< John 3 >
1 Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
Volt pedig a farizeusok közt egy ember, a neve Nikodémus, a zsidók főembere.
2 Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
Eljött Jézushoz éjjel, és mondta neki: „Mester, tudjuk, hogy Istentől jöttél tanítóul, mert senki sem teheti azokat a jeleket, amelyeket te teszel, hacsak nem az Isten van vele.“
3 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
Jézus így felelt, és mondta neki: „Bizony, bizony mondom néked: ha valaki újonnan nem születik, nem láthatja meg az Isten országát.“
4 Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
Nikodémus ezt mondta neki: „Mi módon születhetik az ember, ha vén? Vajon bemehet-e az anyjának méhébe, és megszülethetik-e ismét?“
5 Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
Jézus így felelt: „Bizony, bizony mondom néked: Ha valaki nem születik víztől és Lélektől, nem mehet be az Isten országába.
6 Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
Ami testtől született, test az, és a mi Lélektől született, lélek az.
7 Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
Ne csodálkozz, hogy azt mondtam neked: Szükséges néktek újonnan születnetek.
8 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
A szél fúj, ahová akar, és annak zúgását hallod, de nem tudod, honnan jön, és hová megy: így van mindenki, aki Lélektől született.“
9 Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
Nikodémus így felelt neki: „Hogyan lehetnek ezek?“
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
Jézus így felelt: „Te Izrael tanítója vagy, és nem tudod ezeket?
11 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
Bizony, bizony mondom néked, amit tudunk, azt mondjuk, és amit látunk, arról teszünk bizonyságot, és a mi bizonyságtételünket nem fogadjátok el.
12 Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
Ha a földiekről szóltam nektek, és nem hisztek, mi módon hisztek, ha a mennyeiekről szólok nektek?
13 Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
Senki sem ment fel a mennybe, csak az, aki a mennyből szállt alá, az Emberfia, aki a mennyben van.
14 Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
Amiképpen felemelte Mózes a kígyót a pusztában, úgy kell az Emberfiának felemeltetnie,
15 Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios )
hogy aki hisz őbenne, el ne vesszen, hanem örök élete legyen. (aiōnios )
16 “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
Mert úgy szerette Isten e világot, hogy az ő egyszülött Fiát adta, hogy aki hisz őbenne, el ne vesszen, hanem örök élete legyen. (aiōnios )
17 Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
Mert nem azért küldte az Isten az ő Fiát a világra, hogy kárhoztassa a világot, hanem hogy megtartsa a világot általa.
18 Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
Aki hisz őbenne, el nem kárhozik, aki pedig nem hisz, immár elkárhozott, mivelhogy nem hitt az Isten egyszülött Fiának nevében.
19 Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
A kárhoztatás pedig az, hogy a világosság e világra jött, és az emberek inkább szerették a sötétséget, mint a világosságot, mert az ő cselekedeteik gonoszak voltak.
20 Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
Mert mindenki, aki hamisan cselekszik, gyűlöli a világosságot, és nem megy a világosságra, hogy az ő cselekedeteit fel ne fedjék.
21 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
Aki pedig az igazságot cselekszi, az a világosságra megy, hogy az ő cselekedetei nyilvánvalókká legyenek, hogy Isten szerint való cselekedetek.“
22 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
Ezután elment Jézus az ő tanítványaival a Júdea földére, ott időzött velük, és keresztelt.
23 Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
János pedig szintén keresztelt Ainonban, Szálimhoz közel, mert ott sok volt a víz. És odajárultak és megkeresztelkedtek,
24 (Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
mert Jánost még nem vetették tömlöcbe.
25 Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
Vetekedés támadt azért János tanítványai és a júdeaiak között a mosakodás miatt.
26 Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
Odamentek Jánoshoz, és ezt mondták neki: „Mester! Aki veled volt a Jordánon túl, akiről te bizonyságot tettél, íme, az keresztel, és hozzá megy mindenki.“
27 Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
János így felelt: „Az ember semmit sem vehet, csak ha a mennyből adatott neki.
28 Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
Ti magatok vagytok a bizonyságaim, hogy megmondtam: Nem én vagyok a Krisztus, hanem őelőtte küldettem el.
29 Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
Akinek jegyese van, vőlegény az, a vőlegény barátja pedig, aki ott áll, és hallja őt, örvendezve örül a vőlegény szavának. Ez az én örömöm immár betelt.
30 Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
Annak növekednie kell, nekem pedig alább szállanom.
31 “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
Aki felülről jött, feljebb való mindenkinél. Aki a földről való, földi az, és földieket szól, aki a mennyből jött, feljebb való mindenkinél.
32 Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
És arról tesz bizonyságot, amit látott és hallott, és az ő bizonyságtételét senki sem fogadja be.
33 Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
Aki az ő bizonyságtételét befogadja, az megpecsételte, hogy az Isten igaz.
34 Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
Mert akit az Isten küldött, az Isten beszédeit szólja, mivelhogy az Isten nem mérték szerint adja a Lelket.
35 Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
Az Atya szereti a Fiút, és az ő kezébe adott mindent.
36 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios )
Aki hisz a Fiúban, örök élete van, aki pedig nem enged a Fiúnak, nem lát életet, hanem az Isten haragja marad rajta.“ (aiōnios )