< John 18 >
1 Nígbà tí Jesu sì ti sọ nǹkan wọ̀nyí tán, ó jáde pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ lọ sókè odò Kidironi, níbi tí àgbàlá kan wà, nínú èyí tí ó wọ̀, Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
To když pověděl Ježíš, vyšel s učedlníky svými přes potok Cedron, kdež byla zahrada; do kteréžto všel on i učedlníci jeho.
2 Judasi, ẹni tí ó fihàn, sì mọ ibẹ̀ pẹ̀lú, nítorí nígbà púpọ̀ ni Jesu máa ń lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Věděl pak i Jidáš, zrádce jeho, to místo; nebo často chodíval tam Ježíš s učedlníky svými.
3 Nígbà náà ni Judasi, lẹ́yìn tí ó ti gba ẹgbẹ́ ọmọ-ogun, àti àwọn oníṣẹ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi wá síbẹ̀ ti àwọn ti fìtílà àti ògùṣọ̀, àti ohun ìjà.
Protož Jidáš pojav s sebou zástup, a od předních kněží a farizeů služebníky, přišel tam s lucernami a s pochodněmi a s zbrojí.
4 Nítorí náà bí Jesu ti mọ ohun gbogbo tí ń bọ̀ wá bá òun, ó jáde lọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ta ni ẹyin ń wá?”
Ježíš pak věda všecko, což přijíti mělo na něj, vyšed proti nim, řekl jim: Koho hledáte?
5 Wọ́n sì dá a lóhùn wí pé, “Jesu ti Nasareti.” Jesu sì wí fún wọn pé, “Èmi nìyí.” (Àti Judasi ọ̀dàlẹ̀, dúró pẹ̀lú wọn).
Odpověděli jemu: Ježíše Nazaretského. Řekl jim Ježíš: Jáť jsem. Stál pak s nimi i Jidáš, zrádce jeho.
6 Nítorí náà bí ó ti wí fún wọn pé, “Èmi nìyí,” wọ́n bì sẹ́yìn, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀.
A jakž řekl jim: Já jsem, postoupili nazpět, a padli na zem.
7 Nítorí náà ó tún bi wọ́n léèrè, wí pé, “Ta ni ẹ ń wá?” Wọ́n sì wí pé, “Jesu ti Nasareti.”
I otázal se jich opět: Koho hledáte? A oni řekli: Ježíše Nazaretského.
8 Jesu dáhùn pé, “Mo ti wí fún yín pé, èmi nìyí. Ǹjẹ́ bí èmi ni ẹ bá ń wá, ẹ jẹ́ kí àwọn wọ̀nyí máa lọ.”
Odpověděl Ježíš: Pověděl jsem vám, že já jsem. Poněvadž tedy mne hledáte, nechtež těchto, ať odejdou.
9 Kí ọ̀rọ̀ nì kí ó lè ṣẹ, èyí tó wí pé, “Àwọn tí ìwọ fi fún mi, èmi kò sọ ọ̀kan nù nínú wọn.”
Aby se naplnila řeč, kterouž byl pověděl: Že které jsi mi dal, neztratil jsem z nich žádného.
10 Nígbà náà ni Simoni Peteru ẹni tí ó ní idà, fà á yọ, ó sì ṣá ọmọ ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, ó sì ké etí ọ̀tún rẹ̀ sọnù. Orúkọ ìránṣẹ́ náà a máa jẹ́ Makọọsi.
Tedy Šimon Petr, maje meč, vytrhl jej a udeřil služebníka nejvyššího kněze a uťal mu ucho jeho pravé. A bylo jméno služebníka toho Malchus.
11 Nítorí náà Jesu wí fún Peteru pé, “Tẹ idà rẹ bọ inú àkọ̀ rẹ, ago tí baba ti fi fún mi, èmi ó ṣe aláìmu ún bí?”
I řekl Ježíš Petrovi: Schovej meč svůj do pošvy. Což nemám píti kalicha, kterýž mi dal Otec?
12 Nígbà náà ni ẹgbẹ́ ọmọ-ogun àti olórí ẹ̀ṣọ́, àti àwọn oníṣẹ́ àwọn Júù mú Jesu, wọ́n sì dè é.
Tedy zástup a hejtman a služebníci Židovští jali Ježíše, a svázali jej.
13 Wọ́n kọ́kọ́ fà á lọ sọ́dọ̀ Annasi; nítorí òun ni àna Kaiafa, ẹni tí í ṣe olórí àlùfáà ní ọdún náà.
A vedli ho k Annášovi nejprve; nebo byl test Kaifášův, kterýž byl nejvyšším knězem toho léta.
14 Kaiafa sá à ni ẹni tí ó ti bá àwọn Júù gbìmọ̀ pé, ó ṣàǹfààní kí ènìyàn kan kú fún àwọn ènìyàn.
Kaifáš pak byl ten, kterýž byl radu dal Židům, že by užitečné bylo, aby člověk jeden umřel za lid.
15 Simoni Peteru sì ń tọ Jesu lẹ́yìn, àti ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn kan: ọmọ-ẹ̀yìn náà jẹ́ ẹni mí mọ̀ fún olórí àlùfáà, ó sì bá Jesu wọ ààfin olórí àlùfáà lọ.
Šel pak za Ježíšem Šimon Petr a jiný učedlník. A ten učedlník byl znám nejvyššímu knězi, i všel s Ježíšem do síně nejvyššího kněze.
16 Ṣùgbọ́n Peteru dúró ní ẹnu-ọ̀nà lóde. Nígbà náà ni ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn náà tí í ṣe ẹni mí mọ̀ fún olórí àlùfáà jáde, ó sì bá olùṣọ́nà náà sọ̀rọ̀, ó sì mú Peteru wọlé.
Ale Petr stál u dveří vně. I vyšel ten druhý učedlník, kterýž byl znám nejvyššímu knězi, a promluvil s vrátnou, i uvedl tam Petra.
17 Nígbà náà ni ọmọbìnrin náà tí ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà wí fún Peteru pé, “Ìwọ pẹ̀lú ha ń ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ọkùnrin yìí bí?” Ó wí pé, “Èmi kọ́.”
Tedy řekla Petrovi děvečka vrátná: Nejsi-liž i ty z učedlníků člověka toho? Řekl on: Nejsem.
18 Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ àti àwọn aláṣẹ sì dúró níbẹ̀, àwọn ẹni tí ó ti dáná nítorí ti òtútù mú, wọ́n sì ń yáná, Peteru sì dúró pẹ̀lú wọn, ó ń yáná.
Stáli pak tu služebníci a pacholci, kteříž oheň udělali, nebo zima bylo, i zhřívali se. A byl s nimi také i Petr, stoje tu a zhřívaje se.
19 Nígbà náà ni olórí àlùfáà bi Jesu léèrè ní ti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ní ti ẹ̀kọ́ rẹ̀.
Tedy nejvyšší kněz tázal se Ježíše o učedlnících jeho a o učení jeho.
20 Jesu dá a lóhùn pé, “Èmi ti sọ̀rọ̀ ní gbangba fún aráyé; nígbà gbogbo ni èmi ń kọ́ni nínú Sinagọgu, àti ní tẹmpili níbi tí gbogbo àwọn Júù ń péjọ sí, èmi kò sì sọ ohun kan ní ìkọ̀kọ̀.
Odpověděl jemu Ježíš: Já zjevně mluvil jsem světu, já vždycky učíval jsem v škole a v chrámě, kdežto se odevšad Židé scházejí, a tajně jsem nic nemluvil,
21 Èéṣe tí ìwọ fi ń bi mí léèrè? Béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ó ti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, ohun tí mo wí fún wọn: wò ó, àwọn wọ̀nyí mọ ohun tí èmi wí.”
Co se mne ptáš? Ptej se těch, kteříž mne slýchali, co jsem jim mluvil. Aj, tiť vědí, co jsem já mluvil.
22 Bí ó sì ti wí èyí tan, ọ̀kan nínú àwọn aláṣẹ tí ó dúró tì í fi ọwọ́ rẹ̀ lu Jesu, pé, “Alábojútó àlùfáà ni ìwọ ń dá lóhùn bẹ́ẹ̀?”
A když on to pověděl, jeden z služebníků, stoje tu, dal poliček Ježíšovi, řka: Tak-liž odpovídáš nejvyššímu knězi?
23 Jesu dá a lóhùn pé, “Bí mo bá sọ̀rọ̀ búburú, jẹ́rìí sí búburú náà, ṣùgbọ́n bí rere bá ni, èéṣe tí ìwọ fi ń lù mí?”
Odpověděl mu Ježíš: Mluvil-li jsem zle, svědectví vydej o zlém; pakli dobře, proč mne tepeš?
24 Nítorí Annasi rán an lọ ní dídè sọ́dọ̀ Kaiafa olórí àlùfáà.
I poslal jej Annáš svázaného k Kaifášovi nejvyššímu knězi.
25 Ṣùgbọ́n Simoni Peteru dúró, ó sì ń yáná. Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú ha jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀?” Ó sì sẹ́, wí pé, “Èmi kọ́.”
Stál pak Šimon Petr, a zhříval se. Tedy řekli jemu: Nejsi-liž i ty z učedlníků jeho? Zapřel on a řekl: Nejsem.
26 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, tí ó jẹ́ ìbátan ẹni tí Peteru gé etí rẹ̀ sọnù, wí pé, “Èmi ko ha rí ọ pẹ̀lú rẹ̀ ní àgbàlá?”
Dí jemu jeden z služebníků nejvyššího kněze, příbuzný toho, kterémuž Petr uťal ucho: Zdaž jsem já tebe neviděl s ním v zahradě?
27 Peteru tún sẹ́: lójúkan náà àkùkọ sì kọ.
Tedy Petr opět zapřel. A hned kohout zazpíval.
28 Nígbà náà, wọ́n fa Jesu láti ọ̀dọ̀ Kaiafa lọ sí ibi gbọ̀ngàn ìdájọ́, ó sì jẹ́ kùtùkùtù òwúrọ̀; àwọn tìkára wọn kò wọ inú gbọ̀ngàn ìdájọ́, kí wọn má ṣe di aláìmọ́, ṣùgbọ́n kí wọn lè jẹ àsè ìrékọjá.
I vedli Ježíše od Kaifáše do radného domu, a bylo ráno. Oni pak nevešli do radného domu, aby se neposkvrnili, ale aby jedli beránka.
29 Nítorí náà Pilatu jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí pé, “Ẹ̀sùn kín ní ẹ̀yin mú wá fun ọkùnrin yìí?”
Tedy vyšel k nim Pilát ven a řekl: Jakou žalobu vedete proti člověku tomuto?
30 Wọ́n sì dáhùn wí fún un pé, “Ìbá má ṣe pé ọkùnrin yìí ń hùwà ibi, a kì bá tí fà á lé ọ lọ́wọ́.”
Odpověděli a řekli jemu: Byť tento nebyl zločinec, nedali bychom ho tobě.
31 Nítorí náà Pilatu wí fún wọn pé, “Ẹ mú un tìkára yín, kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òfin yín.” Nítorí náà ni àwọn Júù wí fún un pé, “Kò tọ́ fún wa láti pa ẹnikẹ́ni.”
I řekl jim Pilát: Vezměte vy jej, a podle Zákona vašeho suďte ho. I řekli mu Židé: Námť nesluší zabíti žádného.
32 Kí ọ̀rọ̀ Jesu ba à lè ṣẹ, èyí tí ó sọ tí ó ń ṣàpẹẹrẹ irú ikú tí òun yóò kú.
Aby se řeč Ježíšova naplnila, kterouž řekl, znamenaje, kterou by smrtí měl umříti.
33 Nítorí náà, Pilatu tún wọ inú gbọ̀ngàn ìdájọ́ lọ, ó sì pe Jesu, ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ha ni a pè ni ọba àwọn Júù bí?”
Tedy Pilát všel opět do radného domu, i povolal Ježíše a řekl jemu: Ty-li jsi Král Židovský?
34 Jesu dáhùn pé, “Èrò ti ara rẹ ni èyí, tàbí àwọn ẹlòmíràn sọ ọ́ fún ọ nítorí mi?”
Odpověděl Ježíš: Sám-li od sebe to pravíš, čili jiní tobě pověděli o mně?
35 Pilatu dáhùn wí pé, “Èmi ha jẹ́ Júù bí? Àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè rẹ, àti àwọn olórí àlùfáà ni ó fà ọ́ lé èmi lọ́wọ́, kín ní ìwọ ṣe?”
Odpověděl Pilát: Zdaliž jsem já Žid? Národ tvůj a přední kněží dali mi tebe. Co jsi učinil?
36 Jesu dáhùn wí pé, “Ìjọba mi kì í ṣe ti ayé yìí. Ìbá ṣe pé ìjọba mi jẹ́ ti ayé yìí, àwọn ìránṣẹ́ mi ìbá jà, kí a má ba à fi mí lé àwọn Júù lọ́wọ́, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìjọba mi kì í ṣe láti ìhín lọ.”
Odpověděl Ježíš: Království mé není z tohoto světa. Byť z tohoto světa bylo království mé, služebníci moji bránili by mne, abych nebyl vydán Židům. Ale nyní mé království není odsud.
37 Nítorí náà, Pilatu wí fún un pé, “Ọba ni ọ́ nígbà náà?” Jesu dáhùn wí pé, “Ìwọ wí pé, ọba ni èmi jẹ́. Nítorí èyí ni a ṣe bí mí, àti nítorí ìdí èyí ni mo sì ṣe wá sí ayé kí n lè jẹ́rìí sí òtítọ́, olúkúlùkù ẹni tí í ṣe ti òtítọ́ ń gbọ́ ohùn mi.”
I řekl jemu Pilát: Tedy král jsi ty? Dí Ježíš: Ty pravíš, že já král jsem. Jáť jsem se k tomu narodil, a proto jsem na svět přišel, abych svědectví vydal pravdě. Každý, kdož jest z pravdy, slyší hlas můj.
38 Pilatu wí fún un pé, “Kín ni òtítọ́?” Nígbà tí ó sì ti wí èyí tan, ó tún jáde tọ àwọn Júù lọ, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kan lọ́wọ́ rẹ̀.
Dí jemu Pilát: Co jest pravda? A když to řekl, opět vyšel k Židům, a dí jim: Já na něm žádné viny nenalézám.
39 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ní àṣà kan pé, kí èmi dá ọ̀kan sílẹ̀ fún yín nígbà àjọ ìrékọjá, nítorí náà ẹ ó ha fẹ́ kí èmi dá ọba àwọn Júù sílẹ̀ fún yín bí?”
Ale jest obyčej váš, abych vám propustil jednoho vězně na velikunoc. Chcete-liž tedy, ať vám propustím Krále Židovského?
40 Nítorí náà gbogbo wọn tún kígbe pé, “Kì í ṣe ọkùnrin yìí, bí kò ṣe Baraba!” Ọlọ́ṣà sì ni Baraba.
I zkřikli opět všickni, řkouce: Ne toho, ale Barabbáše. Byl pak Barabbáš lotr.