< John 12 >

1 Nítorí náà, nígbà tí àjọ ìrékọjá ku ọjọ́ mẹ́fà, Jesu wá sí Betani, níbi tí Lasaru wà, ẹni tí ó ti kú, tí Jesu jí dìde kúrò nínú òkú.
А шест дни преди пасхата Исус дойде във Витания, гдето беше Лазар, когото Той възкреси от мъртвите.
2 Wọ́n sì ṣe àsè alẹ́ fún un níbẹ̀. Marta sì ń ṣe ìránṣẹ́, ṣùgbọ́n Lasaru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó jókòó níbi tábìlì rẹ̀.
Там му направиха вечеря, и Марта прислужваше; а Лазар беше един от тия, който седяха с Него на трапезата.
3 Nígbà náà ni Maria mú òróró ìkunra nadi, òsùwọ̀n lita kan, àìlábùlà, olówó iyebíye, ó sì ń fi kun Jesu ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nu ẹsẹ̀ rẹ̀ nù. Ilé sì kún fún òórùn ìkunra náà.
Тогава Мария, като взе един литър миро от чист и скъпоценен нард, помаза нозете на Исуса, и с косата си отри нозете Му; и къщата се изпълни с благоухание от мирото.
4 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Judasi Iskariotu, ọmọ Simoni ẹni tí yóò fi í hàn, wí pé,
Но един от учениците Му, Юда Искариотски, който щеше да Го предаде, рече:
5 “Èéṣe tí a kò ta òróró ìkunra yìí ní ọ̀ọ́dúnrún owó idẹ kí a sì fi fún àwọn tálákà?”
Защо не се продаде това миро за триста динара, за да се раздадат на сиромасите?
6 Ṣùgbọ́n ó wí èyí, kì í ṣe nítorí tí ó náání àwọn tálákà; ṣùgbọ́n nítorí tí ó jẹ́ olè, òun ni ó ni àpò, a sì máa jí ohun tí a fi sínú rẹ̀ láti fi ran ara rẹ lọ́wọ́.
А това рече не защото го беше грижа за сиромасите, а защото бе крадец, и като държеше касата FOOTNOTE ( Гръцки: Торбичката или, кутийката. ) вземаше от това, което пускаха в нея.
7 Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Ẹ fi í sílẹ̀, ó ṣe é sílẹ̀ de ọjọ́ ìsìnkú mi.
Тогава Исус рече: Оставете я; понеже го е запазила за деня на погребението Ми.
8 Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin sá à ní tálákà pẹ̀lú yín; ṣùgbọ́n èmi ni ẹ kò ní nígbà gbogbo.”
Защото сиромасите всякога се намират между вас но Аз не се намирам всякога.
9 Nítorí náà, ìjọ ènìyàn nínú àwọn Júù ni ó mọ̀ pé ó wà níbẹ̀; wọ́n sì wá, kì í ṣe nítorí Jesu nìkan, ṣùgbọ́n kí wọn lè rí Lasaru pẹ̀lú, ẹni tí ó ti jí dìde kúrò nínú òkú.
А голямо множество от юдеите узнаха, че е там; и дойдоха, не само поради Исуса, но за да видят и Лазара, когото възкресил от мъртвите.
10 Ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà gbìmọ̀ kí wọn lè pa Lasaru pẹ̀lú,
А главните свещеници се наговориха да убият и Лазара,
11 nítorí pé nípasẹ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù jáde lọ, wọ́n sì gbà Jesu gbọ́.
защото поради него мнозина от юдеите отиваха към страната на Исуса и вярваха в Него.
12 Ní ọjọ́ kejì nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó wá sí àjọ gbọ́ pé, Jesu ń bọ̀ wá sí Jerusalẹmu.
На следния ден едно голямо множество, което бе дошло на празника, като чуха, че Исус идел в Ерусалим,
13 Wọ́n mú imọ̀ ọ̀pẹ, wọ́n sì jáde lọ pàdé rẹ̀, wọ́n sì ń kígbe pé, “Hosana!” “Olùbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Olùbùkún ni ọba Israẹli!”
взеха палмови клони и излязоха да Го посрещнат, викайки: Осана! благословен, Който иде в Господното име, Израилевият Цар!
14 Nígbà tí Jesu sì rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, ó gùn ún; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ̀wé pé,
А Исус като намери едно осле, възседна го, според както е писано:
15 “Má bẹ̀rù, ọmọbìnrin Sioni; wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá, o jókòó lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.”
Защото ви дадох пример да правите и вие както Аз направих на вас.
16 Nǹkan wọ̀nyí kò tètè yé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí a ṣe Jesu lógo, nígbà náà ni wọ́n rántí pé, a kọ̀wé nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ sí i.
Учениците Му изпърво не разбраха това: а когато се прослави Исус, тогава си спомниха, че това бе писано за Него, и че Му сториха това.
17 Nítorí náà, ìjọ ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nígbà tí o pé Lasaru jáde nínú ibojì rẹ̀, tí ó sì jí i dìde kúrò nínú òkú, jẹ́rìí sí i.
Народът, прочее, който беше с Него, когато повика Лазара от гроба и го възкреси от мъртвите, свидетелствуваше за това чудо.
18 Nítorí èyí ni ìjọ ènìyàn sì ṣe lọ pàdé rẹ̀, nítorí tí wọ́n gbọ́ pé ó ti ṣe iṣẹ́ àmì yìí.
По същата причина Го посрещна и народът, защото чуха, че извършил това знамение.
19 Nítorí náà àwọn Farisi wí fún ara wọn pé, “Ẹ kíyèsi bí ẹ kò ti lè borí ní ohunkóhun? Ẹ wo bí gbogbo ayé ti ń wọ́ tọ̀ ọ́!”
Затуй фарисеите рекоха помежду си: Вижте, че нищо не постигате! Ето, светът отиде след Него.
20 Àwọn Giriki kan sì wà nínú àwọn tí ó gòkè wá láti sìn nígbà àjọ,
А между ония, които дойдоха на поклонение по празника, имаше и някои гърци.
21 Àwọn wọ̀nyí ni ó tọ Filipi wá, ẹni tí í ṣe ará Betisaida tí Galili, wọ́n sì ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Alàgbà, àwa ń fẹ́ rí Jesu!”
Те, прочее, дойдоха при Филипа, който беше от Витсаида галилейска, и го помолиха, казвайки: Господине искаме да видиме Исуса.
22 Filipi wá, ó sì sọ fún Anderu; Anderu àti Filipi wá, wọ́n sì sọ fún Jesu.
Филип дохожда и казва на Андрея; Андрей дохожда, и Филип, и те казват на Исуса.
23 Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Wákàtí náà dé, tí a ó ṣe Ọmọ Ènìyàn lógo.
А Исус в отговор им казва: Дойде часът да се прослави Човешкият Син.
24 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, bí kò ṣe pé alikama bá bọ́ sí ilẹ̀, tí ó bá sì kú, ó wà ní òun nìkan; ṣùgbọ́n bí ó bá kú, yóò sì so ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso.
Истина, истина ви казвам, ако житното зърно не падне в земята и не умре, то си остава самотно; но ако умре, дава много плод.
25 Ẹni tí ó bá fẹ́ ẹ̀mí rẹ̀ yóò sọ ọ́ nù; ẹni tí ó bá sì kórìíra ẹ̀mí rẹ̀ láyé yìí ni yóò sì pa á mọ́ títí ó fi di ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
Който обича живота си, ще го изгуби; и който мрази живота си на този свят, ще го запази за вечен живот. (aiōnios g166)
26 Bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, kí ó máa tọ̀ mí lẹ́yìn, àti pe níbi tí èmi bá wà, níbẹ̀ ni ìránṣẹ́ mi yóò wà pẹ̀lú, bí ẹnikẹ́ni bá ń sìn mí, òun ni Baba yóò bu ọlá fún.
Ако служи някой на Мене, Мене нека последва; и дето съм Аз, там ще бъде и служителят Ми. Който служи на Мене, него ще почете Отец Ми.
27 “Ní ìsinsin yìí ni a ń pọ́n ọkàn mi lójú; kín ni èmi ó sì wí? ‘Baba, gbà mí kúrò nínú wákàtí yìí’? Rárá, ṣùgbọ́n nítorí èyí ni mo ṣe wá sí wákàtí yìí.
Сега душата ми е развълнувана; и какво да кажа? Отче, избави Ме от тоя час. Но за това дойдох на тоя час.
28 Baba, ṣe orúkọ rẹ lógo!” Nígbà náà ni ohùn kan ti ọ̀run wá, wí pé, “Èmi ti ṣe é lógo!”
Отче, прослави името Си. Тогава дойде глас от небето: И Го прославих, и пак ще Го прославя.
29 Nítorí náà ìjọ ènìyàn tí ó dúró níbẹ̀, tí wọ́n sì gbọ́ ọ, wí pé, “Àrá ń sán.” Àwọn ẹlòmíràn wí pé, “Angẹli kan ni ó ń bá a sọ̀rọ̀.”
На това, народът, който стоеше там, като чу гласа каза: Гръм е. Други пък казаха: Ангел Му проговори.
30 Jesu sì dáhùn wí pé, “Kì í ṣe nítorí mi ni ohùn yìí ṣe wá, bí kò ṣe nítorí yín.
Исус в отговор рече: Този глас не дойде заради Мене, но заради вас.
31 Ní ìsinsin yìí ni ìdájọ́ ayé yìí dé: nísinsin yìí ni a ó lé aládé ayé yìí jáde.
Сега е съдба на този свят; сега князът на този свят ще бъде изхвърлен вън.
32 Àti èmi, bí a bá gbé mi sókè kúrò ní ayé, èmi ó fa gbogbo ènìyàn sọ́dọ̀ ara mi!”
И когато бъда Аз издигнат от земята, ще привлека всички при Себе Си.
33 Ṣùgbọ́n ó wí èyí, ó ń ṣe àpẹẹrẹ irú ikú tí òun yóò kú.
А като казваше това, Той означаваше от каква смърт щеше да умре.
34 Nítorí náà àwọn ìjọ ènìyàn dá a lóhùn pé, “Àwa gbọ́ nínú òfin pé, Kristi wà títí láéláé, ìwọ ha ṣe wí pé, ‘A ó gbé Ọmọ Ènìyàn sókè’? Ta ni ó ń jẹ́ ‘Ọmọ Ènìyàn yìí’?” (aiōn g165)
Народът, прочее, Му отговори: Ние сме чули от закона, че Христос пребъдва до века: тогава как казваш Ти, че Човешкият Син трябва да бъде издигнат? Кой е Тоя Човешки Син? (aiōn g165)
35 Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Nígbà díẹ̀ sí i ni ìmọ́lẹ̀ wà láàrín yín, ẹ máa rìn nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, kí òkùnkùn má ṣe bá yín, ẹni tí ó bá sì ń rìn ní òkùnkùn kò mọ ibi òun ń lọ.
Тогава Исус им рече: Още малко време светлината е между вас. Ходете докле имате светлината, за да ви не настигне тъмнината. Който ходи в тъмнината не знае къде отива.
36 Nígbà tí ẹ̀yin ní ìmọ́lẹ̀, ẹ gba ìmọ́lẹ̀ gbọ́, kí ẹ lè jẹ́ ọmọ ìmọ́lẹ̀!” Nǹkan wọ̀nyí ni Jesu sọ, ó sì jáde lọ, ó fi ara pamọ́ fún wọn.
Докле имате светлината, вярвайте в светлината, за да станете просветени чрез FOOTNOTE ( Гръцки: Синове на. ) светлината. Това изговори Исус, и отиде та се скри от тях.
37 Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì tó báyìí lójú wọn, wọn kò gbà á gbọ́.
Но ако и да бе извършил толкова знамения пред тях, те пак не вярваха в Него;
38 Kí ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah lè ṣẹ, èyí tí ó sọ pé, “Olúwa, ta ni ó gba ìwàásù wa gbọ́ Àti ta ni a sì fi apá Olúwa hàn fún?”
за да се изпълни казаното от пророка Исаия, който рече: "Господи, кой от нас е повярвал на онова, което сме чули? И мишцата Господня на кого се е открила"?
39 Nítorí èyí ni wọn kò fi lè gbàgbọ́, nítorí Isaiah sì tún sọ pé,
Те за това не можаха да вярват, защото Исаия пак е рекъл:
40 “Ó ti fọ́ wọn lójú, Ó sì ti sé àyà wọn le; kí wọn má ba à fi ojú wọn rí, kí wọn má ba à fi ọkàn wọn mọ̀, kí wọn má ba à yípadà, kí èmi má ba à mú wọn láradá.”
Ослепил е очите им, и закоравил сърцата им, Да не би с очи да видят, и със сърца да разберат, За да се обърнат и да ги изцеля.
41 Nǹkan wọ̀nyí ni Isaiah wí, nítorí ó ti rí ògo rẹ̀, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀.
Това каза Исаия защото видя славата Му и говори за Него.
42 Síbẹ̀ ọ̀pọ̀ nínú àwọn olórí gbà á gbọ́ pẹ̀lú; ṣùgbọ́n nítorí àwọn Farisi wọn kò jẹ́wọ́ rẹ̀, kí a má ba à yọ wọ́n kúrò nínú Sinagọgu,
Но пак мнозина от първенците повярваха в Него; но поради фарисеите не Го изповядаха, за да не бъдат отлъчени от синагогата;
43 nítorí wọ́n fẹ́ ìyìn ènìyàn ju ìyìn ti Ọlọ́run lọ.
защото обикнаха похвалата от човеците повече от похвалата от Бога.
44 Jesu sì kígbe ó sì wí pé, “Ẹni tí ó bá gbà mí gbọ́, èmi kọ́ ni ó gbàgbọ́ ṣùgbọ́n ẹni tí ó rán mi.
А Исус извика и рече: Който вярва в Мене, не в Мене вярва, но в Този, Който Ме е пратил.
45 Ẹni tí ó bá sì rí mi, ó rí ẹni tí ó rán mi.
И който гледа Мене, гледа Онзи, Който Ме е пратил.
46 Èmi ni ìmọ́lẹ̀ tí ó wá sí ayé, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ má ṣe wà nínú òkùnkùn.
Аз дойдох като светлина на света, за да не остане в тъмнина никой, който вярва Мене.
47 “Bí ẹnikẹ́ni bá sì gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí kò sì pa wọ́n mọ́, èmi kì yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ nítorí tí èmi kò wá láti ṣe ìdájọ́ ayé, bí kò ṣe láti gba ayé là.
И ако чуе някой думите Ми и не ги пази, Аз не го съдя; защото не дойдох да съдя света, но да спася света.
48 Ẹni tí ó bá kọ̀ mí, tí kò sì gba ọ̀rọ̀ mi, ó ní ẹnìkan tí ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀; ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ, òun náà ni yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.
Който Ме отхвърля, и не приема думите Ми, има кой да го съди; словото, което говорих, то ще го съди в последния ден.
49 Nítorí èmi kò dá ọ̀rọ̀ sọ fún ara mi, ṣùgbọ́n Baba tí ó rán mi, ni ó ti fún mi ní àṣẹ, ohun tí èmi ó sọ, àti èyí tí èmi ó wí.
Защото Аз от Себе Си не говорих; но Отец, Който Ме прати, Той Ми даде заповед, какво да кажа и що да говоря.
50 Èmi sì mọ̀ pé ìyè àìnípẹ̀kun ni òfin rẹ̀, nítorí náà, àwọn ohun tí mo bá wí, gẹ́gẹ́ bí Baba ti sọ fún mi, bẹ́ẹ̀ ni mo wí!” (aiōnios g166)
И зная, че онова, което Той заповядва, е вечен живот. И тъй, това, което говоря, говоря го така, както Ми е казал Отец. (aiōnios g166)

< John 12 >