< Joel 3 >

1 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà, nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.
Fiindcă, iată, în acele zile şi în acel timp, când voi întoarce pe captivii lui Iuda şi ai Ierusalimului,
2 Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí àfonífojì Jehoṣafati. Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi, àti nítorí Israẹli ìní mi, tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.
Voi aduna de asemenea toate naţiunile şi le voi coborî în valea lui Iosafat şi acolo, cu ele, mă voi judeca pentru poporul meu şi pentru moştenirea mea Israel, pe care ei l-au împrăştiat printre naţiuni şi au împărţit ţara mea.
3 Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi; wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan, wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.
Şi au aruncat sorţi pentru poporul meu; şi au dat un băiat pentru o curvă şi au vândut o fată pentru vin ca să bea.
4 “Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín.
Da, şi ce aveţi voi a face cu mine, Tirule şi Sidonule, şi toate ţinuturile Palestinei? Doriţi să îmi întoarceţi o răsplată? Şi dacă mă răsplătiţi, repede şi în grabă vă voi întoarce răsplata voastră asupra capului vostru;
5 Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín.
Pentru că aţi luat argintul meu şi aurul meu şi aţi dus în templele voastre lucrurile mele bune şi plăcute;
6 Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.
De asemenea aţi vândut pe copiii lui Iuda şi pe copiii Ierusalimului grecilor, ca să îi îndepărtaţi mult de graniţa lor.
7 “Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín.
Iată, îi voi ridica din locul în care i-aţi vândut şi voi întoarce răsplata voastră asupra capului vostru;
8 Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.
Şi voi vinde pe fiii voştri şi pe fiicele voastre în mâna copiilor lui Iuda şi ei îi vor vinde sabeenilor, unui popor îndepărtat, pentru că DOMNUL a vorbit aceasta.
9 Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí; ẹ dira ogun, ẹ jí àwọn alágbára. Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun.
Vestiţi aceasta printre neamuri: Pregătiţi războiul, treziţi pe războinici, să se apropie şi să se urce toţi bărbaţii de război;
10 Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà, àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀. Jẹ́ kí aláìlera wí pé, “Ara mi le koko.”
Bateţi fiarele voastre de plug în săbii şi prăjinile voastre de curăţat pomi în suliţe; cel slab să spună: Sunt tare.
11 Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká, kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri. Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.
Adunaţi-vă şi veniţi, voi toţi păgânii, strângeţi-vă împreună de jur împrejur; acolo coboară-i pe războinicii tăi, DOAMNE.
12 “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojì Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí: nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.
Păgânii să fie treziţi şi să urce la valea lui Iosafat, pentru că acolo voi şedea, ca să judec pe toţi păgânii de jur împrejur.
13 Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́, nítorí ìkórè pọ́n. Ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀, nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀, nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”
Puneţi secera, pentru că secerişul este copt; veniţi, coborâţi, pentru că presa este plină, teascurile se revarsă, pentru că mare este stricăciunea lor.
14 Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní àfonífojì ìpinnu! Nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ ní àfonífojì ìdájọ́.
Mulţimi, mulţimi în valea hotărârii, pentru că ziua DOMNULUI este aproape în valea hotărârii.
15 Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn, àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.
Soarele şi luna se vor întuneca şi stelele îşi vor retrage strălucirea.
16 Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá, yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá; àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì. Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀, àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.
DOMNUL de asemenea va răcni din Sion şi îşi va înălţa vocea din Ierusalim; şi cerurile şi pământul se vor cutremura; dar DOMNUL va fi speranţa poporului său şi tăria copiilor lui Israel.
17 “Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi. Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́; àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.
Astfel veţi cunoaşte că eu sunt DOMNUL Dumnezeul vostru locuind în Sion, muntele meu sfânt; atunci Ierusalimul va fi sfânt şi acolo străinii nu vor mai trece prin el.
18 “Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀, àwọn òkè kéékèèké yóò máa sàn fún wàrà; gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi. Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá, yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.
Şi se va întâmpla în acea zi că munţii vor picura vin nou şi dealurile vor curge cu lapte şi toate râurile lui Iuda vor curge cu ape şi o fântână va ieşi din casa DOMNULUI şi va uda valea Sitimului.
19 Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro, Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro, nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda, ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
Egiptul va fi o pustie şi Edomul va fi o pustie părăsită, din cauza violenţei împotriva copiilor lui Iuda, deoarece au vărsat sânge nevinovat în ţara lor.
20 Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé, àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.
Dar Iuda va locui pentru totdeauna şi Ierusalimul din generaţie în generaţie.
21 Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.
Fiindcă voi curăţi sângele lor pe care nu l-am curăţit, fiindcă DOMNUL locuieşte în Sion.

< Joel 3 >