< John 5 >
1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, àjọ àwọn Júù kan kò; Jesu sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Depois disso, Jesus foi para Jerusalém, por causa de uma festa dos judeus.
2 Adágún omi kan sì wà ní Jerusalẹmu, létí bodè àgùntàn, tí a ń pè ní Betisaida ní èdè Heberu, tí ó ní ẹnu-ọ̀nà márùn-ún.
Próximo ao Portão das Ovelhas, em Jerusalém, havia um tanque com cinco entradas ao seu redor. Em hebraico, esse tanque era chamado de Betezata.
3 Ní ẹ̀gbẹ́ odò yìí ni ọ̀pọ̀ àwọn abirùn ènìyàn máa ń gbé dùbúlẹ̀ sí, àwọn afọ́jú, arọ àti aláàrùn ẹ̀gbà.
Muitas pessoas doentes estavam deitadas nessas entradas. Eram cegos, mancos, paralíticos, entre outros.
5 Ọkùnrin kan wà níbẹ̀, ẹni tí ó tí wà ní àìlera fún ọdún méjìdínlógójì.
Havia um homem que também estava lá, doente há trinta e oito anos. Jesus olhou para ele, já sabendo que o homem estava deitado lá por muito tempo e lhe perguntou:
6 Bí Jesu ti rí i ní ìdùbúlẹ̀, tí ó sì mọ̀ pé ó pẹ́ tí ó ti wà bẹ́ẹ̀, ó wí fún un pé, “Ìwọ fẹ́ kí a mú ọ láradá bí?”
“Você quer ser curado?”
7 Abirùn náà dá a lóhùn wí pé, “Arákùnrin, èmi kò ní ẹni tí ìbá gbé mi sínú adágún, nígbà tí a bá ń rú omi náà, bí èmi bá ti ń bọ̀ wá, ẹlòmíràn a sọ̀kalẹ̀ sínú rẹ̀ síwájú mi.”
O homem respondeu: “Senhor, não há ninguém que possa me ajudar a entrar na água quando ela é agitada. Quando eu tento entrar na água, sempre há alguém que passa na minha frente e entra primeiro.”
8 Jesu wí fún un pé, “Dìde, gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn.”
Jesus lhe disse: “Fique em pé, pegue sua esteira e comece a andar!”
9 Lọ́gán, a sì mú ọkùnrin náà láradá, ó sì gbé àkéte rẹ̀, ó sì ń rìn. Ọjọ́ náà sì jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
Imediatamente, o homem foi curado. Ele pegou sua esteira e caminhou. Foi em um sábado que isso aconteceu.
10 Nítorí náà àwọn Júù wí fún ọkùnrin náà tí a mú láradá pé, “Ọjọ́ ìsinmi ni òní; kò tọ́ fún ọ láti gbé àkéte rẹ.”
Então, os judeus disseram ao homem que havia sido curado: “Hoje é sábado! É contra a lei carregar sua esteira neste dia.”
11 Ó sì dá wọn lóhùn wí pé, “Ẹni tí ó mú mi láradá, ni ó wí fún mi pé, ‘Gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn.’”
Ele respondeu aos judeus: “O homem que me curou disse para que eu pegasse a minha esteira e começasse a andar.”
12 Nígbà náà ni wọ́n bi í lérè wí pé, “Ọkùnrin wo ni ẹni tí ó wí fún ọ pé gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn?”
Os judeus perguntaram: “Quem lhe disse para pegar sua esteira e andar?”
13 Ẹni tí a mú láradá náà kò sì mọ̀ ẹni tí ó jẹ́ nítorí Jesu ti kúrò níbẹ̀, àwọn ènìyàn púpọ̀ wà níbẹ̀.
Porém, ele não tinha ideia de quem era, pois Jesus havia desaparecido no meio da multidão.
14 Lẹ́yìn náà, Jesu rí i nínú tẹmpili ó sì wí fún un pé, “Wò ó, a mú ọ láradá: má ṣe dẹ́ṣẹ̀ mọ́, kí ohun tí ó burú ju èyí lọ má ba à bá ọ!”
Mais tarde, Jesus encontrou, no Templo, o homem que havia curado e lhe disse: “Veja! Agora você está curado. Então, pare de pecar ou algo pior pode lhe acontecer.”
15 Ọkùnrin náà lọ, ó sì sọ fún àwọn Júù pé, Jesu ni ẹni tí ó mú òun láradá.
O homem foi dizer aos judeus que fora Jesus quem o havia curado.
16 Nítorí èyí ni àwọn Júù ṣe inúnibíni sí Jesu, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á, nítorí tí o ń ṣe nǹkan wọ̀nyí ní ọjọ́ ìsinmi.
Os judeus, então, começaram a perseguir Jesus porque ele estava curando aos sábados.
17 Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Baba mi ń ṣiṣẹ́ títí di ìsinsin yìí, èmi náà sì ń ṣiṣẹ́.”
Mas, Jesus lhes disse: “Meu Pai ainda está trabalhando, e eu também.”
18 Nítorí èyí ni àwọn Júù túbọ̀ ń wá ọ̀nà láti pa á, kì í ṣe nítorí pé ó ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́ nìkan ni, ṣùgbọ́n ó wí pẹ̀lú pé, Baba òun ni Ọlọ́run jẹ́, ó ń mú ara rẹ̀ bá Ọlọ́run dọ́gba.
Essa foi a justificativa para os judeus quererem ainda mais matá-lo, porque, além de não obedecer a lei do sábado, também dizia que Deus era seu próprio Pai, fazendo-se, assim, igual a Deus.
19 Nígbà náà ni Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọmọ kò lè ṣe ohunkóhun fún ara rẹ̀, bí kò ṣe ohun tí ó bá rí pé Baba ń ṣe, nítorí ohunkóhun tí baba bá ń ṣe, ìwọ̀nyí ni ọmọ náà sì ń ṣe pẹ̀lú.
Jesus explicou aos judeus: “Eu lhes digo que isto é verdade: o Filho não pode fazer nada por si mesmo. Ele só faz o que vê o Pai fazer. Tudo o que o Pai fizer, o Filho faz também.
20 Nítorí Baba fẹ́ràn ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo tí ó ń ṣe hàn án, òun yóò sì fi iṣẹ́ tí ó tóbi jù wọ̀nyí lọ hàn án, kí ẹnu lè yà yín.
Pois o Pai ama o Filho e mostra para ele tudo o que faz. E o Pai irá mostrar a ele coisas até mais incríveis do que essas e que farão com que vocês fiquem completamente fascinados.
21 Nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Baba ti ń jí òkú dìde, tí ó sì ń sọ wọ́n di alààyè: bẹ́ẹ̀ ni ọmọ ń sọ àwọn tí ó fẹ́ di alààyè pẹ̀lú.
Pois exatamente como o Pai dá vida aos que ele ressuscita do mundo dos mortos, o Filho também dá vida para os que ele quer.
22 Nítorí pé Baba kì í ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni, ṣùgbọ́n ó ti fi gbogbo ìdájọ́ lé ọmọ lọ́wọ́,
O Pai não julga ninguém. Ele deu ao Filho toda a autoridade para julgar,
23 kí gbogbo ènìyàn lè máa fi ọlá fún ọmọ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń fi ọlá fún Baba. Ẹnikẹ́ni tí kò bá fi ọlá fún ọmọ, kò fi ọlá fún Baba tí ó ran an.
para que, assim, todos possam respeitar o Filho da mesma maneira que respeitam o Pai. Qualquer pessoa que não respeita o Filho também não respeita o Pai, que o enviou.
24 “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó bá sì gba ẹni tí ó rán mi gbọ́, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun, òun kì yóò sì wá sí ìdájọ́; ṣùgbọ́n ó ti ré ikú kọjá bọ́ sí ìyè. (aiōnios )
Eu lhes digo que isto é verdade: quem segue o que eu digo, e tem fé naquele que me enviou, tem a vida eterna. E não será condenado, mas já passou da morte para a vida. (aiōnios )
25 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, wákàtí náà ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn òkú yóò gbọ́ ohùn Ọmọ Ọlọ́run, àwọn tí ó bá gbọ́ yóò sì yè.
Eu lhes digo que isto é verdade: Está chegando o tempo, de fato ele já chegou, quando os mortos ouvirão a voz do Filho de Deus, e aqueles que a ouvirem irão viver!
26 Nítorí pé gẹ́gẹ́ bí Baba ti ní ìyè nínú ara rẹ̀; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ó sì fi fún ọmọ láti ní ìyè nínú ara rẹ̀;
Exatamente como o próprio Pai tem vida em si mesmo também concedeu ao Filho ter vida em si mesmo.
27 Ó sì fún un ní àṣẹ láti máa ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú, nítorí tí òun jẹ́ Ọmọ Ènìyàn.
O Pai também lhe deu autoridade de julgar, pois ele é o Filho do Homem.
28 “Kí èyí má ṣe yà yín lẹ́nu; nítorí pé wákàtí ń bọ̀, nínú èyí tí gbogbo àwọn tí ó wà ní ibojì yóò gbọ́ ohun rẹ̀.
Não fiquem surpresos com isso, pois está chegando o tempo em que todos aqueles que estão mortos ouvirão a sua voz
29 Wọn ó sì jáde wá; àwọn tí ó ṣe rere, sí àjíǹde ìyè; àwọn tí ó sì ṣe búburú sí àjíǹde ìdájọ́.
e sairão dos túmulos. Aqueles que fizeram o bem ressuscitarão para a vida, e aqueles que fizeram o mal ressuscitarão para serem condenados.
30 Èmi kò le ṣe ohun kan fún ara mi, bí mo ti ń gbọ́ ni, mo ń dájọ́, òdodo sì ni ìdájọ́ mi; nítorí èmi kò wá ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.
Eu não posso fazer nada sozinho. Eu julgo com base no que o Pai me diz, e o meu julgamento é correto, pois eu não estou fazendo de acordo com a minha própria vontade e, sim, seguindo a vontade daquele que me enviou.
31 “Bí èmi bá ń jẹ́rìí ara mi, ẹ̀rí mi kì í ṣe òtítọ́.
Se eu fizesse declarações a meu favor, elas não teriam valor.
32 Ẹlòmíràn ni ẹni tí ń jẹ́rìí mi; èmi sì mọ̀ pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi tí ó jẹ́.
Mas, é outro que dá provas a meu respeito, e eu sei que o que ele diz sobre mim é verdade.
33 “Ẹ̀yin ti ránṣẹ́ lọ sọ́dọ̀ Johanu, òun sì ti jẹ́rìí sí òtítọ́.
Vocês perguntaram a João sobre mim, e ele disse a verdade.
34 Ṣùgbọ́n èmi kò gba ẹ̀rí lọ́dọ̀ ènìyàn, nǹkan wọ̀nyí ni èmi ń sọ, kí ẹ̀yin lè là.
Porém, eu não preciso da aprovação dos homens. Eu estou apenas explicando isso para que vocês sejam salvos.
35 Òun ni fìtílà tí ó ń jó, tí ó sì ń tànmọ́lẹ̀, ẹ̀yin sì fẹ́ fún sá à kan láti máa yọ̀ nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
João era como uma luz que brilhava intensamente e, por um tempo, vocês se alegraram com sua luz.
36 “Ṣùgbọ́n èmi ní ẹ̀rí tí ó pọ̀jù ti Johanu lọ. Nítorí iṣẹ́ tí Baba ti fi fún mi láti ṣe parí, iṣẹ́ náà pàápàá tí èmi ń ṣe náà ń jẹ́rìí mi pé, Baba ni ó rán mi.
Mas, a prova que eu estou dando é muito mais importante do que a de João. Pois estou fazendo o trabalho que o Pai me mandou fazer,
37 Àti Baba tìkára rẹ̀ tí ó rán mi ti jẹ́rìí mi. Ẹ̀yin kò gbọ́ ohùn rẹ̀ nígbà kan rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò rí ìrísí rẹ̀.
e esta é a prova de que o Pai me enviou. E o próprio Pai que me enviou testemunha a meu favor. Vocês nunca ouviram a sua voz ou viram como ele se parece,
38 Ẹ kò sì ní ọ̀rọ̀ rẹ̀ láti máa gbé inú yín, nítorí ẹni tí ó rán, òun ni ẹ̀yin kò gbàgbọ́.
e vocês não aceitam o que ele diz, pois não acreditam naquele que ele enviou.
39 Ẹ̀yin ń wá ìwé mímọ́ nítorí ẹ̀yin rò pé nínú wọn ni ẹ̀yin ní ìyè tí kò nípẹ̀kun. Wọ̀nyí sì ni àwọn tí ó ń jẹ́rìí mi. (aiōnios )
Vocês estudam as Sagradas Escrituras porque pensam que, por meio delas, ganharão a vida eterna. E são exatamente elas que testemunham a meu favor. (aiōnios )
40 Ẹ̀yin kò sì fẹ́ láti wá sọ́dọ̀ mi, kí ẹ̀yin ba à lè ní ìyè.
E, no entanto, vocês não querem vir até mim para terem vida.
41 “Èmi kò gba ògo lọ́dọ̀ ènìyàn.
Eu não busco a aprovação dos homens.
42 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé, ẹ̀yin fúnra yín kò ní ìfẹ́ Ọlọ́run nínú yín.
Eu os conheço, e sei que vocês não têm o amor de Deus em seus corações.
43 Èmi wá ní orúkọ Baba mi, ẹ̀yin kò sì gbà mí; bí ẹlòmíràn bá wá ní orúkọ ara rẹ̀, òun ni ẹ̀yin yóò gbà.
Pois eu vim com autoridade do meu Pai, e vocês não me aceitam. Mas, se outro vier com sua própria autoridade, então, este vocês o aceitarão.
44 Ẹ̀yin ó ti ṣe lè gbàgbọ́, ẹ̀yin tí ń gba ògo lọ́dọ̀ ara yín tí kò wá ògo tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nìkan wá?
Como vocês podem crer em mim, se procuram elogios uns dos outros e, no entanto, não buscam o elogio do único Deus verdadeiro?
45 “Ẹ má ṣe rò pé, èmi ó fi yín sùn lọ́dọ̀ Baba, ẹni tí ń fi yín sùn wà, àní Mose, ẹni tí ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé.
Mas, não pensem que eu farei acusações contra vocês diante do Pai. Moisés, aquele em quem vocês colocam sua esperança, é quem vai acusá-los.
46 Nítorí pé ẹ̀yin ìbá gba Mose gbọ́, ẹ̀yin ìbá gbà mí gbọ́, nítorí ó kọ ìwé nípa tèmi.
Se vocês realmente acreditassem em Moisés também acreditariam em mim, pois ele escreveu a meu respeito.
47 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gba ìwé rẹ̀ gbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbà ọ̀rọ̀ mi gbọ́?”
Mas, como não acreditam no que ele escreveu, por que acreditariam no que eu digo?”