< John 2 >

1 Ní ọjọ́ kẹta, wọn ń ṣe ìgbéyàwó kan ní Kana ti Galili. Ìyá Jesu sì wà níbẹ̀.
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁϩⲅ̅ ⲟⲩϩⲟⲡ ⲁϥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲁⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲣⲉ ⳿ⲑⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉ.
2 A sì pe Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sí ibi ìgbéyàwó náà.
ⲃ̅ⲁⲩⲑⲁϩⲉⲙ ⳿ⲡⲕⲉⲒⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏ ⲧⲏⲥ ⳿ⲉⲡⲓϩⲟⲡ.
3 Nígbà tí wáìnì sì tán, ìyá Jesu wí fún un pé, “Wọn kò ní wáìnì mọ́.”
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩⲛⲕ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲏⲣⲡ ⲡⲉϫⲉ ⳿ⲑⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲟⲩ ⲏⲣⲡ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
4 Jesu fèsì pé, “Arábìnrin ọ̀wọ́n, èéṣe tí ọ̀rọ̀ yìí fi kàn mí? Àkókò mi kò tí ì dé.”
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⳿ⲁϧⲟ ⲛⲉⲙⲏⲓ ϩⲱⲓ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉⲥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲧⲁⲟⲩⲛⲟⲩ.
5 Ìyá rẹ̀ wí fún àwọn ìránṣẹ́ náà pé, “Ẹ ṣe ohunkóhun tí ó bá wí fún yín.”
ⲉ̅ⲡⲉϫⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲇⲉ ⳿ⲛⲛⲓⲇⲓ⳿ⲁⲕⲱⲛ ϫⲉ ⲫⲏⲉⲧⲉϥⲛⲁϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲁⲣⲓⲧϥ.
6 Ìkòkò òkúta omi mẹ́fà ni a sì gbé kalẹ̀ níbẹ̀, irú èyí tí àwọn Júù máa ń fi ṣe ìwẹ̀nù, èyí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn gbà tó ìwọ̀n ogún sí ọgbọ̀n jálá.
ⲋ̅ⲛⲁⲩⲭⲏ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲛϩⲩⲇⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲱⲛⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲡⲧⲟⲩⲃⲟ ⳿ⲛⲛⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲉⲩⲱⲗⲓ ⳿ⲙⲙⲉⲧⲣⲓⲧⲏⲥ ⲃ̅ ⲓⲉ ⲅ̅ ⳿ⲉⲑⲟⲩⲓ.
7 Jesu wí fún àwọn ìránṣẹ́ náà pé, “Ẹ pọn omi kún ìkòkò wọ̀nyí.” Wọ́n sì pọn omi kún wọn títí dé etí.
ⲍ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲙⲟϩ ⳿ⲛⲛⲓϩⲩⲇⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲙⲁϩⲟⲩ ϣⲁ⳿ⲡϣⲱⲓ.
8 Lẹ́yìn náà ni ó wí fún wọn pé, “Ẹ bù jáde lára rẹ̀ kí ẹ sì gbé e tọ alábojútó àsè lọ.” Wọ́n sì gbé e lọ;
ⲏ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲟⲩⲱⲧϩ ϯⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲣⲭⲏ⳿ⲧⲣⲓⲕⲗⲓⲛⲟⲥ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲇⲉ ⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ.
9 alábojútó àsè náà tọ́ omi tí a sọ di wáìnì wò. Òun kò sì mọ ibi tí ó ti wá, ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ tí ó bu omi náà wá mọ̀. Alábojútó àsè sì pe ọkọ ìyàwó sí apá kan,
ⲑ̅ϩⲱⲥ ⲇⲉ ⲉⲧⲁϥϫⲉⲙϯⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲁⲣⲭⲏ⳿ⲧⲣⲓⲕⲗⲓⲛⲟⲥ ⳿ⲉⲁϥⲉⲣ ⳿ⲏⲣⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲟⲩ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲑⲱⲛ ⲡⲉ ⲛⲓⲇⲓ⳿ⲁⲕⲱⲛ ⲇⲉ ⲛⲁⲩ⳿ⲉⲙⲓ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩⲙⲁϩ ⲡⲓⲙⲱⲟⲩ ⲁ ⲡⲓⲁⲣⲭⲏ ⳿ⲧⲣⲓⲕⲗⲓⲛⲟⲥ ⲇⲉ ⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲡⲓⲡⲁⲧϣⲉⲗⲉⲧ.
10 Ó sì wí fún un pé, “Olúkúlùkù a máa kọ́kọ́ gbé wáìnì tí ó dára jùlọ kalẹ̀; nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì mu ún yó tan, nígbà náà ní wọn a mú èyí tí kò dára tó bẹ́ẹ̀ wá; ṣùgbọ́n ìwọ ti pa wáìnì dáradára yìí mọ́ títí ó fi di ìsinsin yìí.”
ⲓ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉϣⲁⲩ ⲭⲱ ⳿ⲙⲡⲓⲏⲣⲡ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⲁⲩϣⲁⲛⲑⲓϧⲓ ϣⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧ⳿ⲥⲃⲟⲕ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲇⲉ ⲁⲕ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲡⲓⲏⲣⲡ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ϣⲁ ϯⲛⲟⲩ.
11 Èyí jẹ́ àkọ́ṣe iṣẹ́ àmì, tí Jesu ṣe ní Kana ti Galili. Ó sì fi ògo rẹ̀ hàn; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì gbà á gbọ́.
ⲓ̅ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⲡⲓϩⲟⲩⲓⲧ ⳿ⲙⲙⲏⲓⲛⲓ ⲉⲧⲁϥⲁⲓϥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲁⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲛⲁϩϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ.
12 Lẹ́yìn èyí, ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Kapernaumu, Òun àti ìyá rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀, àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì gbé ibẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.
ⲓ̅ⲃ̅ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲫⲁⲓ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲕⲁⲫⲁⲣⲛⲁⲟⲩⲙ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲁⲛ.
13 Àjọ ìrékọjá àwọn Júù sì súnmọ́ etílé, Jesu sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu,
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϧⲉⲛⲧ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡϣⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅.
14 Ó sì rí àwọn tí n ta màlúù, àti àgùntàn, àti àdàbà, àti àwọn onípàṣípàrọ̀ owó nínú tẹmpili wọ́n jókòó:
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϫⲓⲙⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϯ ⳿ⲉϩⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ϭⲣⲟⲙⲡⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓϥⲁⲓⲕⲉⲣⲙⲁ ⲉⲩϩⲉⲙⲥⲓ.
15 Ó sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ ṣe pàṣán, ó sì lé gbogbo wọn jáde kúrò nínú tẹmpili, àti àgùntàn àti màlúù; ó sì da owó àwọn onípàṣípàrọ̀ owó nù, ó si ti tábìlì wọn ṣubú.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲑⲁⲙⲓⲟ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲫⲣⲁⲅⲉⲗⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲛⲟϩ ⲁϥϩⲓⲧⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲛⲓ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲕⲉⲣⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓϥⲁⲓⲕⲉⲣⲙⲁ ⲁϥⲫⲟⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲟⲩ⳿ⲧⲣⲁⲡⲉⲍⲁ ⲁϥⲫⲟⲛϫⲟⲩ.
16 Ó sì wí fún àwọn tí ń ta àdàbà pé, “Ẹ gbé nǹkan wọ̀nyí kúrò níhìn-ín; ẹ má ṣe sọ ilé Baba mi di ilé ọjà títà.”
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϯ ϭⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϫⲉ ⳿ⲁⲗⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲧⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣ ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲱⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲏⲓ ⳿ⲛϣⲱⲧ.
17 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì rántí pé, a ti kọ ọ́ pé, “Ìtara ilé rẹ jẹ mí run.”
ⲓ̅ⲍ̅ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⳿ⲥ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϫⲉ ⳿ⲡⲭⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉⲕⲏⲓ ⳿ϥⲛⲁⲟⲩⲟⲙⲧ.
18 Nígbà náà ní àwọn Júù dáhùn, wọ́n sì bi í pé, “Àmì wo ni ìwọ lè fihàn wá, tí ìwọ fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí?”
ⲓ̅ⲏ̅ⲁⲩⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲏⲓⲛⲓ ⲉⲧⲉⲕⲛⲁⲧⲁⲙⲟⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⳿ⲕ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ.
19 Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wó tẹmpili yìí palẹ̀, Èmi ó sì tún un kọ ní ọjọ́ mẹ́ta.”
ⲓ̅ⲑ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲃⲉⲗ ⲡⲁⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲁⲧⲁϩⲟϥ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ϧⲉⲛ ⲅ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ.
20 Nígbà náà ní àwọn Júù wí pé, “Ọdún mẹ́rìndínláàádọ́ta ni a fi kọ́ tẹmpili yìí, ìwọ ó ha sì tún un kọ ní ọjọ́ mẹ́ta?”
ⲕ̅ⲡⲉϫⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ϫⲉ ⲁⲩⲉⲣ ⲙ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⲉⲩⲕⲱⲧ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⳿ⲭ ⲛⲁⲧⲁϩⲟϥ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ϧⲉⲛ ⲅ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ.
21 Ṣùgbọ́n òun ń sọ ti tẹmpili ara rẹ̀.
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲡⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥⲥⲱⲙⲁ.
22 Nítorí náà nígbà tí ó jíǹde kúrò nínú òkú, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rántí pé, ó ti sọ èyí fún wọn, wọ́n sì gba Ìwé Mímọ́, àti ọ̀rọ̀ tí Jesu ti sọ gbọ́.
ⲕ̅ⲃ̅ϩⲟⲧⲉ ⲟⲩⲛ ⲉⲧⲁϥⲧⲱⲛϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ ⲁⲩⲉⲣ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏ ⲧⲏⲥ ϫⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲛⲁϩϯ ⳿ⲉϯ⳿ⲅⲣⲁⲫⲏ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲉⲧⲁϥϫⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
23 Nígbà tí ó sì wà ní Jerusalẹmu, ní àjọ ìrékọjá, lákokò àjọ náà, ọ̀pọ̀ ènìyàn gba orúkọ rẹ̀ gbọ́ nígbà tí wọ́n rí iṣẹ́ àmì tí ó ṣe.
ⲕ̅ⲅ̅ⲉϥⲭⲏ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϣⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡⲁⲥⲭⲁ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲁⲩⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲉⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲓⲙⲏⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲛⲁϥ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
24 Ṣùgbọ́n Jesu kò gbé ara lé wọn, nítorí tí ó mọ gbogbo ènìyàn.
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁϥⲧⲉⲛϩⲟⲩⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲉⲑⲃⲉϫⲉ ⲛⲁϥⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
25 Òun kò sì nílò ẹ̀rí nípa ènìyàn, nítorí tí o mọ̀ ohun tí ń bẹ nínú ènìyàn.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲉⲣ⳿ⲭⲣⲓⲁ ⲁⲛ ⲡⲉ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲁϥ ϧⲁ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲅⲁⲣ ⲛⲁϥⲥⲱⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉⲧϧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ

< John 2 >