< John 19 >

1 Nítorí náà ni Pilatu mú Jesu, ó sì nà án.
ܗܝܕܝܢ ܦܝܠܛܘܤ ܢܓܕܗ ܠܝܫܘܥ
2 Àwọn ọmọ-ogun sì hun adé ẹ̀gún, wọ́n sì fi dé e ní orí, wọ́n sì fi aṣọ ìgúnwà elése àlùkò wọ̀ ọ́.
ܘܐܤܛܪܛܝܘܛܐ ܓܕܠܘ ܟܠܝܠܐ ܡܢ ܟܘܒܐ ܘܤܡܘ ܠܗ ܒܪܫܗ ܘܟܤܝܘܗܝ ܢܚܬܐ ܕܐܪܓܘܢܐ
3 Wọ́n sì wí pé, “Kábíyèsí, ọba àwọn Júù!” Wọ́n sì fi ọwọ́ wọn gbá a ní ojú.
ܘܐܡܪܝܢ ܗܘܘ ܫܠܡ ܠܟ ܡܠܟܐ ܕܝܗܘܕܝܐ ܘܡܚܝܢ ܗܘܘ ܠܗ ܥܠ ܦܟܘܗܝ
4 Pilatu sì tún jáde, ó sì wí fún wọn pé, “Wò ó, mo mú u jáde tọ̀ yín wá, kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé, èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ rẹ̀.”
ܘܢܦܩ ܦܝܠܛܘܤ ܬܘܒ ܠܒܪ ܘܐܡܪ ܠܗܘܢ ܗܐ ܡܦܩ ܐܢܐ ܠܗ ܠܟܘܢ ܠܒܪ ܕܬܕܥܘܢ ܕܠܐ ܡܫܟܚ ܐܢܐ ܒܬܪܗ ܐܦܠܐ ܚܕܐ ܥܠܬܐ
5 Nítorí náà Jesu jáde wá, ti òun ti adé ẹ̀gún àti aṣọ elése àlùkò. Pilatu sì wí fún wọn pé, “Ẹ wò ọkùnrin náà!”
ܘܢܦܩ ܝܫܘܥ ܠܒܪ ܟܕ ܐܝܬ ܥܠܘܗܝ ܟܠܝܠܐ ܕܟܘܒܐ ܘܢܚܬܐ ܕܐܪܓܘܢܐ ܘܐܡܪ ܠܗܘܢ ܦܝܠܛܘܤ ܗܐ ܓܒܪܐ
6 Nítorí náà nígbà tí àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn oníṣẹ́ rí i, wọ́n kígbe wí pé, “Kàn án mọ́ àgbélébùú, kàn án mọ́ àgbélébùú.” Pilatu wí fún wọn pé, “Ẹ mú un fún ara yín, kí ẹ sì kàn án mọ́ àgbélébùú: nítorí èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.”
ܟܕ ܕܝܢ ܚܙܐܘܗܝ ܪܒܝ ܟܗܢܐ ܘܕܚܫܐ ܩܥܘ ܘܐܡܪܝܢ ܨܠܘܒܝܗܝ ܨܠܘܒܝܗܝ ܐܡܪ ܠܗܘܢ ܦܝܠܛܘܤ ܕܒܪܘ ܐܢܬܘܢ ܘܙܘܩܦܘܗܝ ܐܢܐ ܓܝܪ ܠܐ ܡܫܟܚ ܐܢܐ ܒܗ ܥܠܬܐ
7 Àwọn Júù dá a lóhùn wí pé, “Àwa ní òfin kan, àti gẹ́gẹ́ bí òfin, wa ó yẹ fún un láti kú, nítorí ó gbà pé Ọmọ Ọlọ́run ni òun ń ṣe.”
ܐܡܪܝܢ ܠܗ ܝܗܘܕܝܐ ܠܢ ܢܡܘܤܐ ܐܝܬ ܠܢ ܘܐܝܟ ܕܒܢܡܘܤܢ ܚܝܒ ܗܘ ܡܘܬܐ ܕܥܒܕ ܢܦܫܗ ܒܪܗ ܕܐܠܗܐ
8 Nítorí náà nígbà tí Pilatu gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀rù túbọ̀ bà á.
ܟܕ ܫܡܥ ܕܝܢ ܦܝܠܛܘܤ ܗܕܐ ܡܠܬܐ ܝܬܝܪܐܝܬ ܕܚܠ
9 Ó sì tún wọ inú gbọ̀ngàn ìdájọ́ lọ, ó sì wí fún Jesu pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Ṣùgbọ́n Jesu kò dá a lóhùn.
ܘܥܠ ܬܘܒ ܠܦܪܛܘܪܝܢ ܘܐܡܪ ܠܝܫܘܥ ܐܝܡܟܐ ܐܢܬ ܝܫܘܥ ܕܝܢ ܦܬܓܡܐ ܠܐ ܝܗܒ ܠܗ
10 Nítorí náà, Pilatu wí fún un pé, “Èmi ni ìwọ kò fọhùn sí? Ìwọ kò mọ̀ pé, èmi ní agbára láti dá ọ sílẹ̀, èmi sì ní agbára láti kàn ọ́ mọ́ àgbélébùú?”
ܐܡܪ ܠܗ ܦܝܠܛܘܤ ܥܡܝ ܠܐ ܡܡܠܠ ܐܢܬ ܠܐ ܝܕܥ ܐܢܬ ܕܫܠܝܛ ܐܢܐ ܕܐܫܪܝܟ ܘܫܠܝܛ ܐܢܐ ܕܐܙܩܦܟ
11 Jesu dá a lóhùn pé, “Ìwọ kì bá tí ní agbára kan lórí mi, bí kò ṣe pé a fi í fún ọ láti òkè wá, nítorí náà ẹni tí ó fi mí lé ọ lọ́wọ́ ni ó ní ẹ̀ṣẹ̀ pọ̀jù.”
ܐܡܪ ܠܗ ܝܫܘܥ ܠܝܬ ܗܘܐ ܠܟ ܥܠܝ ܫܘܠܛܢܐ ܐܦ ܠܐ ܚܕ ܐܠܘ ܠܐ ܝܗܝܒ ܗܘܐ ܠܟ ܡܢ ܠܥܠ ܡܛܠ ܗܢܐ ܗܘ ܡܢ ܕܐܫܠܡܢܝ ܠܟ ܪܒܐ ܗܝ ܚܛܝܬܗ ܡܢ ܕܝܠܟ
12 Nítorí èyí, Pilatu ń wá ọ̀nà láti dá a sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn Júù kígbe, wí pé, “Bí ìwọ bá dá ọkùnrin yìí sílẹ̀, ìwọ kì í ṣe ọ̀rẹ́ Kesari: ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ara rẹ̀ ní ọba, ó sọ̀rọ̀-òdì sí Kesari.”
ܘܡܛܠ ܗܕܐ ܨܒܐ ܗܘܐ ܦܝܠܛܘܤ ܕܢܫܪܝܘܗܝ ܝܗܘܕܝܐ ܕܝܢ ܩܥܝܢ ܗܘܘ ܕܐܢ ܠܗܢܐ ܫܪܐ ܐܢܬ ܠܐ ܗܘܝܬ ܪܚܡܗ ܕܩܤܪ ܟܠ ܡܢ ܓܝܪ ܕܢܦܫܗ ܡܠܟܐ ܥܒܕ ܤܩܘܒܠܐ ܗܘ ܕܩܤܪ
13 Nítorí náà nígbà tí Pilatu gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó mú Jesu jáde wá, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ ìdájọ́ ní ibi tí a ń pè ní Òkúta-títẹ́, ṣùgbọ́n ní èdè Heberu, Gabata.
ܟܕ ܫܡܥ ܕܝܢ ܦܝܠܛܘܤ ܗܕܐ ܡܠܬܐ ܐܦܩܗ ܠܝܫܘܥ ܠܒܪ ܘܝܬܒ ܥܠ ܒܝܡ ܒܕܘܟܬܐ ܕܡܬܩܪܝܐ ܪܨܝܦܬܐ ܕܟܐܦܐ ܥܒܪܐܝܬ ܕܝܢ ܡܬܐܡܪܐ ܓܦܝܦܬܐ
14 Ó jẹ́ ìpalẹ̀mọ́ àjọ ìrékọjá, ó sì jẹ́ ìwọ̀n wákàtí ẹ̀kẹfà: Ó sì wí fún àwọn Júù pé, “Ẹ wo ọba yín!”
ܘܥܪܘܒܬܐ ܗܘܬ ܕܦܨܚܐ ܘܐܝܬ ܗܘܝ ܐܝܟ ܫܥܐ ܫܬ ܘܐܡܪ ܠܝܗܘܕܝܐ ܗܐ ܡܠܟܟܘܢ
15 Nítorí náà wọ́n kígbe wí pé, “Mú un kúrò, mú un kúrò. Kàn án mọ́ àgbélébùú.” Pilatu wí fún wọn pé, “Èmi yóò ha kan ọba yín mọ́ àgbélébùú bí?” Àwọn olórí àlùfáà dáhùn wí pé, “Àwa kò ní ọba bí kò ṣe Kesari.”
ܗܢܘܢ ܕܝܢ ܩܥܝܢ ܗܘܘ ܫܩܘܠܝܗܝ ܫܩܘܠܝܗܝ ܨܠܘܒܝܗܝ ܨܠܘܒܝܗܝ ܐܡܪ ܠܗܘܢ ܦܝܠܛܘܤ ܠܡܠܟܟܘܢ ܐܙܩܘܦ ܐܡܪܝܢ ܪܒܝ ܟܗܢܐ ܠܝܬ ܠܢ ܡܠܟܐ ܐܠܐ ܐܢ ܩܤܪ
16 Nítorí náà ni Pilatu fà á lé wọn lọ́wọ́ láti kàn án mọ́ àgbélébùú. Àwọn ológun gba Jesu lọ́wọ́ Pilatu.
ܗܝܕܝܢ ܐܫܠܡܗ ܠܗܘܢ ܕܢܙܩܦܘܢܝܗܝ ܘܕܒܪܘܗܝ ܠܝܫܘܥ ܘܐܦܩܘܗܝ
17 Nítorí náà, wọ́n mú Jesu, ó sì jáde lọ, ó ru àgbélébùú fúnra rẹ̀ sí ibi tí à ń pè ní ibi agbárí, ní èdè Heberu tí à ń pè ní Gọlgọta.
ܟܕ ܫܩܝܠ ܙܩܝܦܗ ܠܕܘܟܬܐ ܕܡܬܩܪܝܐ ܩܪܩܦܬܐ ܥܒܪܐܝܬ ܕܝܢ ܡܬܐܡܪܐ ܓܓܘܠܬܐ
18 Níbi tí wọ́n gbé kàn án mọ́ àgbélébùú, àti àwọn méjì mìíràn pẹ̀lú rẹ̀, níhà ìhín àti níhà kejì, Jesu sì wà láàrín.
ܐܬܪ ܕܙܩܦܘܗܝ ܘܥܡܗ ܬܪܝܢ ܐܚܪܢܝܢ ܚܕ ܡܟܐ ܘܚܕ ܡܟܐ ܘܠܝܫܘܥ ܒܡܨܥܬܐ
19 Pilatu sì kọ ìwé kan pẹ̀lú, ó sì fi lé e lórí àgbélébùú náà. Ohun tí a sì kọ ni, Jesu ti Nasareti Ọba àwọn Júù.
ܘܟܬܒ ܐܦ ܠܘܚܐ ܦܝܠܛܘܤ ܘܤܡ ܥܠ ܙܩܝܦܗ ܟܬܝܒ ܗܘܐ ܕܝܢ ܗܟܢܐ ܗܢܐ ܝܫܘܥ ܢܨܪܝܐ ܡܠܟܐ ܕܝܗܘܕܝܐ
20 Nítorí náà, ọ̀pọ̀ àwọn Júù ni ó ka ìwé àkọlé yìí, nítorí ibi tí a gbé kan Jesu mọ́ àgbélébùú súnmọ́ etí ìlú, a sì kọ ọ́ ní èdè Heberu àti Latin, àti ti Giriki.
ܘܠܗܢܐ ܕܦܐ ܤܓܝܐܐ ܡܢ ܝܗܘܕܝܐ ܩܪܐܘܗܝ ܡܛܠ ܕܩܪܝܒܐ ܗܘܬ ܠܡܕܝܢܬܐ ܕܘܟܬܐ ܕܐܙܕܩܦ ܒܗ ܝܫܘܥ ܘܟܬܝܒܐ ܗܘܐ ܥܒܪܐܝܬ ܘܝܘܢܐܝܬ ܘܪܗܘܡܐܝܬ
21 Nítorí náà àwọn olórí àlùfáà àwọn Júù wí fún Pilatu pé, “Má ṣe kọ, ‘Ọba àwọn Júù,’ ṣùgbọ́n pé ọkùnrin yìí wí pé, èmi ni ọba àwọn Júù.”
ܘܐܡܪܘ ܪܒܝ ܟܗܢܐ ܠܦܝܠܛܘܤ ܠܐ ܬܟܬܘܒ ܕܡܠܟܐ ܗܘ ܕܝܗܘܕܝܐ ܐܠܐ ܕܗܘ ܐܡܪ ܕܡܠܟܐ ܐܢܐ ܕܝܗܘܕܝܐ
22 Pilatu dáhùn pé, ohun tí mo ti kọ, mo ti kọ ọ́.
ܐܡܪ ܦܝܠܛܘܤ ܡܕܡ ܕܟܬܒܬ ܟܬܒܬ
23 Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ogun, nígbà tí wọ́n kan Jesu mọ́ àgbélébùú tán, wọ́n mú aṣọ rẹ̀, wọ́n sì pín wọn sí ipa mẹ́rin, apá kan fún ọmọ-ogun kọ̀ọ̀kan, àti ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ náà kò ní ojúràn-án, wọ́n hun ún láti òkè títí jálẹ̀.
ܐܤܛܪܛܝܘܛܐ ܕܝܢ ܟܕ ܙܩܦܘܗܝ ܠܝܫܘܥ ܫܩܠܘ ܢܚܬܘܗܝ ܘܥܒܕܘ ܠܐܪܒܥ ܡܢܘܢ ܡܢܬܐ ܠܚܕ ܡܢ ܐܤܛܪܛܝܘܛܐ ܟܘܬܝܢܗ ܕܝܢ ܐܝܬܝܗ ܗܘܬ ܕܠܐ ܚܝܛܐ ܡܢ ܠܥܠ ܙܩܝܪܬܐ ܟܠܗ
24 Nítorí náà wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ẹ má jẹ́ kí a fà á ya, ṣùgbọ́n kí a ṣẹ́ gègé nítorí rẹ̀.” Ti ẹni tí yóò jẹ́: kí ìwé mímọ́ kí ó le ṣẹ, tí ó wí pé, “Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn, wọ́n sì ṣẹ́ gègé fún aṣọ ìlekè mi.” Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọmọ-ogun ṣe.
ܘܐܡܪܘ ܚܕ ܠܚܕ ܠܐ ܢܤܕܩܝܗ ܐܠܐ ܢܦܤ ܥܠܝܗ ܡܦܤ ܕܡܢܘ ܬܗܘܐ ܘܫܠܡ ܟܬܒܐ ܕܐܡܪ ܕܦܠܓܘ ܢܚܬܝ ܒܝܢܬܗܘܢ ܘܥܠ ܠܒܘܫܝ ܐܪܡܝܘ ܦܤܐ ܗܠܝܢ ܥܒܕܘ ܐܤܛܪܛܝܘܛܐ
25 Ìyá Jesu àti arábìnrin ìyá rẹ̀ Maria aya Kilopa, àti Maria Magdalene sì dúró níbi àgbélébùú,
ܩܝܡܢ ܗܘܝ ܕܝܢ ܠܘܬ ܙܩܝܦܗ ܕܝܫܘܥ ܐܡܗ ܘܚܬܗ ܕܐܡܗ ܘܡܪܝܡ ܗܝ ܕܩܠܝܘܦܐ ܘܡܪܝܡ ܡܓܕܠܝܬܐ
26 nígbà tí Jesu rí ìyá rẹ̀ àti ọmọ-ẹ̀yìn náà dúró, ẹni tí Jesu fẹ́ràn, ó wí fún ìyá rẹ̀ pé, “Obìnrin, wo ọmọ rẹ!”
ܝܫܘܥ ܕܝܢ ܚܙܐ ܠܐܡܗ ܘܠܬܠܡܝܕܐ ܗܘ ܕܪܚܡ ܗܘܐ ܕܩܐܡ ܘܐܡܪ ܠܐܡܗ ܐܢܬܬܐ ܗܐ ܒܪܟܝ
27 Lẹ́yìn náà ni ó sì wí fún ọmọ-ẹ̀yìn náà pé, “Wo ìyá rẹ!” Láti wákàtí náà lọ ni ọmọ-ẹ̀yìn náà sì ti mú un lọ sí ilé ara rẹ̀.
ܘܐܡܪ ܠܬܠܡܝܕܐ ܗܘ ܗܐ ܐܡܟ ܘܡܢ ܗܝ ܫܥܬܐ ܕܒܪܗ ܬܠܡܝܕܐ ܗܘ ܠܘܬܗ
28 Lẹ́yìn èyí, bí Jesu ti mọ̀ pé, a ti parí ohun gbogbo tán, kí ìwé mímọ́ bà á lè ṣẹ, ó wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ mí.”
ܒܬܪ ܗܠܝܢ ܝܕܥ ܝܫܘܥ ܕܟܠܡܕܡ ܐܫܬܠܡ ܘܕܢܬܡܠܐ ܟܬܒܐ ܐܡܪ ܨܗܐ ܐܢܐ
29 Ohun èlò kan tí ó kún fún ọtí kíkan wà níbẹ̀, wọ́n tẹ kànìnkànìn tí ó kún fún ọtí kíkan bọ inú rẹ̀, wọ́n sì fi lé orí igi hísópù, wọ́n sì nà án sí i lẹ́nu.
ܘܡܐܢܐ ܤܝܡ ܗܘܐ ܕܡܠܐ ܚܠܐ ܗܢܘܢ ܕܝܢ ܡܠܘ ܐܤܦܘܓܐ ܡܢ ܚܠܐ ܘܤܡܘ ܥܠ ܙܘܦܐ ܘܩܪܒܘ ܠܘܬ ܦܘܡܗ
30 Nígbà tí Jesu sì ti gba ọtí kíkan náà, ó wí pé, “Ó parí!” Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba, ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀.
ܟܕ ܕܝܢ ܫܩܠ ܗܘ ܚܠܐ ܝܫܘܥ ܐܡܪ ܗܐ ܡܫܠܡ ܘܐܪܟܢ ܪܫܗ ܘܐܫܠܡ ܪܘܚܗ
31 Nítorí ó jẹ́ ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́, kí òkú wọn má ba à wà lórí àgbélébùú ní ọjọ́ ìsinmi (nítorí ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ ìsinmi náà), nítorí náà, àwọn Júù bẹ Pilatu pé kí a ṣẹ́ egungun itan wọn, kí a sì gbé wọn kúrò.
ܝܗܘܕܝܐ ܕܝܢ ܡܛܠ ܕܥܪܘܒܬܐ ܗܘܬ ܐܡܪܝܢ ܠܐ ܢܒܘܬܘܢ ܦܓܪܐ ܗܠܝܢ ܥܠ ܙܩܝܦܝܗܘܢ ܡܛܠ ܕܫܒܬܐ ܢܓܗܐ ܝܘܡܐ ܗܘܐ ܓܝܪ ܪܒܐ ܝܘܡܐ ܕܫܒܬܐ ܗܝ ܘܒܥܘ ܡܢ ܦܝܠܛܘܤ ܕܢܬܒܪܘܢ ܫܩܝܗܘܢ ܕܗܢܘܢ ܙܩܝܦܐ ܘܢܚܬܘܢ ܐܢܘܢ
32 Nítorí náà, àwọn ọmọ-ogun wá, wọ́n sì ṣẹ́ egungun itan ti èkínní, àti ti èkejì, tí a kàn mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú rẹ̀.
ܘܐܬܘ ܐܤܛܪܛܝܘܛܐ ܘܬܒܪܘ ܫܩܘܗܝ ܕܩܕܡܝܐ ܘܕܗܘ ܐܚܪܢܐ ܕܐܙܕܩܦ ܥܡܗ
33 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Jesu, tí wọ́n sì rí i pé ó ti kú, wọn kò ṣẹ́ egungun itan rẹ̀,
ܘܟܕ ܐܬܘ ܠܘܬ ܝܫܘܥ ܚܙܘ ܕܡܝܬ ܠܗ ܡܢ ܟܕܘ ܘܠܐ ܬܒܪܘ ܫܩܘܗܝ
34 ṣùgbọ́n ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun náà fi ọ̀kọ̀ gún un lẹ́gbẹ̀ẹ́, lójúkan náà, ẹ̀jẹ̀ àti omi sì tú jáde.
ܐܠܐ ܚܕ ܡܢ ܐܤܛܪܛܝܘܛܐ ܡܚܝܗܝ ܒܕܦܢܗ ܒܠܘܟܝܬܐ ܘܡܚܕܐ ܢܦܩ ܕܡܐ ܘܡܝܐ
35 Ẹni tí ó rí sì jẹ́rìí, òtítọ́ sì ni ẹ̀rí rẹ̀, ó sì mọ̀ pé òtítọ́ ni òun sọ, kí ẹ̀yin ba à lè gbàgbọ́.
ܘܡܢ ܕܚܙܐ ܐܤܗܕ ܘܫܪܝܪܐ ܗܝ ܤܗܕܘܬܗ ܘܗܘ ܝܕܥ ܕܫܪܪܐ ܐܡܪ ܕܐܦ ܐܢܬܘܢ ܬܗܝܡܢܘܢ
36 Nǹkan wọ̀nyí ṣe, kí ìwé mímọ́ ba à lè ṣẹ, tí ó wí pé, “A kì yóò fọ́ egungun rẹ̀.”
ܗܠܝܢ ܓܝܪ ܗܘܝ ܕܢܬܡܠܐ ܟܬܒܐ ܕܐܡܪ ܕܓܪܡܐ ܠܐ ܢܬܬܒܪ ܒܗ
37 Ìwé mímọ́ mìíràn pẹ̀lú sì wí pé, “Wọn ó máa wo ẹni tí a gún lọ́kọ̀.”
ܘܬܘܒ ܟܬܒܐ ܐܚܪܢܐ ܕܐܡܪ ܕܢܚܘܪܘܢ ܒܡܢ ܕܕܩܪܘ
38 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ní Josẹfu ará Arimatea, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn Jesu, ní ìkọ̀kọ̀, nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù, o bẹ Pilatu kí òun lè gbé òkú Jesu kúrò, Pilatu sì fún un ní àṣẹ. Nígbà náà ni ó wá, ó sì gbé òkú Jesu lọ.
ܒܬܪ ܗܠܝܢ ܝܘܤܦ ܗܘ ܕܡܢ ܪܡܬܐ ܒܥܐ ܡܢ ܦܝܠܛܘܤ ܡܛܠ ܕܬܠܡܝܕܐ ܗܘܐ ܕܝܫܘܥ ܘܡܛܫܐ ܗܘܐ ܡܢ ܕܚܠܬܐ ܕܝܗܘܕܝܐ ܕܢܫܩܘܠ ܦܓܪܗ ܕܝܫܘܥ ܘܐܦܤ ܦܝܠܛܘܤ ܘܐܬܐ ܘܫܩܠ ܦܓܪܗ ܕܝܫܘܥ
39 Nikodemu pẹ̀lú sì wá, ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru lákọ̀ọ́kọ́, ó sì mú àdàpọ̀ òjìá àti aloe wá, ó tó ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún lita.
ܘܐܬܐ ܐܦ ܢܝܩܕܡܘܤ ܗܘ ܕܐܬܐ ܗܘܐ ܡܢ ܩܕܝܡ ܠܘܬ ܝܫܘܥ ܒܠܠܝܐ ܘܐܝܬܝ ܥܡܗ ܚܘܢܛܬܐ ܕܡܘܪܐ ܘܕܥܠܘܝ ܐܝܟ ܡܐܐ ܠܝܛܪܝܢ
40 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé òkú Jesu, wọ́n sì fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dì í pẹ̀lú tùràrí, gẹ́gẹ́ bí ìṣe àwọn Júù ti rí ní ìsìnkú wọn.
ܘܫܩܠܘܗܝ ܠܦܓܪܗ ܕܝܫܘܥ ܘܟܪܟܘܗܝ ܒܟܬܢܐ ܘܒܒܤܡܐ ܐܝܟܢܐ ܕܐܝܬ ܥܝܕܐ ܠܝܗܘܕܝܐ ܕܢܩܒܪܘܢ
41 Àgbàlá kan sì wà níbi tí a gbé kàn án mọ́ àgbélébùú; ibojì tuntun kan sì wà nínú àgbàlá náà, nínú èyí tí a kò tí ì tẹ́ ẹnìkan sí rí.
ܐܝܬ ܗܘܬ ܕܝܢ ܒܗܝ ܕܘܟܬܐ ܕܐܙܕܩܦ ܒܗ ܝܫܘܥ ܓܢܬܐ ܘܒܗ ܒܓܢܬܐ ܒܝܬ ܩܒܘܪܐ ܚܕܬܐ ܕܐܢܫ ܥܕܟܝܠ ܠܐ ܐܬܬܤܝܡ ܗܘܐ ܒܗ
42 Ǹjẹ́ níbẹ̀ ni wọ́n sì tẹ́ Jesu sí, nítorí ìpalẹ̀mọ́ àwọn Júù; àti nítorí ibojì náà wà nítòsí.
ܘܤܡܘܗܝ ܬܡܢ ܠܝܫܘܥ ܡܛܠ ܕܫܒܬܐ ܥܐܠܐ ܗܘܬ ܘܡܛܠ ܕܩܪܝܒ ܗܘܐ ܩܒܪܐ

< John 19 >