< John 12 >

1 Nítorí náà, nígbà tí àjọ ìrékọjá ku ọjọ́ mẹ́fà, Jesu wá sí Betani, níbi tí Lasaru wà, ẹni tí ó ti kú, tí Jesu jí dìde kúrò nínú òkú.
Na sześć dni przed rozpoczęciem Paschy Jezus przybył do Betanii, do Łazarza, którego niedawno wskrzesił z martwych.
2 Wọ́n sì ṣe àsè alẹ́ fún un níbẹ̀. Marta sì ń ṣe ìránṣẹ́, ṣùgbọ́n Lasaru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó jókòó níbi tábìlì rẹ̀.
Przygotowano z tej okazji kolację. Marta im usługiwała, Łazarz siedział razem z Jezusem,
3 Nígbà náà ni Maria mú òróró ìkunra nadi, òsùwọ̀n lita kan, àìlábùlà, olówó iyebíye, ó sì ń fi kun Jesu ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nu ẹsẹ̀ rẹ̀ nù. Ilé sì kún fún òórùn ìkunra náà.
natomiast Maria przyniosła butelkę bardzo drogiego olejku nardowego, namaściła nim stopy Jezusa i otarła je własnymi włosami. Cały dom napełnił się wspaniałym zapachem.
4 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Judasi Iskariotu, ọmọ Simoni ẹni tí yóò fi í hàn, wí pé,
Na to Judasz, jeden z uczniów Jezusa (ten, który Go później zdradził), powiedział:
5 “Èéṣe tí a kò ta òróró ìkunra yìí ní ọ̀ọ́dúnrún owó idẹ kí a sì fi fún àwọn tálákà?”
—Przecież można było sprzedać te perfumy i uzyskaną w ten sposób znaczną sumę rozdać biednym!
6 Ṣùgbọ́n ó wí èyí, kì í ṣe nítorí tí ó náání àwọn tálákà; ṣùgbọ́n nítorí tí ó jẹ́ olè, òun ni ó ni àpò, a sì máa jí ohun tí a fi sínú rẹ̀ láti fi ran ara rẹ lọ́wọ́.
Powiedział to jednak nie z troski o biednych, ale dlatego, że był złodziejem. Jako skarbnik trzymał wspólną kasę i wykradał z niej pieniądze.
7 Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀, ó ṣe é sílẹ̀ de ọjọ́ ìsìnkú mi.
—Daj jej spokój!—odrzekł Jezus. —Przygotowała to na dzień mojego pogrzebu.
8 Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin sá à ní tálákà pẹ̀lú yín; ṣùgbọ́n èmi ni ẹ kò ní nígbà gbogbo.”
Biedni zawsze będą wśród was, ale Mnie już wkrótce zabraknie.
9 Nítorí náà, ìjọ ènìyàn nínú àwọn Júù ni ó mọ̀ pé ó wà níbẹ̀; wọ́n sì wá, kì í ṣe nítorí Jesu nìkan, ṣùgbọ́n kí wọn lè rí Lasaru pẹ̀lú, ẹni tí ó ti jí dìde kúrò nínú òkú.
Gdy mieszkańcy Jerozolimy dowiedzieli się, że Jezus jest w Betanii, przybyli tam. Chcieli się bowiem z Nim spotkać, ale także zobaczyć Łazarza, którego wzbudził z martwych.
10 Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà gbìmọ̀ kí wọn lè pa Lasaru pẹ̀lú,
Wówczas najwyżsi kapłani postanowili zabić również Łazarza,
11 nítorí pé nípasẹ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù jáde lọ, wọ́n sì gbà Jesu gbọ́.
bo z jego powodu wielu Żydów uwierzyło Jezusowi.
12 Ní ọjọ́ kejì nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó wá sí àjọ gbọ́ pé, Jesu ń bọ̀ wá sí Jerusalẹmu.
Następnego dnia wśród tłumów, które przybyły na święto, rozeszła się wieść, że Jezus zbliża się do miasta.
13 Wọ́n mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n sì jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n sì ń kígbe pé, “Hosana!” “Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Olùbùkún ni ọba Israẹli!”
Ludzie wzięli więc liście palmowe, wyszli Mu na spotkanie i powitali Go wołając: —Niech żyje Król Izraela! Błogosławiony Ten, który przychodzi w imieniu Pana!
14 Nígbà tí Jesu sì rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ó gùn ún; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé pé,
A Jezus dosiadł osiołka i jechał na nim, spełniając w ten sposób zapowiedź Pisma:
15 “Má bẹ̀rù, ọmọbìnrin Sioni; wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá, o jókòó lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.”
„Nie bój się, córko Syjonu! Oto nadchodzi twój król —jadąc na osiołku!”.
16 Nǹkan wọ̀nyí kò tètè yé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí a ṣe Jesu lógo, nígbà náà ni wọ́n rántí pé, a kọ̀wé nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ sí i.
Wtedy jeszcze uczniowie nie rozumieli tego zdarzenia. Ale później, gdy Jezus został otoczony chwałą, przypomnieli sobie, że to o Nim mówiło Pismo.
17 Nítorí náà, ìjọ ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí o pé Lasaru jáde nínú ibojì rẹ̀, tí ó sì jí i dìde kúrò nínú òkú, jẹ́rìí sí i.
Ci, którzy wcześniej na własne oczy widzieli, jak Jezus zawołał Łazarza i wskrzesił go z martwych, opowiadali o tym innym.
18 Nítorí èyí ni ìjọ ènìyàn sì ṣe lọ pàdé rẹ̀, nítorí tí wọ́n gbọ́ pé ó ti ṣe iṣẹ́ àmì yìí.
Dlatego aż tak wielki tłum wyszedł powitać Jezusa. Ludzie bowiem dowiedzieli się, że dokonał tego cudu.
19 Nítorí náà àwọn Farisi wí fún ara wọn pé, “Ẹ kíyèsi bí ẹ kò ti lè borí ní ohunkóhun? Ẹ wo bí gbogbo ayé ti ń wọ́ tọ̀ ọ́!”
Faryzeusze zaś mówili między sobą: —Chyba nie da się już nic zrobić. Cały świat poszedł za Nim.
20 Àwọn Giriki kan sì wà nínú àwọn tí ó gòkè wá láti sìn nígbà àjọ,
W tym czasie przybyli na święto pewni Grecy, aby oddać chwałę Bogu.
21 Àwọn wọ̀nyí ni ó tọ Filipi wá, ẹni tí í ṣe ará Betisaida tí Galili, wọ́n sì ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Alàgbà, àwa ń fẹ́ rí Jesu!”
Podeszli do Filipa, pochodzącego z Betsaidy w Galilei, i prosili go: —Chcielibyśmy spotkać się z Jezusem.
22 Filipi wá, ó sì sọ fún Anderu; Anderu àti Filipi wá, wọ́n sì sọ fún Jesu.
Filip porozmawiał z Andrzejem i razem powiedzieli o tym Jezusowi.
23 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Wákàtí náà dé, tí a ó ṣe Ọmọ Ènìyàn lógo.
—Nadszedł czas, abym Ja, Syn Człowieczy, został otoczony chwałą—odpowiedział im Jezus.
24 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé alikama bá bọ́ sí ilẹ̀, tí ó bá sì kú, ó wà ní òun nìkan; ṣùgbọ́n bí ó bá kú, yóò sì so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
—Zapewniam was: Jeśli ziarno pszenicy wpada w ziemię i nie obumiera, pozostaje samo. Jeśli obumiera, przynosi obfity plon.
25 Ẹni tí ó bá fẹ́ ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù; ẹni tí ó bá sì kórìíra ẹ̀mí rẹ̀ láyé yìí ni yóò sì pa á mọ́ títí ó fi di ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
Kto kocha ziemskie życie, utraci je. Lecz kto nie przywiązuje wagi do życia na tym świecie, otrzyma życie wieczne. (aiōnios g166)
26 Bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, kí ó máa tọ̀ mí lẹ́yìn, àti pe níbi tí èmi bá wà, níbẹ̀ ni ìránṣẹ́ mi yóò wà pẹ̀lú, bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, òun ni Baba yóò bu ọlá fún.
Kto chce Mi służyć, niech idzie ze Mną. A tam, gdzie Ja będę, będzie i mój sługa. Mój Ojciec doceni bowiem tych, którzy Mi służą.
27 “Ní ìsinsin yìí ni a ń pọ́n ọkàn mi lójú; kín ni èmi ó sì wí? ‘Baba, gbà mí kúrò nínú wákàtí yìí’? Rárá, ṣùgbọ́n nítorí èyí ni mo ṣe wá sí wákàtí yìí.
Teraz zaś przeżywam wielkie rozdarcie. Czy mam prosić: „Ojcze, uchroń Mnie przed tą chwilą”? Przecież właśnie z jej powodu przyszedłem na świat!
28 Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo!” Nígbà náà ni ohùn kan ti ọ̀run wá, wí pé, “Èmi ti ṣe é lógo!”
Ojcze, otocz swoje imię chwałą! Wówczas dał się słyszeć głos z nieba: —Już je otoczyłem chwałą i ponownie otoczę.
29 Nítorí náà ìjọ ènìyàn tí ó dúró níbẹ̀, tí wọ́n sì gbọ́ ọ, wí pé, “Àrá ń sán.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Angẹli kan ni ó ń bá a sọ̀rọ̀.”
—Zagrzmiało!—powiedzieli niektórzy, słysząc ten głos. —To anioł przemówił—twierdzili inni.
30 Jesu sì dáhùn wí pé, “Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín.
—Ten głos odezwał się nie ze względu na Mnie, ale na was—odpowiedział Jezus.
31 Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde.
—Nadszedł bowiem czas sądu nad światem. Teraz jego władca zostanie z niego wyrzucony.
32 Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!”
A Ja, gdy zostanę podniesiony w górę, przyciągnę wszystkich do siebie.
33 Ṣùgbọ́n ó wí èyí, ó ń ṣe àpẹẹrẹ irú ikú tí òun yóò kú.
Mówiąc o podniesieniu, dał im do zrozumienia, w jaki sposób umrze.
34 Nítorí náà àwọn ìjọ ènìyàn dá a lóhùn pé, “Àwa gbọ́ nínú òfin pé, Kristi wà títí láéláé, ìwọ ha ṣe wí pé, ‘A ó gbé Ọmọ Ènìyàn sókè’? Ta ni ó ń jẹ́ ‘Ọmọ Ènìyàn yìí’?” (aiōn g165)
Wtedy ludzie z tłumu pytali Go: —Z Prawa Mojżesza wiemy, że Mesjasz będzie żyć wiecznie. Dlaczego więc mówisz, że Syn Człowieczy zostanie podniesiony w górę? Kim On właściwie jest? (aiōn g165)
35 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà díẹ̀ sí i ni ìmọ́lẹ̀ wà láàrín yín, ẹ máa rìn nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, kí òkùnkùn má ṣe bá yín, ẹni tí ó bá sì ń rìn ní òkùnkùn kò mọ ibi òun ń lọ.
—Jeszcze tylko przez chwilę będziecie mieli wśród siebie światło—odpowiedział Jezus. —Dopóki możecie, chodźcie więc w jego blasku, aby nie ogarnął was mrok. Kto bowiem chodzi w ciemności, nie wie, dokąd zmierza.
36 Nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, ẹ gba ìmọ́lẹ̀ gbọ́, kí ẹ lè jẹ́ ọmọ ìmọ́lẹ̀!” Nǹkan wọ̀nyí ni Jesu sọ, ó sì jáde lọ, ó fi ara pamọ́ fún wọn.
Póki macie światło, uwierzcie w nie, abyście stali się dziećmi światła. Po tych słowach Jezus odszedł i ukrył się przed tłumem.
37 Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì tó báyìí lójú wọn, wọn kò gbà á gbọ́.
Chociaż dokonał na oczach ludzi wielu cudów, nie wszyscy Mu uwierzyli.
38 Kí ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah lè ṣẹ, èyí tí ó sọ pé, “Olúwa, ta ni ó gba ìwàásù wa gbọ́ Àti ta ni a sì fi apá Olúwa hàn fún?”
W ten sposób spełniły się słowa proroka Izajasza, który powiedział: „Panie, kto uwierzy naszym słowom? Kto rozpoznał Twoje działanie?”.
39 Nítorí èyí ni wọn kò fi lè gbàgbọ́, nítorí Isaiah sì tún sọ pé,
Nie mogli jednak uwierzyć, ponieważ Izajasz powiedział również:
40 “Ó ti fọ́ wọn lójú, Ó sì ti sé àyà wọn le; kí wọn má ba à fi ojú wọn rí, kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀, kí wọn má ba à yípadà, kí èmi má ba à mú wọn láradá.”
„Pan zaślepił ich oczy i uczynił twardymi ich serca, aby niczego nie widzieli i niczego nie zrozumieli. Dlatego nie chcą się opamiętać i zostać przeze Mnie uzdrowieni”.
41 Nǹkan wọ̀nyí ni Isaiah wí, nítorí ó ti rí ògo rẹ̀, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀.
Tak właśnie powiedział Izajasz, bo ujrzał Bożą chwałę.
42 Síbẹ̀ ọ̀pọ̀ nínú àwọn olórí gbà á gbọ́ pẹ̀lú; ṣùgbọ́n nítorí àwọn Farisi wọn kò jẹ́wọ́ rẹ̀, kí a má ba à yọ wọ́n kúrò nínú Sinagọgu,
Mimo to wielu przywódców uwierzyło Jezusowi. Nie przyznawali się jednak do tego w obawie przed faryzeuszami, którzy mogli wyrzucić ich z synagogi.
43 nítorí wọ́n fẹ́ ìyìn ènìyàn ju ìyìn ti Ọlọ́run lọ.
Ludzkie uznanie cenili bowiem bardziej niż przychylność Boga.
44 Jesu sì kígbe ó sì wí pé, “Ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, èmi kọ́ ni ó gbàgbọ́ ṣùgbọ́n ẹni tí ó rán mi.
Dalej nauczając, Jezus zawołał do tłumów: —Kto wierzy Mi, wierzy również Temu, który Mnie posłał.
45 Ẹni tí ó bá sì rí mi, ó rí ẹni tí ó rán mi.
A kto Mnie widzi, widzi także Tego, który Mnie posłał.
46 Èmi ni ìmọ́lẹ̀ tí ó wá sí ayé, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ má ṣe wà nínú òkùnkùn.
Przyszedłem na świat jako światło, aby każdy, kto Mi wierzy, nie musiał tkwić w ciemności.
47 “Bí ẹnikẹ́ni bá sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí kò sì pa wọ́n mọ́, èmi kì yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ nítorí tí èmi kò wá láti ṣe ìdájọ́ ayé, bí kò ṣe láti gba ayé là.
Jeśli ktoś Mnie słucha, ale nie jest Mi posłuszny, nie będę go sądzić. Nie przyszedłem bowiem na świat po to, aby potępić ludzi, ale aby ich zbawić.
48 Ẹni tí ó bá kọ̀ mí, tí kò sì gba ọ̀rọ̀ mi, ó ní ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀; ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ, òun náà ni yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.
Kto odrzuca Mnie i moje słowa, będzie miał jednak innego sędziego: będą nim słowa, które wypowiedziałem. To one osądzą go w dniu ostatecznym.
49 Nítorí èmi kò dá ọ̀rọ̀ sọ fún ara mi, ṣùgbọ́n Baba tí ó rán mi, ni ó ti fún mi ní àṣẹ, ohun tí èmi ó sọ, àti èyí tí èmi ó wí.
Nie przemawiałem bowiem z własnej inicjatywy. Ten, który Mnie posłał, przekazał Mi, co i jak mam mówić.
50 Èmi sì mọ̀ pé ìyè àìnípẹ̀kun ni òfin rẹ̀, nítorí náà, àwọn ohun tí mo bá wí, gẹ́gẹ́ bí Baba ti sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni mo wí!” (aiōnios g166)
Przykazania mojego Ojca prowadzą do wiecznego życia, dlatego przekazuję wam, to, co Mi polecił. (aiōnios g166)

< John 12 >