< John 16 >

1 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí a má ba à mú yín yapa kúrò.
Dette har jeg sagt til dere for at dere ikke skal miste troen på meg.
2 Wọ́n ó yọ yín kúrò nínú Sinagọgu: àní, àkókò ń bọ̀, tí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa yín, yóò rò pé òun ń ṣe ìsìn fún Ọlọ́run.
Dere kommer til å bli ekskludert fra Den jødiske menigheten, ja, det skal gå så langt at de som dreper dere, tror at de tjener Gud ved handlingene sine.
3 Nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ó sì ṣe, nítorí tí wọn kò mọ Baba, wọn kò sì mọ̀ mí.
Denne tragiske misforståelsen beror på at de aldri har lært å kjenne min Far i himmelen, og heller ikke meg.
4 Ṣùgbọ́n nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, pé nígbà tí wákàtí wọn bá dé, kí ẹ lè rántí wọn pé mo ti wí fún yín. Ṣùgbọ́n èmi kò sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá, nítorí tí mo wà pẹ̀lú yín.
Jeg sier dere dette nå, for at dere den dagen det skjer, skal huske at jeg advarte dere. Jeg har ikke sagt dette til dere tidligere siden jeg inntil nå har vært hos dere.”
5 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ń lọ sọ́dọ̀ ẹni tí ó rán mi; kò sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó bi mí lérè pé, ‘Níbo ni ìwọ ń lọ?’
Jesus fortsatte:”Nå går jeg til ham som har sendt meg, og ingen av dere spør hvor jeg går.
6 Ṣùgbọ́n nítorí mo sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín, ìbìnújẹ́ kún ọkàn yín.
Dere er altfor bedrøvet og fulle av sorg over det jeg har fortalt dere.
7 Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni èmi ń sọ fún yín; àǹfààní ni yóò jẹ́ fún yín bí èmi bá lọ, nítorí bí èmi kò bá lọ, Olùtùnú kì yóò tọ̀ yín wá; ṣùgbọ́n bí mo bá lọ, èmi ó rán an sí yín.
Sannheten er at det er best for dere at jeg går bort, for ellers kan ikke Hjelperen, Guds Ånd, komme til dere. Når jeg har gått bort, skal jeg sende ham til dere.
8 Nígbà tí òun bá sì dé, yóò fi òye yé aráyé ní ti ẹ̀ṣẹ̀, àti ní ti òdodo, àti ní ti ìdájọ́,
Når Guds Ånd kommer, skal han vise menneskene at de er syndere, at jeg er skyldfri innfor Gud og at Guds dom vil ramme.
9 ní ti ẹ̀ṣẹ̀, nítorí tí wọn kò gbà mí gbọ́;
Syndere er de fordi de ikke tror på meg.
10 ní ti òdodo, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba, ẹ̀yin kò sì mọ̀ mí.
At jeg er skyldfri innfor Gud viser seg ved at Far i himmelen opphøyer meg til å regjere med ham, slik at dere ikke kan se meg mer.
11 Ní ti ìdájọ́, nítorí tí a ti ṣe ìdájọ́ ọmọ-aládé ayé yìí.
Guds dom rammer hver og en som gjør synd, det forstår vi når vi ser at Gud har dømt Satan, som er høvding i denne verden.
12 “Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ fún yín pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ẹ kò lè gbà wọ́n nísinsin yìí.
Det er mye jeg ennå ville si dere, men dere kan ikke forstå det nå.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun, àní Ẹ̀mí òtítọ́ náà bá dé, yóò tọ́ yín sí ọ̀nà òtítọ́ gbogbo, nítorí kì yóò sọ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó bá gbọ́, òun ni yóò máa sọ, yóò sì sọ ohun tí ń bọ̀ fún yín.
Når Guds Ånd kommer, skal han vise dere hele sannheten om Gud. Han vil ikke holde fram sine egne tanker, men fortelle det han hører av meg. Han vil la dere få kjennskap til det som kommer til å skje i framtiden.
14 Òun ó máa yìn mí lógo, nítorí tí yóò gbà nínú ti èmi, yóò sì máa sọ ọ́ fún yín.
Videre vil han opphøye og ære meg, for alt han lar dere få vite, har han fått fra meg.
15 Ohun gbogbo tí Baba ní tèmi ni, nítorí èyí ni mo ṣe wí pé, òun ó gba nínú tèmi, yóò sì sọ ọ́ fún yín.
Alt som min Far i himmelen har, det tilhører meg. Derfor kan jeg si at alt Guds Ånd lar dere få vite, har han fått fra meg.
16 “Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ ó sì rí mi, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.”
Snart ser dere meg ikke lenger. Like plutselig skal dere få se meg igjen.”
17 Nítorí náà díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bá ara wọn sọ pé, “Kín ni èyí tí o wí fún wa yìí, ‘Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ ẹ̀wẹ̀, ẹ̀yin kì yóò rí mi, àti, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba’?”
Noen av disiplene spurte da hverandre:”Hva mener han egentlig når han sier at vi snart ikke skal se ham lenger. Og at vi like plutselig skal få se ham igjen? Hva kan det bety når han sier at han går til sin Far i himmelen? Hvor snart skal dette skje? Vi fatter ingenting av det han sier.”
18 Nítorí náà wọ́n wí pé, kín ni, nígbà díẹ̀? Àwa kò mọ̀ ohun tí ó wí.
19 Jesu sá à ti mọ̀ pé, wọ́n ń fẹ́ láti bi òun léèrè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ń bi ara yín léèrè ní ti èyí tí mo wí pé, nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ̀yin ó sì rí mi?
Jesus visste at de ville spørre ham, og sa:”Dere undrer dere på hva jeg mente da jeg sa at dere ganske snart ikke skulle se meg lenger? Og at dere like snart skal få se meg igjen.
20 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ẹ̀yin yóò máa sọkún ẹ ó sì máa pohùnréré ẹkún, ṣùgbọ́n àwọn aráyé yóò máa yọ̀: ṣùgbọ́n, ìbànújẹ́ yín yóò di ayọ̀.
Ja, jeg forsikrer dere at dere kommer å gråte og klage over det som skal skje med meg, men mange skal bli glade. Dere skal sørge, men sorgen vil bli vendt til glede når dere ser meg igjen.
21 Nígbà tí obìnrin bá ń rọbí, a ní ìbìnújẹ́, nítorí tí wákàtí rẹ̀ dé: ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá ti bí ọmọ náà tán, òun kì í sì í rántí ìrora náà mọ́, fún ayọ̀ nítorí a bí ènìyàn sí ayé.
Det blir som når en kvinne føder sitt barn. Mens forløsningen står på, har hun det smertefullt. Men når hun har født sitt barn, glemmer hun smerten og gleder seg bare over at et lite menneske er blitt født til verden.
22 Nítorí náà ẹ̀yin ní ìbànújẹ́ nísinsin yìí, ṣùgbọ́n èmi ó tún rí yín, ọkàn yín yóò sì yọ̀, kò sì sí ẹni tí yóò gba ayọ̀ yín lọ́wọ́ yín.
Dere har det også vanskelig nettopp nå, men jeg skal treffe dere igjen, og da skal dere bli glade. Ingen kan ta fra dere den gleden.
23 Àti ní ọjọ́ náà ẹ̀yin kì ó bi mí lérè ohunkóhun. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, òhun ó fi fún yín.
Den dagen trenger ingen å spørre meg om noe som helst. Jeg forsikrer dere at fra den dagen skal Far i himmelen gi dere alt dere ber om fordi dere tilhører meg.
24 Títí di ìsinsin yìí ẹ kò tí ì béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, ẹ béèrè, ẹ ó sì rí gbà, kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
Dere har bedt før, men aldri fordi dere tilhørte meg. Nå skal dere be i mitt navn, og dere skal få. Gleden deres skal bli full og hel.
25 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo fi òwe sọ fún yín: ṣùgbọ́n àkókò dé, nígbà tí èmi kì yóò fi òwe bá yín sọ̀rọ̀ mọ́, ṣùgbọ́n èmi ó sọ nípa ti Baba fún yín gbangba.
Alt dette har jeg fortalt dere i bilder, men det kommer en tid da jeg vil snakke åpent og klart til dere uten bilder. Da skal dere få vite mer om min Far i himmelen.
26 Ní ọjọ́ náà, ẹ̀yin ó béèrè ní orúkọ mi, èmi kò sì wí fún yín pé, èmi ó béèrè lọ́wọ́ Baba fún yín.
Den dagen skal dere be til Far i himmelen, og han skal svare dere fordi dere tilhører meg. Jeg trenger ikke å be for dere.
27 Nítorí tí Baba tìkára rẹ̀ fẹ́ràn yín, nítorí tí ẹ̀yin ti fẹ́ràn mi, ẹ sì ti gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni èmi ti jáde wá.
Min Far i himmelen elsker dere, fordi dere har elsket meg og tror at jeg er kommet fra Gud.
28 Mo ti ọ̀dọ̀ Baba jáde wá, mo sì wá sí ayé, àti nísinsin yìí mo fi ayé sílẹ̀, mo sì lọ sọ́dọ̀ Baba.”
Ja, jeg er kommet til verden fra min Far i himmelen, og jeg skal forlate verden for å vende tilbake til ham.”
29 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Wò ó, nígbà yìí ni ìwọ ń sọ̀rọ̀ gbangba, ìwọ kò sì sọ ohunkóhun ní òwe.
Da sa disiplene:”Endelig snakker du i klare meldinger, og ikke i bilder.
30 Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé, ìwọ mọ̀ ohun gbogbo, ìwọ kò ní kí a bi ọ́ léèrè: nípa èyí ni àwa gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ìwọ ti jáde wá.”
Nå forstår vi at du vet alt før noen har stilt et eneste spørsmål til deg. Derfor tror vi at du er kommet fra Gud.”
31 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin gbàgbọ́ wàyí?
Jesus svarte:”Nå endelig tror dere.
32 Kíyèsi i, wákàtí ń bọ̀, àní ó dé tan nísinsin yìí, tí a ó fọ́n yín ká kiri, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀; ẹ ó sì fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò sì ṣe èmi nìkan, nítorí tí Baba ń bẹ pẹ̀lú mi.
Den dagen kommer, ja, den er allerede her, da dere vil bli spredd og vende tilbake til hvert sitt og etterlate meg alene. Ikke en gang da vil jeg være alene, for min Far i himmelen er hos meg.
33 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹ̀yin ó ní ìpọ́njú; ṣùgbọ́n ẹ tújúká; mo ti ṣẹ́gun ayé.”
Dette har jeg fortalt dere for at dere skal ha fred på grunn av fellesskapet med meg. Her på jorden kommer dere til å møte mange sorger og skuffelser, men vær ikke urolige, jeg har overvunnet de onde kreftene i verden.”

< John 16 >