< John 14 >
1 “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín kí ó dàrú, ẹ gba Ọlọ́run gbọ́, kí ẹ sì gbà mí gbọ́ pẹ̀lú.
„Eders Hjerte forfærdes ikke! Tror paa Gud, og tror paa mig!
2 Nínú ilé Baba mi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ibùgbé ni ó wà, ìbá má ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ìbá tí sọ fún yín. Èmi ń lọ láti pèsè ààyè sílẹ̀ fún yín.
I min Faders Hus er der mange Boliger. Dersom det ikke var saa, havde jeg sagt eder det; thi jeg gaar bort for at berede eder Sted.
3 Bí mo bá sì lọ láti pèsè ààyè sílẹ̀ fún un yín, èmi ó tún padà wá, èmi ó sì mú yín lọ sọ́dọ̀ èmi tìkára mi; pé níbi tí èmi gbé wà, kí ẹ̀yin lè wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
Og naar jeg er gaaet bort og har beredt eder Sted, kommer jeg igen og tager eder til mig, for at, hvor jeg er, der skulle ogsaa I være.
4 Ẹ̀yin mọ ibi tí èmi gbé ń lọ, ẹ sì mọ ọ̀nà náà.”
Og hvor jeg gaar hen, derhen vide I Vejen.”
5 Tomasi wí fún un pé, “Olúwa, a kò mọ ibi tí ìwọ ń lọ, a ó ha ti ṣe mọ ọ̀nà náà?”
Thomas siger til ham: „Herre! vi vide ikke, hvor du gaar hen; og hvorledes kunne vi vide Vejen?”
6 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Èmi ni ọ̀nà, òtítọ́ àti ìyè, kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè wá sọ́dọ̀ Baba, bí kò ṣe nípasẹ̀ mi.
Jesus siger til ham: „Jeg er Vejen og Sandheden og Livet; der kommer ingen til Faderen uden ved mig.
7 Ìbá ṣe pé ẹ̀yin ti mọ̀ mí, ẹ̀yin ìbá ti mọ Baba mi pẹ̀lú, láti ìsinsin yìí lọ ẹ̀yin mọ̀ ọ́n, ẹ sì ti rí i.”
Havde I kendt mig, da havde I ogsaa kendt min Fader; og fra nu af kende I ham og have set ham.”
8 Filipi wí fún un pé, “Olúwa, fi Baba náà hàn wá, yóò sì tó fún wa.”
Filip siger til ham: „Herre! vis os Faderen, og det er os nok.”
9 Jesu wí fún un pé, “Bí àkókò tí mo bá yín gbé ti tó yìí, ìwọ, kò sì tí ì mọ̀ mí síbẹ̀ Filipi? Ẹni tí ó bá ti rí mi, ó ti rí Baba. Ìwọ ha ti ṣe wí pé, ‘Fi Baba hàn wá!’
Jesus siger til ham: „Saa lang en Tid har jeg været hos eder, og du kender mig ikke, Filip? Den, som har set mig, har set Faderen; hvorledes kan du da sige: Vis os Faderen?
10 Ìwọ kò ha gbàgbọ́ pé, èmi wà nínú Baba, àti pé Baba wà nínú mi? Ọ̀rọ̀ tí èmi ń sọ fún yín, èmi kò dá a sọ; ṣùgbọ́n Baba ti ó wà nínú mi, òun ní ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
Tror du ikke, at jeg er i Faderen, og Faderen er i mig? De Ord, som jeg siger til eder, taler jeg ikke af mig selv; men Faderen, som bliver i mig, han gør sine Gerninger.
11 Ẹ gbà mí gbọ́ pé, èmi wà nínú Baba, Baba sì wà nínú mi, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ gbà mí gbọ́ nítorí àwọn ẹ̀rí iṣẹ́ náà pàápàá!
Tror mig, at jeg er i Faderen, og Faderen er i mig; men ville I ikke, saa tror mig dog for selve Gerningernes Skyld!
12 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, iṣẹ́ tí èmi ń ṣe ni òun yóò ṣe pẹ̀lú; iṣẹ́ tí ó tóbi ju wọ̀nyí lọ ni yóò sì ṣe; nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.
Sandelig, sandelig, siger jeg eder, den, som tror paa mig, de Gerninger, som jeg gør, skal ogsaa han gøre, og han skal gøre større Gerninger end disse; thi jeg gaar til Faderen,
13 Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá sì béèrè ní orúkọ mi, òun náà ni èmi ó ṣe, kí a lè yin Baba lógo nínú Ọmọ.
og hvad som helst I bede om i mit Navn, det vil jeg gøre, for at Faderen maa herliggøres ved Sønnen.
14 Bí ẹ̀yin bá béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, èmi ó ṣe é.
Dersom I bede om noget i mit Navn, vil jeg gøre det.
15 “Bí ẹ̀yin bá fẹ́ràn mi, ẹ ó pa òfin mi mọ́.
Dersom I elske mig, da holder mine Befalinger!
16 Nígbà náà èmi yóò wá béèrè lọ́wọ́ Baba. Òun yóò sì fún yín ní olùtùnú mìíràn. Olùtùnú náà yóò máa bá yín gbé títí láé. (aiōn )
Og jeg vil bede Faderen, og han skal give eder en anden Talsmand til at være hos eder evindelig, (aiōn )
17 Òun ni Ẹ̀mí òtítọ́. Ayé kò le gbà á. Nítorí ayé kò mọ̀ ọ́n, bẹ́ẹ̀ ni kò rí i rí. Ẹ̀yin mọ̀ ọn nítorí láti ìgbà tí ẹ ti wà pẹ̀lú mí. Òun náà ti wà pẹ̀lú yín. Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kan yóò wọ inú yín láti máa gbé ibẹ̀.
den Sandhedens Aand, som Verden ikke kan modtage, thi den ser den ikke og kender den ikke; men I kende den, thi den bliver hos eder og skal være i eder.
18 Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìní Olùtùnú, kí ẹ ma dàbí ọmọ tí kò ní òbí. Rárá o! Mo tún ń tọ̀ yín bọ̀.
Jeg vil ikke efterlade eder faderløse; jeg kommer til eder.
19 Nígbà díẹ̀ sí i, ayé kì yóò rí mi mọ́; ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò rí mi, nítorí tí èmi wà láààyè, ẹ̀yin yóò wà láààyè pẹ̀lú.
Endnu en liden Stund, og Verden ser mig ikke mere, men I se mig; thi jeg lever, og I skulle leve.
20 Ní ọjọ́ náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi wà nínú Baba mi, àti ẹ̀yin nínú mi, àti èmi nínú yín.
Paa den Dag skulle I erkende, at jeg er i min Fader, og I i mig, og jeg i eder.
21 Ẹni tí ó bá ní òfin mi, tí ó bá sì ń pa wọ́n mọ́, òun ni ẹni tí ó fẹ́ràn mi, ẹni tí ó bá sì fẹ́ràn mi, a ó fẹ́ràn rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Baba mi, èmi ó sì fẹ́ràn rẹ̀, èmi ó sì fi ara mi hàn fún un.”
Den, som har mine Befalinger og holder dem, han er den, som elsker mig; men den, som elsker mig, skal elskes af min Fader; og jeg skal elske ham og aabenbare mig for ham.”
22 Judasi (kì í ṣe Judasi Iskariotu) wí fún un pé, “Olúwa, èéha ti ṣe tí ìwọ ó fi ara rẹ hàn fún àwa, tí kì yóò sì ṣe fún aráyé?”
Judas (ikke Iskariot) siger til ham: „Herre! hvor kommer det, at du vil aabenbare dig for os og ikke for Verden?”
23 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Bí ẹnìkan bá fẹ́ràn mi, yóò pa ọ̀rọ̀ mi mọ́. Baba mi yóò sì fẹ́ràn rẹ̀, àwa ó sì tọ̀ ọ́ wá, a ó sì ṣe ibùgbé wa pẹ̀lú rẹ̀.
Jesus svarede og sagde til ham: „Om nogen elsker mig, vil han holde mit Ord; og min Fader skal elske ham, og vi skulle komme til ham og tage Bolig hos ham.
24 Ẹni tí kò fẹ́ràn mi ni kò pa ọ̀rọ̀ mi mọ́. Ọ̀rọ̀ tí ẹ̀yin ń gbọ́ kì í ṣe ti èmi, ṣùgbọ́n ti Baba tí ó rán mi.
Den, som ikke elsker mig, holder ikke mine Ord; og det Ord, som I høre, er ikke mit, men Faderens, som sendte mig.
25 “Nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti sọ fún yín, nígbà tí mo ń bá yín gbé.
Dette har jeg talt til eder, medens jeg blev hos eder.
26 Ṣùgbọ́n Olùtùnú náà, Ẹ̀mí Mímọ́, ẹni tí Baba yóò rán ní orúkọ mi, òun ni yóò kọ́ yín ní ohun gbogbo, yóò sì rán yín létí ohun gbogbo tí mo ti sọ fún yín.
Men Talsmanden, den Helligaand, som Faderen vil sende i mit Navn, han skal lære eder alle Ting og minde eder om alle Ting, som jeg har sagt eder.
27 Àlàáfíà ni mo fi sílẹ̀ fún yín pé, àlàáfíà mi ni mo fi fún yin, kì í ṣe bí ayé ti fi fún ni. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín dàrú, ẹ má sì jẹ́ kí ó wárìrì.
Fred efterlader jeg eder, min Fred giver jeg eder; jeg giver eder ikke, som Verden giver. Eders Hjerte forfærdes ikke og forsage ikke!
28 “Ẹ̀yin sá ti gbọ́ bí mo ti wí fún yín pé, ‘Èmi ń lọ, èmi ó sì tọ̀ yín wá.’ Ìbá ṣe pé ẹ̀yin fẹ́ràn mi, ẹ̀yin ìbá yọ̀ nítorí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba; nítorí Baba mi tóbi jù mí lọ.
I have hørt, at jeg sagde til eder: Jeg gaar bort og kommer til eder igen. Dersom I elskede mig, da glædede I eder over, at jeg gaar til Faderen; thi Faderen er større end jeg.
29 Èmi sì ti sọ fún yín nísinsin yìí kí ó tó ṣẹ, pé nígbà tí ó bá ṣẹ, kí ẹ lè gbàgbọ́.
Og nu har jeg sagt eder det, før det sker, for at I skulle tro, naar det er sket.
30 Èmi kì yóò bá yín sọ̀rọ̀ púpọ̀, nítorí ọmọ-aládé ayé yí wá, kò sì ní nǹkan kan lòdì sí mi.
Jeg skal herefter ikke tale meget med eder; thi denne Verdens Fyrste kommer, og han har slet intet i mig;
31 Ṣùgbọ́n nítorí kí ayé lè mọ̀ pé èmi fẹ́ràn Baba; gẹ́gẹ́ bí Baba sì ti fi àṣẹ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi ń ṣe. “Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a lọ kúrò níhìn-ín yìí.
men for at Verden skal kende, at jeg elsker Faderen og gør saaledes, som Faderen har befalet mig: saa staar nu op, lader os gaa herfra!”