< John 14 >
1 “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín kí ó dàrú, ẹ gba Ọlọ́run gbọ́, kí ẹ sì gbà mí gbọ́ pẹ̀lú.
Och han sade till sina Lärjungar: Edart hjerta vare icke bedröfvadt: Tron I på Gud, så tror ock på mig.
2 Nínú ilé Baba mi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ibùgbé ni ó wà, ìbá má ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ìbá tí sọ fún yín. Èmi ń lọ láti pèsè ààyè sílẹ̀ fún yín.
I mins Faders hus äro många boningar; om så icke vore, säger jag dock eder, att jag går bort till att bereda eder rum.
3 Bí mo bá sì lọ láti pèsè ààyè sílẹ̀ fún un yín, èmi ó tún padà wá, èmi ó sì mú yín lọ sọ́dọ̀ èmi tìkára mi; pé níbi tí èmi gbé wà, kí ẹ̀yin lè wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
Och om jag än går bort till att bereda eder rum, skall jag likväl komma igen, och taga eder till mig; att hvar jag är, der skolen I ock vara;
4 Ẹ̀yin mọ ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ sì mọ ọ̀nà náà.”
Och hvart jag går, veten I, och vägen veten I.
5 Tomasi wí fún un pé, “Olúwa, a kò mọ ibi tí ìwọ ń lọ, a ó ha ti ṣe mọ ọ̀nà náà?”
Thomas sade till honom: Herre, vi vete icke hvart du går; och huru kunne vi veta vägen?
6 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Èmi ni ọ̀nà, òtítọ́ àti ìyè, kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè wá sọ́dọ̀ Baba, bí kò ṣe nípasẹ̀ mi.
Jesus sade till honom: Jag är vägen, sanningen och lifvet; ingen kommer till Fadren, utan genom mig.
7 Ìbá ṣe pé ẹ̀yin ti mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá ti mọ Baba mi pẹ̀lú, láti ìsinsin yìí lọ ẹ̀yin mọ̀ ọ́n, ẹ sì ti rí i.”
Känden I mig, så känden I ju ock min Fader; och nu kännen I honom, och hafven sett honom.
8 Filipi wí fún un pé, “Olúwa, fi Baba náà hàn wá, yóò sì tó fún wa.”
Philippus sade till honom: Herre, låt oss se Fadren, så hafve vi nog.
9 Jesu wí fún un pé, “Bí àkókò tí mo bá yín gbé ti tó yìí, ìwọ, kò sì tí ì mọ̀ mí síbẹ̀ Filipi? Ẹni tí ó bá ti rí mi, ó ti rí Baba. Ìwọ ha ti ṣe wí pé, ‘Fi Baba hàn wá!’
Sade Jesus till honom: Jag är så lång tid när eder, och du känner mig icke; Philippe, den mig ser, han ser Fadren; och huru säger du: Låt oss se Fadren?
10 Ìwọ kò ha gbàgbọ́ pé, èmi wà nínú Baba, àti pé Baba wà nínú mi? Ọ̀rọ̀ tí èmi ń sọ fún yín, èmi kò dá a sọ; ṣùgbọ́n Baba ti ó wà nínú mi, òun ní ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
Tror du icke, att jag är i Fadrenom, och Fadren i mig? Orden, som jag talar till eder, talar jag icke af mig sjelf; Fadren, som är i mig, han gör gerningarna.
11 Ẹ gbà mí gbọ́ pé, èmi wà nínú Baba, Baba sì wà nínú mi, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ gbà mí gbọ́ nítorí àwọn ẹ̀rí iṣẹ́ náà pàápàá!
Tror mig, att jag är i Fadrenom, och Fadren i mig; eljest, tror mig för gerningarnas skull.
12 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, iṣẹ́ tí èmi ń ṣe ni òun yóò ṣe pẹ̀lú; iṣẹ́ tí ó tóbi ju wọ̀nyí lọ ni yóò sì ṣe; nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.
Sannerliga, sannerliga säger jag eder: Den der tror på mig, de gerningar, som jag gör, skall ock han göra; och skall göra större än dessa; ty jag går till Fadren.
13 Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá sì béèrè ní orúkọ mi, òun náà ni èmi ó ṣe, kí a lè yin Baba lógo nínú Ọmọ.
Och allt det I bedjen i mitt Namn, det skall jag göra; på det att Fadren skall prisad varda i Sonenom.
14 Bí ẹ̀yin bá béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, èmi ó ṣe é.
Hvad I bedjen i mitt Namn, det skall jag göra.
15 “Bí ẹ̀yin bá fẹ́ràn mi, ẹ ó pa òfin mi mọ́.
Älsken I mig, så håller min bud.
16 Nígbà náà èmi yóò wá béèrè lọ́wọ́ Baba. Òun yóò sì fún yín ní olùtùnú mìíràn. Olùtùnú náà yóò máa bá yín gbé títí láé. (aiōn )
Och jag skall bedja Fadren, och han skall gifva eder en annan Hugsvalare, att han skall blifva när eder evinnerliga; (aiōn )
17 Òun ni Ẹ̀mí òtítọ́. Ayé kò le gbà á. Nítorí ayé kò mọ̀ ọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò rí i rí. Ẹ̀yin mọ̀ ọn nítorí láti ìgbà tí ẹ ti wà pẹ̀lú mí. Òun náà ti wà pẹ̀lú yín. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kan yóò wọ inú yín láti máa gbé ibẹ̀.
Sanningenes Anda, den verlden icke kan undfå; ty hon ser honom icke, och känner honom icke; men I kännen honom; ty han blifver när eder, och skall vara i eder.
18 Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìní Olùtùnú, kí ẹ ma dàbí ọmọ tí kò ní òbí. Rárá o! Mo tún ń tọ̀ yín bọ̀.
Jag skall icke låta eder vara faderlösa; jag skall komma till eder.
19 Nígbà díẹ̀ sí i, ayé kì yóò rí mi mọ́; ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò rí mi, nítorí tí èmi wà láààyè, ẹ̀yin yóò wà láààyè pẹ̀lú.
Än är en liten tid, och verlden ser mig icke mer. Men I skolen se mig; ty jag lefver; I skolen ock lefva.
20 Ní ọjọ́ náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi wà nínú Baba mi, àti ẹ̀yin nínú mi, àti èmi nínú yín.
På den dagen skolen I förstå, att jag är i minom Fader; och I i mig, och jag i eder.
21 Ẹni tí ó bá ní òfin mi, tí ó bá sì ń pa wọ́n mọ́, òun ni ẹni tí ó fẹ́ràn mi, ẹni tí ó bá sì fẹ́ràn mi, a ó fẹ́ràn rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Baba mi, èmi ó sì fẹ́ràn rẹ̀, èmi ó sì fi ara mi hàn fún un.”
Den min bud hafver, och håller dem, han är den mig älskar; och den mig älskar, han skall varda älskad af minom Fader; och jag skall älska honom, och honom skall jag uppenbara mig.
22 Judasi (kì í ṣe Judasi Iskariotu) wí fún un pé, “Olúwa, èéha ti ṣe tí ìwọ ó fi ara rẹ hàn fún àwa, tí kì yóò sì ṣe fún aráyé?”
Sade till honom Judas, icke den Ischarioth: Herre, hvad är det då, att du skall uppenbara dig oss, och icke verldene?
23 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Bí ẹnìkan bá fẹ́ràn mi, yóò pa ọ̀rọ̀ mi mọ́. Baba mi yóò sì fẹ́ràn rẹ̀, àwa ó sì tọ̀ ọ́ wá, a ó sì ṣe ibùgbé wa pẹ̀lú rẹ̀.
Svarade Jesus, och sade till honom: Den mig älskar, han varder hållandes min ord, och min Fader skall älska honom; och vi skole komma till honom, och blifva boende när honom.
24 Ẹni tí kò fẹ́ràn mi ni kò pa ọ̀rọ̀ mi mọ́. Ọ̀rọ̀ tí ẹ̀yin ń gbọ́ kì í ṣe ti èmi, ṣùgbọ́n ti Baba tí ó rán mi.
Men den mig icke älskar, han håller icke min ord; och det ordet I hören, är icke mitt, utan Fadrens som mig sändt hafver.
25 “Nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti sọ fún yín, nígbà tí mo ń bá yín gbé.
Detta hafver jag talat till eder, medan jag hafver varit när eder.
26 Ṣùgbọ́n Olùtùnú náà, Ẹ̀mí Mímọ́, ẹni tí Baba yóò rán ní orúkọ mi, òun ni yóò kọ́ yín ní ohun gbogbo, yóò sì rán yín létí ohun gbogbo tí mo ti sọ fún yín.
Men Hugsvalaren, den Helge Ande, hvilken Fadren skall sända i mitt Namn, han skall lära eder all ting, och påminna eder allt det jag eder sagt hafver.
27 Àlàáfíà ni mo fi sílẹ̀ fún yín pé, àlàáfíà mi ni mo fi fún yin, kì í ṣe bí ayé ti fi fún ni. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín dàrú, ẹ má sì jẹ́ kí ó wárìrì.
Friden låter jag eder; min frid gifver jag eder; icke gifver jag eder, såsom verlden gifver. Edart hjerta vare icke bedröfvadt, ej heller rädes.
28 “Ẹ̀yin sá ti gbọ́ bí mo ti wí fún yín pé, ‘Èmi ń lọ, èmi ó sì tọ̀ yín wá.’ Ìbá ṣe pé ẹ̀yin fẹ́ràn mi, ẹ̀yin ìbá yọ̀ nítorí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba; nítorí Baba mi tóbi jù mí lọ.
I hörden, att jag sade eder: Jag går bort, och kommer åter till eder. Haden I mig kär, då gladdens I ju, att jag sade: Jag går till Fadren; ty Fadren är större än jag.
29 Èmi sì ti sọ fún yín nísinsin yìí kí ó tó ṣẹ, pé nígbà tí ó bá ṣẹ, kí ẹ lè gbàgbọ́.
Och nu sade jag eder det, förr än det sker, att I tro skolen, när det skedt är.
30 Èmi kì yóò bá yín sọ̀rọ̀ púpọ̀, nítorí ọmọ-aládé ayé yí wá, kò sì ní nǹkan kan lòdì sí mi.
Härefter talar jag icke mycket med eder; ty denna verldenes Förste kommer; och i mig hafver han intet.
31 Ṣùgbọ́n nítorí kí ayé lè mọ̀ pé èmi fẹ́ràn Baba; gẹ́gẹ́ bí Baba sì ti fi àṣẹ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi ń ṣe. “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a lọ kúrò níhìn-ín yìí.
Men på det att verlden skall förstå, att jag hafver Fadren kär, och så gör som Fadren mig budit hafver; står upp, låter oss gå hädan.