< John 15 >
1 “Èmi ni àjàrà tòótọ́, Baba mi sì ni olùṣọ́gbà.
„Én vagyok az igazi szőlőtő, és az én Atyám a szőlőműves.
2 Gbogbo ẹ̀ka nínú mi tí kò bá so èso, òun a mú kúrò, gbogbo ẹ̀ka tí ó bá sì so èso, òun a wẹ̀ ẹ́ mọ́, kí ó lè so èso sí i.
Minden szőlővesszőt, amely énbennem gyümölcsöt nem terem, lemetsz, mindazt pedig, amely gyümölcsöt terem, megtisztítja, hogy több gyümölcsöt teremjen.
3 Ẹ̀yin mọ́ nísinsin yìí nítorí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín.
Ti már tiszták vagytok az által a beszéd által, amelyet szóltam néktek.
4 Ẹ máa gbé inú mi, èmi ó sì máa gbé inú yín. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka kò ti lè so èso fún ara rẹ̀ bí kò ṣe pé ó ba ń gbé inú àjàrà, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin, bí kò ṣe pé ẹ bá ń gbé inú mi.
Maradjatok énbennem és én is tibennetek. Miképpen a szőlővessző nem teremhet gyümölcsöt magától, ha nem marad a szőlőtőkén, akképpen ti sem, ha nem maradtok énbennem.
5 “Èmi ni àjàrà, ẹ̀yin ni ẹ̀ka. Ẹni tí ó ń gbé inú mi, àti èmi nínú rẹ̀, òun ni yóò so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀, nítorí ní yíya ara yín kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ kò lè ṣe ohun kan.
Én vagyok a szőlőtő, ti a szőlővesszők: Aki énbennem marad, én pedig őbenne, az terem sok gyümölcsöt: mert nélkülem semmit sem cselekedhettek.
6 Bí ẹnìkan kò bá gbé inú mi, a gbé e sọnù gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka, a sì gbẹ; wọn a sì kó wọn jọ, wọn a sì sọ wọ́n sínú iná, wọn a sì jóná.
Ha valaki nem marad énbennem, kivettetik, mint a szőlővessző, és megszárad, és egybegyűjtik ezeket, és a tűzre vetik, és megégnek.
7 Bí ẹ̀yin bá ń gbé inú mi, tí ọ̀rọ̀ mi bá sì gbé inú yín, ẹ ó béèrè ohunkóhun tí ẹ bá fẹ́, a ó sì ṣe é fún yín.
Ha énbennem maradtok, és az én beszédeim bennetek maradnak, kérjetek, amit csak akartok, és megadatik néktek.
8 Nínú èyí ní a yìn Baba mi lógo pé, kí ẹ̀yin kí ó máa so èso púpọ̀; ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi.
Abban dicsőül meg az én Atyám, hogy sok gyümölcsöt teremtek, és tanítványaim lesztek.
9 “Gẹ́gẹ́ bí Baba ti fẹ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì fẹ́ yín, ẹ dúró nínú ìfẹ́ rẹ̀.
„Amiképpen az Atya szeretett engem, én is úgy szerettelek titeket: maradjatok meg ebben az én szeretetemben.
10 Bí ẹ̀yin bá pa òfin mi mọ́, ẹ ó dúró nínú ìfẹ́ mi; gẹ́gẹ́ bí èmi ti pa òfin Baba mi mọ́, tí mo sì dúró nínú ìfẹ́ rẹ̀.
Ha az én parancsolataimat megtartjátok, megmaradtok az én szeretetemben, amiképpen én megtartottam az én Atyámnak parancsolatait, és megmaradok az ő szeretetében.
11 Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí ayọ̀ mi kí ó lè wà nínú yín, àti kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
Ezeket beszéltem néktek, hogy megmaradjon bennetek az én örömöm, és a ti örömötök teljessé legyen.
12 Èyí ni òfin mi, pé kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn ara yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti fẹ́ràn yín.
Az az én parancsolatom, hogy úgy szeressétek egymást, amiképpen én szerettelek titeket.
13 Kò sí ẹnìkan tí ó ní ìfẹ́ tí ó tóbi ju èyí lọ, pé ẹnìkan fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Nincsen senkiben nagyobb szeretet annál, mint ha valaki életét adja az ő barátaiért.
14 Ọ̀rẹ́ mi ni ẹ̀yin ń ṣe, bí ẹ bá ṣe ohun tí èmi pàṣẹ fún yín.
Ti az én barátaim vagytok, ha azokat cselekszitek, amiket én parancsolok nektek.
15 Èmi kò pè yín ní ọmọ ọ̀dọ̀ mọ́; nítorí ọmọ ọ̀dọ̀ kò mọ ohun tí olúwa rẹ̀ ń ṣe, ṣùgbọ́n èmi pè yín ní ọ̀rẹ́ nítorí ohun gbogbo tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá, mo ti fihàn fún yín.
Nem mondtalak többé titeket szolgáknak, mert a szolga nem tudja, mit cselekszik az ő ura, titeket pedig barátaimnak mondtalak, mert mindazt, amit az én Atyámtól hallottam, tudtul adtam nektek.
16 Kì í ṣe ẹ̀yin ni ó yàn mí, ṣùgbọ́n èmi ni ó yàn yín, mo sì fi yín sípò, kí ẹ̀yin kí ó lè lọ, kí ẹ sì so èso, àti kí èso yín lè dúró; kí ohunkóhun tí ẹ bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, kí ó lè fi í fún yín.
Nem ti választottatok engem, hanem én választottalak titeket, és én rendeltelek titeket, hogy ti elmenjetek, és gyümölcsöt teremjetek, és a ti gyümölcsötök megmaradjon, hogy akármit kértek az Atyától az én nevemben, megadja nektek.
17 Nǹkan wọ̀nyí ni mo pàṣẹ fún yín pé, kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn ara yín.
Ezeket parancsolom nektek, hogy egymást szeressétek.
18 “Bí ayé bá kórìíra yín, ẹ mọ̀ pé, ó ti kórìíra mi ṣáájú yín.
„Ha gyűlöl titeket a világ, tudjátok meg, hogy engem előbb gyűlölt, mint titeket.
19 Ìbá ṣe pé ẹ̀yin ń ṣe ti ayé, ayé ìbá fẹ́ yin bi àwọn tirẹ̀; gẹ́gẹ́ bi o ṣe ri tí ẹ̀yin kì ń ṣe ti ayé, ṣùgbọ́n èmi ti yàn yín kúrò nínú ayé, nítorí èyí ni ayé ṣe kórìíra yín.
Ha e világból volnátok, a világ szeretné azt, ami az övé, de mivel nem vagytok e világból, hanem én választottalak ki magamnak titeket e világból, azért gyűlöl titeket a világ.
20 Ẹ rántí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín pé, ‘Ọmọ ọ̀dọ̀ kò tóbi ju olúwa rẹ̀ lọ.’ Bí wọ́n bá ti ṣe inúnibíni sí mi, wọ́n ó ṣe inúnibíni sí yín pẹ̀lú: bí wọ́n bá ti pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, wọ́n ó sì pa tiyín mọ́ pẹ̀lú.
Emlékezzetek meg arról a beszédről, amelyet én mondtam nektek: Nem nagyobb a szolga az ő uránál. Ha engem üldöztek, titeket is üldöznek majd, ha az én beszédemet megtartották, a tiéteket is megtartják majd.
21 Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n yóò ṣe sí yín, nítorí orúkọ mi, nítorí tí wọn kò mọ ẹni tí ó rán mi.
De mindezt az én nevemért cselekszik veletek, mivel nem ismerik azt, aki küldött engem.
22 Ìbá ṣe pé èmi kò ti wá kí n sì ti bá wọn sọ̀rọ̀, wọn kì bá tí ní ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n di aláìríwí fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Ha nem jöttem volna, és nem beszéltem volna nekik, nem volna bűnük: de most nincs mivel menteniük bűnüket.
23 Ẹni tí ó bá kórìíra mi, ó kórìíra Baba mi pẹ̀lú.
Aki engem gyűlöl, gyűlöli az én Atyámat is.
24 Ìbá ṣe pé èmi kò ti ṣe iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì láàrín wọn tí ẹlòmíràn kò ṣe rí, wọn kì bá tí ní ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n sì rí, wọ́n sì kórìíra èmi àti Baba mi.
Ha azokat a cselekedeteket nem cselekedtem volna közöttük, amelyeket senki más nem cselekedett, nem volna bűnük, de most láttak is, gyűlöltek is, mind engem, mind az én Atyámat.
25 Ṣùgbọ́n èyí rí bẹ́ẹ̀ kí ọ̀rọ̀ tí a kọ nínú òfin wọn kí ó lè ṣẹ pé, ‘Wọ́n kórìíra mi ní àìnídìí.’
De azért lett így, hogy beteljesedjék a mondás, amely megíratott az ő törvényükben: »Ok nélkül gyűlöltek engem.«
26 “Ṣùgbọ́n nígbà tí Olùtùnú náà bá dé, ẹni tí èmi ó rán sí yín láti ọ̀dọ̀ Baba wá, àní Ẹ̀mí òtítọ́ nì, tí ń ti ọ̀dọ̀ Baba wá, òun náà ni yóò jẹ́rìí mi.
Mikor pedig eljön majd a Vigasztaló, akit én küldök néktek az Atyától, az igazságnak Lelke, aki az Atyától származik, az tesz majd énrólam bizonyságot.
27 Ẹ̀yin pẹ̀lú yóò sì jẹ́rìí mi, nítorí tí ẹ̀yin ti wà pẹ̀lú mi láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá.
De ti is bizonyságot tesztek, mert kezdettől fogva énvelem vagytok.