< John 10 >
1 “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí kò bá gba ẹnu-ọ̀nà wọ inú agbo àgùntàn, ṣùgbọ́n tí ó bá gba ibòmíràn gun òkè, òun náà ni olè àti ọlọ́ṣà.
“Nangmih taengah rhep rhep kan thui, thohka lamloh tu vongup khuila kun pawt tih a hloeh la aka yoeng tah hlanghuen neh dingca ni.
2 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ti ẹnu-ọ̀nà wọlé, Òun ni olùṣọ́ àwọn àgùntàn.
Tedae tu kah tudawn la aka om tah thohka longah kun.
3 Òun ni aṣọ́nà yóò ṣílẹ̀kùn fún; àwọn àgùntàn gbọ́ ohùn rẹ̀, ó sì pe àwọn àgùntàn tirẹ̀ lórúkọ, ó sì ṣe amọ̀nà wọn jáde.
Anih te imtawt loh thohka a ong pah tih tu loh a ol te a yaak. Amah kah tu te khaw a ming neh a khue tih a mawt.
4 Nígbà tí ó bá sì ti mú àwọn àgùntàn tirẹ̀ jáde, yóò síwájú wọn, àwọn àgùntàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, nítorí tí wọ́n mọ ohùn rẹ̀.
Amah kah te boeih a hlah vaengah a hmaiah cet tih tu rhoek loh a ol te a hmat uh dongah anih te a vai uh.
5 Wọn kò jẹ́ tọ àlejò lẹ́yìn, ṣùgbọ́n wọn a sá kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí tí wọn kò mọ ohùn àlejò.”
Tedae hlanglang tah vai uh loengloeng pawt vetih hlanglang kah ol te a hmat uh pawt dongah anih taeng lamloh rhaelrham uh ni,” a ti nah.
6 Òwe yìí ni Jesu pa fún wọn, ṣùgbọ́n òye ohun tí nǹkan wọ̀nyí tí ó ń sọ fún wọn kò yé wọn.
Hekah thuidoeknah he amih taengah Jesuh loh a thui dae amih taengah a thui te metla a om khaw tekah rhoek loh ming uh pawh.
7 Nítorí náà Jesu tún wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, Èmi ni ìlẹ̀kùn àwọn àgùntàn.
Te donagah Jesuh loh, “Nangmih taengah rhep rhep kan thui, Kai tah tu thohka la ka om.
8 Olè àti ọlọ́ṣà ni gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú mi, ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn kò gbọ́ tiwọn.
Kai hmaikah aka pawk boeih tah hlanghuen neh dingca rhoek ni. Tedae tu loh amih ol te a hnatun moenih.
9 Èmi ni ìlẹ̀kùn, bí ẹnìkan bá bá ọ̀dọ̀ mi wọlé, òun ni a ó gbàlà, yóò wọlé, yóò sì jáde, yóò sì rí koríko.
Kai tah thohka la ka om, u khaw kai lamloh a kun atah daem vetih a voei a bal ah rhamtlim a hmuh ni.
10 Olè kì í wá bí kò ṣe láti jalè, láti pa, àti láti parun; èmi wá kí wọn lè ní ìyè, àní kí wọn lè ní i lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Hlanghuen tah huen ham, ngawn ham neh poci sak ham pawt atah ha pawk moenih. Kai tah hingnah a khueh uh phoeiah a puehsoi dang sak ham ka pawk.
11 “Èmi ni olùṣọ́-àgùntàn rere, olùṣọ́-àgùntàn rere fi ọkàn rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn àgùntàn.
Kai tah tudawn then la ka om. Tudawn then loh a hinglu te tu rhoek ham a hmoel.
12 Ṣùgbọ́n alágbàṣe, tí kì í ṣe olùṣọ́-àgùntàn, ẹni tí àwọn àgùntàn kì í ṣe tirẹ̀, ó rí ìkookò ń bọ̀, ó sì fi àgùntàn sílẹ̀, ó sì fọ́n wọn ká kiri.
Kutloh tah tudawn lam khaw om pawh. A tu khaw amah kah om pawh. Uithang ha pawk te a hmuh vaengah tu a hno tih a rhaelrham tak dongah uithang loh a poelyoe tih a thaek.
13 Òun sálọ nítorí tí ó jẹ́ alágbàṣe, kò sì náání àwọn àgùntàn.
Kutloh la a om dongah tu ham anih a ngaihuet pawh.
14 “Èmi ni olùṣọ́-àgùntàn rere, mo sì mọ àwọn tèmi, àwọn tèmi sì mọ̀ mí.
Kai tah tudawn then la ka om dongah kamah kah rhoek te ka ming tih kamah kah rhoek loh kai m'ming uh.
15 Gẹ́gẹ́ bí Baba ti mọ̀ mí, tí èmi sì mọ Baba, mo sì fi ọkàn mi lélẹ̀ nítorí àwọn àgùntàn.
Pa loh kai m'ming tih kai loh pa te ka ming vanbangla ka hinglu te khaw tu rhoek ham ka hmoel.
16 Èmi sì ní àwọn àgùntàn mìíràn, tí kì í ṣe agbo yìí: àwọn ni èmi yóò mú wá pẹ̀lú, wọn yóò sì gbọ́ ohùn mi; wọn ó sì jẹ́ agbo kan, olùṣọ́-àgùntàn kan.
Tedae hekah vongup ah aka om mueh tu a tloe rhoek te ka khueh pueng. Amih khaw ka khue ham a kuek. Te vaengah kai ol te a yaak uh vetih tuping pakhat, tudawn pakhat la om uh ni.
17 Nítorí náà ni Baba mi ṣe fẹ́ràn mi, nítorí tí mo fi ẹ̀mí mi lélẹ̀, kí èmi lè tún gbà á.
Kai loh ka hinglu te koep dang ham ka voeih dongah pa loh kai n'lungnah.
18 Ẹnìkan kò gbà á lọ́wọ́ mi, ṣùgbọ́n mo fi í lélẹ̀, mo sì lágbára láti tún gbà á. Àṣẹ yìí ni mo ti gbà wá láti ọ̀dọ̀ Baba mi.”
Kai lamkah hingnah te a rhawt uh thai moenih. Tedae te te kai kamah lamkah ni ka voeih. Te te voeih ham saithainah ka khueh tih koep lat ham khaw saithainah ka khueh. Hekah olpaek he a pa taeng lamkah ka dang,” koep a ti nah.
19 Nítorí náà ìyapa tún wà láàrín àwọn Júù nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Hekah olka kongah Judah rhoek khuiah paekboenah koep om.
20 Ọ̀pọ̀ nínú wọn sì wí pé, “Ó ní ẹ̀mí èṣù, orí rẹ̀ sì dàrú; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń gbọ́rọ̀ rẹ̀?”
Te dongah amih khuikah a kumngai loh, “Rhaithae a kaem tih ang coeng, balae tih anih ol na hnatun uh?” a ti uh.
21 Àwọn mìíràn wí pé, “Ìwọ̀nyí kì í ṣe ọ̀rọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù. Ẹ̀mí èṣù lè la ojú àwọn afọ́jú bí?”
A tloe rhoek loh, “He tah rhaithae aka kaem kah olka la om mahpawh. Rhaithae loh mikdael kah mik tueng sak thai pawt maco?” a ti uh.
22 Àkókò náà sì jẹ́ àjọ̀dún ìyàsímímọ́ ní Jerusalẹmu, ni ìgbà òtútù.
Te vaengah sikca la om tih Jerusalem ah imciim khotue te om.
23 Jesu sì ń rìn ní tẹmpili, ní ìloro Solomoni.
Te vaengah Jesuh tah Bawkim kah Solomon impup ah pongpa.
24 Nítorí náà àwọn Júù wá dúró yí i ká, wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ó ti mú wa ṣe iyèméjì pẹ́ tó? Bí ìwọ bá ni Kristi náà, wí fún wa gbangba.”
Te vaengah Judah rhoek loh amah te a vael uh tih, “Mevaeng duela kaimih kah hinglu te na ngaihlih sak eh? Khrih la na om atah kaimih taengah sayalh la thui lah,” a ti nauh.
25 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Èmi ti wí fún yín, ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́; iṣẹ́ tí èmi ń ṣe lórúkọ Baba mi, àwọn ni ó ń jẹ́rìí mi.
Jesuh loh amih te, “Nangmih taengah ka thui dae na tangnah uh pawh. A pa ming neh ka bibi saii long te kai kawng a phong.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbàgbọ́, nítorí ẹ̀yin kò sí nínú àwọn àgùntàn mi, gẹ́gẹ́ bí mo tí wí fún yín.
Tedae kai kah tu khuiah na om uh pawt dongah na tangnah uh pawh.
27 Àwọn àgùntàn mi ń gbọ́ ohùn mi, èmi sì mọ̀ wọ́n, wọn a sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
Ka tu rhoek tah ka ol te a yaak uh tih kai long khaw amih te ka ming dongah kai m'vai uh.
28 Èmi sì fún wọn ní ìyè àìnípẹ̀kun; wọn kì yóò sì ṣègbé láéláé, kò sí ẹni tí ó lè já wọn gbà kúrò lọ́wọ́ mi. (aiōn , aiōnios )
Kai loh amih taengah dungyan hingnah ka paek tih kumhal duela poci uh loengloeng mahpawh. Te dongah amih te khat khat long khaw kai kut lamloh poelyoe mahpawh. (aiōn , aiōnios )
29 Baba mi, ẹni tí ó fi wọ́n fún mi pọ̀ ju gbogbo wọn lọ; kò sì ṣí ẹni tí ó lè já wọn gbà kúrò lọ́wọ́ Baba mi.
A pa loh kai m'paek coeng te tah tanglue la boeih om tih pa kut lamkah te a poelyoe thai moenih.
30 Ọ̀kan ni èmi àti Baba mi.”
Kai neh pa tah pakhat ni,” a ti nah.
31 Àwọn Júù sì tún mú òkúta, láti sọ lù ú.
Judah rhoek loh amah te dae ham lungto koep a muk uh.
32 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ rere ni mo fihàn yín láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá, nítorí èwo nínú iṣẹ́ wọ̀nyí ni ẹ̀yin ṣe sọ mí ní òkúta?”
Jesuh loh amih te, “Pa lamkah khoboe then te nangmih muep kan tueng coeng. Te khuiah mebang khoboe nen nim kai nan dae uh eh,” a ti nah.
33 Àwọn Júù sì dá a lóhùn pé, “Àwa kò sọ ọ́ lókùúta nítorí iṣẹ́ rere, ṣùgbọ́n nítorí ọ̀rọ̀-òdì, àti nítorí ìwọ tí í ṣe ènìyàn ń fi ara rẹ pe Ọlọ́run.”
Judah rhoek loh amah te, “Khoboe then dongah pawt tih soehsalnah neh nang hlang la aka om loh Pathen la namah te na sa uh dongah nang te kan dae uh,” a ti nauh.
34 Jesu dá wọn lóhùn pé, “A kò ha tí kọ ọ́ nínú òfin yín pé, ‘Mo ti wí pé, Ọlọ́run ni ẹ̀yin jẹ́’?
Amih te Jesuh loh, “Nangmih taengah ka thui dae na tangnah uh pawh. A pa ming neh ka bibi saii long te kai kawng a phong.
35 Bí ó bá pè wọ́n ní ‘ọlọ́run,’ àwọn ẹni tí a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún, a kò sì lè ba ìwé mímọ́ jẹ́.
Pathen kah olka aka dang te Pathen rhoek la a khue atah cacim te a phae thai moenih.
36 Kín ni ẹyin ha ń wí ní ti ẹni tí Baba yà sọ́tọ̀, tí ó sì rán sí ayé kín lo de ti ẹ fi ẹ̀sùn kàn mi pé mò ń sọ̀rọ̀-òdì nítorí pé mo sọ pé, ‘Èmi ni Ọmọ Ọlọ́run.’
Pa loh a cil tih diklai la a tueih loh, ' Kai Pathen capa ni,' ka ti dongah a salpham tila na thui uh a?
37 Bí èmi kò bá ṣe iṣẹ́ Baba mi, ẹ má ṣe gbà mí gbọ́.
A pa kah bibi te ka saii pawt atah kai n'tangnah uh boeh.
38 Ṣùgbọ́n bí èmi bá ṣe wọ́n, bí ẹ̀yin kò tilẹ̀ gbà mí gbọ́, ẹ gbà iṣẹ́ náà gbọ́, kí ẹ̀yin ba à lè mọ̀, kí ó sì lè yé yín pé, Baba wà nínú mi, èmi sì wà nínú rẹ̀.”
Tedae ka saii atah kai nan tangnah uh pawt cakhaw kai ah a pa om tih kai khaw a pa dongah ka om tila na ming uh tih phat om ham bibi te tangnah uh,” a,” a ti nah.
39 Wọ́n sì tún ń wá ọ̀nà láti mú un: ó sì bọ́ lọ́wọ́ wọn.
Te dongah amah te tuuk ham koep a mae uh dae amih kut lamkah loh vik cet.
40 Ó sì tún kọjá lọ sí apá kejì Jordani sí ibi tí Johanu ti kọ́kọ́ ń bamitiisi; níbẹ̀ ni ó sì jókòó.
Te phoeiah Jordan rhalvangan la koep cet tih pahoi naeh. Te hmuen ah te Johan om lamhma tih a nuem.
41 Àwọn ènìyàn púpọ̀ sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Johanu kò ṣe iṣẹ́ àmì kan, Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni ohun gbogbo tí Johanu sọ nípa ti ọkùnrin yìí.”
Te vaengah a taengla muep a paan uh tih, “Johan loh miknoek saii ngawn pawt dae Johan loh anih kawng a thui boeih te thuem,” a ti uh.
42 Àwọn ènìyàn púpọ̀ níbẹ̀ sì gbà á gbọ́.
Te dongah tekah rhoek loh amah te muep a tangnah uh.