< Joel 3 >

1 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà, nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.
Mert íme ama napokban és amaz időben, a mikor visszahozom majd Jehúdának és Jeruzsálemnek foglyait,
2 Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí àfonífojì Jehoṣafati. Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi, àti nítorí Israẹli ìní mi, tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.
összegyűjtöm mind a nemzeteket és leviszem őket a Jehósáfát völgyébe, és pörbe szállok ott velök, népem és birtokon Izraél miatt, a melyet szétszórtak a nemzetek közt, országomat pedig fölosztották.
3 Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi; wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan, wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.
S népem fölött sorsot vetettek és odaadták a figyermeket egy parázna nőért s a leánygyermeket eladták borért, és ittak.
4 “Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín.
De mik is vagytok ti nékem Czór és Czídón és ti mind, Peléset kerületei? Vajon tettet akartok-e nekem fizetni, avagy tettet elkövetni akartok-e rajtam: könnyen, csakhamar visszahárítom tetteteket a ti fejetekre.
5 Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín.
Akik ezüstömet és aranyomat elvettétek és legjobb drágaságaimat bevittétek templomaitokba.
6 Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.
Jehúda fiait pedig és Jeruzsálem fiait eladtátok a Jávánbeliek fiainak, azért hogy eltávolítsátok az ő határuktól.
7 “Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín.
Íme én fölserkentem őket ama helyről, ahova eladtátok őket és visszahárítom tetteteket a ti fejetekre;
8 Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.
és eladom fiaitokat és leányaitokat Jehúda fiainak kezébe, hogy eladják őket a Sábabelieknek, egy távoli nemzethez; mert az Örökkévaló szólott.
9 Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí; ẹ dira ogun, ẹ jí àwọn alágbára. Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun.
Hirdessétek ezt a nemzetek közt; szenteljetek háborút; serkentsétek föl a vitézeket, lépjenek elő, vonuljanak föl mind a harczosok.
10 Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà, àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀. Jẹ́ kí aláìlera wí pé, “Ara mi le koko.”
Törjétek össze kapáitokat kardokká és kaczoraitokat lándzsákká; a gyönge hadd mondja: vitéz vagyok.
11 Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká, kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri. Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.
Siessetek és jöjjetek el, ti nemzetek mind köröskörül és gyülekezzetek; oda vezesd le, oh Örökkévaló, a te vitézeidet!
12 “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojì Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí: nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.
Serkenjenek és vonuljanak föl a nemzetek Jehósáfát völgyébe; mert ott fogok ülni, hogy ítéljem mind a nemzeteket köröskörül.
13 Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́, nítorí ìkórè pọ́n. Ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀, nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀, nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”
Eresszétek neki a sarlót, mert megérett az aratás: jöjjetek, vonuljatok le, mert megtelt a sajtó, áradoznak a présházak, mert nagy az ő gonoszságuk.
14 Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní àfonífojì ìpinnu! Nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ ní àfonífojì ìdájọ́.
Tömegek meg tömegek a döntés völgyében: mert közel van az Örökkévaló napja a döntés völgyében.
15 Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn, àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.
Nap és hold elsötétültek s a csillagok behúzták ragyogásukat.
16 Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá, yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá; àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì. Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀, àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.
Az Örökkévaló pedig Czión felől ordít és Jeruzsálem felől hallatja hangját, és megrendülnek ég és föld; de az Örökkévaló menedéke az őnépének és ótalma Izraél fiainak.
17 “Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi. Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́; àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.
Akkor megtudjátok, hogy én vagyok az Örökkévaló, a ti Istentek, a ki Cziónban, az én szent hegyemen lakik; és szent lesz Jeruzsálem s idegenek többé nem vonulnak át rajta.
18 “Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀, àwọn òkè kéékèèké yóò máa sàn fún wàrà; gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi. Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá, yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.
És lészen ama napon: musttól csepegnek a hegyek, és a halmok tejtől folynak és mind Jehúdának medrei vízzel folynak; s egy forrás jön ki az Örökkévaló házából és megáztatja a Sittím völgyét.
19 Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro, Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro, nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda, ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
Egyiptom pusztulássá lesz és Edóm sivatag pusztává lesz, a Jehúda fiain tett erőszak miatt, hogy ártatlan vért ontottak országukban.
20 Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé, àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.
Jehúda pedig örökre lakva lesz, és Jeruzsálem nemzedékre meg nemzedékre.
21 Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.
És megtorlom véröket, melyet meg nem toroltam; s az Örökkévaló lakik Cziónban!

< Joel 3 >