< John 4 >
1 Àwọn Farisi sì gbọ́ pé, Jesu ni, ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn púpọ̀ ju Johanu lọ.
Lorsque le Seigneur sut que les pharisiens avaient appris qu'il faisait et baptisait plus de disciples que Jean
2 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Jesu tìkára rẹ̀ kò ṣe ìtẹ̀bọmi bí kò ṣe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀,
(toutefois ce n'était pas Jésus lui-même qui baptisait, mais c'étaient ses disciples),
3 Ó fi Judea sílẹ̀, ó sì tún lọ sí Galili.
il quitta la Judée et retourna en Galilée.
4 Òun sì ní láti kọjá láàrín Samaria.
Or il fallait qu'il passât par la Samarie.
5 Nígbà náà ni ó dé ìlú Samaria kan, tí a ń pè ní Sikari, tí ó súnmọ́ etí ilẹ̀ oko tí Jakọbu ti fi fún Josẹfu, ọmọ rẹ̀.
Il arriva donc à une ville de Samarie, nommée Sychar, située près du fond de terre que Jacob avait donné à son fils Joseph.
6 Kànga Jakọbu sì wà níbẹ̀. Nítorí pé ó rẹ Jesu nítorí ìrìn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó jókòó létí kànga, ó sì jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́.
Là, se trouvait la fontaine de Jacob. Jésus, fatigué de la route, s'assit tout simplement au bord de la fontaine. C'était environ la sixième heure du jour.
7 Obìnrin kan, ará Samaria sì wá láti fà omi, Jesu wí fún un pé ṣe ìwọ yóò fún mi ni omi mu.
Une femme samaritaine étant venue pour puiser de l'eau, Jésus lui dit: «Donne-moi à boire; »
8 Nítorí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti lọ sí ìlú láti lọ ra oúnjẹ.
car ses disciples étaient allés à la ville pour acheter des vivres.
9 Obìnrin ará Samaria náà sọ fún un pé, “Júù ni ìwọ, obìnrin ará Samaria ni èmi. Èétirí tí ìwọ ń béèrè ohun mímu lọ́wọ́ mi?” (Nítorí tí àwọn Júù kì í bá àwọn ará Samaria ṣe pọ̀.)
Cette femme samaritaine lui dit donc: «Comment, toi qui es Juif, me demandes-tu à boire, à moi qui suis une femme samaritaine?» Les Juifs, en effet, ne frayent pas avec les Samaritains.
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ ẹ̀bùn Ọlọ́run, àti ẹni tí ó wí fún ọ pé, ‘Fún mi ni omi mu’, ìwọ ìbá sì ti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, òun ìbá ti fi omi ìyè fún ọ.”
Jésus lui répondit: «Si tu connaissais la grâce que Dieu te fait, et qui est celui qui te dit, «donne-moi à boire, » tu lui aurais toi-même demandé à boire, et il t'aurait donné de l'eau vive.»
11 Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, ìwọ kò ní igbá-ìfami tí ìwọ ó fi fà omi, bẹ́ẹ̀ ni kànga náà jì, Níbo ni ìwọ ó ti rí omi ìyè náà?
— «Seigneur, lui dit cette femme, tu n'as point de seau, et le puits est profond. D'où aurais-tu donc cette eau vive?
12 Ìwọ pọ̀ ju Jakọbu baba wa lọ bí, ẹni tí ó fún wa ní kànga náà, tí òun tìkára rẹ̀ si mu nínú rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ẹran ọ̀sìn rẹ̀?”
Es-tu plus grand que notre père Jacob, qui nous a donné ce puits, et qui en a bu lui-même, aussi bien que ses fils et ses troupeaux?»
13 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi yìí, òǹgbẹ yóò sì tún gbẹ ẹ́.
Jésus lui répondit: «Quiconque boit de cette eau aura encore soif;
14 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi tí èmi ó fi fún un, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé; ṣùgbọ́n omi tí èmi ó fi fún un yóò di kànga omi nínú rẹ̀, tí yóò máa sun si ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn , aiōnios )
celui qui boira de l'eau que je lui donnerai, n'aura plus jamais soif; mais l'eau que je lui donnerai, deviendra en lui une source d'eau jaillissant en vie éternelle.» (aiōn , aiōnios )
15 Obìnrin náà sì wí fún u pé, “Alàgbà, fún mi ní omi yìí, kí òǹgbẹ kí ó má ṣe gbẹ mí, kí èmi kí ó má sì wá fa omi níbí mọ́.”
Cette femme lui dit: «Seigneur, donne-moi de cette eau, afin que je n'aie pas soif, et que je ne vienne pas ici pour puiser.»
16 Jesu wí fún un pé, “Lọ pe ọkọ rẹ, kí ó sì padà wá sí ìhín yìí.”
— «Va, lui dit Jésus, appelle ton mari, et viens ici.»
17 Obìnrin náà dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Èmi kò ní ọkọ.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn dáradára pé, èmi kò ní ọkọ:
— «Je n'ai point de mari, » repartit cette femme. Jésus lui dit: «Tu as raison de dire, «je n'ai point de mari, »
18 Nítorí tí ìwọ ti ní ọkọ márùn-ún rí, ọkùnrin tí ìwọ sì ní báyìí kì í ṣe ọkọ rẹ. Ohun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ tán yìí, òtítọ́ ni.”
car tu as eu cinq maris, et celui que tu as maintenant, n'est pas ton mari. Tu as dit vrai en cela.»
19 Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé, wòlíì ni ìwọ ń ṣe.
— «Seigneur, lui dit cette femme, je vois que tu es prophète.
20 Àwọn baba wa sìn lórí òkè yìí; ẹ̀yin sì wí pé, Jerusalẹmu ni ibi tí ó yẹ tí à bá ti máa sìn.”
Nos pères ont adoré sur cette montagne, et vous dites, vous, que c'est à Jérusalem qu'est le lieu où l'on doit adorer.»
21 Jesu wí fún un pé, “Gbà mí gbọ́ obìnrin yìí, àkókò náà ń bọ̀, nígbà tí kì yóò ṣe lórí òkè yìí tàbí ní Jerusalẹmu ni ẹ̀yin ó máa sin Baba.
Jésus lui dit: «Femme, crois-moi; l'heure vient où vous n'adorerez le Père ni sur cette montagne, ni à Jérusalem.
22 Ẹ̀yin ń sin ohun tí ẹ̀yin kò mọ̀, àwa ń sin ohun tí àwa mọ̀, nítorí ìgbàlà ti ọ̀dọ̀ àwọn Júù wá.
Vous adorez ce que vous ne connaissez pas; pour nous, nous adorons ce que nous connaissons, car le salut vient des Juifs.
23 Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn olùsìn tòótọ́ yóò máa sin Baba ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́, nítorí irú wọn ni Baba ń wá kí ó máa sin òun.
Mais l'heure vient, et elle est déjà venue, où les vrais adorateurs adoreront le Père en esprit et en vérité: ce sont là les adorateurs que le Père demande.
24 Ẹ̀mí ni Ọlọ́run: àwọn ẹni tí ń sìn ín kò lè ṣe aláìsìn ín ní Ẹ̀mí àti ní òtítọ́.”
Dieu est esprit, et il faut que ceux qui l'adorent, l'adorent en esprit et en vérité»
25 Obìnrin náà wí fún un pé, mo mọ̀ pé, “Messia ń bọ̀ wá, tí a ń pè ní Kristi, nígbà tí Òun bá dé, yóò sọ ohun gbogbo fún wa.”
Cette femme lui dit: «Je sais que le Messie va venir; » (celui qu'on appelle Christ) «quand il sera venu, il nous enseignera toutes choses.»
26 Jesu sọ ọ́ di mí mọ̀ fún un pé, “Èmi ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí ni Òun.”
Jésus lui dit: «Je le suis, moi qui te parle.»
27 Lákokò yí ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ dé, ẹnu sì yà wọ́n pé ó ń bá obìnrin sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó wí pé, “Kí ni ìwọ ń wá?” tàbí “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá a sọ̀rọ̀?”
Là-dessus, ses disciples arrivèrent, et ils s'étonnèrent de ce qu'il parlait avec une femme; cependant aucun d'eux ne lui dit: «Que demandes-tu?» ou «Pourquoi parles-tu avec elle?»
28 Nígbà náà ni obìnrin náà fi ládugbó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n lọ sí ìlú, ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé,
Alors la femme laissant là sa cruche, s'en alla à la ville et dit aux gens de l'endroit:
29 “Ẹ wá wò ọkùnrin kan, ẹni tí ó sọ ohun gbogbo tí mo ti ṣe rí fún mi, èyí ha lè jẹ́ Kristi náà?”
«Venez voir un homme qui m'a dit tout ce que j'ai fait; ne serait-ce point le Messie?»
30 Nígbà náà ni wọ́n ti ìlú jáde, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
Les gens sortirent de la ville et vinrent vers Jésus.
31 Láàrín èyí, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń rọ̀ ọ́ wí pé, “Rabbi, jẹun.”
Cependant ses disciples le priaient de prendre quelque nourriture, disant: «Maître, mange.»
32 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ní oúnjẹ láti jẹ, tí ẹ̀yin kò mọ̀.”
Il leur dit: «J'ai à prendre une nourriture que vous ne connaissez pas.»
33 Nítorí náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bi ara wọn lérè wí pé, “Ẹnìkan mú oúnjẹ fún un wá láti jẹ bí?”
Ses disciples se disaient donc les uns aux autres: «Lui aurait-on apporté à manger?»
34 Jesu wí fún wọn pé, “Oúnjẹ mi ni láti ṣe ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, àti láti parí iṣẹ́ rẹ̀.
Jésus leur dit: «Ma nourriture à moi, c'est de faire la volonté de celui qui m'a envoyé, et d'accomplir son oeuvre.
35 Ẹ̀yin kò ha wí pé, ‘Ó ku oṣù mẹ́rin, ìkórè yóò sì dé?’ wò ó, mo wí fún un yín, Ẹ ṣí ojú yín sókè, kí ẹ sì wo oko; nítorí tí wọn ti pọ́n fún ìkórè.
Ne dites-vous pas qu'il y a encore quatre mois jusqu’à la moisson? Voici, je vous dis: Levez les yeux, et regardez les campagnes, elles sont blanches pour la moisson.
36 Kódà báyìí, ẹni tí ó ń kórè ń gba owó ọ̀yà rẹ̀, ó si ń kó èso jọ sí ìyè àìnípẹ̀kun, kí ẹni tí ó ń fúnrúgbìn àti ẹni tí ń kórè lè jọ máa yọ̀ pọ̀. (aiōnios )
Déjà le moissonneur reçoit sa récompense, et serre la récolte pour la vie éternelle, afin que le semeur et le moissonneur se réjouissent ensemble; (aiōnios )
37 Nítorí nínú èyí ni ọ̀rọ̀ náà fi jẹ́ òtítọ́, ‘Ẹnìkan ni ó fúnrúgbìn, ẹlòmíràn ni ó sì ń kórè jọ.’
car c'est bien ici que l’on peut dire: L'un sème, un autre moissonne.
38 Mo rán yín lọ kórè ohun tí ẹ kò ṣiṣẹ́ fún. Àwọn ẹlòmíràn ti ṣiṣẹ́, ẹ̀yin sì kórè èrè làálàá wọn.”
Je vous ai envoyés moissonner là où vous n'avez pas travaillé; d'autres ont travaillé, et vous êtes entrés dans leurs travaux.»
39 Ọ̀pọ̀ àwọn ará Samaria láti ìlú náà wá sì gbà á gbọ́ nítorí ìjẹ́rìí obìnrin náà pé, “Ó sọ gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún mi.”
Plusieurs des Samaritains de cette ville crurent en Jésus, pour avoir entendu cette femme les assurer qu'il lui avait dit tout ce qu'elle avait fait.
40 Nítorí náà, nígbà tí àwọn ará Samaria wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n rọ̀ ọ́ pé, kí ó wà pẹ̀lú wọn, ó sì dúró fún ọjọ́ méjì.
Lors donc que les Samaritains furent venus vers lui, ils le prièrent de demeurer chez eux; et il y demeura deux jours.
41 Àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì gbàgbọ́ sí i nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Un bien plus grand nombre crurent, pour l'avoir entendu lui-même,
42 Wọ́n sì wí fún obìnrin náà pé, “Kì í ṣe nítorí ọ̀rọ̀ rẹ nìkan ni àwa ṣe gbàgbọ́, nítorí tí àwa tìkára wa ti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àwa sì mọ̀ pé, nítòótọ́ èyí ni Kristi náà, Olùgbàlà aráyé.”
et ils disaient à la femme: «Ce n'est plus sur ton rapport que nous croyons, car nous l'avons entendu nous-mêmes, et nous savons que c'est lui qui est vraiment le Sauveur du monde.»
43 Lẹ́yìn ọjọ́ méjì ó sì ti ibẹ̀ kúrò, ó lọ sí Galili.
Après ces deux jours, Jésus partit de là, et s'en alla en Galilée;
44 Nítorí Jesu tìkára rẹ̀ ti jẹ́rìí wí pé, Wòlíì kì í ní ọlá ní ilẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
car il avait déclaré lui-même qu'un prophète n'est point honoré dans sa patrie.
45 Nítorí náà nígbà tí ó dé Galili, àwọn ará Galili gbà á, nítorí ti wọ́n ti rí ohun gbogbo tí ó ṣe ní Jerusalẹmu nígbà àjọ ìrékọjá; nítorí àwọn tìkára wọn lọ sí àjọ pẹ̀lú.
Quand il arriva en Galilée, les Galiléens l'accueillirent, parce qu'ils avaient vu tout ce qu'il avait fait à Jérusalem, lors de la fête; car ils étaient aussi allés à la fête.
46 Bẹ́ẹ̀ ni Jesu tún wá sí Kana ti Galili, níbi tí ó gbé sọ omi di wáìnì. Ọkùnrin ọlọ́lá kan sì wá, ẹni tí ara ọmọ rẹ̀ kò dá ní Kapernaumu.
Il vint donc de nouveau à Cana en Galilée, où il avait changé l'eau en vin. Il y avait à Capernaoum un officier du roi, dont le fils était malade.
47 Nígbà tí ó gbọ́ pé Jesu ti Judea wá sí Galili, ó tọ̀ ọ́ wá, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, kí ó lè sọ̀kalẹ̀ wá kí ó mú ọmọ òun láradá: nítorí tí ó wà ní ojú ikú.
Cet homme, ayant appris que Jésus était revenu de Judée en Galilée, se rendit auprès de lui, et le pria de descendre à Capernaoum, pour guérir son fils qui était mourant.
48 Nígbà náà ni Jesu wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá rí àmì àti iṣẹ́ ìyanu, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́ láé.”
Jésus lui dit: «Si vous ne voyez des miracles et des prodiges, vous ne croyez point.»
49 Ọkùnrin ọlọ́lá náà wí fún un pé, “Olúwa, sọ̀kalẹ̀ wá kí ọmọ mi tó kú.”
L'officier du roi lui dit: «Seigneur, viens avant que mon enfant meure.»
50 Jesu wí fún un pé, “Máa bá ọ̀nà rẹ lọ; ọmọ rẹ yóò yè.” Ọkùnrin náà sì gba ọ̀rọ̀ Jesu gbọ́, ó sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
— «Va, lui dit Jésus, ton fils vit.» Cet homme crut à la parole que Jésus lui avait dite, et partit.
51 Bí ó sì ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pàdé rẹ̀, wọ́n sì wí fún un pé, ọmọ rẹ ti yè.
Il était déjà en route, lorsqu'il rencontra ses serviteurs, qui lui donnèrent cette nouvelle: «Ton enfant vit.»
52 Nígbà náà ni ó béèrè wákàtí tí ara rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í yá lọ́wọ́ wọn, wọ́n sì wí fún un pé, “Ní àná, ní wákàtí keje ni ibà náà fi í sílẹ̀.”
Il s'informa de l'heure à laquelle l'enfant s'était trouvé mieux; et ils lui dirent: «Hier, à la septième heure, la fièvre l'a quitté.»
53 Bẹ́ẹ̀ ni baba náà mọ̀ pé ní wákàtí kan náà ni, nínú èyí tí Jesu wí fún un pé “Ọmọ rẹ̀ yè.” Òun tìkára rẹ̀ sì gbàgbọ́, àti gbogbo ilé rẹ̀.
Le père reconnut que c'était à cette heure-là que Jésus lui avait dit, «ton fils vit, » et il crut, lui et toute sa maison.
54 Èyí ni iṣẹ́ àmì kejì tí Jesu ṣe nígbà tí ó ti Judea jáde wá sí Galili.
Ce fut là un second miracle que Jésus fit encore à son retour de Judée en Galilée.