< John 1 >

1 Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
Au commencement était la Parole; la Parole était avec Dieu, et la Parole était dieu.
2 Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
Elle était au commencement avec Dieu.
3 Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
Toutes choses ont été faites par elle, et rien de ce qui a été fait, n'a été fait sans elle.
4 Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
En elle était la vie, et cette vie était la lumière des hommes:
5 ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
la lumière brille dans les ténèbres, mais les ténèbres ne l'ont point reçue.
6 Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
Un homme parut; il était envoyé de Dieu, son nom était Jean.
7 Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
Il vint pour un témoignage, pour rendre témoignage à la Lumière, afin que tous crussent par lui:
8 Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
il n'était pas la Lumière, mais il devait rendre témoignage à la Lumière.
9 Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
La véritable Lumière, qui éclaire tout homme, était entrée dans le monde;
10 Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
elle était dans le monde, et le monde a été fait par elle, mais le monde ne l'a point connue.
11 Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
Elle est venue chez les siens, et les siens ne l'ont point reçue;
12 Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
mais à tous ceux qui l'ont reçue, à tous ceux qui croient en son nom, elle a donné la prérogative d'être enfants de Dieu:
13 Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
enfants, qui ne sont pas nés du sang, ni de la volonté de la chair, ni de la volonté de l'homme, mais qui sont nés de Dieu.
14 Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
Et la Parole a été faite chair; elle a habité au milieu de nous pleine de grâce et de vérité, et nous avons contemplé sa gloire, une gloire comme celle d'un fils unique envoyé par son père.
15 Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
Jean lui rend témoignage, quand il dit à haute voix: «Voici celui dont je disais: Celui qui vient après moi. a pris le pas devant moi, parce qu'il est plus grand que moi.»
16 Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
C'est de sa plénitude que nous avons tous reçu grâce sur grâce;
17 Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
car la Loi a été donnée par Moïse; mais la Grâce et la Vérité sont venues par Jésus-Christ.
18 Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
Personne n'a jamais vu Dieu; le Fils unique, qui est dans le sein du Père, est celui qui l'a révélé.
19 Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
Voici le témoignage que rendit Jean, lorsque les Juifs envoyèrent de Jérusalem des sacrificateurs et des lévites pour lui adresser cette question: «Qui es-tu?»
20 Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
Il le déclara, et ne le nia point; il déclara qu'il n'était pas le Messie.
21 Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
— «Quoi donc! Es-tu Élie?» lui demandèrent-ils; et il dit: «Je ne le suis point.» - «Es-tu le Prophète?» et il répondit: «Non.»
22 Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
Ils lui dirent donc: «Qui es-tu? afin que nous rendions réponse à ceux qui nous ont envoyés. Que dis-tu que tu es?»
23 Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
— «Moi, dit-il, je suis «une voix qui crie au désert: Redressez le chemin du Seigneur, » comme a dit le prophète Ésaïe.
24 Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
Ceux qu'on avait envoyés étaient des pharisiens.
25 bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
Ils insistèrent, et lui dirent: «Pourquoi donc baptises-tu, si tu n'es pas le Messie, ni même Elie ou le Prophète?»
26 Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
Jean leur répondit: «Pour moi, je baptise d'eau, mais il y a au milieu de vous quelqu'un que vous ne connaissez pas:
27 Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
c'est celui qui vient après moi; je ne suis pas digne de délier la courroie de ses sandales.»
28 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
Ces choses se passèrent à Béthanie, au delà du Jourdain, où Jean baptisait.
29 Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
Le lendemain, Jean vit Jésus qui venait vers lui, et il dit: «Voici l'agneau de Dieu qui ôte le péché du monde.»
30 Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
C'est de lui que j'ai dit: Il vient après moi un homme qui a pris le pas devant moi, parce qu'il est plus grand que moi.
31 Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
Je ne le connaissais pas; mais je suis venu baptiser d'eau, afin qu'il fût manifesté à Israël»
32 Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
et Jean avait rendu ce témoignage: «J'ai vu l'Esprit descendre du ciel comme une colombe, et demeurer sur lui.»
33 Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
Je ne le connaissais pas; mais celui-là même qui m'a envoyé baptiser d'eau m'a dit: «Celui sur qui tu verras l'Esprit descendre et demeurer, c'est lui qui baptise d'esprit saint.»
34 Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
Je l'ai vu, et j'ai rendu témoignage que c'est lui qui est le Fils de Dieu.»
35 Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Le lendemain, Jean se trouvait là de nouveau, avec deux de ses disciples;
36 Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
et, ayant considéré Jésus qui passait, il dit: «Voilà l'agneau de Dieu.»
37 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
Ces deux disciples l'ayant entendu parler de la sorte, suivirent Jésus.
38 Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
Jésus s'étant retourné, et voyant qu'ils le suivaient, leur dit. «Que cherchez- vous?» Ils lui dirent: «Rabbi, »(ce qui signifie Maître) «où demeures-tu?»
39 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
— «Venez, leur dit-il, et vous verrez. Ils allèrent, et ils virent où il demeurait, et ils restèrent auprès de lui ce jour-là. C'était environ la dixième heure du jour.
40 Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
André, frère de Simon-Pierre, était l'un des deux disciples qui avaient entendu la parole de Jean, et qui avaient suivi Jésus.
41 Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
Il rencontra, le premier, son frère Simon, et il lui dit: «Nous avons trouvé le Messie» (ce qui signifie Christ);
42 Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
et il le mena vers Jésus. Celui-ci, l'ayant considéré, lui dit: «Tu es Simon, fils de Jona; on t'appellera Céphas» (ce qui signifie Pierre).
43 Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
Le lendemain, Jésus résolut de partir pour la Galilée. Il rencontra Philippe, et lui dit: «Suis-moi.»
44 Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
Philippe était de la ville de Bethsaïde, d'où étaient aussi André et Pierre.
45 Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
Philippe rencontra Nathanaël, et lui dit: «Nous avons trouvé celui dont Moïse a parlé dans la Loi, et que les prophètes ont annoncé; c'est Jésus, fils de Joseph, de Nazareth.»
46 Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
Nathanaël lui dit: «Peut-il sortir de Nazareth quelque chose de bon?» Philippe lui répondit: «Viens et vois.»
47 Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
Jésus voyant venir Nathanaël, dit en parlant de lui: «Voici un vrai Israélite, un homme sans détour.»
48 Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
— «D'où me connais-tu?» lui dit Nathanaël. Jésus lui répondit: «Avant que Philippe t'appelât, je t'ai vu sous le figuier.»
49 Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
— «Maître, lui repartit Nathanaël, tu es le Fils de Dieu, tu es le roi d'Israël.»
50 Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
Jésus répondit et lui dit: «Parce que je t'ai dit que je t'ai vu sous le figuier, tu crois! Tu verras de plus grandes choses que celles-là.»
51 Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”
Et il ajouta: «En vérité, en vérité, je vous le dis, vous verrez désormais le ciel ouvert, et les anges de Dieu monter et descendre sur le Fils de l'homme.

< John 1 >