< John 3 >
1 Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
Bil je pa človek med Farizeji, Nikodem mu je bilo ime, starešina Judovski.
2 Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
Ta pride k Jezusu po noči, in reče mu: Rabi! vémo, da si od Boga prišel učenik; kajti nikdor ne more delati téh znamenj, ktera ti delaš, če ne bo Bog ž njim.
3 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
Jezus odgovorí in mu reče: Resnično resnično ti pravim: Če se kdo na novo ne rodí, ne more videti kraljestva Božjega.
4 Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
Reče mu Nikodem: Kako se more človek roditi, ko je star? Jeli more drugoč vniti v telo matere svoje in se roditi?
5 Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
Jezus odgovorí: Resnično resnično ti pravim: Če se kdo ne rodí iz vode in Duha, ne more vniti v kraljestvo Božje.
6 Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
Kar se je rodilo iz telesa, telo je; in kar se je rodilo iz Duha, duh je.
7 Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
Ne čudi se, da sem ti rekel: Treba vam se je na novo roditi.
8 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
Veter veje, kjer hoče, in glas njegov slišiš, pa ne véš, odkod prihaja in kam gre; tako je vsak, kdor se je rodil iz Duha.
9 Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
Nikodem odgovorí in mu reče: Kako more to biti?
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
Jezus odgovorí in mu reče: Ti si učenik Izraelov, in tega ne véš?
11 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
Resnično resnično ti pravim, da kar vémo, govorimo; in kar smo videli, pričamo: ali pričevanja našega ne sprejemate.
12 Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
Če vam pozemeljske reči pravim, in ne verujete: kako boste verovali, če vam bom pravil nebeške?
13 Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
In nikdor ni stopil na nebo, razen kdor je z neba sešel, sin človečji, ki je na nebu.
14 Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
In kakor je Mojzes povzdignil kačo v puščavi, tako se mora tudi sin človečji povišati:
15 Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios )
Da kdorkoli veruje va-nj, ne pogine, nego da ima večno življenje. (aiōnios )
16 “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
Kajti tako je Bog ljubil svet, da je sina svojega edinorojenega dal, da kdorkoli veruje va-nj, ne pogine, nego da ima večno življenje. (aiōnios )
17 Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
Bog namreč ni poslal sina svojega na svet, da bi svet sodil, nego da se svet zveliča po njem.
18 Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
Kdor veruje va-nj, ne bo sojen; kdor pa ne veruje, sojen je uže, ker ne veruje v ime edinorojenega sina Božjega.
19 Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
Sodba je pa to, da je luč prišla na svet; ali ljudjé so bolj ljubili temo, nego luč: kajti njih dela so bila hudobna.
20 Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
Vsak namreč, kdor dela hudobno, sovraži luč, in ne hodi k luči, da se ne posvaré dela njegova;
21 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
Kdor pa dela resnico, hodi k luči, da se dela njegova razodenejo, ker so v Bogu storjena.
22 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
Po tem pride Jezus in učenci njegovi v Judejsko zemljo. In tu je prebival ž njimi in krščeval.
23 Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
Krščeval je pa tudi Janez v Enonu blizu Salima, ker je bilo tam veliko vode; in dohajali so, in krščeval jih je.
24 (Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
Kajti Janez še ni bil vržen v ječo.
25 Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
Vstane pa vprašanje med učenci Janezovimi in Judi ob očiščevanji.
26 Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
Ter pridejo k Janezu in mu rekó: Rabi! ta, ki je bil s teboj onkraj Jordana, za kogar si ti pričal, glej, krščuje, in vsi gredó k njemu.
27 Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
Janez odgovorí in reče: Človek ne more ničesar vzeti, če mu ne bo dano z neba.
28 Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
Vi sami mi pričate, da sem rekel: Jaz nisem Kristus, nego poslan sem pred njim.
29 Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
Kdor ima nevesto, ženin je; prijatelj pa ženinov, kteri stoji in ga posluša, z radostjo se raduje glasu ženinovemu. Ta torej radost moja se je izpolnila.
30 Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
On mora rasti, a jaz manjšati se.
31 “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
Kdor od zgoraj prihaja, ta je nad vsemi. Kdor je z zemlje, ta je od zemlje, in govorí od zemlje; kdor je prišel z neba, ta je nad vsemi,
32 Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
In kar je videl in slišal, to priča: ali pričevanja njegovega nikdor ne sprejema.
33 Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
Kdor sprejme njegovo pričevanje, potrdil je, da je Bog resničen.
34 Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
Kajti kogar je poslal Bog, besede Božje govorí: Bog namreč ne daje Duha na mero.
35 Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
Oče ljubi sina, in vse mu je dal v roko.
36 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios )
Kdor veruje v sina, ima večno življenje; a kdor ne veruje v sina, ne bo videl življenja, nego jeza Božja prebiva na njem. (aiōnios )