< John 6 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu kọjá sí apá kejì Òkun Galili, tí í ṣe Òkun Tiberia.
Potem odszedł Jezus za morze Galilejskie, które jest Tyberyjadzkie;
2 Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, nítorí tí wọ́n rí iṣẹ́ àmì rẹ̀ tí ó ń ṣe lára àwọn aláìsàn.
I szedł za nim lud wielki, iż widzieli cuda jego, które czynił nad chorymi.
3 Jesu sì gun orí òkè lọ, níbẹ̀ ni ó sì gbé jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
I wszedł Jezus na górę, i siedział tam z uczniami swoimi;
4 Àjọ ìrékọjá ọdún àwọn Júù sì súnmọ́ etílé.
A była blisko wielkanoc, święto żydowskie.
5 Ǹjẹ́ bí Jesu ti gbé ojú rẹ̀ sókè, tí ó sì rí ọ̀pọ̀ ènìyàn wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó wí fún Filipi pé, “Níbo ni a ó ti ra àkàrà, kí àwọn wọ̀nyí lè jẹ?”
Tedy podniósł Jezus oczy i ujrzawszy, iż wielki lud idzie do niego, rzekł do Filipa: Skąd kupimy chleba, aby ci jedli?
6 Ó sì sọ èyí láti dán an wò; nítorí tí òun fúnra rẹ̀ mọ ohun tí òun ó ṣe.
(Ale to mówił, kusząc go; bo on wiedział, co miał czynić.)
7 Filipi dá a lóhùn pé, “Àkàrà igba owó idẹ kò lè tó fún wọn, bí olúkúlùkù wọn kò tilẹ̀ ní í rí ju díẹ̀ bù jẹ.”
Odpowiedział mu Filip: Za dwieście groszy chleba nie dosyć im będzie, choćby każdy z nich mało co wziął.
8 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Anderu, arákùnrin Simoni Peteru wí fún un pé,
Rzekł mu jeden z uczniów jego, Andrzej, brat Szymona Piotra:
9 “Ọmọdékùnrin kan ń bẹ níhìn-ín yìí, tí ó ní ìṣù àkàrà barle márùn-ún àti ẹja wẹ́wẹ́ méjì, ṣùgbọ́n kín ni ìwọ̀nyí jẹ́ láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí?”
Jest tu jedno pacholę, co ma pięcioro chleba jęczmiennego i dwie rybki; ale cóż to jest na tak wielu?
10 Jesu sì wí pé, “Ẹ mú kí àwọn ènìyàn náà jókòó!” Koríko púpọ̀ sì wá níbẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin náà jókòó; ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn ní iye.
Tedy rzekł Jezus: Każcie ludowi usiąść. A było trawy dość na onemże miejscu, i usiadło mężów w liczbie około pięciu tysięcy.
11 Jesu sì mú ìṣù àkàrà náà. Nígbà tí ó sì ti dúpẹ́, ó pín wọn fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì pín wọn fún àwọn tí ó jókòó; bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ sì ni ẹja ní ìwọ̀n bí wọ́n ti ń fẹ́.
Wziął tedy Jezus one chleby, a podziękowawszy rozdał uczniom, a uczniowie siedzącym; także i z onych rybek, ile jedno chcieli.
12 Nígbà tí wọ́n sì yó, ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ kó àjẹkù tí ó kù jọ, kí ohunkóhun má ṣe ṣòfò.”
A gdy byli nasyceni, rzekł uczniom swoim: Zbierzcie te ułomki, które zbywają, żeby nic nie zginęło.
13 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó wọn jọ wọ́n sì fi àjẹkù ìṣù àkàrà barle márùn-ún náà kún agbọ̀n méjìlá, èyí tí àwọn tí ó jẹun jẹ kù.
I zebrali i napełnili dwanaście koszów ułomków z onego pięciorga chleba jęczmiennego, które zbywały tym, co jedli.
14 Nítorí náà nígbà tí àwọn ọkùnrin náà rí iṣẹ́ àmì tí Jesu ṣe, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà tí ń bọ̀ wá sí ayé.”
A oni ludzie, ujrzawszy cud, który uczynił Jezus, mówili: Tenci jest zaprawdę on prorok, który miał przyjść na świat.
15 Nígbà tí Jesu sì wòye pé wọ́n ń fẹ́ wá fi agbára mú òun láti lọ fi jẹ ọba, ó tún padà lọ sórí òkè, òun nìkan.
Tedy Jezus poznawszy, iż mieli przyjść i porwać go, aby go uczynili królem, uszedł zasię sam tylko na górę.
16 Nígbà tí alẹ́ sì lẹ́, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun.
A gdy był wieczór, zstąpili uczniowie jego do morza.
17 Wọ́n sì bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, wọ́n sì rékọjá Òkun lọ sí Kapernaumu. Ilẹ̀ sì ti ṣú, Jesu kò sì tí ì dé ọ̀dọ̀ wọn.
A wstąpiwszy w łódź, jechali za morze do Kapernaum, a już było ciemno, a Jezus nie przyszedł był do nich.
18 Òkun sì ń ru nítorí ẹ̀fúùfù líle tí ń fẹ́.
A morze, gdy powstał wielki wiatr, burzyć się poczynało.
19 Nígbà tí wọ́n wa ọkọ̀ ojú omi tó bí ìwọ̀n ibùsọ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tàbí ọgbọ̀n, wọ́n rí Jesu ń rìn lórí Òkun, ó sì súnmọ́ ọkọ̀ ojú omi náà; ẹ̀rù sì bà wọ́n.
Gdy tedy odpłynęli jakoby na dwadzieścia i pięć lub trzydzieści stajan, ujrzeli Jezusa chodzącego po morzu, przybliżającego się ku łodzi, i ulękli się.
20 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ni; ẹ má bẹ̀rù.”
A on im rzekł: Jamci jest, nie bójcie się.
21 Nítorí náà wọ́n fi ayọ̀ gbà á sínú ọkọ̀; lójúkan náà ọkọ̀ náà sì dé ilẹ̀ ibi tí wọ́n ń lọ.
I wzięli go ochotnie do łodzi, a zarazem łódź przypłynęła do ziemi, do której jechali.
22 Ní ọjọ́ kejì nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó dúró ní òdìkejì Òkun rí i pé, kò sí ọkọ̀ ojú omi mìíràn níbẹ̀, bí kò ṣe ọ̀kan náà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ̀, àti pé Jesu kò bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ inú ọkọ̀ ojú omi náà, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ nìkan ni ó lọ.
Nazajutrz lud, który był za morzem, widząc, że tam nie było drugiej łodzi, tylko ona jedna, w którą byli wstąpili uczniowie jego, a iż Jezus nie wszedł był w łódź z uczniami swoimi, ale sami uczniowie jego ujechali;
23 Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ̀ ojú omi mìíràn ti Tiberia wá, létí ibi tí wọn gbé jẹ àkàrà, lẹ́yìn ìgbà tí Olúwa ti dúpẹ́.
(Przyszły też były drugie łodzie z Tyberyjady, blisko do onego miejsca, gdzie jedli chleb, gdy był Pan dzięki uczynił.)
24 Nítorí náà nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Jesu tàbí ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò sí níbẹ̀, àwọn pẹ̀lú wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Kapernaumu, wọ́n ń wá Jesu.
To gdy obaczył lud, iż tam nie było Jezusa, ani uczniów jego, wstąpili i oni w łodzie i przeprawili się do Kapernaum, szukając Jezusa;
25 Nígbà tí wọ́n sì rí i ní apá kejì Òkun, wọ́n wí fún un pé, “Rabbi, nígbà wo ni ìwọ wá síyìn-ín yìí?”
A znalazłszy go za morzem, rzekli mu: Mistrzu! kiedyś tu przybył?
26 Jesu dá wọn lóhùn ó sì wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín. Ẹ̀yin ń wá mi, kì í ṣe nítorí tí ẹ̀yin rí iṣẹ́ àmì, ṣùgbọ́n nítorí ẹ̀yin jẹ àjẹyó ìṣù àkàrà.
Odpowiedział im Jezus i rzekł: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Szukacie mię nie przeto, iżeście widzieli cuda, ale iżeście jedli chleb, i byliście nasyceni.
27 Ẹ má ṣe ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tí ń ṣègbé, ṣùgbọ́n fún oúnjẹ tí ó wà títí di ayé àìnípẹ̀kun, èyí tí Ọmọ Ènìyàn yóò fi fún yín. Nítorí pé òun ni, àní Ọlọ́run Baba ti fi èdìdì dì í.” (aiōnios )
Sprawujcież nie pokarm, który ginie, ale pokarm, który trwa ku żywotowi wiecznemu, który wam da Syn człowieczy; albowiem tego zapieczętował Bóg Ojciec. (aiōnios )
28 Nígbà náà ni wọ́n wí fún wọn pé, “Kín ni àwa ó ha ṣe, kí a lè ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run?”
Rzekli tedy do niego: Cóż będziemy czynili, abyśmy sprawowali sprawy Boże?
29 Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni iṣẹ́ Ọlọ́run pé, kí ẹ̀yin gba ẹni tí ó rán an gbọ́.”
Odpowiedział Jezus i rzekł im: Toć jest sprawa Boża, abyście wierzyli w tego, którego on posłał.
30 Nígbà náà ni wọ́n wí fún wọn pé, “Iṣẹ́ àmì kín ní ìwọ ń ṣe, tí àwa lè rí, kí a sì gbà ọ́ gbọ́? Iṣẹ́ kín ní ìwọ ṣe?
Rzekli mu tedy: Cóż wżdy ty za znak czynisz, abyśmy widzieli i wierzyli tobie? Cóż czynisz?
31 Àwọn baba wa jẹ manna ní aginjù; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, ‘Ó fi oúnjẹ láti ọ̀run wá fún wọn jẹ.’”
Ojcowie nasi jedli mannę na puszczy, jako jest napisano: Chleb z nieba dał im ku jedzeniu.
32 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kì í ṣe Mose ni ó fi oúnjẹ fún yín láti ọ̀run wá, ṣùgbọ́n Baba mi ni ó fi oúnjẹ òtítọ́ náà fún yín láti ọ̀run wá.
Rzekł im tedy Jezus: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Nie Mojżesz wam dał chleb z nieba, ale Ojciec mój daje wam chleb on prawdziwy z nieba.
33 Nítorí pé oúnjẹ Ọlọ́run ni èyí tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, tí ó sì fi ìyè fún aráyé.”
Albowiem chleb Boży ten jest, który zstępuje z nieba i żywot daje światu.
34 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Olúwa, máa fún wa ní oúnjẹ yìí títí láé.”
Tedy mu rzekli: Panie! daj nam zawsze tego chleba.
35 Jesu wí fún wọn pé, “Èmi ni oúnjẹ ìyè, ẹnikẹ́ni tí ó bá tọ̀ mí wá, ebi kì yóò pa á; ẹni tí ó bá sì gbà mí gbọ́, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé.
I rzekł im Jezus: Jamci jest on chleb żywota; kto do mnie przychodzi, łaknąć nie będzie, a kto wierzy w mię, nigdy pragnąć nie będzie.
36 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín pé, Ẹ̀yin ti rí mi, ẹ kò sì gbàgbọ́.
Alem wam powiedział: Owszem, widzieliście mię, a nie wierzycie.
37 Gbogbo èyí tí Baba fi fún mi, yóò tọ̀ mí wá; ẹni tí ó bá sì tọ̀ mí wá, èmi kì yóò tà á nù, bí ó tí wù kó rí.
Wszystko, co mi daje Ojciec, do mnie przyjdzie, a tego, co do mnie przyjdzie, nie wyrzucę precz.
38 Nítorí èmi sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, kì í ṣe láti máa ṣe ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.
Bom zstąpił z nieba, nie iżbym czynił wolę moję, ale wolę onego, który mię posłał.
39 Èyí sì ni ìfẹ́ Baba tí ó rán mi pé ohun gbogbo tí o fi fún mi, kí èmi má ṣe sọ ọ̀kan nù nínú wọn, ṣùgbọ́n kí èmi lè jí wọn dìde níkẹyìn ọjọ́.
A tać jest wola onego, który mię posłał, Ojca, abym z tego wszystkiego, co mi dał, nic nie stracił, ale abym to wzbudził w on ostateczny dzień.
40 Èyí sì ni ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, pé ẹnikẹ́ni tí ó bá wo ọmọ, tí ó bá sì gbà á gbọ́, kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun, Èmi ó sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́.” (aiōnios )
A tać jest wola onego, który mię posłał, aby każdy, kto widzi Syna, a wierzy weń, miał żywot wieczny; a ja go wzbudzę w on ostateczny dzień. (aiōnios )
41 Nígbà náà ni àwọn Júù ń kùn sí i, nítorí tí ó wí pé, “Èmi ni oúnjẹ tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá.”
I szemrali Żydowie o nim, iż rzekł: Jam jest on chleb, który z nieba zstąpił.
42 Wọ́n sì wí pé, “Jesu ha kọ́ èyí, ọmọ Josẹfu, baba àti ìyá ẹni tí àwa mọ̀? Báwo ni ó ṣe wí pé, ‘Èmi ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá’?”
I mówili: Izaż ten nie jest Jezus, syn Józefa, którego my ojca i matkę znamy; jakoż teraz tedy ten powiada: Żem z nieba zstąpił?
43 Nítorí náà Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe kùn láàrín yín!
Tedy odpowiedział Jezus i rzekł im: Nie szemrzyjcie między sobą.
44 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè wá sọ́dọ̀ mi, bí kò ṣe pé Baba tí ó rán mi fà á, Èmi ó sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́.
Żaden do mnie przyjść nie może, jeźli go Ojciec mój, który mię posłał, nie pociągnie; a ja go wzbudzę w ostateczny dzień.
45 A sá à ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé, ‘A ó sì kọ́ gbogbo wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,’ nítorí náà ẹnikẹ́ni tí ó bá ti gbọ́, tí a sì ti ọ̀dọ̀ Baba kọ́, òun ni ó ń tọ̀ mí wá.
Napisano w prorokach: I będą wszyscy wyuczeni od Boga; przetoż każdy, kto słyszał od Ojca, a nauczył się, przychodzi do mnie.
46 Kì í ṣe pé ẹnìkan ti rí Baba bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, òun ni ó ti rí Baba.
Nie iżby kto widział Ojca, oprócz tego, który jest od Boga; ten widział Ojca.
47 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Kto w mię wierzy, ma żywot wieczny. (aiōnios )
Jam jest on chleb żywota.
49 Àwọn baba yín jẹ manna ní aginjù, wọ́n sì kú.
Ojcowie wasi jedli mannę na puszczy, a pomarli.
50 Èyí ni oúnjẹ tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, kí ènìyàn lè máa jẹ nínú rẹ̀ kí ó má sì kú.
Ten jest on chleb, który z nieba zstępuje; jeźliby go kto jadł, nie umrze.
51 Èmi ni oúnjẹ ìyè náà tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, bí ẹnikẹ́ni bá jẹ nínú oúnjẹ yìí, yóò yè títí láéláé, oúnjẹ náà tí èmi ó sì fi fún ni fún ìyè aráyé ni ara mi.” (aiōn )
Jamci jest chleb on żywy, którym z nieba zstąpił: jeźliby kto jadł z tego chleba, żyć będzie na wieki; a chleb, który ja dam, jest ciało moje, które ja dam za żywot świata. (aiōn )
52 Nítorí náà ni àwọn Júù ṣe ń bá ara wọn jiyàn, pé, “Ọkùnrin yìí yóò ti ṣe lè fi ara rẹ̀ fún wa láti jẹ?”
Wadzili się tedy Żydowie między sobą, mówiąc: Jakoż ten może nam dać ciało swoje ku jedzeniu?
53 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá jẹ ara Ọmọ Ènìyàn, kí ẹ sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ẹ̀yin kò ní ìyè nínú yin.
I rzekł im Jezus: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Jeźli nie będziecie jedli ciała Syna człowieczego, i pili krwi jego, nie macie żywota w sobie.
54 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ara mi, tí ó bá sì mu ẹ̀jẹ̀ mi, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun. Èmi o sì jí i dìde níkẹyìn ọjọ́. (aiōnios )
Kto je ciało moje, a pije krew moję, ma żywot wieczny, a ja go wzbudzę w on ostateczny dzień. (aiōnios )
55 Nítorí ara mi ni ohun jíjẹ nítòótọ́, àti ẹ̀jẹ̀ mi ni ohun mímu nítòótọ́.
Albowiem ciało moje prawdziwie jest pokarm, a krew moja prawdziwie jest napój.
56 Ẹni tí ó bá jẹ ara mi, tí ó bá sì mu ẹ̀jẹ̀ mi, ó ń gbé inú mi, èmi sì ń gbé inú rẹ̀.
Kto je ciało moje i pije krew moję, we mnie mieszka, a ja w nim.
57 Gẹ́gẹ́ bí Baba alààyè ti rán mi, tí èmi sì yè nípa Baba gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó jẹ mí, òun pẹ̀lú yóò yè nípa mi.
Jako mię posłał żyjący Ojciec, i ja żyję przez Ojca; tak kto mnie pożywa, i on żyć będzie przez mię.
58 Èyí sì ni oúnjẹ náà tí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, kì í ṣe bí àwọn baba yín ti jẹ manna, tí wọ́n sì kú, ẹni tí ó bá jẹ́ oúnjẹ yìí yóò yè láéláé.” (aiōn )
Tenci jest chleb on, który z nieba zstąpił, nie jako ojcowie wasi jedli mannę, a pomarli; kto je ten chleb, żyć będzie na wieki. (aiōn )
59 Nǹkan wọ̀nyí ni ó sọ nínú Sinagọgu, bí ó ti ń kọ́ni ní Kapernaumu.
To mówił w bóżnicy, ucząc w Kapernaum.
60 Nítorí náà nígbà tí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wí pé, “Ọ̀rọ̀ tí ó le ni èyí; ta ní lè gbọ́ ọ?”
Wiele ich tedy z uczniów jego słysząc to, mówili: Twardać to jest mowa, któż jej słuchać może?
61 Nígbà tí Jesu sì mọ̀ nínú ara rẹ̀ pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń kùn sí ọ̀rọ̀ náà, ó wí fún wọn pé, “Èyí jẹ́ ìkọ̀sẹ̀ fún yín bí?
Ale wiedząc Jezus sam w sobie, iż o tem szemrali uczniowie jego, rzekł im: Toż was obraża?
62 Ǹjẹ́, bí ẹ̀yin bá sì rí i tí Ọmọ Ènìyàn ń gòkè lọ sí ibi tí ó gbé ti wà rí ń kọ́?
Cóż, gdybyście ujrzeli Syna człowieczego wstępującego, gdzie był pierwej?
63 Ẹ̀mí ní ń sọ ni di ààyè; ara kò ní èrè kan; ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí mo sọ fún yín, ẹ̀mí ni, ìyè sì ni pẹ̀lú.
Duchci jest, który ożywia, ciało nic nie pomaga; słowa, które ja wam mówię, duch są i żywot są.
64 Ṣùgbọ́n àwọn kan wà nínú yín tí kò gbàgbọ́.” Nítorí Jesu mọ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá ẹni tí wọ́n jẹ́ tí kò gbàgbọ́, àti ẹni tí yóò fi òun hàn.
Ale są niektórzy z was, co nie wierzą; albowiem wiedział od początku Jezus, którzy byli, co nie wierzyli, i kto jest, co go miał wydać;
65 Ó sì wí pé, “Nítorí náà ni mo ṣe wí fún yín pé, kò sí ẹni tí ó lè tọ̀ mí wá, bí kò ṣe pé a fi fún un láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá.”
I mówił: Dlategomci wam powiedział: Iż żaden nie może przyjść do mnie, jeźliby mu nie było dane od Ojca mojego.
66 Nítorí èyí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ padà sẹ́yìn, wọn kò sì bá a rìn mọ́.
Od tego czasu wiele uczniów jego odeszło nazad, a więcej z nim nie chodzili.
67 Nítorí náà Jesu wí fún àwọn méjìlá pé, “Ẹ̀yin pẹ̀lú ń fẹ́ lọ bí?”
Tedy rzekł Jezus do onych dwunastu: Izali i wy chcecie odejść?
68 Nígbà náà ni Simoni Peteru dá a lóhùn pé, “Olúwa, ọ̀dọ̀ ta ni àwa ó lọ? Ìwọ ni ó ni ọ̀rọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
I odpowiedział mu Szymon Piotr: Panie! do kogóż pójdziemy? Ty masz słowa żywota wiecznego; (aiōnios )
69 Àwa sì ti gbàgbọ́, a sì mọ̀ pé ìwọ ni Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run alààyè.”
A myśmy uwierzyli i poznali, żeś ty jest Chrystus, on Syn Boga żywego.
70 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin méjìlá kọ́ ni mo yàn, ọ̀kan nínú yín kò ha sì ya èṣù?”
Odpowiedział im Jezus: Izalim ja nie dwunastu was obrał? a jeden z was jest dyjabeł.
71 (Ó ń sọ ti Judasi Iskariotu ọmọ Simoni ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, nítorí pé òun ni ẹni tí yóò fi í hàn.)
A to mówił o Judaszu, synu Szymona, Iszkaryjocie; bo go ten wydać miał, będąc jednym z onych dwunastu.