< John 20 >

1 Ní kùtùkùtù ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, nígbà tí ilẹ̀ kò tí ì mọ́, ni Maria Magdalene wá sí ibojì, ó sì rí i pé, a ti gbé òkúta kúrò lẹ́nu ibojì.
În prima zi a săptămânii, Maria Magdalena s-a dus dis-de-dimineață la mormânt, pe când era încă întuneric, și a văzut că piatra fusese scoasă de pe mormânt.
2 Nítorí náà, ó sáré, ó sì tọ Simoni Peteru àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn wá, ẹni tí Jesu fẹ́ràn, ó sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gbé Olúwa kúrò nínú ibojì, àwa kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”
De aceea a alergat și a venit la Simon Petru și la celălalt ucenic pe care-l iubea Isus și le-a zis: “L-au luat pe Domnul din mormânt și nu știm unde L-au pus!”
3 Nígbà náà ni Peteru àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà jáde, wọ́n sì wá sí ibojì.
Atunci Petru și celălalt ucenic au ieșit și s-au dus la mormânt.
4 Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ sáré: èyí ọmọ-ẹ̀yìn náà sì sáré ya Peteru, ó sì kọ́kọ́ dé ibojì.
Și amândoi alergau împreună. Celălalt ucenic l-a întrecut pe Petru și a ajuns primul la mormânt.
5 Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti wo inú rẹ̀, ó rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀; ṣùgbọ́n òun kò wọ inú rẹ̀.
S-a aplecat și a privit înăuntru, a văzut pânzele de in așezate acolo, dar n-a intrat.
6 Nígbà náà ni Simoni Peteru tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ dé, ó sì wọ inú ibojì, ó sì rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀.
Atunci Simon Petru a venit după el și a intrat în mormânt. A văzut așezate pânzele de in,
7 Àti pé, gèlè tí ó wà níbi orí rẹ̀ kò sì wà pẹ̀lú aṣọ ọ̀gbọ̀ náà, ṣùgbọ́n ó ká jọ ní ibìkan fúnra rẹ̀.
iar pânza care fusese pe capul Lui, nu era așezată împreună cu pânzele de in, ci înfășurată într-un loc de sine stătător.
8 Nígbà náà ni ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà, ẹni tí ó kọ́ dé ibojì wọ inú rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì rí i, ó sì gbàgbọ́.
Atunci a intrat și celălalt ucenic care venise primul la mormânt; a văzut și el și a crezut.
9 (Nítorí tí wọn kò sá à tí mọ ìwé mímọ́ pé, Jesu ní láti jíǹde kúrò nínú òkú).
Căci încă nu cunoșteau Scriptura, că trebuie să învieze din morți.
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sì tún padà lọ sí ilé wọn.
Ucenicii s-au dus din nou la casele lor.
11 Ṣùgbọ́n Maria dúró létí ibojì lóde, ó ń sọkún: bí ó ti ń sọkún, bẹ́ẹ̀ ni ó bẹ̀rẹ̀, ó sì wo inú ibojì.
Dar Maria stătea afară la mormânt și plângea. Și, în timp ce plângea, s-a aplecat și s-a uitat în mormânt,
12 Ó sì kíyèsi àwọn angẹli méjì aláṣọ funfun, wọ́n jókòó, ọ̀kan níhà orí àti ọ̀kan níhà ẹsẹ̀, níbi tí òkú Jesu gbé ti sùn sí.
și a văzut doi îngeri în alb care stăteau, unul la cap și altul la picioare, unde fusese așezat trupul lui Isus.
13 Wọ́n sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún?” Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí tí wọ́n ti gbé Olúwa mi, èmi kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”
Ei au întrebat-o: “Femeie, de ce plângi?”. Ea le-a spus: “Pentru că l-au luat pe Domnul meu și nu știu unde l-au pus”.
14 Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó yípadà, ó sì rí Jesu dúró, kò sì mọ̀ pé Jesu ni.
După ce a spus aceasta, s-a întors și a văzut pe Isus în picioare, și nu știa că este Isus.
15 Jesu wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Ta ni ìwọ ń wá?” Òun ṣe bí olùṣọ́gbà ní í ṣe, ó wí fún un pé, “Alàgbà, bí ìwọ bá ti gbé e kúrò níhìn-ín yìí, sọ ibi tí ìwọ tẹ́ ẹ sí fún mi, èmi yóò sì gbé e kúrò.”
Isus i-a zis: “Femeie, de ce plângi? Pe cine cauți?” Ea, presupunând că este grădinarul, i-a spus: “Domnule, dacă l-ai dus, spune-mi unde l-ai pus și îl voi lua.”
16 Jesu wí fún un pé, “Maria!” Ó sì yípadà, ó wí fún un ní èdè Heberu pé, “Rabboni!” (èyí tí ó túmọ̀ sí “Olùkọ́”).
Isus i-a zis: “Maria.” Ea s-a întors și i-a spus: “Rabboni!”, adică “Învățătorule!”.
17 Jesu wí fún un pé, “Má ṣe fi ọwọ́ kàn mí; nítorí tí èmi kò tí ì gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi. Ṣùgbọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin mi, sì wí fún wọn pé, ‘Èmi ń gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi, àti Baba yín, àti sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run mi, àti Ọlọ́run yín.’”
Isus i-a zis: “Nu Mă țineți, căci încă nu M-am înălțat la Tatăl Meu, ci du-te la frații Mei și spune-le: Mă înalț la Tatăl Meu și Tatăl vostru, la Dumnezeul Meu și Dumnezeul vostru.”
18 Maria Magdalene wá, ó sì sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, “Òun ti rí Olúwa!” Àti pé, ó sì ti fi nǹkan wọ̀nyí fún òun.
Maria Magdalena a venit și a spus ucenicilor că a văzut pe Domnul și că El i-a spus aceste lucruri.
19 Ní ọjọ́ kan náà, lọ́jọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀ nígbà tí alẹ́ lẹ́, tí a sì ti ìlẹ̀kùn ibi tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbé péjọ, nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù, bẹ́ẹ̀ ni Jesu dé, ó dúró láàrín, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
Așadar, când s-a făcut seară în ziua aceea, prima zi a săptămânii, și când ușile erau încuiate acolo unde erau adunați discipolii, de frica iudeilor, Isus a venit, a stat în mijloc și le-a zis: “Pace vouă!”.
20 Nígbà tí ó sì ti wí bẹ́ẹ̀ tán, ó fi ọwọ́ àti ìhà rẹ̀ hàn wọ́n. Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn yọ̀, nígbà tí wọ́n rí Olúwa.
După ce a zis acestea, le-a arătat mâinile și coasta Lui. Ucenicii s-au bucurat, așadar, când L-au văzut pe Domnul.
21 Nítorí náà, Jesu sì tún wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín: gẹ́gẹ́ bí Baba ti rán mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì rán yín.”
Isus le-a zis din nou: “Pace vouă! Cum M-a trimis Tatăl, așa vă trimit și Eu pe voi”.
22 Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó mí sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gba Ẹ̀mí Mímọ́!
După ce a spus acestea, a suflat peste ei și le-a zis: “Primiți Duhul Sfânt!
23 Ẹ̀ṣẹ̀ ẹnikẹ́ni tí ẹ̀yin bá fi jì, a fi jì wọ́n; ẹ̀ṣẹ̀ ẹnikẹ́ni tí ẹ̀yin bá dádúró, a dá wọn dúró.”
Dacă iertați păcatele cuiva, i-au fost iertate. Dacă rețineți păcatele cuiva, ele au fost reținute.”
24 Ṣùgbọ́n Tomasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, tí a ń pè ní Didimu, kò wà pẹ̀lú wọn nígbà tí Jesu dé.
Dar Toma, unul din cei doisprezece, numit Didimus, nu era cu ei când a venit Isus.
25 Nítorí náà àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ìyókù wí fún un pé, “Àwa ti rí Olúwa!” Ṣùgbọ́n ó wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé mo bá rí àpá ìṣó ni ọwọ́ rẹ̀ kí èmi sì fi ìka mi sí àpá ìṣó náà, kí èmi sì fi ọwọ́ mi sí ìhà rẹ̀, èmi kì yóò gbàgbọ́!”
De aceea, ceilalți discipoli i-au spus: “L-am văzut pe Domnul!” Dar el le-a zis: “Dacă nu voi vedea în mâinile Lui amprenta cuielor, dacă nu voi pune degetul meu în amprenta cuielor și dacă nu voi pune mâna mea în coasta Lui, nu voi crede.”
26 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́jọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì tún wà nínú ilé, àti Tomasi pẹ̀lú wọn: nígbà tí a sì ti ti ìlẹ̀kùn, Jesu dé, ó sì dúró láàrín, ó wí pé, “Àlàáfíà fún yín.”
După opt zile, ucenicii Lui au intrat din nou înăuntru și Toma era cu ei. Isus a venit, ușile fiind încuiate, a stat în mijloc și a zis: “Pace vouă!”.
27 Nígbà náà ni ó wí fún Tomasi pé, “Mú ìka rẹ wá níhìn-ín yìí, kí o sì wo ọwọ́ mi; sì mú ọwọ́ rẹ wá níhìn-ín, kí o sì fi sí ìhà mi: kí ìwọ má ṣe jẹ́ aláìgbàgbọ́ mọ́, ṣùgbọ́n jẹ́ onígbàgbọ́.”
Apoi i-a spus lui Toma: “Întinde aici degetul tău și vezi mâinile Mele. Întinde aici mâna ta și pune-o în coasta Mea. Nu fi necredincios, ci credincios.”
28 Tomasi dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olúwa mi àti Ọlọ́run mi!”
Toma I-a răspuns: “Domnul meu și Dumnezeul meu!”
29 Jesu wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ rí mi ni ìwọ ṣe gbàgbọ́, alábùkún fún ni àwọn tí kò rí mi, tí wọ́n sì gbàgbọ́!”
Isus i-a zis: “Pentru că M-ai văzut, ai crezut. Ferice de cei care nu au văzut și au crezut.”
30 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì mìíràn ni Jesu ṣe níwájú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, tí a kò kọ sínú ìwé yìí.
Isus a mai făcut multe alte semne în fața ucenicilor Săi, care nu sunt scrise în cartea aceasta;
31 Ṣùgbọ́n wọ̀nyí ni a kọ, kí ẹ̀yin lè gbàgbọ́ pé Jesu ní í ṣe Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run, àti pé nípa gbígbàgbọ́, kí ẹ̀yin lè ní ìyè ní orúkọ rẹ̀.
dar acestea sunt scrise pentru ca voi să credeți că Isus este Hristosul, Fiul lui Dumnezeu, și, crezând, să aveți viață în Numele Lui.

< John 20 >