< John 1 >
1 Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
ⲁ̅ϦⲈⲚ ⲦⲀⲢⲬⲎ ⲚⲈⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲀϤⲬⲎ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲚⲞⲨϮ ⲠⲈ ⲠⲒⲤⲀϪⲒ.
2 Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
ⲃ̅ⲪⲀⲒ ⲈⲚⲀϤⲬⲎ ⲒⲤϪⲈⲚ ϨⲎ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ.
3 Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
ⲅ̅ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲀⲨϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲦϬⲚⲞⲨϤ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲪⲎ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ
4 Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
ⲇ̅ⲚⲈ ⲠⲰⲚϦ ⲠⲈⲦⲈⲚϦⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲰⲚϦ ⲚⲈⲪⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲠⲈ.
5 ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲬⲀⲔⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈ ⲠⲒⲬⲀⲔⲒ ⲦⲀϨⲞϤ.
6 Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
ⲋ̅ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈⲀⲨⲞⲨⲞⲢⲠϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲠⲈ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ.
7 Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
ⲍ̅ⲪⲀⲒ ⲀϤⲒ ⲈⲨⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀ ⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲀϨϮ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ.
8 Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
ⲏ̅ⲚⲈ ⲚⲐⲞϤ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲀⲖⲖⲀ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀ ⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ.
9 Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
ⲑ̅ⲚⲀϤϢⲞⲠ ⲚϪⲈⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲚⲦⲀⲪⲘⲎⲒ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲢⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲈⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ⲈⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ.
10 Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
ⲓ̅ⲚⲀϤⲬⲎ ϦⲈⲚⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈ ⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲤⲞⲨⲰⲚϤ.
11 Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
ⲓ̅ⲁ̅ⲀϤⲒ ϨⲀ ⲚⲎ ⲈⲦⲈⲚⲞⲨϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲦⲈⲚⲞⲨϤ ⲘⲠⲞⲨϢⲞⲠϤ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
12 Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲃ̅ⲚⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨϢⲞⲠϤ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲀϤϮⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲈⲢϢⲎⲢⲒ ⲚⲚⲞⲨϮ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲚ.
13 Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲅ̅ⲚⲎ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲤⲚⲞϤ ⲀⲚ ⲚⲈⲞⲨⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲞⲨⲰϢ ⲚⲤⲀⲢⲜ ⲀⲚ ⲚⲈⲞⲨⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲞⲨⲰϢ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲀⲚ ⲚⲈⲀⲖⲖⲀ ⲈⲦⲀⲨⲘⲀⲤⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲚⲞⲨϮ.
14 Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲤⲀⲢⲜ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦⲈⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲚⲀⲨ ⲈⲠⲈϤⲰⲞⲨ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲘⲠⲰⲞⲨ ⲚⲞⲨϢⲎⲢⲒ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲈϤⲒⲰⲦ ⲈϤⲘⲈϨ ⲚϨⲘⲞⲦ ⲚⲈⲘ ⲘⲈⲐⲘⲎⲒ.
15 Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
ⲓ̅ⲉ̅ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ϤⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲪⲎ ⲈⲦⲀⲒϪⲞϤ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲰⲒ ⲀϤⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲈⲢⲞⲒ ϪⲈ ⲚⲈⲞⲨϢⲞⲢⲠ ⲈⲢⲞⲒ ⲢⲰ ⲠⲈ
16 Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
ⲓ̅ⲋ̅ϪⲈ ⲀⲚⲞⲚ ⲦⲎⲢⲈⲚ ⲀⲚϬⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲈϤⲘⲞϨ ⲚⲈⲘ ⲞⲨϨⲘⲞⲦ ⲚⲦϢⲈⲂⲒⲰ ⲚⲞⲨϨⲘⲞⲦ.
17 Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
ⲓ̅ⲍ̅ϪⲈ ⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲀⲨⲦⲎⲒϤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲆⲈ ⲚⲈⲘ ϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲀⲨϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
18 Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
ⲓ̅ⲏ̅ⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲚⲈϨ ⲠⲒⲘⲞⲚⲞⲄⲈⲚⲎ ⲤⲚⲚⲞⲨϮ ⲪⲎ ⲈⲦⲬⲎ ϦⲈⲚⲔⲈⲚϤ ⲘⲠⲈϤⲒⲰⲦ ⲚⲐⲞϤ ⲠⲈⲦⲀϤⲤⲀϪⲒ.
19 Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
ⲓ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲐⲀⲒ ⲦⲈ ϮⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲦⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ϨⲞⲦⲈ ⲈⲦⲀⲨⲞⲨⲰⲢⲠ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲚϨⲀⲚⲞⲨⲎⲂ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲖⲈⲨⲒⲦⲎⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨϢⲈⲚϤ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ.
20 Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲰⲚϨ ⲘⲠⲈϤϪⲰⲖ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲰⲚϨ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
21 Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲈⲚϤ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲎⲖⲒⲀⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ.
22 Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
ⲕ̅ⲃ̅ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ⲞⲨⲚ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲚϪⲈⲘⲠϢⲒⲚⲒ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲦⲀⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈⲔϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲐⲂⲎⲦⲔ.
23 Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
ⲕ̅ⲅ̅ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ϮⲤⲘⲎ ⲈⲦⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒ ⲠϢⲀϤⲈ ϪⲈ ⲤⲞⲨⲦⲈⲚ ⲠⲒⲘⲰⲒⲦ ⲚⲦⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀϤϪⲞⲤ ⲚϪⲈⲎⲤⲀⲒⲀⲤ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎ ⲦⲎⲤ.
24 Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
ⲕ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲀⲨⲞⲨⲰⲢⲠ ⲠⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ
25 bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
ⲕ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲈⲚϤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲔϮⲰⲘⲤ ⲒⲤϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲞⲨⲆⲈ ⲎⲖⲒⲀⲤ ⲞⲨⲆⲈ ⲠⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ.
26 Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
ⲕ̅ⲋ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲰⲘⲤ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲰⲞⲨ ϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ϦⲈⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲘⲎϮ ⲚϪⲈⲪⲎ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲀⲚ
27 Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
ⲕ̅ⲍ̅ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲰⲒ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲚϮⲘⲠϢⲀ ⲀⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲀϮⲞⲨⲰ ⲚⲞⲨⲘⲞⲨⲤⲈⲢ ⲚⲦⲈⲠⲈϤⲐⲰⲞⲨⲒ.
28 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
ⲕ̅ⲏ̅ⲚⲀⲒ ⲀⲨϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲂⲎⲐⲀⲚⲒⲀ ϨⲒⲘⲎⲢ ⲘⲠⲒⲒⲞⲢⲆⲀⲚⲎⲤ ⲠⲒⲘⲀ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ϮⲰⲘⲤ ⲘⲘⲞϤ.
29 Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
ⲕ̅ⲑ̅ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤⲚⲎⲞⲨ ϨⲀⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲒⲤ ⲠⲒϨⲒⲎⲂ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀⲰⲖⲒ ⲘⲪⲚⲞⲂⲒ ⲘⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ.
30 Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
ⲗ̅ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲀⲒϪⲞⲤ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲐⲂⲎⲦⲔ ϪⲈ ϤⲚⲎⲞⲨ ⲘⲈⲚⲈⲚⲤⲰⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈⲀϤⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲈⲢⲞⲒ ϪⲈ ⲞⲨϢⲞⲢⲠ ⲈⲢⲞⲒ ⲢⲰ ⲠⲈ.
31 Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
ⲗ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲔ ⲚⲀⲒⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲞⲨⲰⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲠⲒⲤⲖ ⲈⲐⲂⲈ ⲪⲀⲒ ⲀⲒⲒ ⲈϮⲰⲘⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲰⲞⲨ.
32 Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
ⲗ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚϪⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲒⲚⲀⲨ ⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲚⲎⲞⲨ ⲈϦⲢⲎ ⲒⲈϪⲰϤ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲞⲨϬⲢⲞⲘⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ ⲀϤⲞϨⲒ ϨⲒϪⲰϤ.
33 Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
ⲗ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲔ ⲚⲀⲒⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲈϮⲰⲘⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲰⲞⲨ ⲚⲐⲞϤ ⲠⲈⲦⲀϤϪⲞⲤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲔⲚⲀⲨ ⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲚⲎⲞⲨ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤⲞϨⲒ ϨⲒϪⲰϤ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲪⲎ ⲈⲐⲚⲀϮⲰⲘⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈϤⲞⲨⲀⲂ
34 Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
ⲗ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲒⲚⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲒⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϪⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
35 Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
ⲗ̅ⲉ̅ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲞⲚ ⲚⲀⲢⲈ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲚⲈⲘ ⲂⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ
36 Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
ⲗ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤϪⲞⲨϢⲦ ⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈϤⲘⲞϢⲒ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲒⲤ ⲠⲒϨⲎⲒⲂ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
37 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
ⲗ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲞϤ ⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲚϪⲈⲠⲒⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲂⲚⲦⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲀⲒⲎⲤⲞⲨⲤ.
38 Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
ⲗ̅ⲏ̅ⲈⲦⲀϤⲪⲞⲚϨϤ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲀⲞⲨ ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲢⲀⲂⲂⲒ ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ϢⲀⲨⲞⲨⲀϨⲘⲈϤ ϪⲈ ⲪⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲀⲔϢⲞⲠ ⲐⲰⲚ.
39 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
ⲗ̅ⲑ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲀⲨ ⲀⲨⲒ ⲞⲨⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲚⲀⲨ ϪⲈ ⲀϤϢⲞⲠ ⲐⲰⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲰⲠⲒ ϦⲀⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲚⲈⲪⲚⲀⲨ ⲆⲈ ⲚⲀϪⲠ Ⲓ- ⲠⲈ.
40 Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
ⲙ̅ⲀⲚⲆⲢⲈⲀⲤ ⲆⲈ ⲠⲤⲞⲚ ⲚⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲚⲈⲞⲨⲀⲒ ⲠⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲂ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚⲦⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ.
41 Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
ⲙ̅ⲁ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲀϤϪⲒⲘⲒ ⲚϢⲞⲢⲠ ⲘⲠⲈϤⲤⲞⲚ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚϪⲒⲘⲒ ⲘⲘⲈⲤⲒⲀⲤ ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲠⲈϤⲞⲨⲰϨⲈⲘ ⲠⲈ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
42 Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
ⲙ̅ⲃ̅ⲪⲀⲒ ⲀϤⲈⲚϤ ϨⲀ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈⲦⲀϤϪⲞⲨϢⲦ ⲆⲈ ⲈⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲚⲐⲞⲔ ⲈⲨⲈⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞⲔ ϪⲈ ⲔⲎⲪⲀ ⲪⲎ ⲈϢⲀⲨⲞⲨⲀϨⲘⲈϤ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ.
43 Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
ⲙ̅ⲅ̅ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲈⲒ ⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϪⲒⲘⲒ ⲘⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰⲒ.
44 Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
ⲙ̅ⲇ̅ⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲤ ⲆⲈ ⲚⲈⲞⲨⲢⲈⲘⲂⲎⲐⲤⲀⲒⲆⲀ ⲠⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲐⲂⲀⲔⲒ ⲚⲀⲚⲆⲢⲈⲀⲤ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲦⲢⲞⲤ.
45 Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
ⲙ̅ⲉ̅ⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲤ ⲆⲈ ⲀϤϪⲒⲘⲒ ⲚⲚⲀⲐⲀⲚⲀⲎⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲀ ⲘⲰⲨⲤⲎⲤ ⲤϦⲀⲒ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϨⲒ ⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲀⲚϪⲈⲘϤ ⲈⲦⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲒⲰⲤⲎⲪ ⲠⲒⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ.
46 Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
ⲙ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲈ ⲚⲀⲐⲀⲚⲀⲎⲖ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚ ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲞⲨⲀⲄⲀⲐⲞⲚ ϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲀⲌⲀⲢⲈⲐ ⲠⲈϪⲈ ⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲀⲨ.
47 Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
ⲙ̅ⲍ̅ⲀϤⲚⲀⲨ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈⲚⲀⲐⲀⲚⲀⲎⲖ ⲈϤⲚⲎⲞⲨ ϨⲀⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϪⲈ ⲒⲤ ϨⲎⲠⲠⲈ ⲦⲀⲪⲘⲎⲒ ⲒⲤ ⲞⲨⲒⲤⲢⲀⲎⲖⲒⲦⲎⲤ ⲘⲘⲞⲚ ⲆⲞⲖⲞⲤ ⲚϦⲎⲦϤ
48 Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
ⲙ̅ⲏ̅ⲠⲈϪⲈ ⲚⲀⲐⲀⲚⲀⲎⲖ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲔⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞⲒ ⲐⲰⲚ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲘⲠⲀⲦⲈ ⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲤ ⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞⲔ ⲈⲔⲬⲎ ϦⲀⲦⲞⲦⲤ ⲚϮⲂⲰ ⲚⲔⲈⲚⲦⲈ ⲀⲒⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞⲔ.
49 Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
ⲙ̅ⲑ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲚⲀⲐⲀⲚⲀⲎⲖ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲢⲀⲂⲂⲀⲒ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲐⲞⲔ ⲠⲈ ⲠⲞⲨⲢⲞ ⲘⲠⲒⲤⲖ.
50 Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
ⲛ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀⲒϪⲞⲤ ⲚⲀⲔ ϪⲈ ⲀⲒⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞⲔ ϦⲀⲢⲀⲦⲤ ⲚϮⲂⲰ ⲚⲔⲈⲚⲦⲈ ⲬⲚⲀϨϮ ϨⲀⲚⲚⲒϢϮ ⲈⲚⲀⲒ ⲈⲔⲈⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
51 Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”
ⲛ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀⲘⲎⲚ ⲀⲘⲎⲚ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲚⲀⲨ ⲈⲦⲪⲈ ⲈⲤⲞⲨⲎ ⲚⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲨⲚⲀ ⲈⲠϢⲰⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲚⲎⲞⲨ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲚⲤⲀⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲢⲰⲘⲒ.