲀ ⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ϪⲈ ⲘⲎ ⲪⲀⲒ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲨⲔⲰϮ ⲚⲤⲰϤ ⲈϦⲞⲐⲂⲈϤ.
26 Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
ⲕ̅ⲋ̅ϨⲎⲠⲠⲈ ϤⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲀⲢⲢⲎⲤⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲈϪⲈ ϨⲖⲒ ⲚⲀϤ ⲀⲚ ⲘⲎⲠⲰⲤ ⲢⲰ ⲀⲨⲈⲘⲒ ⲦⲀⲪⲘⲎⲒ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲰⲚ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
27 Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
ⲕ̅ⲍ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲀⲒ ⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ⲐⲰⲚ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲆⲈ ⲀϤϢⲀⲚⲒ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲚⲀⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ⲐⲰⲚ ⲠⲈ.
28 Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
ⲕ̅ⲏ̅ⲀϤⲰϢ ⲞⲨⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲈⲦⲀⲒⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲐⲰⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲦⲀⲒⲒ ⲀⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦ ⲀⲖⲖⲀ ⲞⲨⲐⲘⲎⲒ ⲠⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲪⲎ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲀⲚ.
29 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
ⲕ̅ⲑ̅ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ϮⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲎ ⲠⲈ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ.
30 Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
ⲗ̅ⲚⲀⲨⲔⲰϮ ⲞⲨⲚ ⲈⲦⲀϨⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ⲈⲚ ⲚⲈϤϪⲒϪ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ ϪⲈ ⲞⲨⲎⲒ ⲚⲈⲘⲠⲀⲦⲈⲤⲒ ⲚϪⲈⲦⲈϤⲞⲨⲚⲞⲨ.
31 Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
ⲗ̅ⲁ̅ϨⲀⲚⲘⲎϢ ⲞⲨⲚ ⲀⲨⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈϢⲰⲠ ⲀϤϢⲀⲚⲒ ⲘⲎ ϤⲚⲀⲈⲢ ϨⲞⲨⲞ ⲢⲰ ⲈⲚⲀⲒⲘⲎⲒⲚⲒ ⲈⲦⲀ ⲪⲀⲒ ⲀⲒⲦⲞⲨ.
32 Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
ⲗ̅ⲃ̅ⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚϪⲈⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲈⲚⲒⲘⲎϢ ⲈⲨⲬⲢⲈⲘⲢⲈⲘ ⲚⲚⲀⲒ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲚϨⲀⲚϨⲨⲠⲎ ⲢⲈⲦⲎⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈⲦⲀϨⲞϤ.
33 Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
ⲗ̅ⲅ̅ⲠⲈϪⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲚ ϪⲈ ⲈⲦⲒ ⲔⲈⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲬⲢⲞⲚⲞⲤ ϮϢⲞⲠ ⲚⲈⲘⲰⲦⲈⲚ ⲞⲨⲞϨ ϮⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ϨⲀ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ.
34 Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
ⲗ̅ⲇ̅ⲦⲈⲦⲈⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲈⲘⲦ ⲀⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲘⲀ ⲈϮⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚ.
35 Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
ⲗ̅ⲉ̅ⲠⲈϪⲈ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲞⲨⲚ ⲚⲚⲞⲨⲈⲢⲎⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲢⲈ ⲪⲀⲒ ⲚⲀϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲐⲰⲚ ⲚⲦⲈⲚϢⲦⲈⲘϪⲈⲘϤ ⲘⲎ ϤⲚⲀϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲠⲒϪⲰⲢ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲦⲈⲚⲒⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲚⲚⲒⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ.
36 Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
ⲗ̅ⲋ̅ⲠⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲈⲦⲀϤϪⲞⲤ ϪⲈ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀⲔⲰϮ ⲚⲤⲰⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϪⲈⲘⲦ ⲀⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲘⲀ ⲈϮⲚⲀϢⲈ ⲚⲎⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲒ ⲈⲢⲞϤ.
37 Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
ⲗ̅ⲍ̅ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲚϦⲀⲈ ⲚⲦⲈⲠⲒⲚⲒϢϮ ⲚϢⲀⲒ ⲀϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲂⲒ ⲘⲀⲢⲈϤⲒ ϨⲀⲢⲞⲒ ⲚⲦⲈϤⲤⲰ.
38 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
ⲗ̅ⲏ̅ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞⲒ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀⲤϪⲞⲤ ⲚϪⲈϮⲄⲢⲀⲪⲎ ϪⲈ ϨⲀⲚⲒⲀⲢⲰⲞⲨ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲚⲰⲚϦ ⲈⲐⲚⲀϦⲀϮ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲈϤⲚⲈϪⲒ.
39 Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
ⲗ̅ⲑ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲀϤϪⲞϤ ⲈⲐⲂⲈ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲚⲀⲨⲚⲀϬ ⲒⲦϤ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲈⲘⲠⲀⲦⲈ ⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲄⲀⲢ ϢⲰⲠⲒ ⲠⲈ ϪⲈ ⲚⲈⲘⲠⲀⲦⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϬⲒⲰⲞⲨ ⲠⲈ.
40 Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
ⲙ̅ϨⲀⲚⲞⲨⲞⲚ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲎϢ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲚⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲦⲀⲪⲘⲎⲒ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ.
41 Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
ⲙ̅ⲁ̅ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲎ ⲀⲢⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ.
42 Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
ⲙ̅ⲃ̅ⲘⲎ ⲚⲈⲦⲀⲤϪⲞⲤ ⲀⲚ ⲚϪⲈϮⲄⲢⲀⲪⲎ ϪⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠϪⲢⲞϪ ⲚⲆⲀⲨⲒⲆ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ϪⲈ ⲀⲢⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲂⲎⲐⲖⲈⲈⲘ ⲠⲒϮⲘⲒ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲆⲀⲨⲒⲆ ⲬⲎ ⲘⲘⲀⲨ.
43 Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
ⲙ̅ⲅ̅ⲞⲨⲤⲬⲒⲤⲘⲀ ⲞⲨⲚ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲎ ϢⲈⲐⲂⲎⲦϤ.
44 Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
ⲙ̅ⲇ̅ϨⲀⲚⲞⲨⲞⲚ ⲆⲈ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ⲚⲀⲨⲞⲨⲰϢ ⲈⲦⲀϨⲞϤ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ϢⲈⲚ ⲚⲈϤϪⲒϪ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ.
45 Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
ⲙ̅ⲉ̅ⲀⲨⲒ ⲞⲨⲚ ⲚϪⲈⲚⲒϨⲨⲠⲎⲢⲈⲦⲎⲤ ϨⲀ ⲚⲒⲀⲢⲬ ⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲈⲚϤ.
46 Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
ⲙ̅ⲋ̅ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲚⲒϨⲨⲠⲎⲢⲈⲦⲎⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲠⲈ ⲢⲰⲘⲒ ⲤⲀϪⲒ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲈⲚⲈϨ.
47 Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
ⲙ̅ⲍ̅ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲆⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲎ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲢⲈⲘ ϨⲰⲦⲈⲚ.
48 Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
ⲙ̅ⲏ̅ⲘⲎ ⲀϨⲖⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲀⲢⲬⲰⲚ ⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲒⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ.
49 Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
ⲙ̅ⲑ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲠⲀⲒⲘⲎϢ ⲈⲦⲈⲚⲤⲈⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲀⲚ ⲤⲈⲬⲎ ϦⲀ ⲠⲤⲀϨⲞⲨⲒ.
50 Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
ⲛ̅ⲠⲈϪⲈ ⲚⲒⲔⲞⲆⲎⲘⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲒ ϨⲀ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚϢⲞⲢⲠ ⲚϪⲰⲢϨ ⲈⲞⲨⲀⲒ ⲠⲈ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ.
51 “Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
ⲛ̅ⲁ̅ϪⲈ ⲘⲎ ⲠⲈⲚⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲀϮϨⲀⲠ ⲈⲠⲒⲢⲰⲘⲒ ⲀϤϢⲦⲈⲘⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲞϤ ⲚϢⲞⲢⲠ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈϤⲒⲢⲒ ⲘⲘⲞϤ.
52 Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
ⲛ̅ⲃ̅ⲀⲨⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲀϤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲎ ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ϨⲰⲔ ϦⲞⲦϦⲈⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲀⲨ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲚⲀⲦⲰⲚϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ.
53 Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
ⲛ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲪⲞⲨⲀⲒ ⲪⲞⲨⲀⲒ ⲈⲠⲈϤⲘⲀ

< John 7 >