< John 3 >

1 Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
ⲁ̅ⲛⲉⲩⲛ̅ⲟⲩⲣⲱⲙⲉ ⲇⲉ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲛⲉⲫⲁⲣⲓⲥⲁⲓⲟⲥ ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲛⲓⲕⲟⲇⲏⲙⲟⲥ ⲉⲩⲁⲣⲭⲱⲛ ⲛ̅ⲓ̈ⲟⲩⲇⲁⲓ̈ ⲡⲉ.
2 Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
ⲃ̅ⲡⲁⲓ̈ ⲁϥⲉ͡ⲓ ϣⲁⲣⲟϥ ⲛ̅ⲧⲉⲩϣⲏ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ. ϫⲉ ⲣⲁⲃⲃⲉⲓ. ⲧⲛ̅ⲥⲟⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲕ̅ⲟⲩⲥⲁϩ ⲉⲁⲕⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ. ⲙ̅ⲙⲛϣϭⲟⲙ ⲅⲁⲣ ⲗ̅ⲗⲁⲁⲩ ⲉⲣⲛⲉⲓ̈ⲙⲁⲓ̈ⲛ. ⲉⲧⲕⲉ͡ⲓⲣⲉ ⲛ̅ⲧⲟⲕ ⲙ̅ⲙⲟⲟⲩ. ⲉ͡ⲓⲙⲏⲧⲓ ⲉⲣⲉⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ϣⲟⲟⲡ ⲛⲙ̅ⲙⲁϥ.
3 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
ⲅ̅ⲁⲓ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲱϣⲃ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ϩⲁⲙⲏⲛ ϩⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⲉⲩⲧⲙ̅ϫⲡⲉⲟⲩⲁ ⲛ̅ⲕⲉⲥⲟⲡ. ⲙ̅ⲙⲛ̅ϭⲟⲙ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲉⲛⲁⲩ ⲉⲧⲙⲛ̅ⲧⲉⲣⲟ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ.
4 Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
ⲇ̅ⲡⲉϫⲉⲛⲓⲕⲟⲇⲏⲙⲟⲥ ⲛⲁϥ. ϫⲉ ⲛ̅ⲁϣ ⲛ̅ϩⲉ ⲥⲉⲛⲁϫⲡⲉⲡⲣⲱⲙⲉ ⲛ̅ⲕⲉⲥⲟⲡ ⲉⲁϥⲣ̅ϩⲗⲗⲟ. ⲙⲏ ⲟⲩⲛϣϭⲟⲙ ⲉⲧⲣⲉϥⲃⲱⲕ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲉϩⲏⲧⲥ ⲛ̅ⲧⲉϥⲙⲁⲁⲩ ⲛ̅ⲕⲉⲥⲟⲡ ⲛ̅ⲥⲉϫⲡⲟϥ.
5 Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
ⲉ̅ⲁϥⲟⲩⲱϣⲃ̅ ⲛ̅ϭⲓⲓ̅ⲥ̅. ϫⲉ ϩⲁⲙⲏⲛ ϩⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⲉⲩⲧⲙ̅ϫⲡⲉⲟⲩⲁ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲟⲩⲙⲟⲟⲩ ⲛⲙ̅ⲟⲩⲡⲛ̅ⲁ. ⲙⲛ̅ϭⲟⲙ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲉⲉ͡ⲓ ⲉϩⲟⲩⲛ ⲉⲧⲙⲛ̅ⲧⲉⲣⲟ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ.
6 Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
ⲋ̅ⲡⲉⲛⲧⲁⲩϫⲡⲟϥ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲥⲁⲣⲝ̅. ⲟⲩⲥⲁⲣⲝ̅ ⲡⲉ. ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲛⲧⲁⲩϫⲡⲟϥ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲉⲡⲛ̅ⲁ. ⲟⲩⲡⲛ̅ⲁ ⲡⲉ.
7 Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
ⲍ̅ⲙ̅ⲡⲣ̅ⲣϣⲡⲏⲣⲉ ϫⲉ ⲁⲉ͡ⲓϫⲟⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ϩⲁⲡⲥ̅ ⲉⲧⲣⲉⲩϫⲡⲉⲧⲏⲩⲧⲛ̅ ⲛ̅ⲕⲉⲥⲟⲡ.
8 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
ⲏ̅ⲡⲉⲡⲛ̅ⲁ ⲛⲓϥⲉ ⲉⲡⲙⲁ ⲉⲧϥ̅ⲟⲩⲁϣϥ̅ ⲁⲩⲱ ⲕⲥⲱⲧⲙ̅ ⲉⲧⲉϥⲥⲙⲏ. ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲅ̅ⲥⲟⲟⲩⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲁϥⲉ͡ⲓ ⲧⲱⲛ ⲏ ⲉϥⲛⲁ ⲉⲧⲱⲛ. ⲧⲁⲓ̈ ⲧⲉ ⲑⲉ ⲛ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ⲉⲛⲧⲁⲩϫⲡⲟϥ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲉⲡⲛ̅ⲁ.
9 Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
ⲑ̅ⲁⲛⲓⲕⲟⲇⲏⲙⲟⲥ ⲟⲩⲱϣⲃ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ. ϫⲉ ⲛ̅ⲁϣ ⲛ̅ϩⲉ ⲉⲣⲉϣⲛⲁⲓ̈ ⲛⲁϣⲱⲡⲉ.
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
ⲓ̅ⲁⲓ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲱϣⲃ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ. ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲟⲕ ⲡⲉ ⲡⲥⲁϩ ⲙ̅ⲡⲓⲥⲣⲁⲏⲗ. ⲁⲩⲱ ⲛⲅ̅ⲥⲟⲟⲩⲛ ⲁⲛ ⲛ̅ⲛⲁⲓ̈.
11 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
ⲓ̅ⲁ̅ϩⲁⲙⲏⲛ ϩⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⲡⲉⲧⲛ̅ⲥⲟⲟⲩⲛ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲡⲉⲧⲛ̅ϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲧⲛ̅ⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉⲧⲛ̅ⲣ̅ⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲁⲩⲱ ⲛ̅ⲧⲉⲧⲛ̅ϫⲓ ⲁⲛ ⲛ̅ⲧⲉⲛⲙⲛ̅ⲧⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ.
12 Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
ⲓ̅ⲃ̅ⲉϣϫⲉⲁⲉ͡ⲓϫⲱ ⲛⲏⲧⲛ̅ ⲛ̅ⲛⲁⲡⲕⲁϩ ⲁⲩⲱ ⲛ̅ⲧⲉⲧⲛ̅ⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲁⲛ. ⲛ̅ⲁϣ ⲛ̅ϩⲉ ⲉⲓ̈ϣⲁⲛϫⲱ ⲉⲣⲱⲧⲛ̅ ⲛ̅ⲛⲁⲧⲡⲉ ⲧⲉⲧⲛⲁⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ.
13 Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
ⲓ̅ⲅ̅ⲁⲩⲱ ⲙ̅ⲡⲉⲗⲁⲁⲩ ⲃⲱⲕ ⲉϩⲣⲁⲓ̈ ⲉⲧⲡⲉ ⲉ͡ⲓⲙⲏⲧⲓ ⲡⲉⲛⲧⲁϥⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲡⲉ ⲡϣⲏⲣⲉ ⲙ̅ⲡⲣⲱⲙⲉ.
14 Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲇ̅ⲁⲩⲱ ⲕⲁⲧⲁⲑⲉ ⲉⲛⲧⲁⲙⲱⲩ̈ⲥⲏⲥ ϫⲓⲥⲉ ⲙ̅ⲡϩⲟϥ ϩⲛ̅ⲧⲉⲣⲏⲙⲟⲥ. ⲧⲁⲓ̈ ⲧⲉ ⲑⲉ ϩⲁⲡⲥ̅ ⲉⲧⲣⲉⲩϫⲉⲥⲧⲡϣⲏⲣⲉ ⲙ̅ⲡⲣⲱⲙⲉ
15 Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios g166)
ⲓ̅ⲉ̅ϫⲉⲕⲁⲁⲥ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲉⲣⲟϥ ⲉϥⲉⲕⲱ ⲛⲁϥ ϩⲣⲁⲓ̈ ⲛ̅ϩⲏⲧϥ̅ ⲛ̅ⲟⲩⲱⲛϩ ϣⲁⲉⲛⲉϩ. (aiōnios g166)
16 “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
ⲓ̅ⲋ̅ⲧⲁⲓ̈ ⲅⲁⲣ ⲧⲉ ⲑⲉ ⲉⲛⲧⲁⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲙⲉⲣⲉⲡⲕⲟⲥⲙⲟⲥ. ϩⲱⲥⲧⲉ ⲡⲉϥϣⲏⲣⲉ ⲛ̅ⲟⲩⲱⲧ ⲁϥⲧⲁⲁϥ ϫⲉⲕⲁⲥ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲉⲣⲟϥ ⲛ̅ⲛⲉϥϩⲉ ⲉⲃⲟⲗ ⲁⲗⲗⲁ ⲉϥⲉϫⲓ ⲛ̅ⲟⲩⲱⲛϩ ϣⲁⲉⲛⲉϩ. (aiōnios g166)
17 Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
ⲓ̅ⲍ̅ⲛ̅ⲧⲁⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲅⲁⲣ ⲧⲛ̅ⲛⲉⲩⲡⲉϥϣⲏⲣⲉ ⲁⲛ ⲉⲡⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲉϥⲉⲕⲣⲓⲛⲉ ⲙ̅ⲡⲕⲟⲥⲙⲟⲥ. ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉⲕⲁⲥ ⲉⲣⲉⲡⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲟⲩϫⲁⲓ̈ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲟⲧϥ̅.
18 Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
ⲓ̅ⲏ̅ⲡⲉⲧⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲉⲣⲟϥ ⲛ̅ⲥⲉⲛⲁⲕⲣⲓⲛⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲁⲛ. ⲡⲉⲧⲉⲛϥ̅ⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲇⲉ ⲁⲛ ⲏⲇⲏ ⲁⲩⲕⲣⲓⲛⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ϫⲉ ⲙ̅ⲡϥ̅ⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲉⲡⲣⲁⲛ ⲙ̅ⲡϣⲏⲣⲉ ⲛ̅ⲟⲩⲱⲧ ⲛ̅ⲧⲉⲡⲛⲟⲩⲧⲉ.
19 Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
ⲓ̅ⲑ̅ⲧⲁⲓ̈ ⲇⲉ ⲧⲉ ⲧⲉⲕⲣⲓⲥⲓⲥ ϫⲉ ⲁⲡⲟⲩⲟⲓ̈ⲛ ⲉ͡ⲓ ⲉⲡⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲁⲩⲱ ⲁⲛⲣⲱⲙⲉ ⲙⲉⲣⲉⲡⲕⲁⲕⲉ ⲉϩⲟⲩⲉⲡⲟⲩⲟⲓ̈ⲛ. ⲛⲉⲣⲉⲛⲉⲩϩⲃⲏⲩⲉ ⲅⲁⲣ ϩⲟⲟⲩ ⲡⲉ.
20 Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
ⲕ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲅⲁⲣ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲓⲣⲉ ⲛ̅ⲙ̅ⲡⲉⲑⲟⲟⲩ ϥⲙⲟⲥⲧⲉ ⲙ̅ⲡⲟⲩⲟⲓ̈ⲛ ϫⲉⲕⲁⲥ ⲉⲛⲛⲉⲩϫⲡⲓⲉⲛⲉϥϩⲃⲏⲩⲉ ϫⲉ ⲥⲉϩⲟⲟⲩ.
21 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲡⲉⲧⲓⲣⲉ ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲛ̅ⲧⲙⲉ ϣⲁϥⲉ͡ⲓ ϣⲁⲡⲟⲩⲟⲓ̈ⲛ ϫⲉⲕⲁⲥ ⲉⲣⲉⲛⲉϥϩⲃⲏⲩⲉ ⲟⲩⲱⲛϩ ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲁϥⲁⲁⲩ ϩⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ·
22 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
ⲕ̅ⲃ̅ⲙⲛ̅ⲛ̅ⲥⲁⲛⲁⲓ̈ ⲁϥⲉ͡ⲓ ⲛ̅ϭⲓⲓ̅ⲥ̅ ⲛⲙ̅ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲉⲡⲕⲁϩ ⲛ̅ϯⲟⲩⲇⲁⲓⲁ ⲁⲩⲱ ⲛⲉϥⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲡⲉ ⲛⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲉϥⲃⲁⲡⲧⲓⲍⲉ.
23 Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
ⲕ̅ⲅ̅ⲛⲉⲣⲉⲡⲕⲉⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲇⲉ ⲃⲁⲡⲧⲓⲍⲉ ϩⲛ̅ⲁⲓⲛⲱⲛ ϩⲁⲧⲛ̅ⲥⲁⲗⲉⲓⲙ ϫⲉ ⲛⲉⲩ(ⲛ)ϩⲁϩ ⲙ̅ⲙⲟⲟⲩ ϩⲙ̅ⲡⲙⲁ ⲉⲧⲙ̅ⲙⲁⲩ. ⲁⲩⲱ ⲛⲉⲩⲛⲏⲩ ⲡⲉ ⲉⲩϫⲓⲃⲁⲡⲧⲓⲥⲙⲁ
24 (Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
ⲕ̅ⲇ̅ⲛⲉⲙ̅ⲡⲁⲧⲟⲩⲛⲉϫⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⲉⲡⲉϣⲧⲉⲕⲟ.
25 Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
ⲕ̅ⲉ̅ⲁⲩⲍⲏⲧⲏⲥⲓⲥ ϭⲉ ϣⲱⲡⲉ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲙ̅ⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛ̅ⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲛⲙ̅ⲟⲩⲓ̈ⲟⲩⲇⲁⲓ̈ ⲉⲧⲃⲉⲡⲧⲃ̅ⲃⲟ
26 Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
ⲕ̅ⲋ̅ⲁⲩⲉ͡ⲓ ϣⲁⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲡⲉϫⲁⲩ ⲛⲁϥ. ϫⲉ ϩⲣⲁⲃⲃⲉⲓ. ⲡⲏ ⲉⲧⲉⲛⲉϥϣⲟⲟⲡ ⲛⲙ̅ⲙⲁⲕ ϩⲓⲡⲓⲕⲣⲟ ⲙ̅ⲡⲓⲟⲣⲇⲁⲛⲏⲥ. ⲡⲁⲓ̈ ⲛ̅ⲧⲟⲕ ⲉⲛⲧⲁⲕⲣ̅ⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ ϩⲁⲣⲟϥ. ⲉⲓⲥϩⲏⲏⲡⲉ ⲛ̅ⲧⲟϥ ϥⲃⲁⲡⲧⲓⲍⲉ ⲁⲩⲱ ϥⲣ̅ϩⲁϩ ⲙ̅ⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲁⲩⲱ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ⲛⲏⲩ ⲉⲣⲁⲧϥ̅.
27 Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
ⲕ̅ⲍ̅ⲁⲓ̈ⲱϩⲁⲛⲛⲏⲥ ⲟⲩⲱϣⲃ̅ ⲉϥϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ. ϫⲉ ⲙⲛϣϭⲟⲙ ⲙ̅ⲡⲣⲱⲙⲉ ⲉϫⲓⲗⲁⲁⲩ ϩⲁⲣⲟϥ ⲟⲩⲁⲁϥ ⲉ͡ⲓⲙⲏⲧⲓ ⲛ̅ⲥⲉⲧⲁⲁⲥ ⲛⲁϥ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲡⲉ.
28 Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
ⲕ̅ⲏ̅ⲛ̅ⲧⲱⲧⲛ̅ ⲧⲉⲧⲛ̅ⲣ̅ⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ ⲛⲁⲓ ϫⲉ ⲁⲉ͡ⲓϫⲟⲟⲥ ϫⲉ ⲛ̅ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲡⲉⲭ̅ⲥ̅ ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉ ⲛ̅ⲧⲁⲩⲧⲁⲟ(ⲩⲟ)ⲉ͡ⲓ ϩⲁⲑⲏ ⲙ̅ⲡⲉⲧⲙ̅ⲙⲁⲩ.
29 Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
ⲕ̅ⲑ̅ⲡⲉⲧⲉⲩⲛ̅ⲧⲁϥ (ⲙ̅ⲙⲁⲩ) ⲛ̅ⲧϣⲉⲗⲉⲉⲧ. ⲛ̅ⲧⲟϥ ⲡⲉ ⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲉⲧ. ⲡⲉϣⲃⲏⲣ ⲇⲉ ⲙ̅ⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲉⲧ ⲉⲧⲁϩⲉⲣⲁⲧϥ̅ ⲁⲩⲱ ⲉⲧⲥⲱⲧⲙ̅ ⲉⲣⲟϥ. ϩⲛ̅ⲟⲩⲣⲁϣⲉ ϥⲣⲁϣⲉ ⲉⲧⲃⲉⲧⲉⲥⲙⲏ ⲙ̅ⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲉⲧ. ⲡⲁⲣⲁϣⲉ ϭⲉ ⲉⲧⲉⲡⲁⲓ̈ ⲡⲉ ⲁϥϫⲱⲕ ⲉⲃⲟⲗ
30 Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
ⲗ̅ϩⲁⲡⲥ ⲉⲧⲣⲉⲡⲉⲧⲙ̅ⲙⲁⲩ ϫⲓⲥⲉ. ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⲉⲧⲣⲁⲑⲃ̅ⲃⲓⲟ.
31 “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
ⲗ̅ⲁ̅ⲡⲉⲛⲧⲁϥⲉ͡ⲓ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲡⲉ ϥϩⲓϫⲛ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ. ⲡⲉⲧϣⲟⲟⲡ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲕⲁϩ ⲟⲩⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲕⲁϩ ⲡⲉ ⲁⲩⲱ ⲉϥϣⲁϫⲉ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲙ̅ⲡⲕⲁϩ. ⲡⲉⲛⲧⲁϥⲉ͡ⲓ ⲇⲉ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲧⲡⲉ.
32 Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
ⲗ̅ⲃ̅ⲡⲉⲛⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟϥ ⲁⲩⲱ ⲁϥⲥⲟⲧⲙⲉϥ ϥⲣ̅ⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲁⲩⲱ ⲙ̅ⲙⲛ̅ⲗⲁⲁⲩ ϫⲓ ⲛ̅ⲧⲉϥⲙⲛ̅ⲧⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ.
33 Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
ⲗ̅ⲅ̅ⲡⲉⲛⲧⲁϥϫⲓ ⲇⲉ ⲛ̅ⲧⲉϥⲙⲛ̅ⲧⲙⲛ̅ⲧⲣⲉ ⲁϥⲥⲫⲣⲁⲅⲓⲍⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ϫⲉ ⲟⲩⲙⲉ ⲡⲉ ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ.
34 Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
ⲗ̅ⲇ̅ⲡⲉⲛⲧⲁⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲅⲁⲣ ⲧⲛ̅ⲛⲟⲟⲩϥ ⲉϥϫⲱ ⲛ̅ⲛ̅ϣⲁϫⲉ ϫⲉ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲛⲉⲣⲉⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲅⲁⲣ ϯ ⲁⲛ ⲙ̅ⲡⲉⲡⲛ̅ⲁ ϩⲛ̅ⲟⲩϣⲓ.
35 Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
ⲗ̅ⲉ̅ⲡⲓⲱⲧ ⲙⲉ ⲙ̅ⲡϣⲏⲣⲉ ⲁⲩⲱ ⲁϥϯⲛ̅ⲕⲁ ⲛⲓⲙ ⲉϩⲣⲁⲓ̈ ⲉⲧⲉϥϭⲓϫ.
36 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios g166)
ⲗ̅ⲋ̅ⲡⲉⲧⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲉⲡϣⲏⲣⲉ ⲟⲩⲛ̅ⲧⲁϥ ⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲙ̅ⲡⲱⲛϩ ϣⲁⲉⲛⲉϩ. ⲡⲉⲧⲉⲛ̅ϥⲡⲓⲥⲧⲉⲩⲉ ⲇⲉ ⲁⲛ ⲉⲡϣⲏⲣⲉ. ⲛ̅ϥⲛⲁⲛⲁⲩ ⲁⲛ ⲉⲡⲱⲛϩ̅. ⲁⲗⲗⲁ ⲧⲟⲣⲅⲏ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲛⲁϭⲱ ⲉϩⲣⲁⲓ̈ ⲉϫⲱϥ. (aiōnios g166)

< John 3 >