< John 16 >

1 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí a má ba à mú yín yapa kúrò.
Tomci wam powiedział, abyście się nie gorszyli.
2 Wọ́n ó yọ yín kúrò nínú Sinagọgu: àní, àkókò ń bọ̀, tí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa yín, yóò rò pé òun ń ṣe ìsìn fún Ọlọ́run.
Wyłączać was będą z bóżnic; owszem przyjdzie godzina, że wszelki, który was zabije, będzie mniemał, że Bogu posługę czyni.
3 Nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ó sì ṣe, nítorí tí wọn kò mọ Baba, wọn kò sì mọ̀ mí.
A toć wam uczynią, iż nie poznali Ojca ani mnie.
4 Ṣùgbọ́n nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, pé nígbà tí wákàtí wọn bá dé, kí ẹ lè rántí wọn pé mo ti wí fún yín. Ṣùgbọ́n èmi kò sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá, nítorí tí mo wà pẹ̀lú yín.
Alemci wam to powiedział, abyście gdy przyjdzie ta godzina, wspomnieli na to, żem ja wam opowiedział; a tegom wam z początku nie powiadał, bom był z wami.
5 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ń lọ sọ́dọ̀ ẹni tí ó rán mi; kò sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó bi mí lérè pé, ‘Níbo ni ìwọ ń lọ?’
Lecz teraz idę do onego, który mię posłał, a żaden z was nie pyta mię: Dokąd idziesz?
6 Ṣùgbọ́n nítorí mo sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín, ìbìnújẹ́ kún ọkàn yín.
Ale żem wam to powiedział, smutek napełnił serce wasze.
7 Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni èmi ń sọ fún yín; àǹfààní ni yóò jẹ́ fún yín bí èmi bá lọ, nítorí bí èmi kò bá lọ, Olùtùnú kì yóò tọ̀ yín wá; ṣùgbọ́n bí mo bá lọ, èmi ó rán an sí yín.
Lecz ja wam prawdę mówię, wamci to pożyteczno, abym ja odszedł; bo jeźli ja nie odejdę, pocieszyciel on nie przyjdzie do was, a jeźli odejdę, poślę go do was.
8 Nígbà tí òun bá sì dé, yóò fi òye yé aráyé ní ti ẹ̀ṣẹ̀, àti ní ti òdodo, àti ní ti ìdájọ́,
A on przyszedłszy, będzie karał świat z grzechu i z sprawiedliwości, i z sądu;
9 ní ti ẹ̀ṣẹ̀, nítorí tí wọn kò gbà mí gbọ́;
Z grzechu mówię, iż nie uwierzyli we mnie;
10 ní ti òdodo, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba, ẹ̀yin kò sì mọ̀ mí.
Z sprawiedliwości zasię, iż do Ojca mego idę, a już mnie więcej nie ujrzycie;
11 Ní ti ìdájọ́, nítorí tí a ti ṣe ìdájọ́ ọmọ-aládé ayé yìí.
Z sądu, iż książę tego świata już jest osądzony.
12 “Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ fún yín pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ẹ kò lè gbà wọ́n nísinsin yìí.
Mamci wam jeszcze wiele mówić, ale teraz znieść nie możecie.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun, àní Ẹ̀mí òtítọ́ náà bá dé, yóò tọ́ yín sí ọ̀nà òtítọ́ gbogbo, nítorí kì yóò sọ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó bá gbọ́, òun ni yóò máa sọ, yóò sì sọ ohun tí ń bọ̀ fún yín.
Lecz gdy przyjdzie on Duch prawdy, wprowadzi was we wszelką prawdę; bo nie sam od siebie mówić będzie, ale cokolwiek usłyszy, mówić będzie, i przyszłe rzeczy wam opowie.
14 Òun ó máa yìn mí lógo, nítorí tí yóò gbà nínú ti èmi, yóò sì máa sọ ọ́ fún yín.
On mię uwielbi; bo z mego weźmie, a opowie wam.
15 Ohun gbogbo tí Baba ní tèmi ni, nítorí èyí ni mo ṣe wí pé, òun ó gba nínú tèmi, yóò sì sọ ọ́ fún yín.
Wszystko, co ma Ojciec, moje jest; dlategom rzekł: Że z mego weźmie, a wam opowie.
16 “Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ ó sì rí mi, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.”
Maluczko, a nie ujrzycie mię, i zasię maluczko, a ujrzycie mię; bo ja idę do Ojca.
17 Nítorí náà díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bá ara wọn sọ pé, “Kín ni èyí tí o wí fún wa yìí, ‘Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ ẹ̀wẹ̀, ẹ̀yin kì yóò rí mi, àti, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba’?”
Mówili tedy niektórzy z uczniów jego między sobą: Cóż to jest, co nam mówi: Maluczko, a nie ujrzycie mię, i zasię maluczko, a ujrzycie mię, a iż ja idę do Ojca?
18 Nítorí náà wọ́n wí pé, kín ni, nígbà díẹ̀? Àwa kò mọ̀ ohun tí ó wí.
Przetoż mówili: Cóż to jest, co mówi: Maluczko? Nie wiemy, co mówi.
19 Jesu sá à ti mọ̀ pé, wọ́n ń fẹ́ láti bi òun léèrè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ń bi ara yín léèrè ní ti èyí tí mo wí pé, nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ̀yin ó sì rí mi?
Tedy Jezus poznał, że go pytać chcieli, i rzekł im: O tem się pytacie między sobą, żem rzekł: Maluczko, a nie ujrzycie mię, i zasię maluczko, a ujrzycie mię.
20 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ẹ̀yin yóò máa sọkún ẹ ó sì máa pohùnréré ẹkún, ṣùgbọ́n àwọn aráyé yóò máa yọ̀: ṣùgbọ́n, ìbànújẹ́ yín yóò di ayọ̀.
Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Że wy będziecie płakać i narzekać, a świat się będzie weselił; wy smutni będziecie, ale smutek wasz obróci się wam w wesele.
21 Nígbà tí obìnrin bá ń rọbí, a ní ìbìnújẹ́, nítorí tí wákàtí rẹ̀ dé: ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá ti bí ọmọ náà tán, òun kì í sì í rántí ìrora náà mọ́, fún ayọ̀ nítorí a bí ènìyàn sí ayé.
Niewiasta gdy rodzi, smutek ma, bo przyszła godzina jej; lecz gdy porodzi dzieciątko, już nie pamięta uciśnienia, dla radości, iż się człowiek na świat narodził.
22 Nítorí náà ẹ̀yin ní ìbànújẹ́ nísinsin yìí, ṣùgbọ́n èmi ó tún rí yín, ọkàn yín yóò sì yọ̀, kò sì sí ẹni tí yóò gba ayọ̀ yín lọ́wọ́ yín.
I wy teraz smutek macie; ale zasię ujrzę was, a będzie się radowało serce wasze, a radości waszej nikt nie odejmie od was.
23 Àti ní ọjọ́ náà ẹ̀yin kì ó bi mí lérè ohunkóhun. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, òhun ó fi fún yín.
A dnia onego nie będziecie mnie o nic pytać. Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: O cokolwiek byście prosili Ojca w imieniu mojem, da wam.
24 Títí di ìsinsin yìí ẹ kò tí ì béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, ẹ béèrè, ẹ ó sì rí gbà, kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
Dotąd o niceście nie prosili w imieniu mojem; proścież, a weźmiecie, aby radość wasza była doskonała.
25 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo fi òwe sọ fún yín: ṣùgbọ́n àkókò dé, nígbà tí èmi kì yóò fi òwe bá yín sọ̀rọ̀ mọ́, ṣùgbọ́n èmi ó sọ nípa ti Baba fún yín gbangba.
Tomci wam przez przypowieść mówił; ale idzie godzina, gdy już dalej nie przez przypowieści mówić wam będę, ale jawnie o Ojcu moim oznajmię wam.
26 Ní ọjọ́ náà, ẹ̀yin ó béèrè ní orúkọ mi, èmi kò sì wí fún yín pé, èmi ó béèrè lọ́wọ́ Baba fún yín.
W on dzień w imieniu mojem prosić będziecie; a nie mówię wam: Iż ja będę Ojca prosił za wami;
27 Nítorí tí Baba tìkára rẹ̀ fẹ́ràn yín, nítorí tí ẹ̀yin ti fẹ́ràn mi, ẹ sì ti gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni èmi ti jáde wá.
Albowiem sam Ojciec miłuje was, żeście wy mię umiłowali i uwierzyliście, żem ja od Boga przyszedł.
28 Mo ti ọ̀dọ̀ Baba jáde wá, mo sì wá sí ayé, àti nísinsin yìí mo fi ayé sílẹ̀, mo sì lọ sọ́dọ̀ Baba.”
Wyszedłem od Ojca, a przyszedłem na świat; i zasię opuszczam świat, a idę do Ojca.
29 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Wò ó, nígbà yìí ni ìwọ ń sọ̀rọ̀ gbangba, ìwọ kò sì sọ ohunkóhun ní òwe.
Rzekli mu uczniowie jego: Oto teraz jawnie mówisz, a żadnej przypowieści nie powiadasz;
30 Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé, ìwọ mọ̀ ohun gbogbo, ìwọ kò ní kí a bi ọ́ léèrè: nípa èyí ni àwa gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ìwọ ti jáde wá.”
Teraz wiemy, że wszystko wiesz, a nie potrzebujesz, aby cię kto pytał; przez to wierzymy, żeś od Boga wyszedł.
31 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin gbàgbọ́ wàyí?
Odpowiedział im Jezus: Teraz wierzycie.
32 Kíyèsi i, wákàtí ń bọ̀, àní ó dé tan nísinsin yìí, tí a ó fọ́n yín ká kiri, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀; ẹ ó sì fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò sì ṣe èmi nìkan, nítorí tí Baba ń bẹ pẹ̀lú mi.
Oto przyjdzie godzina; owszem już przyszła, że się rozproszycie każdy do swego, a mię samego zostawicie; lecz nie jestem sam, bo Ojciec jest ze mną.
33 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹ̀yin ó ní ìpọ́njú; ṣùgbọ́n ẹ tújúká; mo ti ṣẹ́gun ayé.”
Tomci wam powiedział, abyście we mnie pokój mieli. Na świecie ucisk mieć będziecie; ale ufajcie, jam zwyciężył świat.

< John 16 >