< John 16 >

1 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí a má ba à mú yín yapa kúrò.
ⲁ̅ⲛⲁⲓ ⲁⲓϫⲟⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲣ⳿ⲥⲕⲁⲛⲇⲁⲗⲓⲍⲉⲥⲑⲉ.
2 Wọ́n ó yọ yín kúrò nínú Sinagọgu: àní, àkókò ń bọ̀, tí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa yín, yóò rò pé òun ń ṣe ìsìn fún Ọlọ́run.
ⲃ̅ⲁⲩϣⲁⲛⲉⲣ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲁⲡⲟⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ϩⲓⲛⲁ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁϧⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉϥⲙⲉⲩⲓ ϫⲉ ⲁϥ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩϣⲟⲩϣⲱⲟⲩϣⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲙⲫϯ.
3 Nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ó sì ṣe, nítorí tí wọn kò mọ Baba, wọn kò sì mọ̀ mí.
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲓ ⲉⲩ⳿ⲉⲁⲓⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲟⲩ ⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲥⲟⲩⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲥⲟⲩⲱⲛⲧ.
4 Ṣùgbọ́n nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, pé nígbà tí wákàtí wọn bá dé, kí ẹ lè rántí wọn pé mo ti wí fún yín. Ṣùgbọ́n èmi kò sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá, nítorí tí mo wà pẹ̀lú yín.
ⲇ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲁⲓ ⲁⲓϫⲟⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⲁⲥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲡⲟⲩⲙⲉⲩⲓ ϫⲉ ⲁⲓⲟⲩⲱ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲓϫⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓϫⲟⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲓⲥϫⲉⲛ ϩⲏ ϫⲉ ⲛⲁⲓⲭⲏ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⲡⲉ.
5 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ń lọ sọ́dọ̀ ẹni tí ó rán mi; kò sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó bi mí lérè pé, ‘Níbo ni ìwọ ń lọ?’
ⲉ̅ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ϯⲛⲁϣⲉ ⲛⲏⲓ ϩⲁ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲧⲁⲟⲩⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲑⲏ ⲛⲟⲩ ϣⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ϫⲉ ⳿ⲭⲛⲁϣⲉ ⲛⲁⲕ ⳿ⲉⲑⲱⲛ.
6 Ṣùgbọ́n nítorí mo sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín, ìbìnújẹ́ kún ọkàn yín.
ⲋ̅ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉ ⲁⲓϫⲉ ⲛⲁⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲁ ⳿ⲡⲉⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲙⲁϩ ⲡⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ.
7 Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni èmi ń sọ fún yín; àǹfààní ni yóò jẹ́ fún yín bí èmi bá lọ, nítorí bí èmi kò bá lọ, Olùtùnú kì yóò tọ̀ yín wá; ṣùgbọ́n bí mo bá lọ, èmi ó rán an sí yín.
ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲑⲙⲏⲓ ⲡⲉϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲥⲉⲣⲛⲟϥⲣⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲛⲧⲁϣⲉ ⲛⲏⲓ ⲉϣⲱⲡ ⲅⲁⲣ ⲁⲓ⳿ϣⲧⲉⲙϣⲉ ⲛⲏⲓ ⲡⲓⲡⲁⲣⲁⲕⲗⲏ ⲧⲟⲥ ⲛⲁⲓ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁⲓϣⲁⲛϣⲉ ⲛⲏⲓ ϯⲛⲁⲟⲩⲟⲣⲡϥ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ.
8 Nígbà tí òun bá sì dé, yóò fi òye yé aráyé ní ti ẹ̀ṣẹ̀, àti ní ti òdodo, àti ní ti ìdájọ́,
ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉϥ⳿ⲉⲥⲟϩⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⲛⲉⲙ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲛⲉⲙ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩϩⲁⲡ.
9 ní ti ẹ̀ṣẹ̀, nítorí tí wọn kò gbà mí gbọ́;
ⲑ̅ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲫⲛⲟⲃⲓ ⲙⲉⲛ ϫⲉ ⲥⲉⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲁⲛ.
10 ní ti òdodo, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba, ẹ̀yin kò sì mọ̀ mí.
ⲓ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲇⲉ ϫⲉ ϯⲛⲁϣⲉ ⲛⲏⲓ ϩⲁ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲁⲛ ϫⲉ.
11 Ní ti ìdájọ́, nítorí tí a ti ṣe ìdájọ́ ọmọ-aládé ayé yìí.
ⲓ̅ⲁ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩϩⲁⲡ ⲇⲉ ϫⲉ ⳿ⲡⲁⲣⲭⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲁⲩⲟⲩⲱ ⲉⲩϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
12 “Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ fún yín pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ẹ kò lè gbà wọ́n nísinsin yìí.
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟⲛϯ ϩⲁⲛⲕⲉⲙⲏϣ ⳿ⲉϫⲟⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁ⳿ϣϥⲁⲓ ϧⲁⲣⲱⲟⲩ ϯⲛⲟⲩ ⲁⲛ.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun, àní Ẹ̀mí òtítọ́ náà bá dé, yóò tọ́ yín sí ọ̀nà òtítọ́ gbogbo, nítorí kì yóò sọ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó bá gbọ́, òun ni yóò máa sọ, yóò sì sọ ohun tí ń bọ̀ fún yín.
ⲓ̅ⲅ̅ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲉϥ⳿ⲉϭⲓⲙⲱⲓⲧ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁϥⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲏⲉⲧⲁϥⲛⲁⲥⲟⲑⲙⲟⲩ ⲉⲧⲉϥⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⲉϥ⳿ⲉⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ.
14 Òun ó máa yìn mí lógo, nítorí tí yóò gbà nínú ti èmi, yóò sì máa sọ ọ́ fún yín.
ⲓ̅ⲇ̅ⲫⲏ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲑⲛⲁϯⲱⲟⲩ ⲛⲏⲓ ϫⲉ ⲁϥⲛⲁϭⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉⲫⲱⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲛⲁⲧⲁⲙⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
15 Ohun gbogbo tí Baba ní tèmi ni, nítorí èyí ni mo ṣe wí pé, òun ó gba nínú tèmi, yóò sì sọ ọ́ fún yín.
ⲓ̅ⲉ̅ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲉⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲱⲧ ⲛⲟⲩ⳿Ⲓ ⲛⲉ ⲉⲑⲃⲉⲫⲁⲓ ⲁⲓϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲁϥⲛⲁϭⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉⲫⲱⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲁⲙⲉ ⲑⲏ ⲛⲟⲩ.
16 “Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ ó sì rí mi, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.”
ⲓ̅ⲋ̅ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ.
17 Nítorí náà díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bá ara wọn sọ pé, “Kín ni èyí tí o wí fún wa yìí, ‘Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ ẹ̀wẹ̀, ẹ̀yin kì yóò rí mi, àti, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba’?”
ⲓ̅ⲍ̅ⲡⲉϫⲉ ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏ ⲧⲏⲥ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲉⲣⲏⲟⲩ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲉⲧⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲁⲛ ϫⲉ ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϯⲛⲁϣⲉ ⲛⲏⲓ ϩⲁ ⳿ⲫⲓⲱⲧ.
18 Nítorí náà wọ́n wí pé, kín ni, nígbà díẹ̀? Àwa kò mọ̀ ohun tí ó wí.
ⲓ̅ⲏ̅ⲛⲁⲩϫⲱ ⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲡⲉ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϫⲉ ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩ.
19 Jesu sá à ti mọ̀ pé, wọ́n ń fẹ́ láti bi òun léèrè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ń bi ara yín léèrè ní ti èyí tí mo wí pé, nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ̀yin ó sì rí mi?
ⲓ̅ⲑ̅ⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲉ ⲛⲁⲩⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉϣⲉⲛϥ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ϫⲉ ⲁⲓϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲕⲉⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲁⲛⲁⲩ ⲉⲣⲟⲓ.
20 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ẹ̀yin yóò máa sọkún ẹ ó sì máa pohùnréré ẹkún, ṣùgbọ́n àwọn aráyé yóò máa yọ̀: ṣùgbọ́n, ìbànújẹ́ yín yóò di ayọ̀.
ⲕ̅ⲁⲙⲏⲛ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲣⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣϩⲏ ⲃⲓ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲇⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⳿ϥⲛⲁⲣⲁϣⲓ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ϥⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲉⲩⲣⲁϣⲓ.
21 Nígbà tí obìnrin bá ń rọbí, a ní ìbìnújẹ́, nítorí tí wákàtí rẹ̀ dé: ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá ti bí ọmọ náà tán, òun kì í sì í rántí ìrora náà mọ́, fún ayọ̀ nítorí a bí ènìyàn sí ayé.
ⲕ̅ⲁ̅ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲁⲥϣⲁⲛⲛⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲙⲓⲥⲓ ϣⲁⲥⲉⲣ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ϫⲉ ⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲧⲉⲥⲟⲩⲛⲟⲩ ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁⲥϣⲁⲛⲙⲓⲥⲓ ⳿ⲙⲡⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲥⲉⲣ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲙⲡⲓϩⲟϫϩⲉϫ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓⲣⲁϣⲓ ϫⲉ ⲁⲥⲙⲉⲥ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ.
22 Nítorí náà ẹ̀yin ní ìbànújẹ́ nísinsin yìí, ṣùgbọ́n èmi ó tún rí yín, ọkàn yín yóò sì yọ̀, kò sì sí ẹni tí yóò gba ayọ̀ yín lọ́wọ́ yín.
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ϯⲛⲟⲩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϭ ⲓ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲟⲛ ϯⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲣⲁϣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉⲧⲉⲛⲣⲁϣⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⲛⲁⲟⲗϥ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
23 Àti ní ọjọ́ náà ẹ̀yin kì ó bi mí lérè ohunkóhun. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, òhun ó fi fún yín.
ⲕ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲉⲛⲧ ⳿ⲉ⳿ϩⲗⲓ ⲁⲛ ⲁⲙⲏⲛ ⲁⲙⲏⲛ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲫⲏⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲓⲱⲧ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⲉϥ⳿ⲉⲧⲏⲓϥ ⲛⲱⲧⲉⲛ.
24 Títí di ìsinsin yìí ẹ kò tí ì béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, ẹ béèrè, ẹ ó sì rí gbà, kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
ⲕ̅ⲇ̅ϣⲁ ϯⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⲁⲣⲓⲉⲧⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϭⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲣⲁϣⲓ ϣⲱⲡⲓ ⲉϥϫⲏⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
25 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo fi òwe sọ fún yín: ṣùgbọ́n àkókò dé, nígbà tí èmi kì yóò fi òwe bá yín sọ̀rọ̀ mọ́, ṣùgbọ́n èmi ó sọ nípa ti Baba fún yín gbangba.
ⲕ̅ⲉ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲁⲓϫⲟⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲡⲁⲣⲟⲓⲙⲓ⳿ⲁ ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ϩⲟⲧⲉ ⲉⲓⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲡⲁⲣⲟⲓⲙⲓ⳿ⲁ ⲁⲗⲗⲁ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡⲁⲣⲣⲏⲥⲓ⳿ⲁ ϯⲛⲁⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲫⲓⲱⲧ.
26 Ní ọjọ́ náà, ẹ̀yin ó béèrè ní orúkọ mi, èmi kò sì wí fún yín pé, èmi ó béèrè lọ́wọ́ Baba fún yín.
ⲕ̅ⲋ̅ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲣⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲁϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲑⲛⲁϯϩⲟ ⳿ⲉ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲉⲑⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
27 Nítorí tí Baba tìkára rẹ̀ fẹ́ràn yín, nítorí tí ẹ̀yin ti fẹ́ràn mi, ẹ sì ti gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni èmi ti jáde wá.
ⲕ̅ⲍ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲅⲁⲣ ϩⲱϥ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⳿ϥⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲛⲣⲓⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ϫⲉ ⲉⲧⲁⲓ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⳿ⲫⲓⲱⲧ.
28 Mo ti ọ̀dọ̀ Baba jáde wá, mo sì wá sí ayé, àti nísinsin yìí mo fi ayé sílẹ̀, mo sì lọ sọ́dọ̀ Baba.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲁⲓ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲓ⳿Ⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲟⲛ ϯⲛⲁⲭⲱ ⳿ⲙⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲁϣⲉ ⲛⲏⲓ ϩⲁ ⳿ⲫⲓⲱⲧ.
29 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Wò ó, nígbà yìí ni ìwọ ń sọ̀rọ̀ gbangba, ìwọ kò sì sọ ohunkóhun ní òwe.
ⲕ̅ⲑ̅ⲡⲉϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ϩⲏⲡⲡⲉ ϯⲛⲟⲩ ⳿ⲕⲥⲁϫⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡⲁⲣⲣⲏⲥⲓ⳿ⲁ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲕϫⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲟⲓⲙⲓ⳿ⲁ.
30 Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé, ìwọ mọ̀ ohun gbogbo, ìwọ kò ní kí a bi ọ́ léèrè: nípa èyí ni àwa gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ìwọ ti jáde wá.”
ⲗ̅ϯⲛⲟⲩ ⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⳿ⲕⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛ⳿ⲕⲉⲣ⳿ⲭⲣⲓⲁ ⲁⲛ ⲉⲑⲣⲉ ⲟⲩⲁⲓ ϣⲉⲛⲕ ϧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ϫⲉ ⲁⲕ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⲫϯ.
31 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin gbàgbọ́ wàyí?
ⲗ̅ⲁ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲉ ϯⲛⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ.
32 Kíyèsi i, wákàtí ń bọ̀, àní ó dé tan nísinsin yìí, tí a ó fọ́n yín ká kiri, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀; ẹ ó sì fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò sì ṣe èmi nìkan, nítorí tí Baba ń bẹ pẹ̀lú mi.
ⲗ̅ⲃ̅ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥ⳿ⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϫⲱⲣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲉⲡⲉϥⲙⲁ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲭⲁⲧ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧ ⲟⲩⲟϩ ϯⲭⲏ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ϥⲭⲏ ⲛⲉⲙⲏⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁⲓⲱⲧ.
33 “Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹ̀yin ó ní ìpọ́njú; ṣùgbọ́n ẹ tújúká; mo ti ṣẹ́gun ayé.”
ⲗ̅ⲅ̅ⲛⲁⲓ ⲁⲓϫⲟⲧⲟⲩ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏ ϣⲱⲡⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲟⲩϩⲟϫϩⲉϫ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉⲙⲛⲟⲙϯ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲓϭⲣⲟ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ

< John 16 >