< John 3 >
1 Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
ⲁ̅ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲫⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲛⲓⲕⲟⲇⲏⲙⲟⲥ ⲟⲩⲁⲣ ⲭⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ.
2 Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
ⲃ̅ⲫⲁⲓ ⲁϥ⳿ⲓ ϩⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲣⲁⲃⲃⲓ ⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲉⲧⲁⲕ⳿Ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲫϯ ⳿ⲛⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲉⲣ ⲛⲁⲓⲙⲏⲓⲛⲓ ⲉⲧⲉⲕ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲁⲣⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⲫϯ ϣⲱⲡⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ.
3 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
ⲅ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲁⲙⲏⲛ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⲁⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲙⲉⲥ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲕⲉⲥⲟⲡ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
4 Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
ⲇ̅ⲡⲉϫⲉ ⲛⲓⲕⲟⲇⲏⲙⲟⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲙⲉⲥ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲕⲉⲥⲟⲡ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⳿ⲑⲣⲉϥⲉⲣϧⲉⲗⲗⲟ ⲙⲏ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⲉⲑⲣⲉϥϣⲉ ⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ⲑⲛⲉϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲙⲁϩ ⲥⲟⲡ ⲃ̅ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲙⲁⲥϥ.
5 Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
ⲉ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⲁⲙⲏⲛ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⲁⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲙⲉⲥ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯ ⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
6 Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
ⲋ̅ⲡⲓⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ ⲟⲩⲥⲁⲣⲝ ⲡⲉ ⲡⲓⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲡⲉ.
7 Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
ⲍ̅⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ϫⲉ ⲁⲓϫⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ϩⲱϯ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲙⲉⲥ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲕⲉⲥⲟⲡ.
8 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
ⲏ̅ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ϥⲛⲓϥⲓ ⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲁ ⲉⲧⲉϩⲛⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲕⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲧⲉϥ⳿ⲥⲙⲏ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲕ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲁϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲑⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲛⲁ ⳿ⲉⲑⲱⲛ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲟⲩⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅.
9 Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
ⲑ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲕⲟⲇⲏⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲁⲓ ϣⲱⲡⲓ.
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
ⲓ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲡⲉ ⳿ⲡⲥⲁϧ ⳿ⲙ⳿ⲡⲓⲥ̅ⲗ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲓ ⳿ⲕ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲁⲛ.
11 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
ⲓ̅ⲁ̅ⲁⲙⲏⲛ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁⲕ ϫⲉ ⲫⲏⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲧⲉⲛⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲧⲉⲛⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲛⲙⲉⲧⲙⲉⲑⲣⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛϭⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ.
12 Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
ⲓ̅ⲃ̅ⲓⲥϫⲉ ⲁⲓϫⲉ ⲛⲁ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⲡⲱⲥ ⲁⲓϣⲁⲛϫⲉ ⲛⲁ ⳿ⲧⲫⲉ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ.
13 Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉ ⳿ϩⲗⲓ ϣⲉ ⲛⲁϥ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⲉⲫⲏⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⲉⲧⲉ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ ⲡⲉ ⲫⲏⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ.
14 Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁ ⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ϭⲉⲥ ⲡⲓϩⲟϥ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϩⲓ ⳿ⲡϣⲁϥⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϩⲱϯ ⲡⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲩϭⲉⲥ ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ.
15 Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios )
ⲓ̅ⲉ̅ϩⲓⲛⲁ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛⲧⲉϥϭⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿ⲉⲛⲉϩ. (aiōnios )
16 “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
ⲓ̅ⲋ̅ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲅⲁⲣ ⲁ ⲫϯ ⲙⲉⲛⲣⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ϩⲱⲥⲧⲉ ⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲏⲓϥ ϩⲓⲛⲁ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲧⲁⲕⲟ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϭⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿ⲉⲛⲉϩ. (aiōnios )
17 Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
ⲓ̅ⲍ̅ⲛⲉⲧⲁ ⲫϯ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲙⲡⲉϥϣⲏ ⲣⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲛⲟϩⲉⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ.
18 Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
ⲓ̅ⲏ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲥⲉⲛⲁϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲉ⳿ⲛ⳿ϥⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲛ ϩⲏⲇⲏ ⲁⲩⲟⲩⲱ ⲉⲩϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲉϥⲛⲁϩϯ ⳿ⲉ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲙⲟⲛⲟⲅⲉⲛⲏⲥ ⳿ⲛϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
19 Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
ⲓ̅ⲑ̅ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⲡⲓϩⲁⲡ ϫⲉ ⲡⲓⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲁϥ⳿Ⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲩⲙⲉⲛⲣⲉ ⲡⲓⲭⲁⲕⲓ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲉϩⲟⲧⲉ ⲡⲓⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲛⲟⲩϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲅⲁⲣ ⲛⲁⲩϩⲱⲟⲩ ⲡⲉ.
20 Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
ⲕ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲅⲁⲣ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⳿ϥⲙⲟⲥϯ ⳿ⲙⲡⲓⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲁϥ⳿ⲓ ϩⲁ ⲡⲓⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲥⲟϩⲓ ⳿ⲛⲛⲉϥ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿Ⲓ ϫⲉ ⲥⲉϩⲱⲟⲩ.
21 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ϣⲁϥ⳿ⲓ ϩⲁ ⲡⲓⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ϫⲉ ⲉⲧⲁϥⲁⲓⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲫϯ.
22 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
ⲕ̅ⲃ̅ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲉ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲓⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲭⲏ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲡⲉ ⲉϥϯⲱⲙⲥ.
23 Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
ⲕ̅ⲅ̅ⲛⲁⲣⲉ ⳿ⲡⲕⲉⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲇⲉ ϯⲱⲙⲥ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⳿ⲉⲛⲱⲛ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲥⲁⲗⲓⲙ ϫⲉ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲛⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϭⲓⲱⲙⲥ ⲡⲉ.
24 (Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
ⲕ̅ⲇ̅ⲛⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲟⲩϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⳿ⲉ⳿ⲡ⳿ϣⲧⲉⲕⲟ ⲡⲉ.
25 Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
ⲕ̅ⲉ̅ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲍⲏⲧⲏⲥⲓⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩⲧⲟⲩⲃⲟ.
26 Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁ ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲣⲁⲃⲃⲓ ⲫⲏⲉⲧⲭⲏ ⲛⲉⲙⲁⲕ ϩⲓⲙⲏⲣ ⳿ⲙⲡⲓⲓⲟⲣⲇⲁⲛⲏⲥ ⲫⲏ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲉⲧⲉⲕⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ϧⲁⲣⲟϥ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲫⲁⲓ ⳿ϥϯⲱⲙⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲛⲏⲟⲩ ϩⲁⲣⲟϥ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
27 Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
ⲕ̅ⲍ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ϭⲓ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ ⲁⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲧⲏ ⲓⲥ ⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ.
28 Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
ⲕ̅ⲏ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲏⲓ ϫⲉ ⲁⲓϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲛ ⲡⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉ ⲉⲧⲁⲩⲧⲁⲟⲩⲟⲓ ϧⲁϫⲱϥ ⳿ⲙⲫⲏ.
29 Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
ⲕ̅ⲑ̅ⲫⲏⲉⲧⲉ ϯϣⲉⲗⲉⲧ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲉ ⲡⲓⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲧ ⳿ⲡ⳿ϣⲫⲏⲣ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲧ ⲡⲉⲧ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲣⲁϣⲓ ⳿ϥⲣⲁϣⲓ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲧ⳿ⲥⲙⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲧ ⲫⲁⲓ ⲟⲩⲛ ⲡⲉ ⲡⲁⲣⲁϣⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁϥϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
30 Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
ⲗ̅ϩⲱϯ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫⲏ ⲁⲓⲁⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⲛⲧⲁⲑⲉⲃⲓ⳿ⲟ.
31 “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
ⲗ̅ⲁ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ϥⲥⲁ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲟⲩ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁϥⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲫⲏⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲫⲉ ⳿ϥⲥⲁ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
32 Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
ⲗ̅ⲃ̅ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥⲥⲟⲑⲙⲉϥ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲉϥⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉϥⲙⲉⲧⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ϭⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲥ.
33 Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
ⲗ̅ⲅ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϭⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥⲙⲉⲧⲙⲉⲑⲣⲉ ⲫⲁⲓ ⲁϥⲉⲣ⳿ⲥⲫⲣⲁⲅⲓⲍⲓⲛ ϫⲉ ⲫϯ ⲟⲩ⳿ⲑⲙⲏⲓ ⲡⲉ.
34 Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
ⲗ̅ⲇ̅ⲫⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲁ ⲫϯ ⲟⲩⲟⲣⲡϥ ⲛⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲉⲧⲉϥⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲛⲁⲣⲉ ⲫϯ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ϯ ⳿ⲙⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ϧⲉⲛ ⲟⲩϣⲓ.
35 Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
ⲗ̅ⲉ̅⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲙⲉⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁϥⲧⲏⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲛⲉϥϫⲓϫ.
36 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios )
ⲗ̅ⲋ̅ⲫⲏⲉⲑⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲡⲓϣⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉϥ ⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿ⲉⲛⲉϩ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧⲑⲱⲧ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ⲉⲡⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲛⲉϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡⲱⲛϧ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲡ⳿ϫⲱⲛⲧ ⳿ⲙⲫϯ ⲉϥ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ϩⲓϫⲱϥ (aiōnios )