< John 15 >
1 “Èmi ni àjàrà tòótọ́, Baba mi sì ni olùṣọ́gbà.
Já jsem ten vinný kmen pravý, a Otec můj vinař jest
2 Gbogbo ẹ̀ka nínú mi tí kò bá so èso, òun a mú kúrò, gbogbo ẹ̀ka tí ó bá sì so èso, òun a wẹ̀ ẹ́ mọ́, kí ó lè so èso sí i.
Každou ratolest, kteráž ve mně nenese ovoce, odřezuje, a každou, kteráž nese ovoce, čistí, aby hojnější ovoce nesla.
3 Ẹ̀yin mọ́ nísinsin yìí nítorí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín.
Již vy čisti jste pro řeč, kterouž jsem mluvil vám.
4 Ẹ máa gbé inú mi, èmi ó sì máa gbé inú yín. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka kò ti lè so èso fún ara rẹ̀ bí kò ṣe pé ó ba ń gbé inú àjàrà, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin, bí kò ṣe pé ẹ bá ń gbé inú mi.
Zůstaňtež ve mně, a já v vás. Jakož ratolest nemůže nésti ovoce sama od sebe, nezůstala-li by při kmenu, takž ani vy, leč zůstanete ve mně.
5 “Èmi ni àjàrà, ẹ̀yin ni ẹ̀ka. Ẹni tí ó ń gbé inú mi, àti èmi nínú rẹ̀, òun ni yóò so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀, nítorí ní yíya ara yín kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ kò lè ṣe ohun kan.
Já jsem vinný kmen a vy ratolesti. Kdo zůstává ve mně, a já v něm, ten nese ovoce mnohé; nebo beze mne nic nemůžete učiniti.
6 Bí ẹnìkan kò bá gbé inú mi, a gbé e sọnù gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka, a sì gbẹ; wọn a sì kó wọn jọ, wọn a sì sọ wọ́n sínú iná, wọn a sì jóná.
Nezůstal-li by kdo ve mně, vyvržen bude ven jako ratolest, a uschneť, a sberouť ty ratolesti a na oheň uvrhou a shoříť.
7 Bí ẹ̀yin bá ń gbé inú mi, tí ọ̀rọ̀ mi bá sì gbé inú yín, ẹ ó béèrè ohunkóhun tí ẹ bá fẹ́, a ó sì ṣe é fún yín.
Zůstanete-li ve mně, a slova má zůstanou-liť v vás, což byste koli chtěli, proste, a staneť se vám.
8 Nínú èyí ní a yìn Baba mi lógo pé, kí ẹ̀yin kí ó máa so èso púpọ̀; ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọ-ẹ̀yìn mi.
V tomť bývá oslaven Otec můj, když ovoce nesete hojné, a takť budete moji učedlníci.
9 “Gẹ́gẹ́ bí Baba ti fẹ́ mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì fẹ́ yín, ẹ dúró nínú ìfẹ́ rẹ̀.
Jakož miloval mne Otec, tak i já miloval jsem vás. Zůstaňtež v milování mém.
10 Bí ẹ̀yin bá pa òfin mi mọ́, ẹ ó dúró nínú ìfẹ́ mi; gẹ́gẹ́ bí èmi ti pa òfin Baba mi mọ́, tí mo sì dúró nínú ìfẹ́ rẹ̀.
Budete-li zachovávati přikázaní má, zůstanete v mém milování, jakož i já přikázání Otce svého zachoval jsem, i zůstávám v jeho milování.
11 Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí ayọ̀ mi kí ó lè wà nínú yín, àti kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
Toto mluvil jsem vám, aby radost má zůstala v vás, a radost vaše aby byla plná.
12 Èyí ni òfin mi, pé kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn ara yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti fẹ́ràn yín.
Totoť jest přikázání mé, abyste se milovali vespolek, jako i já miloval jsem vás.
13 Kò sí ẹnìkan tí ó ní ìfẹ́ tí ó tóbi ju èyí lọ, pé ẹnìkan fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Většího milování nad to žádný nemá, než aby duši svou položil za přátely své.
14 Ọ̀rẹ́ mi ni ẹ̀yin ń ṣe, bí ẹ bá ṣe ohun tí èmi pàṣẹ fún yín.
Vy přátelé moji jste, učiníte-li to, což já přikazuji vám.
15 Èmi kò pè yín ní ọmọ ọ̀dọ̀ mọ́; nítorí ọmọ ọ̀dọ̀ kò mọ ohun tí olúwa rẹ̀ ń ṣe, ṣùgbọ́n èmi pè yín ní ọ̀rẹ́ nítorí ohun gbogbo tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá, mo ti fihàn fún yín.
Již vás nebudu více nazývati služebníky, nebo služebník neví, co by činil pán jeho. Ale vás jsem nazval přáteli, nebo všecko, což jsem koli slyšel od Otce svého, oznámil jsem vám.
16 Kì í ṣe ẹ̀yin ni ó yàn mí, ṣùgbọ́n èmi ni ó yàn yín, mo sì fi yín sípò, kí ẹ̀yin kí ó lè lọ, kí ẹ sì so èso, àti kí èso yín lè dúró; kí ohunkóhun tí ẹ bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, kí ó lè fi í fún yín.
Ne vy jste mne vyvolili, ale já jsem vás vyvolil a postavil, abyste šli a ovoce přinesli, a ovoce vaše aby zůstalo, aby zač byste koli prosili Otce ve jménu mém, dal vám.
17 Nǹkan wọ̀nyí ni mo pàṣẹ fún yín pé, kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn ara yín.
To přikazuji vám, abyste se milovali vespolek.
18 “Bí ayé bá kórìíra yín, ẹ mọ̀ pé, ó ti kórìíra mi ṣáájú yín.
Jestližeť vás svět nenávidí, víte, žeť jest mne prve než vás v nenávisti měl.
19 Ìbá ṣe pé ẹ̀yin ń ṣe ti ayé, ayé ìbá fẹ́ yin bi àwọn tirẹ̀; gẹ́gẹ́ bi o ṣe ri tí ẹ̀yin kì ń ṣe ti ayé, ṣùgbọ́n èmi ti yàn yín kúrò nínú ayé, nítorí èyí ni ayé ṣe kórìíra yín.
Byste byli z světa, svět, což jest jeho, miloval by; že pak nejste z světa, ale já z světa vyvolil jsem vás, protož vás svět nenávidí.
20 Ẹ rántí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ fún yín pé, ‘Ọmọ ọ̀dọ̀ kò tóbi ju olúwa rẹ̀ lọ.’ Bí wọ́n bá ti ṣe inúnibíni sí mi, wọ́n ó ṣe inúnibíni sí yín pẹ̀lú: bí wọ́n bá ti pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, wọ́n ó sì pa tiyín mọ́ pẹ̀lú.
Pamatujte na řeč mou, kterouž jsem já mluvil vám: Neníť služebník větší nežli pán jeho. Poněvadž se mně protivili, i vámť se protiviti budou; poněvadž jsou řeči mé šetřili, i vaší šetřiti budou.
21 Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n yóò ṣe sí yín, nítorí orúkọ mi, nítorí tí wọn kò mọ ẹni tí ó rán mi.
Ale toto všecko učiní vám pro jméno mé; nebo neznají toho, jenž mne poslal.
22 Ìbá ṣe pé èmi kò ti wá kí n sì ti bá wọn sọ̀rọ̀, wọn kì bá tí ní ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n di aláìríwí fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Kdybych byl nepřišel a nemluvil jim, hříchu by neměli; ale nyní výmluvy nemají z hříchu svého.
23 Ẹni tí ó bá kórìíra mi, ó kórìíra Baba mi pẹ̀lú.
Kdož mne nenávidí, i Otceť mého nenávidí.
24 Ìbá ṣe pé èmi kò ti ṣe iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì láàrín wọn tí ẹlòmíràn kò ṣe rí, wọn kì bá tí ní ẹ̀ṣẹ̀, ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n sì rí, wọ́n sì kórìíra èmi àti Baba mi.
Bych byl skutků nečinil mezi nimi, jichžto žádný jiný nečinil, hříchu by neměli; ale nyní jsou i viděli, i nenáviděli, i mne i Otce mého.
25 Ṣùgbọ́n èyí rí bẹ́ẹ̀ kí ọ̀rọ̀ tí a kọ nínú òfin wọn kí ó lè ṣẹ pé, ‘Wọ́n kórìíra mi ní àìnídìí.’
Ale musilo tak býti, aby se naplnila řeč, kteráž v Zákoně jejich napsána jest: Že v nenávisti měli mne bez příčiny.
26 “Ṣùgbọ́n nígbà tí Olùtùnú náà bá dé, ẹni tí èmi ó rán sí yín láti ọ̀dọ̀ Baba wá, àní Ẹ̀mí òtítọ́ nì, tí ń ti ọ̀dọ̀ Baba wá, òun náà ni yóò jẹ́rìí mi.
Když pak přijde Utěšitel, kteréhož já pošli vám od Otce, Duch pravdy, kterýž od Otce pochází, tenť svědectví vydávati bude o mně.
27 Ẹ̀yin pẹ̀lú yóò sì jẹ́rìí mi, nítorí tí ẹ̀yin ti wà pẹ̀lú mi láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá.
Ano i vy svědectví vydávati budete, nebo od počátku se mnou jste.