< John 12 >

1 Nítorí náà, nígbà tí àjọ ìrékọjá ku ọjọ́ mẹ́fà, Jesu wá sí Betani, níbi tí Lasaru wà, ẹni tí ó ti kú, tí Jesu jí dìde kúrò nínú òkú.
ནིསྟཱརོཏྶཝཱཏ྄ པཱུཪྻྭཾ དིནཥཊྐེ སྠིཏེ ཡཱིཤུ ཪྻཾ པྲམཱིཏམ྄ ཨིལིཡཱསརཾ ཤྨཤཱནཱད྄ ཨུདསྠཱཔརཏ྄ ཏསྱ ནིཝཱསསྠཱནཾ བཻཐནིཡཱགྲཱམམ྄ ཨཱགཙྪཏ྄།
2 Wọ́n sì ṣe àsè alẹ́ fún un níbẹ̀. Marta sì ń ṣe ìránṣẹ́, ṣùgbọ́n Lasaru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó jókòó níbi tábìlì rẹ̀.
ཏཏྲ ཏདརྠཾ རཛནྱཱཾ བྷོཛྱེ ཀྲྀཏེ མརྠཱ པཪྻྱཝེཥཡད྄ ཨིལིཡཱསར྄ ཙ ཏསྱ སངྒིབྷིཿ སཱརྡྡྷཾ བྷོཛནཱསན ཨུཔཱཝིཤཏ྄།
3 Nígbà náà ni Maria mú òróró ìkunra nadi, òsùwọ̀n lita kan, àìlábùlà, olówó iyebíye, ó sì ń fi kun Jesu ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nu ẹsẹ̀ rẹ̀ nù. Ilé sì kún fún òórùn ìkunra náà.
ཏདཱ མརིཡམ྄ ཨརྡྡྷསེཊཀཾ བཧུམཱུལྱཾ ཛཊཱམཱཾསཱིཡཾ ཏཻལམ྄ ཨཱནཱིཡ ཡཱིཤོཤྩརཎཡོ རྨརྡྡཡིཏྭཱ ནིཛཀེཤ རྨཱརྵྚུམ྄ ཨཱརབྷཏ; ཏདཱ ཏཻལསྱ པརིམལེན གྲྀཧམ྄ ཨཱམོདིཏམ྄ ཨབྷཝཏ྄།
4 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Judasi Iskariotu, ọmọ Simoni ẹni tí yóò fi í hàn, wí pé,
ཡཿ ཤིམོནཿ པུཏྲ རིཥྐརིཡོཏཱིཡོ ཡིཧཱུདཱནཱམཱ ཡཱིཤུཾ པརཀརེཥུ སམརྤཡིཥྱཏི ས ཤིཥྱསྟདཱ ཀཐིཏཝཱན྄,
5 “Èéṣe tí a kò ta òróró ìkunra yìí ní ọ̀ọ́dúnrún owó idẹ kí a sì fi fún àwọn tálákà?”
ཨེཏཏྟཻལཾ ཏྲིབྷིཿ ཤཏཻ རྨུདྲཱཔདཻ ཪྻིཀྲཱིཏཾ སད྄ དརིདྲེབྷྱཿ ཀུཏོ ནཱདཱིཡཏ?
6 Ṣùgbọ́n ó wí èyí, kì í ṣe nítorí tí ó náání àwọn tálákà; ṣùgbọ́n nítorí tí ó jẹ́ olè, òun ni ó ni àpò, a sì máa jí ohun tí a fi sínú rẹ̀ láti fi ran ara rẹ lọ́wọ́.
ས དརིདྲལོཀཱརྠམ྄ ཨཙིནྟཡད྄ ཨིཏི ན, ཀིནྟུ ས ཙཽར ཨེཝཾ ཏནྣིཀཊེ མུདྲཱསམྤུཊཀསྠིཏྱཱ ཏནྨདྷྱེ ཡདཏིཥྛཏ྄ ཏདཔཱཧརཏ྄ ཏསྨཱཏ྄ ཀཱརཎཱད྄ ཨིམཱཾ ཀཐཱམཀཐཡཏ྄།
7 Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀, ó ṣe é sílẹ̀ de ọjọ́ ìsìnkú mi.
ཏདཱ ཡཱིཤུརཀཐཡད྄ ཨེནཱཾ མཱ ཝཱརཡ སཱ མམ ཤྨཤཱནསྠཱཔནདིནཱརྠཾ ཏདརཀྵཡཏ྄།
8 Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin sá à ní tálákà pẹ̀lú yín; ṣùgbọ́n èmi ni ẹ kò ní nígbà gbogbo.”
དརིདྲཱ ཡུཥྨཱཀཾ སནྣིདྷཽ སཪྻྭདཱ ཏིཥྛནྟི ཀིནྟྭཧཾ སཪྻྭདཱ ཡུཥྨཱཀཾ སནྣིདྷཽ ན ཏིཥྛཱམི།
9 Nítorí náà, ìjọ ènìyàn nínú àwọn Júù ni ó mọ̀ pé ó wà níbẹ̀; wọ́n sì wá, kì í ṣe nítorí Jesu nìkan, ṣùgbọ́n kí wọn lè rí Lasaru pẹ̀lú, ẹni tí ó ti jí dìde kúrò nínú òkú.
ཏཏཿ པརཾ ཡཱིཤུསྟཏྲཱསྟཱིཏི ཝཱརྟྟཱཾ ཤྲུཏྭཱ བཧཝོ ཡིཧཱུདཱིཡཱསྟཾ ཤྨཤཱནཱདུཏྠཱཔིཏམ྄ ཨིལིཡཱསརཉྩ དྲཥྚུཾ ཏཏ྄ སྠཱནམ྄ ཨཱགཙྪན།
10 Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà gbìmọ̀ kí wọn lè pa Lasaru pẹ̀lú,
ཏདཱ པྲདྷཱནཡཱཛཀཱསྟམ྄ ཨིལིཡཱསརམཔི སཾཧརྟྟུམ྄ ཨམནྟྲཡན྄;
11 nítorí pé nípasẹ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù jáde lọ, wọ́n sì gbà Jesu gbọ́.
ཡཏསྟེན བཧཝོ ཡིཧཱུདཱིཡཱ གཏྭཱ ཡཱིཤཽ ཝྱཤྭསན྄།
12 Ní ọjọ́ kejì nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó wá sí àjọ gbọ́ pé, Jesu ń bọ̀ wá sí Jerusalẹmu.
ཨནནྟརཾ ཡཱིཤུ ཪྻིརཱུཤཱལམ྄ ནགརམ྄ ཨཱགཙྪཏཱིཏི ཝཱརྟྟཱཾ ཤྲུཏྭཱ པརེ྅ཧནི ཨུཏྶཝཱགཏཱ བཧཝོ ལོཀཱཿ
13 Wọ́n mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n sì jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n sì ń kígbe pé, “Hosana!” “Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Olùbùkún ni ọba Israẹli!”
ཁརྫྫཱུརཔཏྲཱདྱཱནཱིཡ ཏཾ སཱཀྵཱཏ྄ ཀརྟྟུཾ བཧིརཱགཏྱ ཛཡ ཛཡེཏི ཝཱཙཾ པྲོཙྩཻ ཪྻཀྟུམ྄ ཨཱརབྷནྟ, ཨིསྲཱཡེལོ ཡོ རཱཛཱ པརམེཤྭརསྱ ནཱམྣཱགཙྪཏི ས དྷནྱཿ།
14 Nígbà tí Jesu sì rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ó gùn ún; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé pé,
ཏདཱ "ཧེ སིཡོནཿ ཀནྱེ མཱ བྷཻཥཱིཿ པཤྱཱཡཾ ཏཝ རཱཛཱ གརྡྡབྷཤཱཝཀམ྄ ཨཱརུཧྱཱགཙྪཏི"
15 “Má bẹ̀rù, ọmọbìnrin Sioni; wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá, o jókòó lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.”
ཨིཏི ཤཱསྟྲཱིཡཝཙནཱནུསཱརེཎ ཡཱིཤུརེཀཾ ཡུཝགརྡྡབྷཾ པྲཱཔྱ ཏདུཔཪྻྱཱརོཧཏ྄།
16 Nǹkan wọ̀nyí kò tètè yé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí a ṣe Jesu lógo, nígbà náà ni wọ́n rántí pé, a kọ̀wé nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ sí i.
ཨསྱཱཿ གྷཊནཱཡཱསྟཱཏྤཪྻྱཾ ཤིཥྱཱཿ པྲཐམཾ ནཱབུདྷྱནྟ, ཀིནྟུ ཡཱིཤཽ མཧིམཱནཾ པྲཱཔྟེ སཏི ཝཱཀྱམིདཾ ཏསྨིན ཨཀཐྱཏ ལོཀཱཤྩ ཏམྤྲཏཱིཏྠམ྄ ཨཀུཪྻྭན྄ ཨིཏི ཏེ སྨྲྀཏཝནྟཿ།
17 Nítorí náà, ìjọ ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí o pé Lasaru jáde nínú ibojì rẹ̀, tí ó sì jí i dìde kúrò nínú òkú, jẹ́rìí sí i.
ས ཨིལིཡཱསརཾ ཤྨཤཱནཱད྄ ཨཱགནྟུམ྄ ཨཱཧྭཏཝཱན྄ ཤྨཤཱནཱཉྩ ཨུདསྠཱཔཡད྄ ཡེ ཡེ ལོཀཱསྟཏྐརྨྱ སཱཀྵཱད྄ ཨཔཤྱན྄ ཏེ པྲམཱཎཾ དཱཏུམ྄ ཨཱརབྷནྟ།
18 Nítorí èyí ni ìjọ ènìyàn sì ṣe lọ pàdé rẹ̀, nítorí tí wọ́n gbọ́ pé ó ti ṣe iṣẹ́ àmì yìí.
ས ཨེཏཱདྲྀཤམ྄ ཨདྦྷུཏཾ ཀརྨྨཀརོཏ྄ ཏསྱ ཛནཤྲུཏེ རློཀཱསྟཾ སཱཀྵཱཏ྄ ཀརྟྟུམ྄ ཨཱགཙྪན྄།
19 Nítorí náà àwọn Farisi wí fún ara wọn pé, “Ẹ kíyèsi bí ẹ kò ti lè borí ní ohunkóhun? Ẹ wo bí gbogbo ayé ti ń wọ́ tọ̀ ọ́!”
ཏཏཿ ཕིརཱུཤིནཿ པརསྤརཾ ཝཀྟུམ྄ ཨཱརབྷནྟ ཡུཥྨཱཀཾ སཪྻྭཱཤྩེཥྚཱ ཝྲྀཐཱ ཛཱཏཱཿ, ཨིཏི ཀིཾ ཡཱུཡཾ ན བུདྷྱདྷྭེ? པཤྱཏ སཪྻྭེ ལོཀཱསྟསྱ པཤྩཱདྭརྟྟིནོབྷཝན྄།
20 Àwọn Giriki kan sì wà nínú àwọn tí ó gòkè wá láti sìn nígbà àjọ,
བྷཛནཾ ཀརྟྟུམ྄ ཨུཏྶཝཱགཏཱནཱཾ ལོཀཱནཱཾ ཀཏིཔཡཱ ཛནཱ ཨནྱདེཤཱིཡཱ ཨཱསན྄,
21 Àwọn wọ̀nyí ni ó tọ Filipi wá, ẹni tí í ṣe ará Betisaida tí Galili, wọ́n sì ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Alàgbà, àwa ń fẹ́ rí Jesu!”
ཏེ གཱལཱིལཱིཡབཻཏྶཻདཱནིཝཱསིནཿ ཕིལིཔསྱ སམཱིཔམ྄ ཨཱགཏྱ ཝྱཱཧརན྄ ཧེ མཧེཙྪ ཝཡཾ ཡཱིཤུཾ དྲཥྚུམ྄ ཨིཙྪཱམཿ།
22 Filipi wá, ó sì sọ fún Anderu; Anderu àti Filipi wá, wọ́n sì sọ fún Jesu.
ཏཏཿ ཕིལིཔོ གཏྭཱ ཨཱནྡྲིཡམ྄ ཨཝདཏ྄ པཤྩཱད྄ ཨཱནྡྲིཡཕིལིཔཽ ཡཱིཤཝེ ཝཱརྟྟཱམ྄ ཨཀཐཡཏཱཾ།
23 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Wákàtí náà dé, tí a ó ṣe Ọmọ Ènìyàn lógo.
ཏདཱ ཡཱིཤུཿ པྲཏྱུདིཏཝཱན྄ མཱནཝསུཏསྱ མཧིམཔྲཱཔྟིསམཡ ཨུཔསྠིཏཿ།
24 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé alikama bá bọ́ sí ilẹ̀, tí ó bá sì kú, ó wà ní òun nìkan; ṣùgbọ́n bí ó bá kú, yóò sì so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
ཨཧཾ ཡུཥྨཱནཏིཡཐཱརྠཾ ཝདཱམི, དྷཱནྱབཱིཛཾ མྲྀཏྟིཀཱཡཱཾ པཏིཏྭཱ ཡདི ན མྲྀཡཏེ ཏརྷྱེཀཱཀཱི ཏིཥྛཏི ཀིནྟུ ཡདི མྲྀཡཏེ ཏརྷི བཧུགུཎཾ ཕལཾ ཕལཏི།
25 Ẹni tí ó bá fẹ́ ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù; ẹni tí ó bá sì kórìíra ẹ̀mí rẹ̀ láyé yìí ni yóò sì pa á mọ́ títí ó fi di ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
ཡོ ཛནེ ནིཛཔྲཱཎཱན྄ པྲིཡཱན྄ ཛཱནཱཏི ས ཏཱན྄ ཧཱརཡིཥྱཏི ཀིནྟུ ཡེ ཛན ཨིཧལོཀེ ནིཛཔྲཱཎཱན྄ ཨཔྲིཡཱན྄ ཛཱནཱཏི སེནནྟཱཡུཿ པྲཱཔྟུཾ ཏཱན྄ རཀྵིཥྱཏི། (aiōnios g166)
26 Bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, kí ó máa tọ̀ mí lẹ́yìn, àti pe níbi tí èmi bá wà, níbẹ̀ ni ìránṣẹ́ mi yóò wà pẹ̀lú, bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, òun ni Baba yóò bu ọlá fún.
ཀཤྩིད྄ ཡདི མམ སེཝཀོ བྷཝིཏུཾ ཝཱཉྪཏི ཏརྷི ས མམ པཤྩཱདྒཱམཱི བྷཝཏུ, ཏསྨཱད྄ ཨཧཾ ཡཏྲ ཏིཥྛཱམི མམ སེཝཀེཔི ཏཏྲ སྠཱསྱཏི; ཡོ ཛནོ མཱཾ སེཝཏེ མམ པིཏཱཔི ཏཾ སམྨཾསྱཏེ།
27 “Ní ìsinsin yìí ni a ń pọ́n ọkàn mi lójú; kín ni èmi ó sì wí? ‘Baba, gbà mí kúrò nínú wákàtí yìí’? Rárá, ṣùgbọ́n nítorí èyí ni mo ṣe wá sí wákàtí yìí.
སཱམྤྲཏཾ མམ པྲཱཎཱ ཝྱཱཀུལཱ བྷཝནྟི, ཏསྨཱད྄ ཧེ པིཏར ཨེཏསྨཱཏ྄ སམཡཱན྄ མཱཾ རཀྵ, ཨིཏྱཧཾ ཀིཾ པྲཱརྠཡིཥྱེ? ཀིནྟྭཧམ྄ ཨེཏཏྶམཡཱརྠམ྄ ཨཝཏཱིརྞཝཱན྄།
28 Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo!” Nígbà náà ni ohùn kan ti ọ̀run wá, wí pé, “Èmi ti ṣe é lógo!”
ཧེ པིཏ: སྭནཱམྣོ མཧིམཱནཾ པྲཀཱཤཡ; ཏནཻཝ སྭནཱམྣོ མཧིམཱནམ྄ ཨཧཾ པྲཱཀཱཤཡཾ པུནརཔི པྲཀཱཤཡིཥྱཱམི, ཨེཥཱ གགཎཱིཡཱ ཝཱཎཱི ཏསྨིན྄ སམཡེ྅ཛཱཡཏ།
29 Nítorí náà ìjọ ènìyàn tí ó dúró níbẹ̀, tí wọ́n sì gbọ́ ọ, wí pé, “Àrá ń sán.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Angẹli kan ni ó ń bá a sọ̀rọ̀.”
ཏཙྴྲུཏྭཱ སམཱིཔསྠལོཀཱནཱཾ ཀེཙིད྄ ཨཝདན྄ མེགྷོ྅གརྫཱིཏ྄, ཀེཙིད྄ ཨཝདན྄ སྭརྒཱིཡདཱུཏོ྅ནེན སཧ ཀཐཱམཙཀཐཏ྄།
30 Jesu sì dáhùn wí pé, “Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín.
ཏདཱ ཡཱིཤུཿ པྲཏྱཝཱདཱིཏ྄, མདརྠཾ ཤབྡོཡཾ ནཱབྷཱུཏ྄ ཡུཥྨདརྠམེཝཱབྷཱུཏ྄།
31 Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde.
ཨདྷུནཱ ཛགཏོསྱ ཝིཙཱར: སམྤཏྶྱཏེ, ཨདྷུནཱསྱ ཛགཏ: པཏཱི རཱཛྱཱཏ྄ ཙྱོཥྱཏི།
32 Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!”
ཡདྱཨཱི པྲྀཐིཝྱཱ ཨཱུརྡྭྭེ པྲོཏྠཱཔིཏོསྨི ཏརྷི སཪྻྭཱན྄ མཱནཝཱན྄ སྭསམཱིཔམ྄ ཨཱཀརྵིཥྱཱམི།
33 Ṣùgbọ́n ó wí èyí, ó ń ṣe àpẹẹrẹ irú ikú tí òun yóò kú.
ཀཐཾ ཏསྱ མྲྀཏི རྦྷཝིཥྱཏི, ཨེཏད྄ བོདྷཡིཏུཾ ས ཨིམཱཾ ཀཐཱམ྄ ཨཀཐཡཏ྄།
34 Nítorí náà àwọn ìjọ ènìyàn dá a lóhùn pé, “Àwa gbọ́ nínú òfin pé, Kristi wà títí láéláé, ìwọ ha ṣe wí pé, ‘A ó gbé Ọmọ Ènìyàn sókè’? Ta ni ó ń jẹ́ ‘Ọmọ Ènìyàn yìí’?” (aiōn g165)
ཏདཱ ལོཀཱ ཨཀཐཡན྄ སོབྷིཥིཀྟཿ སཪྻྭདཱ ཏིཥྛཏཱིཏི ཝྱཝསྠཱགྲནྠེ ཤྲུཏམ྄ ཨསྨཱབྷིཿ, ཏརྷི མནུཥྱཔུཏྲཿ པྲོཏྠཱཔིཏོ བྷཝིཥྱཏཱིཏི ཝཱཀྱཾ ཀཐཾ ཝདསི? མནུཥྱཔུཏྲོཡཾ ཀཿ? (aiōn g165)
35 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà díẹ̀ sí i ni ìmọ́lẹ̀ wà láàrín yín, ẹ máa rìn nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, kí òkùnkùn má ṣe bá yín, ẹni tí ó bá sì ń rìn ní òkùnkùn kò mọ ibi òun ń lọ.
ཏདཱ ཡཱིཤུརཀཐཱཡད྄ ཡུཥྨཱབྷིཿ སཱརྡྡྷམ྄ ཨལྤདིནཱནི ཛྱོཏིརཱསྟེ, ཡཐཱ ཡུཥྨཱན྄ ཨནྡྷཀཱརོ ནཱཙྪཱདཡཏི ཏདརྠཾ ཡཱཝཏྐཱལཾ ཡུཥྨཱབྷིཿ སཱརྡྡྷཾ ཛྱོཏིསྟིཥྛཏི ཏཱཝཏྐཱལཾ གཙྪཏ; ཡོ ཛནོ྅ནྡྷཀཱརེ གཙྪཏི ས ཀུཏྲ ཡཱཏཱིཏི ན ཛཱནཱཏི།
36 Nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, ẹ gba ìmọ́lẹ̀ gbọ́, kí ẹ lè jẹ́ ọmọ ìmọ́lẹ̀!” Nǹkan wọ̀nyí ni Jesu sọ, ó sì jáde lọ, ó fi ara pamọ́ fún wọn.
ཨཏཨེཝ ཡཱཝཏྐཱལཾ ཡུཥྨཱཀཾ ནིཀཊེ ཛྱོཏིརཱསྟེ ཏཱཝཏྐཱལཾ ཛྱོཏཱིརཱུཔསནྟཱནཱ བྷཝིཏུཾ ཛྱོཏིཥི ཝིཤྭསིཏ; ཨིམཱཾ ཀཐཱཾ ཀཐཡིཏྭཱ ཡཱིཤུཿ པྲསྠཱཡ ཏེབྷྱཿ སྭཾ གུཔྟཝཱན྄།
37 Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì tó báyìí lójú wọn, wọn kò gbà á gbọ́.
ཡདྱཔི ཡཱིཤུསྟེཥཱཾ སམཀྵམ྄ ཨེཏཱཝདཱཤྩཪྻྱཀརྨྨཱཎི ཀྲྀཏཝཱན྄ ཏཐཱཔི ཏེ ཏསྨིན྄ ན ཝྱཤྭསན྄།
38 Kí ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah lè ṣẹ, èyí tí ó sọ pé, “Olúwa, ta ni ó gba ìwàásù wa gbọ́ Àti ta ni a sì fi apá Olúwa hàn fún?”
ཨཏཨེཝ ཀཿ པྲཏྱེཏི སུསཾཝཱདཾ པརེཤཱསྨཏ྄ པྲཙཱརིཏཾ? པྲཀཱཤཏེ པརེཤསྱ ཧསྟཿ ཀསྱ ཙ སནྣིདྷཽ? ཡིཤཡིཡབྷཝིཥྱདྭཱདིནཱ ཡདེཏད྄ ཝཱཀྱམུཀྟཾ ཏཏ྄ སཕལམ྄ ཨབྷཝཏ྄།
39 Nítorí èyí ni wọn kò fi lè gbàgbọ́, nítorí Isaiah sì tún sọ pé,
ཏེ པྲཏྱེཏུཾ ནཱཤནྐུཝན྄ ཏསྨིན྄ ཡིཤཡིཡབྷཝིཥྱདྭཱདི པུནརཝཱདཱིད྄,
40 “Ó ti fọ́ wọn lójú, Ó sì ti sé àyà wọn le; kí wọn má ba à fi ojú wọn rí, kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀, kí wọn má ba à yípadà, kí èmi má ba à mú wọn láradá.”
ཡདཱ, "ཏེ ནཡནཻ རྣ པཤྱནྟི བུདྡྷིབྷིཤྩ ན བུདྷྱནྟེ ཏཻ རྨནཿསུ པརིཝརྟྟིཏེཥུ ཙ ཏཱནཧཾ ཡཐཱ སྭསྠཱན྄ ན ཀརོམི ཏཐཱ ས ཏེཥཱཾ ལོཙནཱནྱནྡྷཱནི ཀྲྀཏྭཱ ཏེཥཱམནྟཿཀརཎཱནི གཱཌྷཱནི ཀརིཥྱཏི། "
41 Nǹkan wọ̀nyí ni Isaiah wí, nítorí ó ti rí ògo rẹ̀, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀.
ཡིཤཡིཡོ ཡདཱ ཡཱིཤོ རྨཧིམཱནཾ ཝིལོཀྱ ཏསྨིན྄ ཀཐཱམཀཐཡཏ྄ ཏདཱ བྷཝིཥྱདྭཱཀྱམ྄ ཨཱིདྲྀཤཾ པྲཀཱཤཡཏ྄།
42 Síbẹ̀ ọ̀pọ̀ nínú àwọn olórí gbà á gbọ́ pẹ̀lú; ṣùgbọ́n nítorí àwọn Farisi wọn kò jẹ́wọ́ rẹ̀, kí a má ba à yọ wọ́n kúrò nínú Sinagọgu,
ཏཐཱཔྱདྷིཔཏིནཱཾ བཧཝསྟསྨིན྄ པྲཏྱཱཡན྄། ཀིནྟུ ཕིརཱུཤིནསྟཱན྄ བྷཛནགྲྀཧཱད྄ དཱུརཱིཀུཪྻྭནྟཱིཏི བྷཡཱཏ྄ ཏེ ཏཾ ན སྭཱིཀྲྀཏཝནྟཿ།
43 nítorí wọ́n fẹ́ ìyìn ènìyàn ju ìyìn ti Ọlọ́run lọ.
ཡཏ ཨཱིཤྭརསྱ པྲཤཾསཱཏོ མཱནཝཱནཱཾ པྲཤཾསཱཡཱཾ ཏེ྅པྲིཡནྟ།
44 Jesu sì kígbe ó sì wí pé, “Ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, èmi kọ́ ni ó gbàgbọ́ ṣùgbọ́n ẹni tí ó rán mi.
ཏདཱ ཡཱིཤུརུཙྩཻཿཀཱརམ྄ ཨཀཐཡད྄ ཡོ ཛནོ མཡི ཝིཤྭསིཏི ས ཀེཝལེ མཡི ཝིཤྭསིཏཱིཏི ན, ས མཏྤྲེརཀེ྅པི ཝིཤྭསིཏི།
45 Ẹni tí ó bá sì rí mi, ó rí ẹni tí ó rán mi.
ཡོ ཛནོ མཱཾ པཤྱཏི ས མཏྤྲེརཀམཔི པཤྱཏི།
46 Èmi ni ìmọ́lẹ̀ tí ó wá sí ayé, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ má ṣe wà nínú òkùnkùn.
ཡོ ཛནོ མཱཾ པྲཏྱེཏི ས ཡཐཱནྡྷཀཱརེ ན ཏིཥྛཏི ཏདརྠམ྄ ཨཧཾ ཛྱོཏིཿསྭརཱུཔོ བྷཱུཏྭཱ ཛགཏྱསྨིན྄ ཨཝཏཱིརྞཝཱན྄།
47 “Bí ẹnikẹ́ni bá sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí kò sì pa wọ́n mọ́, èmi kì yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ nítorí tí èmi kò wá láti ṣe ìdájọ́ ayé, bí kò ṣe láti gba ayé là.
མམ ཀཐཱཾ ཤྲུཏྭཱ ཡདི ཀཤྩིན྄ ན ཝིཤྭསིཏི ཏརྷི ཏམཧཾ དོཥིཎཾ ན ཀརོམི, ཡཏོ ཧེཏོ རྫགཏོ ཛནཱནཱཾ དོཥཱན྄ ནིཤྩིཏཱན྄ ཀརྟྟུཾ ནཱགཏྱ ཏཱན྄ པརིཙཱཏུམ྄ ཨཱགཏོསྨི།
48 Ẹni tí ó bá kọ̀ mí, tí kò sì gba ọ̀rọ̀ mi, ó ní ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀; ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ, òun náà ni yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.
ཡཿ ཀཤྩིན྄ མཱཾ ན ཤྲདྡྷཱཡ མམ ཀཐཾ ན གྲྀཧླཱཏི, ཨནྱསྟཾ དོཥིཎཾ ཀརིཥྱཏི ཝསྟུཏསྟུ ཡཱཾ ཀཐཱམཧམ྄ ཨཙཀཐཾ སཱ ཀཐཱ ཙརམེ྅ནྷི ཏཾ དོཥིཎཾ ཀརིཥྱཏི།
49 Nítorí èmi kò dá ọ̀rọ̀ sọ fún ara mi, ṣùgbọ́n Baba tí ó rán mi, ni ó ti fún mi ní àṣẹ, ohun tí èmi ó sọ, àti èyí tí èmi ó wí.
ཡཏོ ཧེཏོརཧཾ སྭཏཿ ཀིམཔི ན ཀཐཡཱམི, ཀིཾ ཀིཾ མཡཱ ཀཐཡིཏཝྱཾ ཀིཾ སམུཔདེཥྚཝྱཉྩ ཨིཏི མཏྤྲེརཡིཏཱ པིཏཱ མཱམཱཛྙཱཔཡཏ྄།
50 Èmi sì mọ̀ pé ìyè àìnípẹ̀kun ni òfin rẹ̀, nítorí náà, àwọn ohun tí mo bá wí, gẹ́gẹ́ bí Baba ti sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni mo wí!” (aiōnios g166)
ཏསྱ སཱཛྙཱ ཨནནྟཱཡུརིཏྱཧཾ ཛཱནཱམི, ཨཏཨེཝཱཧཾ ཡཏ྄ ཀཐཡཱམི ཏཏ྄ པིཏཱ ཡཐཱཛྙཱཔཡཏ྄ ཏཐཻཝ ཀཐཡཱམྱཧམ྄། (aiōnios g166)

< John 12 >