< John 20 >

1 Ní kùtùkùtù ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, nígbà tí ilẹ̀ kò tí ì mọ́, ni Maria Magdalene wá sí ibojì, ó sì rí i pé, a ti gbé òkúta kúrò lẹ́nu ibojì.
Le premier jour de la semaine, Marie Madeleine se rendit au sépulcre, de grand matin, lorsqu'il faisait encore obscur: elle vit que la pierre en était ôtée.
2 Nítorí náà, ó sáré, ó sì tọ Simoni Peteru àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn wá, ẹni tí Jesu fẹ́ràn, ó sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gbé Olúwa kúrò nínú ibojì, àwa kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”
Elle courut donc trouver Simon Pierre, ainsi que l'autre disciple que Jésus aimait, et leur dit: «On a enlevé du sépulcre le Seigneur, et nous ne savons où on l’a mis.»
3 Nígbà náà ni Peteru àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà jáde, wọ́n sì wá sí ibojì.
Pierre sortit donc, ainsi que l'autre disciple, et ils se rendirent au sépulcre.
4 Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ sáré: èyí ọmọ-ẹ̀yìn náà sì sáré ya Peteru, ó sì kọ́kọ́ dé ibojì.
Ils couraient tous deux; mais l'autre disciple courut plus vite que Pierre, et arriva le premier au sépulcre;
5 Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti wo inú rẹ̀, ó rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀; ṣùgbọ́n òun kò wọ inú rẹ̀.
et s'étant baissé, il vit les bandes qui étaient à terre; cependant, il n'entra point.
6 Nígbà náà ni Simoni Peteru tí ń bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ dé, ó sì wọ inú ibojì, ó sì rí aṣọ ọ̀gbọ̀ náà ní ilẹ̀.
Simon Pierre, qui le suivait, arriva à son tour; il entra dans le sépulcre, et vit les bandes qui étaient à terre,
7 Àti pé, gèlè tí ó wà níbi orí rẹ̀ kò sì wà pẹ̀lú aṣọ ọ̀gbọ̀ náà, ṣùgbọ́n ó ká jọ ní ibìkan fúnra rẹ̀.
et le suaire, dont on avait couvert la tête de Jésus, non point avec les bandes, mais roulé à part dans un coin.
8 Nígbà náà ni ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà, ẹni tí ó kọ́ dé ibojì wọ inú rẹ̀ pẹ̀lú, ó sì rí i, ó sì gbàgbọ́.
Alors cet autre disciple qui était arrivé le premier au sépulcre, y entra aussi: il vit, et il crut;
9 (Nítorí tí wọn kò sá à tí mọ ìwé mímọ́ pé, Jesu ní láti jíǹde kúrò nínú òkú).
car ces disciples ne savaient pas encore que, d'après l'Écriture, le Messie devait ressusciter des morts.
10 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sì tún padà lọ sí ilé wọn.
Là-dessus, ils s'en retournèrent chez eux.
11 Ṣùgbọ́n Maria dúró létí ibojì lóde, ó ń sọkún: bí ó ti ń sọkún, bẹ́ẹ̀ ni ó bẹ̀rẹ̀, ó sì wo inú ibojì.
Cependant Marie se tenait près du sépulcre, en dehors, et pleurait. Tout en pleurant, elle se baissa pour regarder dans le sépulcre,
12 Ó sì kíyèsi àwọn angẹli méjì aláṣọ funfun, wọ́n jókòó, ọ̀kan níhà orí àti ọ̀kan níhà ẹsẹ̀, níbi tí òkú Jesu gbé ti sùn sí.
et elle vit deux anges, vêtus de blanc, assis au lieu où avait reposé le corps de Jésus, l'un à la tête, l'autre aux pieds.
13 Wọ́n sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún?” Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí tí wọ́n ti gbé Olúwa mi, èmi kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé tẹ́ ẹ sí.”
Et ces anges lui dirent: «Femme, pourquoi pleures-tu?» Elle leur répondit: «C'est qu'on a enlevé mon Seigneur, et je ne sais où on l’a mis.»
14 Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó yípadà, ó sì rí Jesu dúró, kò sì mọ̀ pé Jesu ni.
En disant ces mots, elle se retourna et vit Jésus qui était là; mais elle ne savait pas que c'était Jésus.
15 Jesu wí fún un pé, “Obìnrin yìí, èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Ta ni ìwọ ń wá?” Òun ṣe bí olùṣọ́gbà ní í ṣe, ó wí fún un pé, “Alàgbà, bí ìwọ bá ti gbé e kúrò níhìn-ín yìí, sọ ibi tí ìwọ tẹ́ ẹ sí fún mi, èmi yóò sì gbé e kúrò.”
Jésus lui dit: «Femme, pourquoi pleures-tu? Qui cherches-tu?» Marie, croyant que c'était le jardinier, lui dit: «Seigneur, si c'est toi qui l'as emporté, dis-moi où tu l'as mis, et j'irai le prendre.»
16 Jesu wí fún un pé, “Maria!” Ó sì yípadà, ó wí fún un ní èdè Heberu pé, “Rabboni!” (èyí tí ó túmọ̀ sí “Olùkọ́”).
Jésus lui dit: «Marie!» Elle se retourna, et lui dit en hébreu: «Rabboni!» c’est-à-dire, Maître.
17 Jesu wí fún un pé, “Má ṣe fi ọwọ́ kàn mí; nítorí tí èmi kò tí ì gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi. Ṣùgbọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin mi, sì wí fún wọn pé, ‘Èmi ń gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Baba mi, àti Baba yín, àti sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run mi, àti Ọlọ́run yín.’”
Jésus lui dit: «Ne me touche pas, car je ne suis pas encore monté vers le Père; mais va trouver mes frères, et dis-leur que je monte vers mon Père et votre Père, vers mon Dieu et votre Dieu.»
18 Maria Magdalene wá, ó sì sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, “Òun ti rí Olúwa!” Àti pé, ó sì ti fi nǹkan wọ̀nyí fún òun.
Marie Madeleine alla annoncer aux disciples qu'elle avait vu le Seigneur, et qu'il lui avait dit ces choses.
19 Ní ọjọ́ kan náà, lọ́jọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀ nígbà tí alẹ́ lẹ́, tí a sì ti ìlẹ̀kùn ibi tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn gbé péjọ, nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù, bẹ́ẹ̀ ni Jesu dé, ó dúró láàrín, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
Dans la soirée de ce même jour, qui était le premier de la semaine, les portes du lieu où étaient les disciples étant fermées par crainte des Juifs, Jésus vint, et, se présentant au milieu d'eux, il leur dit: «La paix soit avec vous!»
20 Nígbà tí ó sì ti wí bẹ́ẹ̀ tán, ó fi ọwọ́ àti ìhà rẹ̀ hàn wọ́n. Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn yọ̀, nígbà tí wọ́n rí Olúwa.
Ayant ainsi parlé, il leur montra ses mains et son côté. Les disciples furent remplis de joie en voyant le Seigneur.
21 Nítorí náà, Jesu sì tún wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín: gẹ́gẹ́ bí Baba ti rán mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì rán yín.”
Jésus leur dit une seconde fois: «La paix soit avec vous! Comme le Père m'a envoyé, moi aussi je vous envoie.»
22 Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó mí sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gba Ẹ̀mí Mímọ́!
Après ces paroles, il souffla sur eux, et leur dit: «Recevez le Saint-Esprit.
23 Ẹ̀ṣẹ̀ ẹnikẹ́ni tí ẹ̀yin bá fi jì, a fi jì wọ́n; ẹ̀ṣẹ̀ ẹnikẹ́ni tí ẹ̀yin bá dádúró, a dá wọn dúró.”
Ceux à qui vous pardonnerez leurs péchés, ces péchés leur seront pardonnés; ceux à qui vous retiendrez leurs péchés, ces péchés leur seront retenus.»
24 Ṣùgbọ́n Tomasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, tí a ń pè ní Didimu, kò wà pẹ̀lú wọn nígbà tí Jesu dé.
Thomas, l'un des Douze, celui qu'on appelle Didyme, n'était pas avec eux, lorsque Jésus vint.
25 Nítorí náà àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ìyókù wí fún un pé, “Àwa ti rí Olúwa!” Ṣùgbọ́n ó wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé mo bá rí àpá ìṣó ni ọwọ́ rẹ̀ kí èmi sì fi ìka mi sí àpá ìṣó náà, kí èmi sì fi ọwọ́ mi sí ìhà rẹ̀, èmi kì yóò gbàgbọ́!”
Les autres disciples lui dirent donc: «Nous avons vu le Seigneur.» Mais Thomas leur dit: «Si je ne vois dans ses mains la marque des clous, si je ne mets mon doigt à la place où étaient les clous, et si je ne mets ma main dans son côté, je ne le croirai point.»
26 Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́jọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì tún wà nínú ilé, àti Tomasi pẹ̀lú wọn: nígbà tí a sì ti ti ìlẹ̀kùn, Jesu dé, ó sì dúró láàrín, ó wí pé, “Àlàáfíà fún yín.”
Huit jours après, les disciples se trouvaient de nouveau dans la maison, et Thomas était avec eux. Jésus vint, quoique les, portes fussent fermées, et, se présentant au milieu d'eux, leur dit: «La paix soit avec vous!»
27 Nígbà náà ni ó wí fún Tomasi pé, “Mú ìka rẹ wá níhìn-ín yìí, kí o sì wo ọwọ́ mi; sì mú ọwọ́ rẹ wá níhìn-ín, kí o sì fi sí ìhà mi: kí ìwọ má ṣe jẹ́ aláìgbàgbọ́ mọ́, ṣùgbọ́n jẹ́ onígbàgbọ́.”
Il dit ensuite à Thomas: «Approche ici ton doigt, et regarde mes mains; approche aussi ta main et la mets dans mon côté; et ne sois pas incrédule, mais crois.»
28 Tomasi dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Olúwa mi àti Ọlọ́run mi!”
Thomas répondit et lui dit: «Mon Seigneur et mon Dieu!»
29 Jesu wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ rí mi ni ìwọ ṣe gbàgbọ́, alábùkún fún ni àwọn tí kò rí mi, tí wọ́n sì gbàgbọ́!”
Jésus lui dit: «Parce que tu m'as vu, tu as cru: heureux ceux qui croiront sans avoir vu!»
30 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì mìíràn ni Jesu ṣe níwájú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, tí a kò kọ sínú ìwé yìí.
Jésus a fait, en présence de ses disciples, beaucoup d'autres miracles qui ne sont pas consignés dans ce livre;
31 Ṣùgbọ́n wọ̀nyí ni a kọ, kí ẹ̀yin lè gbàgbọ́ pé Jesu ní í ṣe Kristi náà, Ọmọ Ọlọ́run, àti pé nípa gbígbàgbọ́, kí ẹ̀yin lè ní ìyè ní orúkọ rẹ̀.
mais ceux-ci ont été rapportés, afin que vous croyiez que Jésus est le Messie, le Fils de Dieu, et qu'en croyant vous ayez la vie en son nom.

< John 20 >