< John 5 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, àjọ àwọn Júù kan kò; Jesu sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Było potem święto żydowskie, i wstąpił Jezus do Jeruzalemu.
2 Adágún omi kan sì wà ní Jerusalẹmu, létí bodè àgùntàn, tí a ń pè ní Betisaida ní èdè Heberu, tí ó ní ẹnu-ọ̀nà márùn-ún.
A była w Jeruzalemie przy owczej bramie sadzawka, którą zowią po żydowsku Betesda, mająca pięć ganków.
3 Ní ẹ̀gbẹ́ odò yìí ni ọ̀pọ̀ àwọn abirùn ènìyàn máa ń gbé dùbúlẹ̀ sí, àwọn afọ́jú, arọ àti aláàrùn ẹ̀gbà.
W tych leżało mnóstwo wielkie niedołężnych, ślepych, chromych, wyschłych, którzy czekali poruszenia wody.
4
Albowiem Anioł czasu pewnego zstępował w sadzawkę i poruszał wodę; a tak, kto pierwszy wstąpił po wzruszeniu wody, stawał się zdrowym, jakąbykolwiek chorobą zdjęty był.
5 Ọkùnrin kan wà níbẹ̀, ẹni tí ó tí wà ní àìlera fún ọdún méjìdínlógójì.
A był tam niektóry człowiek trzydzieści i ośm lat chorobą złożony.
6 Bí Jesu ti rí i ní ìdùbúlẹ̀, tí ó sì mọ̀ pé ó pẹ́ tí ó ti wà bẹ́ẹ̀, ó wí fún un pé, “Ìwọ fẹ́ kí a mú ọ láradá bí?”
Tego gdy Jezus ujrzał leżącego, a poznawszy, że już przez długi czas chorował, rzekł mu: Chcesz być zdrów?
7 Abirùn náà dá a lóhùn wí pé, “Arákùnrin, èmi kò ní ẹni tí ìbá gbé mi sínú adágún, nígbà tí a bá ń rú omi náà, bí èmi bá ti ń bọ̀ wá, ẹlòmíràn a sọ̀kalẹ̀ sínú rẹ̀ síwájú mi.”
Odpowiedział mu on chory: Panie! nie ma człowieka, który by mię, gdy bywa poruszona woda, wrzucił do sadzawki; ale gdy ja idę, inszy przede mną wstępuje.
8 Jesu wí fún un pé, “Dìde, gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn.”
Rzekł mu Jezus: Wstań, weźmij łoże twoje, a chodź.
9 Lọ́gán, a sì mú ọkùnrin náà láradá, ó sì gbé àkéte rẹ̀, ó sì ń rìn. Ọjọ́ náà sì jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
A zarazem stał się zdrowym on człowiek, i wziął łoże swoje, i chodził. A był sabat onego dnia.
10 Nítorí náà àwọn Júù wí fún ọkùnrin náà tí a mú láradá pé, “Ọjọ́ ìsinmi ni òní; kò tọ́ fún ọ láti gbé àkéte rẹ.”
Tedy rzekli Żydowie onemu uzdrowionemu: Sabat jest, nie godzi ci się łoża nosić.
11 Ó sì dá wọn lóhùn wí pé, “Ẹni tí ó mú mi láradá, ni ó wí fún mi pé, ‘Gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn.’”
Odpowiedział im: Ten, który mię uzdrowił, tenże mi rzekł: Weźmij łoże twoje, a chodź.
12 Nígbà náà ni wọ́n bi í lérè wí pé, “Ọkùnrin wo ni ẹni tí ó wí fún ọ pé gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn?”
I pytali go: Któryż jest ten człowiek, co ci powiedział: Weźmij łoże twoje, a chodź?
13 Ẹni tí a mú láradá náà kò sì mọ̀ ẹni tí ó jẹ́ nítorí Jesu ti kúrò níbẹ̀, àwọn ènìyàn púpọ̀ wà níbẹ̀.
A on uzdrowiony nie wiedział, kto by był; albowiem był Jezus ustąpił, ponieważ wiele ludu było na onem miejscu.
14 Lẹ́yìn náà, Jesu rí i nínú tẹmpili ó sì wí fún un pé, “Wò ó, a mú ọ láradá: má ṣe dẹ́ṣẹ̀ mọ́, kí ohun tí ó burú ju èyí lọ má ba à bá ọ!”
Potem go Jezus znalazł w kościele i rzekł mu: Otoś się stał zdrowym, nie grzesz więcej, aby co gorszego na cię nie przyszło.
15 Ọkùnrin náà lọ, ó sì sọ fún àwọn Júù pé, Jesu ni ẹni tí ó mú òun láradá.
A odszedłszy on człowiek, powiedział Żydom, iż to był Jezus, który go uzdrowił.
16 Nítorí èyí ni àwọn Júù ṣe inúnibíni sí Jesu, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á, nítorí tí o ń ṣe nǹkan wọ̀nyí ní ọjọ́ ìsinmi.
A przetoż Żydowie prześladowali Jezusa i szukali, jakoby go zabili, że to uczynił w sabat.
17 Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Baba mi ń ṣiṣẹ́ títí di ìsinsin yìí, èmi náà sì ń ṣiṣẹ́.”
A Jezus im odpowiedział: Ojciec mój aż dotąd pracuje, i ja pracuję;
18 Nítorí èyí ni àwọn Júù túbọ̀ ń wá ọ̀nà láti pa á, kì í ṣe nítorí pé ó ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́ nìkan ni, ṣùgbọ́n ó wí pẹ̀lú pé, Baba òun ni Ọlọ́run jẹ́, ó ń mú ara rẹ̀ bá Ọlọ́run dọ́gba.
Dlatego tedy tem więcej szukali Żydowie, jakoby go zabili, nie tylko, iż gwałcił sabat, ale że i Ojca swego powiadał być Bogiem, czyniąc się równym Bogu.
19 Nígbà náà ni Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọmọ kò lè ṣe ohunkóhun fún ara rẹ̀, bí kò ṣe ohun tí ó bá rí pé Baba ń ṣe, nítorí ohunkóhun tí baba bá ń ṣe, ìwọ̀nyí ni ọmọ náà sì ń ṣe pẹ̀lú.
Odpowiedział tedy Jezus i rzekł im: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam, nie może Syn sam od siebie nic czynić, jedno co widzi, że Ojciec czyni; albowiem cokolwiek on czyni, to także i Syn czyni.
20 Nítorí Baba fẹ́ràn ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo tí ó ń ṣe hàn án, òun yóò sì fi iṣẹ́ tí ó tóbi jù wọ̀nyí lọ hàn án, kí ẹnu lè yà yín.
Boć Ojciec miłuje Syna i ukazuje mu wszystko, co sam czyni, i większe mu nad te sprawy pokaże, abyście się wy dziwowali.
21 Nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Baba ti ń jí òkú dìde, tí ó sì ń sọ wọ́n di alààyè: bẹ́ẹ̀ ni ọmọ ń sọ àwọn tí ó fẹ́ di alààyè pẹ̀lú.
Albowiem jako Ojciec wzbudza umarłe i ożywia, tak i Syn, które chce, ożywia.
22 Nítorí pé Baba kì í ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni, ṣùgbọ́n ó ti fi gbogbo ìdájọ́ lé ọmọ lọ́wọ́,
Bo Ojciec nikogo nie sądzi, lecz wszystek sąd dał Synowi,
23 kí gbogbo ènìyàn lè máa fi ọlá fún ọmọ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń fi ọlá fún Baba. Ẹnikẹ́ni tí kò bá fi ọlá fún ọmọ, kò fi ọlá fún Baba tí ó ran an.
Aby wszyscy czcili Syna, tak jako czczą Ojca; kto nie czci Syna, nie czci i Ojca, który go posłał.
24 “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó bá sì gba ẹni tí ó rán mi gbọ́, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun, òun kì yóò sì wá sí ìdájọ́; ṣùgbọ́n ó ti ré ikú kọjá bọ́ sí ìyè. (aiōnios g166)
Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Kto słowa mego słucha i wierzy onemu, który mię posłał, ma żywot wieczny i nie przyjdzie na sąd, ale przeszedł z śmierci do żywota. (aiōnios g166)
25 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, wákàtí náà ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn òkú yóò gbọ́ ohùn Ọmọ Ọlọ́run, àwọn tí ó bá gbọ́ yóò sì yè.
Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Że idzie godzina i teraz jest, gdy umarli usłyszą głos Syna Bożego, a którzy usłyszą, żyć będą.
26 Nítorí pé gẹ́gẹ́ bí Baba ti ní ìyè nínú ara rẹ̀; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ó sì fi fún ọmọ láti ní ìyè nínú ara rẹ̀;
Albowiem jako Ojciec ma żywot sam w sobie, tak dał i Synowi, aby miał żywot w samym sobie.
27 Ó sì fún un ní àṣẹ láti máa ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú, nítorí tí òun jẹ́ Ọmọ Ènìyàn.
I dał mu moc i sąd czynić; bo jest Synem człowieczym.
28 “Kí èyí má ṣe yà yín lẹ́nu; nítorí pé wákàtí ń bọ̀, nínú èyí tí gbogbo àwọn tí ó wà ní ibojì yóò gbọ́ ohun rẹ̀.
Nie dziwujcież się temu; boć przyjdzie godzina, w którą wszyscy, co są w grobach, usłyszą głos jego;
29 Wọn ó sì jáde wá; àwọn tí ó ṣe rere, sí àjíǹde ìyè; àwọn tí ó sì ṣe búburú sí àjíǹde ìdájọ́.
I pójdą ci, którzy dobrze czynili, na powstanie żywota; ale ci, którzy źle czynili, na powstanie sądu.
30 Èmi kò le ṣe ohun kan fún ara mi, bí mo ti ń gbọ́ ni, mo ń dájọ́, òdodo sì ni ìdájọ́ mi; nítorí èmi kò wá ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.
Nie mogęć ja sam od siebie nic czynić; jako słyszę, tak sądzę, a sąd mój jest sprawiedliwy; bo nie szukam woli mojej, ale woli tego, który mię posłał, Ojca.
31 “Bí èmi bá ń jẹ́rìí ara mi, ẹ̀rí mi kì í ṣe òtítọ́.
Jeźliżeć ja sam o sobie świadczę, świadectwo moje nie jest prawdziwe.
32 Ẹlòmíràn ni ẹni tí ń jẹ́rìí mi; èmi sì mọ̀ pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi tí ó jẹ́.
Inszy jest, co o mnie świadczy, i wiem, że prawdziwe jest świadectwo, które wydaje o mnie.
33 “Ẹ̀yin ti ránṣẹ́ lọ sọ́dọ̀ Johanu, òun sì ti jẹ́rìí sí òtítọ́.
Wyście słali do Jana, a on dał świadectwo prawdzie.
34 Ṣùgbọ́n èmi kò gba ẹ̀rí lọ́dọ̀ ènìyàn, nǹkan wọ̀nyí ni èmi ń sọ, kí ẹ̀yin lè là.
Ale ja nie od człowieka świadectwo biorę, ale to mówię, abyście wy byli zbawieni.
35 Òun ni fìtílà tí ó ń jó, tí ó sì ń tànmọ́lẹ̀, ẹ̀yin sì fẹ́ fún sá à kan láti máa yọ̀ nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
Onci był świecą gorejącą i świecącą, a wyście się chcieli do czasu poradować w światłości jego.
36 “Ṣùgbọ́n èmi ní ẹ̀rí tí ó pọ̀jù ti Johanu lọ. Nítorí iṣẹ́ tí Baba ti fi fún mi láti ṣe parí, iṣẹ́ náà pàápàá tí èmi ń ṣe náà ń jẹ́rìí mi pé, Baba ni ó rán mi.
Ale ja mam świadectwo większe niż Janowe; albowiem sprawy, które mi dał Ojciec, abym je wykonał, te same sprawy, które ja czynię, świadczą o mnie, iż mię Ojciec posłał.
37 Àti Baba tìkára rẹ̀ tí ó rán mi ti jẹ́rìí mi. Ẹ̀yin kò gbọ́ ohùn rẹ̀ nígbà kan rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò rí ìrísí rẹ̀.
A Ojciec, który mię posłał, onże świadczył o mnie, któregoście wy głosu nigdy nie słyszeli, aniście osoby jego widzieli;
38 Ẹ kò sì ní ọ̀rọ̀ rẹ̀ láti máa gbé inú yín, nítorí ẹni tí ó rán, òun ni ẹ̀yin kò gbàgbọ́.
I słowa jego nie macie w sobie mieszkającego; albowiem, którego on posłał, temu nie wierzycie.
39 Ẹ̀yin ń wá ìwé mímọ́ nítorí ẹ̀yin rò pé nínú wọn ni ẹ̀yin ní ìyè tí kò nípẹ̀kun. Wọ̀nyí sì ni àwọn tí ó ń jẹ́rìí mi. (aiōnios g166)
Badajcież się Pism; boć się wam zda, że w nich żywot wieczny macie, a one są, które świadectwo wydawają o mnie. (aiōnios g166)
40 Ẹ̀yin kò sì fẹ́ láti wá sọ́dọ̀ mi, kí ẹ̀yin ba à lè ní ìyè.
A wżdy do mnie przyjść nie chcecie, abyście żywot mieli.
41 “Èmi kò gba ògo lọ́dọ̀ ènìyàn.
Chwały od ludzi nie przyjmuję.
42 Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé, ẹ̀yin fúnra yín kò ní ìfẹ́ Ọlọ́run nínú yín.
Alem was poznał, że miłości Bożej nie macie w sobie.
43 Èmi wá ní orúkọ Baba mi, ẹ̀yin kò sì gbà mí; bí ẹlòmíràn bá wá ní orúkọ ara rẹ̀, òun ni ẹ̀yin yóò gbà.
Jam przyszedł w imieniu Ojca mego, a nie przyjmujecie mnie: jeźliżby przyszedł inny w imieniu swojem, onego przyjmiecie.
44 Ẹ̀yin ó ti ṣe lè gbàgbọ́, ẹ̀yin tí ń gba ògo lọ́dọ̀ ara yín tí kò wá ògo tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nìkan wá?
Jakoż wy możecie wierzyć, chwałę jedni od drugich przyjmując, ponieważ chwały, która jest od samego Boga, nie szukacie?
45 “Ẹ má ṣe rò pé, èmi ó fi yín sùn lọ́dọ̀ Baba, ẹni tí ń fi yín sùn wà, àní Mose, ẹni tí ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé.
Nie mniemajcie, abym ja was miał oskarżać przed Ojcem; jestci, który skarży na was, Mojżesz, w którym wy nadzieję macie.
46 Nítorí pé ẹ̀yin ìbá gba Mose gbọ́, ẹ̀yin ìbá gbà mí gbọ́, nítorí ó kọ ìwé nípa tèmi.
Bo gdybyście wierzyli Mojżeszowi, wierzylibyście i mnie; gdyż on o mnie pisał.
47 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gba ìwé rẹ̀ gbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbà ọ̀rọ̀ mi gbọ́?”
Ale ponieważ pismom jego nie wierzycie, i jakoż słowom moim uwierzycie?

< John 5 >