< John 20 >

1 Ní kùtùkùtù ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, nígbà tí ilẹ̀ kò tí ì mọ́, ni Maria Magdalene wá sí ibojì, ó sì rí i pé, a ti gbé òkúta kúrò lẹ́nu ibojì.
A pierwszego dnia po sabacie Maryja Magdalena przyszła rano do grobu, gdy jeszcze było ciemno, i ujrzała kamień odwalony od grobu.
2 Nítorí náà, ó sáré, ó sì tọ Simoni Peteru àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn wá, ẹni tí Jesu fẹ́ràn, ó sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gbé Olúwa kúrò nínú ibojì, àwa kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”
I bieżała, a przyszła do Szymona Piotra i do onego drugiego ucznia, którego miłował Jezus, i rzekła im: Wzięli Pana z grobu, a nie wiemy, gdzie go położyli.
3 Nígbà náà ni Peteru àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà jáde, wọ́n sì wá sí ibojì.
Tedy wyszedł Piotr i on drugi uczeń, a szli do grobu.
4 Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ sáré: èyí ọmọ-ẹ̀yìn náà sì sáré ya Peteru, ó sì kọ́kọ́ dé ibojì.
I bieżeli obaj społem; ale on drugi uczeń wyścignął Piotra i pierwej przyszedł do grobu.
5 Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti wo inú rẹ̀, ó rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀; ṣùgbọ́n òun kò wọ inú rẹ̀.
A nachyliwszy się, ujrzał leżące prześcieradła; wszakże tam nie wszedł.
6 Nígbà náà ni Simoni Peteru tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ dé, ó sì wọ inú ibojì, ó sì rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀.
Przyszedł też i Szymon Piotr, idąc za nim, i wszedł w grób, i ujrzał prześcieradła leżące,
7 Àti pé, gèlè tí ó wà níbi orí rẹ̀ kò sì wà pẹ̀lú aṣọ ọ̀gbọ̀ náà, ṣùgbọ́n ó ká jọ ní ibìkan fúnra rẹ̀.
I chustkę, która była na głowie jego, nie z prześcieradłami położoną, ale z osobna na jednem miejscu zwiniętą.
8 Nígbà náà ni ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà, ẹni tí ó kọ́ dé ibojì wọ inú rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì rí i, ó sì gbàgbọ́.
Potem wszedł i on drugi uczeń, który był pierwej przyszedł do grobu, i ujrzał, a uwierzył.
9 (Nítorí tí wọn kò sá à tí mọ ìwé mímọ́ pé, Jesu ní láti jíǹde kúrò nínú òkú).
Albowiem jeszcze nie rozumieli Pisma, iż miał zmartwychwstać.
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sì tún padà lọ sí ilé wọn.
I odeszli zaś oni uczniowie do domu.
11 Ṣùgbọ́n Maria dúró létí ibojì lóde, ó ń sọkún: bí ó ti ń sọkún, bẹ́ẹ̀ ni ó bẹ̀rẹ̀, ó sì wo inú ibojì.
Ale Maryja stała u grobu, na dworze płacząc; a gdy płakała, nachyliła się w grób.
12 Ó sì kíyèsi àwọn angẹli méjì aláṣọ funfun, wọ́n jókòó, ọ̀kan níhà orí àti ọ̀kan níhà ẹsẹ̀, níbi tí òkú Jesu gbé ti sùn sí.
I ujrzała dwóch Aniołów w bieli siedzących, jednego u głowy, a drugiego u nóg, tam gdzie było położone ciało Jezusowe.
13 Wọ́n sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún?” Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí tí wọ́n ti gbé Olúwa mi, èmi kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”
Którzy jej rzekli: Niewiasto! czemu płaczesz? Rzekła im: Iż wzięli Pana mego, a nie wiem, gdzie go położyli.
14 Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó yípadà, ó sì rí Jesu dúró, kò sì mọ̀ pé Jesu ni.
A to rzekłszy, obróciła się nazad i ujrzała Jezusa stojącego; lecz nie wiedziała, iż Jezus był.
15 Jesu wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Ta ni ìwọ ń wá?” Òun ṣe bí olùṣọ́gbà ní í ṣe, ó wí fún un pé, “Alàgbà, bí ìwọ bá ti gbé e kúrò níhìn-ín yìí, sọ ibi tí ìwọ tẹ́ ẹ sí fún mi, èmi yóò sì gbé e kúrò.”
Rzekł jej Jezus: Niewiasto! czemu płaczesz? kogo szukasz? A ona mniemając, że był ogrodnik, rzekła mu: Panie! jeźliś go ty wziął, powiedz mi, gdzieś go położył, a ja go wezmę.
16 Jesu wí fún un pé, “Maria!” Ó sì yípadà, ó wí fún un ní èdè Heberu pé, “Rabboni!” (èyí tí ó túmọ̀ sí “Olùkọ́”).
Rzekł jej Jezus: Maryjo! Która obróciwszy się, rzekła mu: Rabbuni! co się wykłada: Nauczycielu!
17 Jesu wí fún un pé, “Má ṣe fi ọwọ́ kàn mí; nítorí tí èmi kò tí ì gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi. Ṣùgbọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin mi, sì wí fún wọn pé, ‘Èmi ń gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi, àti Baba yín, àti sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run mi, àti Ọlọ́run yín.’”
Rzekł jej Jezus: Nie dotykaj się mnie, bom jeszcze nie wstąpił do Ojca mego; ale idź do braci moich, a powiedz im: Wstępuję do Ojca mego i Ojca waszego, i do Boga mego i Boga waszego.
18 Maria Magdalene wá, ó sì sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, “Òun ti rí Olúwa!” Àti pé, ó sì ti fi nǹkan wọ̀nyí fún òun.
Tedy przyszła Maryja Magdalena, oznajmując uczniom, że widziała Pana, a że jej to powiedział.
19 Ní ọjọ́ kan náà, lọ́jọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀ nígbà tí alẹ́ lẹ́, tí a sì ti ìlẹ̀kùn ibi tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbé péjọ, nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù, bẹ́ẹ̀ ni Jesu dé, ó dúró láàrín, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
A gdy był wieczór dnia onego pierwszego po sabacie, a drzwi były zamknięte, gdzie byli uczniowie zgromadzeni dla bojaźni żydowskiej, przyszedł Jezus i stanął w pośrodku nich, i rzekł im: Pokój wam!
20 Nígbà tí ó sì ti wí bẹ́ẹ̀ tán, ó fi ọwọ́ àti ìhà rẹ̀ hàn wọ́n. Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn yọ̀, nígbà tí wọ́n rí Olúwa.
A to rzekłszy pokazał im ręce i bok swój; a uradowali się uczniowie, ujrzawszy Pana.
21 Nítorí náà, Jesu sì tún wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín: gẹ́gẹ́ bí Baba ti rán mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì rán yín.”
Rzekł im zasię Jezus: Pokój wam; jako mię posłał Ojciec, tak i ja was posyłam.
22 Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó mí sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gba Ẹ̀mí Mímọ́!
A to rzekłszy tchnął na nie i rzekł im: Weźmijcie Ducha Świętego.
23 Ẹ̀ṣẹ̀ ẹnikẹ́ni tí ẹ̀yin bá fi jì, a fi jì wọ́n; ẹ̀ṣẹ̀ ẹnikẹ́ni tí ẹ̀yin bá dádúró, a dá wọn dúró.”
Którymkolwiek grzechy odpuścicie, są im odpuszczone, a którymkolwiek zatrzymacie, są zatrzymane.
24 Ṣùgbọ́n Tomasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, tí a ń pè ní Didimu, kò wà pẹ̀lú wọn nígbà tí Jesu dé.
A Tomasz, jeden ze dwunastu, którego zowią Dydymus, nie był z nimi, gdy był przyszedł Jezus.
25 Nítorí náà àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ìyókù wí fún un pé, “Àwa ti rí Olúwa!” Ṣùgbọ́n ó wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé mo bá rí àpá ìṣó ni ọwọ́ rẹ̀ kí èmi sì fi ìka mi sí àpá ìṣó náà, kí èmi sì fi ọwọ́ mi sí ìhà rẹ̀, èmi kì yóò gbàgbọ́!”
I rzekli mu drudzy uczniowie: Widzieliśmy Pana. Ale im on rzekł: Jeźli nie ujrzę w ręku jego znaków gwoździ, a nie włożę palca mego w znaki gwoździ, a nie włożę ręki mojej w bok jego, nie uwierzę.
26 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́jọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì tún wà nínú ilé, àti Tomasi pẹ̀lú wọn: nígbà tí a sì ti ti ìlẹ̀kùn, Jesu dé, ó sì dúró láàrín, ó wí pé, “Àlàáfíà fún yín.”
A po ośmiu dniach byli zasię uczniowie jego w domu, i Tomasz z nimi. I przyszedł Jezus, gdy były drzwi zamknięte, a stanął w pośrodku nich, i rzekł: Pokój wam!
27 Nígbà náà ni ó wí fún Tomasi pé, “Mú ìka rẹ wá níhìn-ín yìí, kí o sì wo ọwọ́ mi; sì mú ọwọ́ rẹ wá níhìn-ín, kí o sì fi sí ìhà mi: kí ìwọ má ṣe jẹ́ aláìgbàgbọ́ mọ́, ṣùgbọ́n jẹ́ onígbàgbọ́.”
Potem rzekł Tomaszowi: Włóż sam palec twój, a oglądaj ręce moje i ściągnij rękę twoję, i włóż ją w bok mój, a nie bądź niewiernym, ale wiernym.
28 Tomasi dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olúwa mi àti Ọlọ́run mi!”
Tedy odpowiedział Tomasz i rzekł mu: Panie mój, i Boże mój!
29 Jesu wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ rí mi ni ìwọ ṣe gbàgbọ́, alábùkún fún ni àwọn tí kò rí mi, tí wọ́n sì gbàgbọ́!”
Rzekł mu Jezus: Żeś mię ujrzał, Tomaszu, uwierzyłeś; błogosławieni którzy nie widzieli, a uwierzyli.
30 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì mìíràn ni Jesu ṣe níwájú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, tí a kò kọ sínú ìwé yìí.
Wieleć i innych cudów uczynił Jezus przed oczyma uczniów swoich, które nie są napisane w tych księgach.
31 Ṣùgbọ́n wọ̀nyí ni a kọ, kí ẹ̀yin lè gbàgbọ́ pé Jesu ní í ṣe Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run, àti pé nípa gbígbàgbọ́, kí ẹ̀yin lè ní ìyè ní orúkọ rẹ̀.
Ale te są napisane, abyście wy wierzyli, że Jezus jest Chrystus, Syn Boży, a żebyście wierząc żywot mieli w imieniu jego.

< John 20 >