< John 3 >
1 Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
Na rĩrĩ, kwarĩ na mũndũ wa Afarisai wetagwo Nikodemo, warĩ wa kĩama kĩrĩa gĩathanaga kĩa Ayahudi.
2 Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
Nĩokire kũrĩ Jesũ ũtukũ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Rabii, nĩtũũĩ we ũrĩ mũrutani uumĩte kũrĩ Ngai. Nĩgũkorwo gũtirĩ mũndũ ũngĩhota kũringa ciama iria ũringaga Ngai atarĩ hamwe nake.”
3 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
Nake Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Ngũkwĩra atĩrĩ na ma, gũtirĩ mũndũ ũngĩona ũthamaki wa Ngai atangĩciarwo rĩngĩ.”
4 Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
Nake Nikodemo akĩmũũria atĩrĩ, “Mũndũ angĩciarwo atĩa arĩ mũkũrũ? Ti-itherũ ndangĩhota gũtoonya nda ya nyina hĩndĩ ya keerĩ nĩguo aciarwo!”
5 Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
Jesũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ngũkwĩra atĩrĩ na ma, gũtirĩ mũndũ ũngĩtoonya ũthamaki-inĩ wa Ngai atangĩciarwo na maaĩ na Roho.
6 Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
Mwĩrĩ ũciaraga mwĩrĩ, no Roho aciaraga roho.
7 Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
Ndũkagegio nĩ ũguo ndoiga atĩ, ‘No nginya ũciarwo rĩngĩ.’
8 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
Rũhuho rũhurutanaga na kũrĩa rũngĩenda. Ũiguaga rũkĩhurutana, no ndũmenyaga kũrĩa rumĩte kana kũrĩa rũrorete. Ũguo noguo gũtariĩ harĩ mũndũ ũrĩa wothe ũciarĩtwo nĩ Roho.”
9 Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
Nake Nikodemo akĩmũũria atĩrĩ, “Ũndũ ũcio ũngĩhoteka atĩa?”
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
Nake Jesũ akĩmũũria atĩrĩ, “Wee ũrĩ mũrutani wa Isiraeli na ndũrataũkĩrwo nĩ maũndũ maya?
11 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
Ngũkwĩra atĩrĩ na ma, twaragia ũrĩa tũũĩ, na tũkoimbũra ũrĩa tuonete, no inyuĩ, mũtiĩtĩkagĩra ũira witũ.
12 Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
Ndakwĩra maũndũ ma gũkũ thĩ, waga gwĩtĩkia; ũngĩtĩkia atĩa ingĩkwĩra maũndũ ma na igũrũ?
13 Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
Gũtirĩ mũndũ ũrĩ wathiĩ igũrũ tiga ũrĩa woimire igũrũ, na nĩwe Mũrũ wa Mũndũ.”
14 Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
Na o ta ũrĩa Musa aambararirie nyoka ya gĩcango werũ-inĩ, ũguo no taguo Mũrũ wa Mũndũ akaambarario,
15 Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios )
nĩguo ũrĩa wothe ũmwĩhokete agĩe na muoyo wa tene na tene. (aiōnios )
16 “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
“Nĩgũkorwo Ngai nĩendire kĩrĩndĩ, akĩruta Mũrũ wake wa mũmwe, nĩgeetha mũndũ o wothe ũmwĩtĩkĩtie ndakoore, no agĩe na muoyo wa tene na tene. (aiōnios )
17 Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
Nĩgũkorwo Ngai ndaatũmire Mũrũwe gũkũ thĩ aciirithie kĩrĩndĩ, no nĩguo kĩrĩndĩ kĩhonoke nĩ ũndũ wake.
18 Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
Ũrĩa wothe ũmwĩtĩkĩtie ti wa gũciirithio, no ũrĩa wothe ũtamwĩtĩkĩtie ũcio nĩarĩkĩtie gũtuĩrwo ciira, nĩgũkorwo ndehokete rĩĩtwa rĩa Mũrũ wa Ngai wa mũmwe.
19 Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
Rĩĩrĩ nĩrĩo ituĩro: Ũtheri nĩwokire gũkũ thĩ, no andũ makĩenda nduma gũkĩra ũtheri, nĩ ũndũ ciĩko ciao ciarĩ njũru.
20 Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
Mũndũ o wothe wĩkaga ũũru nĩathũire ũtheri, na ndangiumĩra ũtheri-inĩ nĩ gwĩtigĩra ciĩko ciake itikoimbũke.
21 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
No mũndũ ũrĩa wothe wĩkaga maũndũ ma ma nĩoimagĩra ũtheri-inĩ, nĩguo kuonekane kũna atĩ ũguo ekĩte nĩ Ngai ũmũhotithĩtie.”
22 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
Thuutha wa ũguo, Jesũ na arutwo ake nĩmoimagarire magĩthiĩ bũrũri wa Judea, kũrĩa aikarangire nao, na akabatithanagia.
23 Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
O nake Johana nĩabatithanagĩria Ainoni gũkuhĩ na Salimu, nĩgũkorwo kũu nĩ kwarĩ maaĩ maingĩ, nao andũ nĩmookaga kuo kaingĩ kaingĩ mabatithio.
24 (Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
(Hĩndĩ ĩyo Johana ndaakoretwo aikĩtio njeera.)
25 Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
Nĩ kwagĩire na ngarari gatagatĩ-inĩ ka arutwo amwe a Johana na Mũyahudi ũmwe ũhoro-inĩ wa mĩtugo yao ya gwĩtheria.
26 Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
Magĩũka kũrĩ Johana makĩmwĩra atĩrĩ, “Rabii, mũndũ ũrĩa mũraarĩ nake mũrĩmo ũrĩa ũngĩ wa Jorodani, ũrĩa wee warutire ũira ũmũkoniĩ-rĩ, nĩarabatithania, nao andũ othe nĩmarathiĩ kũrĩ we.”
27 Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
Ũhoro-inĩ ũcio Johana agĩcookia atĩrĩ, “Mũndũ ndarĩ ũndũ angĩamũkĩra o tiga ũrĩa aheetwo kuuma igũrũ.
28 Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
Inyuĩ ene no mũheane ũira muuge atĩ nĩndoigire atĩrĩ, ‘Niĩ ti niĩ Kristũ, no ndũmĩtwo njũke mbere yake.’
29 Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
Mũhiki nĩ wa mũhikania. No rĩrĩ, mũrata wa mũhikania ũrĩa ũmũrũgamĩrĩire nĩamũthikagĩrĩria, na akaiyũrwo nĩ gĩkeno rĩrĩa aigua mũgambo wa mũhikania. Gĩkeno ta kĩu nĩkĩo ndĩ na kĩo, na rĩu nĩgĩkinyanĩru.
30 Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
We no nginya akĩrĩrĩrie kũneneha, na niĩ ngĩrĩrĩrie kũnyiiha.
31 “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
“Ũrĩa uumĩte igũrũ nĩ mũnene kũrĩ andũ othe; nake ũrĩa uumĩte thĩ nĩ wa gũkũ thĩ, na maũndũ marĩa aragia no ma gũkũ thĩ. Ũrĩa uumĩte igũrũ arĩ igũrũ rĩa andũ arĩa angĩ othe.
32 Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
We oimbũraga maũndũ marĩa onete na akaigua no gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wĩtĩkagĩra ũira wake.
33 Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
Mũndũ ũrĩa wĩtĩkĩrĩte ũira ũcio nĩahũũrĩte mũhũũri atĩ Ngai nĩ wa ma.
34 Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
Nĩgũkorwo ũrĩa Ngai atũmĩte aragia ciugo cia Ngai nĩ ũndũ Ngai aheanaga Roho hatarĩ gĩthimi.
35 Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
Ithe nĩendete Mũriũ na nĩ aigĩte indo ciothe moko-inĩ make.
36 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios )
Ũrĩa wothe wĩtĩkĩtie Mũriũ, arĩ na muoyo wa tene na tene, no ũrĩa wothe ũregete Mũriũ ndakona muoyo, nĩgũkorwo egũtũũra arakarĩirwo nĩ Ngai.” (aiōnios )