< John 2 >
1 Ní ọjọ́ kẹta, wọn ń ṣe ìgbéyàwó kan ní Kana ti Galili. Ìyá Jesu sì wà níbẹ̀.
And, on the third day, a marriage, took place, in Cana, of Galilee; and the mother of Jesus was there, —
2 A sì pe Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sí ibi ìgbéyàwó náà.
and Jesus also was invited, with his disciples, unto the marriage.
3 Nígbà tí wáìnì sì tán, ìyá Jesu wí fún un pé, “Wọn kò ní wáìnì mọ́.”
And, wine falling short, the mother of Jesus saith unto him—Wine, have they none!
4 Jesu fèsì pé, “Arábìnrin ọ̀wọ́n, èéṣe tí ọ̀rọ̀ yìí fi kàn mí? Àkókò mi kò tí ì dé.”
And Jesus saith unto her—What part can I take with thee, O woman? Not yet, hath come, mine hour.
5 Ìyá rẹ̀ wí fún àwọn ìránṣẹ́ náà pé, “Ẹ ṣe ohunkóhun tí ó bá wí fún yín.”
His mother saith unto them who are ministering—Whatsoever he may say to you, do!
6 Ìkòkò òkúta omi mẹ́fà ni a sì gbé kalẹ̀ níbẹ̀, irú èyí tí àwọn Júù máa ń fi ṣe ìwẹ̀nù, èyí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn gbà tó ìwọ̀n ogún sí ọgbọ̀n jálá.
Now there were there, six stone water-vessels, placed, according to the purification of the Jews; holding each, two or three measures.
7 Jesu wí fún àwọn ìránṣẹ́ náà pé, “Ẹ pọn omi kún ìkòkò wọ̀nyí.” Wọ́n sì pọn omi kún wọn títí dé etí.
Jesus saith unto them—Fill the vessels with water. And they filled them up to the brim.
8 Lẹ́yìn náà ni ó wí fún wọn pé, “Ẹ bù jáde lára rẹ̀ kí ẹ sì gbé e tọ alábojútó àsè lọ.” Wọ́n sì gbé e lọ;
And he saith unto them—Draw out now, and be bearing unto the master of the feast. And they bare.
9 alábojútó àsè náà tọ́ omi tí a sọ di wáìnì wò. Òun kò sì mọ ibi tí ó ti wá, ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ tí ó bu omi náà wá mọ̀. Alábojútó àsè sì pe ọkọ ìyàwó sí apá kan,
And, when the master of the feast had tasted the water, now made, wine, and knew not whence it was, —though, they who were ministering, knew, even they who had drawn out the water, the master accosteth the bridegroom,
10 Ó sì wí fún un pé, “Olúkúlùkù a máa kọ́kọ́ gbé wáìnì tí ó dára jùlọ kalẹ̀; nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì mu ún yó tan, nígbà náà ní wọn a mú èyí tí kò dára tó bẹ́ẹ̀ wá; ṣùgbọ́n ìwọ ti pa wáìnì dáradára yìí mọ́ títí ó fi di ìsinsin yìí.”
and saith unto him—Every man, first the good wine, setteth out; and, when they had been well-supplied, the inferior: —Thou, hast kept the good wine until, even now.
11 Èyí jẹ́ àkọ́ṣe iṣẹ́ àmì, tí Jesu ṣe ní Kana ti Galili. Ó sì fi ògo rẹ̀ hàn; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì gbà á gbọ́.
This, beginning of his signs, did Jesus, in Cana of Galilee, and manifested his glory; and his disciples believed on him.
12 Lẹ́yìn èyí, ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Kapernaumu, Òun àti ìyá rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀, àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì gbé ibẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.
After this, he came down into Capernaum, —he, and his mother and brethren, and his disciples; and, there, they abode, not many days.
13 Àjọ ìrékọjá àwọn Júù sì súnmọ́ etílé, Jesu sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu,
And, near, was the passover of the Jews; and, Jesus, went up unto Jerusalem.
14 Ó sì rí àwọn tí n ta màlúù, àti àgùntàn, àti àdàbà, àti àwọn onípàṣípàrọ̀ owó nínú tẹmpili wọ́n jókòó:
And he found, in the temple, them that were selling oxen and sheep and doves, also the money-changers sitting.
15 Ó sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ ṣe pàṣán, ó sì lé gbogbo wọn jáde kúrò nínú tẹmpili, àti àgùntàn àti màlúù; ó sì da owó àwọn onípàṣípàrọ̀ owó nù, ó si ti tábìlì wọn ṣubú.
And, making a scourge out of rushes, all of them, thrust he forth out of the temple, both the sheep and the oxen; and, the money-changers’ small coins, poured he forth, and, the tables, he overturned;
16 Ó sì wí fún àwọn tí ń ta àdàbà pé, “Ẹ gbé nǹkan wọ̀nyí kúrò níhìn-ín; ẹ má ṣe sọ ilé Baba mi di ilé ọjà títà.”
and unto them who were selling, the doves, he said—Take these things hence! Be not making, the house of my Father, a house of merchandise.
17 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì rántí pé, a ti kọ ọ́ pé, “Ìtara ilé rẹ jẹ mí run.”
His disciples remembered that it was written—The zeal of thy house, eateth me up.
18 Nígbà náà ní àwọn Júù dáhùn, wọ́n sì bi í pé, “Àmì wo ni ìwọ lè fihàn wá, tí ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí?”
The Jews therefore answered, and said unto him, What sign, dost thou point out to us, in that, these things, thou doest?
19 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wó tẹmpili yìí palẹ̀, Èmi ó sì tún un kọ ní ọjọ́ mẹ́ta.”
Jesus answered, and said unto them—Take down this shrine, and, in three days, will I raise it.
20 Nígbà náà ní àwọn Júù wí pé, “Ọdún mẹ́rìndínláàádọ́ta ni a fi kọ́ tẹmpili yìí, ìwọ ó ha sì tún un kọ ní ọjọ́ mẹ́ta?”
The Jews, therefore, said—In forty and six years, was this shrine built. And, thou, in three days, wilt raise it!
21 Ṣùgbọ́n òun ń sọ ti tẹmpili ara rẹ̀.
But, he, was speaking concerning the shrine of his body.
22 Nítorí náà nígbà tí ó jíǹde kúrò nínú òkú, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rántí pé, ó ti sọ èyí fún wọn, wọ́n sì gba Ìwé Mímọ́, àti ọ̀rọ̀ tí Jesu ti sọ gbọ́.
When, therefore, he had been raised from among the dead, his disciples remembered, that, this, he had been saying; and they believed in the Scripture, and in the word which Jesus had spoken.
23 Nígbà tí ó sì wà ní Jerusalẹmu, ní àjọ ìrékọjá, lákokò àjọ náà, ọ̀pọ̀ ènìyàn gba orúkọ rẹ̀ gbọ́ nígbà tí wọ́n rí iṣẹ́ àmì tí ó ṣe.
Now, when he was in Jerusalem, during the passover, during the feast, many, believed on his name, viewing his signs which he was doing.
24 Ṣùgbọ́n Jesu kò gbé ara lé wọn, nítorí tí ó mọ gbogbo ènìyàn.
Jesus himself, however, was not trusting himself unto them, by reason of his understanding them all,
25 Òun kò sì nílò ẹ̀rí nípa ènìyàn, nítorí tí o mọ̀ ohun tí ń bẹ nínú ènìyàn.
and because he had, no need, that anyone should bear witness concerning man; for, he, understood what was in man.