< Joel 3 >
1 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà, nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.
“Saa nna no mu, mede Yuda ne Yerusalem ahonyade bɛsan aba.
2 Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí àfonífojì Jehoṣafati. Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi, àti nítorí Israẹli ìní mi, tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.
Mɛboa aman nyinaa ano, na mede wɔn aba Yehosafat bon mu. Ɛhɔ na mebu wɔn atɛn wɔ nea wɔyɛɛ mʼagyapade, a ɛyɛ Israelfo ho, efisɛ wɔbɔɔ me nkurɔfo hwetee aman so, na wɔkyekyɛɛ mʼasase mu.
3 Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi; wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan, wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.
Wɔbɔɔ me nkurɔfo so ntonto, Wɔtɔn mmerantewa de mu sika bɔɔ aguaman. Wɔtɔn mmeawa nso de gyee nsa, a wɔbɛnom.
4 “Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín.
“Dɛn na mowɔ tia me, Tiro ne Sidon ne mo Filisti amantam nyinaa? Mopɛ sɛ motɔ me so were ana? Sɛ saa na ɛte de a, monhwɛ yiye. Mɛyɛ ntɛm, atua mo biribiara a moayɛ no so ka.
5 Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín.
Mofaa me dwetɛ ne me sikakɔkɔɔ ne mʼagyapade a ɛsom bo, na mosoa koguu mo abosonnan mu.
6 Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.
Motontɔn nnipa a wɔte Yuda ne Yerusalem maa Helafo sɛnea ɛbɛyɛ a, wobefi wɔn asase so akɔ akyirikyiri.
7 “Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín.
“Nanso, mɛsan de wɔn afi faako a mokɔtɔn wɔn no aba, na nea moayɛ no nyinaa, metua mo so ka.
8 Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.
Mɛtontɔn mo mmabarima ne mo mmabea ama Yudafo, na wɔn nso atɔn wɔn ama Arabfo, ɔman a ɛwɔ akyirikyiri no.” Me, Awurade, na makasa.
9 Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí; ẹ dira ogun, ẹ jí àwọn alágbára. Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun.
Mompae mu nka eyi wɔ aman so: Munsiesie mo ho mma ɔko! Monkanyan asraafo! Momma mo mmarima akofo no ntwiw mmra, na wɔmmɛko.
10 Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà, àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀. Jẹ́ kí aláìlera wí pé, “Ara mi le koko.”
Momfa mo funtumnnade no mmɔ afoa, na momfa mo asosɔw mmɔ mpeaw. Ma nea wɔayɛ mmerɛw nka se, “mewɔ ahoɔden!”
11 Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká, kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri. Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.
Monyɛ ntɛm mmra, mo amanaman a moatwa ahyia, mommɛboa mo ho ano wɔ hɔ. Fa wʼakofo bra, Awurade!
12 “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojì Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí: nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.
“Wɔnkanyan aman no; wontu nteɛ nkɔ Yehosafat bon no mu, efisɛ ɛhɔ na mɛtena na mabu aman a atwa ahyia no nyinaa atɛn.
13 Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́, nítorí ìkórè pọ́n. Ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀, nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀, nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”
Munhwim kantankrankyi no, efisɛ otwabere no adu so. Mommra, muntiatia bobe no so, efisɛ nsakyiamoa no ayɛ ma na ahina no ayɛ ma abu so. Saa ara na wɔn amumɔyɛ dɔɔso!”
14 Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní àfonífojì ìpinnu! Nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ ní àfonífojì ìdájọ́.
Nnipadɔm, nnipadɔm wɔ gyinaesi subon no mu! Awurade da no abɛn wɔ gyinaesi subon no mu.
15 Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn, àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.
Owia ne ɔsram beduru sum, na nsoromma renhyerɛn bio.
16 Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá, yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá; àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì. Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀, àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.
Awurade bɛbobɔ mu afi Sion, ne nne gyegyeegye afi Yerusalem, asase ne ɔsoro bɛwosow. Nanso Awurade bɛyɛ guankɔbea ama ne nkurɔfo, ɔbɛyɛ abandennen ama Israelfo.
17 “Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi. Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́; àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.
“Afei mubehu sɛ, me Awurade, mo Nyankopɔn, mete Sion, me bepɔw kronkron so. Yerusalem bɛyɛ kronkron; na ananafo rentu wɔn so sa bio.
18 “Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀, àwọn òkè kéékèèké yóò máa sàn fún wàrà; gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi. Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá, yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.
“Saa da no, nsa foforo bɛsosɔ afi mmepɔw no mu, na nufusu ateɛ wɔ nkoko so; Nsu bɛba Yuda nsuwansuwa mu, na asuti betue afi Awurade fi, na agugu akasia subon no so nsu.
19 Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro, Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro, nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda, ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
Nanso Misraim bɛdan amamfo, na Edom nso bɛyɛ nweatam, esiane awurukasɛm a wɔyɛ de tiaa nnipa a wɔwɔ Yuda nti. Ɛhɔ na wohwiee mogya a enni fɔ gui.
20 Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé, àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.
Nnipa bɛtena Yuda afebɔɔ na Yerusalem de, wɔbɛtena hɔ awo ntoatoaso nyinaa mu.
21 Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.
So merentɔ wɔn mogya a edi bem no so were ana? Mɛtɔ kɛ.”