< Joel 3 >

1 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà, nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.
Oui, en ces jours-là et à cette époque, quand je ramènerai les captifs de Juda et de Jérusalem,
2 Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí àfonífojì Jehoṣafati. Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi, àti nítorí Israẹli ìní mi, tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.
je rassemblerai toutes les nations et les ferai descendre dans la vallée de Josaphat, et là je les mettrai en jugement à cause de mon peuple et d’Israël, mon héritage, qu’ils ont dispersé parmi les peuples, en se partageant mon pays.
3 Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi; wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan, wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.
Mon peuple, ils en ont disposé par la voie du sort; ils ont troqué le jeune homme contre la courtisane, et la jeune fille, ils l’ont cédée contre du vin, pour pouvoir boire.
4 “Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín.
Et de fait, que réclamez-vous de moi, Tyr et Sidon, et vous tous, districts des Philistins? Pré-tendez-vous me rendre la pareille? Essayez donc de m’infliger quelque mauvais traitement: rapidement, sur-le-champ, je ferai retomber votre manière d’agir sur vos têtes.
5 Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín.
Vous avez bien enlevé mon argent et mon or, et enrichi vos sanctuaires de mes trésors les plus précieux!
6 Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.
Les fils de Juda et les enfants de Jérusalem, vous les avez vendus aux fils de lawân, pour les emmener loin de leur territoire.
7 “Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín.
Mais voici que, réveillant leur courage, je les ramène de la contrée où vous les avez vendus et je fais retomber sur vos têtes un juste châtiment.
8 Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.
A votre tour, je vendrai vos fils et vos filles par l’entremise des fils de Juda; ceux-ci les vendront aux Sabéens, à une nation lointaine, car c’est l’Eternel qui le déclare.
9 Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí; ẹ dira ogun, ẹ jí àwọn alágbára. Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun.
Faites cette annonce parmi les nations: proclamez une guerre sainte! Eveillez l’ardeur des guerriers! Qu’ils s’avancent et entrent en campagne, tous les combattants!
10 Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà, àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀. Jẹ́ kí aláìlera wí pé, “Ara mi le koko.”
Forgez vos socs de charrue en épées et vos serpettes en lances! Que le plus timoré dise: "Je suis un brave."
11 Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká, kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri. Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.
Hâtez-vous, venez, vous tous, peuples d’alentour, et concentrez-vous! Là, ô Eternel, fais descendre tes guerriers à toi!
12 “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojì Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí: nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.
Que les nations s’excitent donc et montent dans la vallée de Josaphat, car là je siégerai pour juger tous les peuples d’alentour.
13 Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́, nítorí ìkórè pọ́n. Ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀, nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀, nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”
Brandissez la faucille, car la moisson est mûre! Venez pour fouler, le pressoir étant rempli et les cuves débordantes, car grande est leur perversité.
14 Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní àfonífojì ìpinnu! Nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ ní àfonífojì ìdájọ́.
Foules sur foules dans la vallée du Jugement! Car il est proche, le jour de l’Eternel, dans la vallée du Jugement.
15 Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn, àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.
Soleil et lune s’obscurcissent, les étoiles voilent leur éclat.
16 Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá, yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá; àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì. Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀, àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.
De Sion l’Eternel rugit, de Jérusalem il fait retentir sa voix: ciel et terre en tremblent. Mais l’Eternel est un abri pour son peuple, un refuge fortifié pour les enfants d’Israël.
17 “Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi. Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́; àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.
Vous reconnaîtrez alors que c’est moi l’Eternel, votre Dieu; je réside à Sion, ma sainte montagne; Jérusalem sera sacrée, et des étrangers n’y passeront plus.
18 “Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀, àwọn òkè kéékèèké yóò máa sàn fún wàrà; gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi. Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá, yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.
En ce jour, les montagnes ruisselleront du jus de la vigne, les collines feront couler du lait, tous les ruisseaux de Juda seront pleins d’eau. Une source jaillira de la maison de l’Eternel et arrosera la vallée de Chittîm.
19 Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro, Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro, nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda, ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
L’Egypte sera une solitude, Edom un désert délaissé, en raison de la violence exercée sur les fils de Juda, dont ils ont versé le sang innocent dans leur pays.
20 Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé, àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.
Juda, au contraire, sera habité à jamais, et Jérusalem de génération en génération.
21 Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.
Je vengerai leur sang que je n’avais pas encore vengé, et moi, l’Eternel, je résiderai à Sion.

< Joel 3 >