< Joel 3 >

1 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà, nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.
[Yahweh says this]: “At that time [DOU], I will enable [the people of] Jerusalem and [other places in] Judah to prosper again.
2 Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí àfonífojì Jehoṣafati. Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi, àti nítorí Israẹli ìní mi, tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.
[Then] in the Valley of Judgment I will gather together [the people of] all the [other] nations; I will judge [and punish] them because they scattered my Israeli people and forced them to go to other countries. They divided up my land
3 Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi; wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan, wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.
and they (threw marked stones/cast lots) to determine who would get [each of] my people. Then they sold [some of] the Israeli boys and girls [to get money to pay] for prostitutes and wine to drink.
4 “Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín.
You [people of] [APO] Tyre and Sidon [cities] and [you people of] the Philistia [region], I certainly have not [RHQ] done anything to harm you! [So] if you are trying to get revenge on me, I will very quickly get revenge on you.
5 Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín.
You have taken the silver and gold and [other] things from my temple and put them in your temples.
6 Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.
[You dragged away] the people of Jerusalem and [other places in] Judah, and you took them far away and sold them to people in Greece.
7 “Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín.
But I will cause my people to want to return from the places to which you sold them, and I will do to you what you did to them.
8 Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.
Then I will cause [some of] your sons and your daughters to be sold to the people of Judah! And [some of] them will be sold to the Sabea people-group, who live far away. [That will certainly happen because I], Yahweh, have said it.”
9 Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí; ẹ dira ogun, ẹ jí àwọn alágbára. Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun.
Proclaim to the [people of all] nations, “Prepare for a war! Summon your soldiers, and tell them to stand in their battle positions.
10 Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà, àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀. Jẹ́ kí aláìlera wí pé, “Ara mi le koko.”
[Take] your plows and make swords from them, and [take] your pruning knives and make spears from them. [Even] the weak people must [also] be like [MET] [strong] soldiers.
11 Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká, kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri. Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.
All you [people from the] nations that are near [Judah] must come quickly and gather [in the Valley of Judgment].” But Yahweh, [when that happens], send your army [of angels to attack them]!
12 “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojì Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí: nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.
The [people in] the nations near [Judah] must get ready and come to the Valley of Judgment. There Yahweh will sit and judge [and punish] them.
13 Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́, nítorí ìkórè pọ́n. Ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀, nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀, nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”
[They are like] [MET] crops that are ready to be harvested; so [strike them like] [MET] [a farmer] swings his sickle to cut the grain. They are like [MET] grapes that are piled high in the pits where they will be pressed; because they are very wicked, [punish them severely] [MET] now, like [MET] [a farmer] tramples on the grapes until the pits are full of juice.
14 Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní àfonífojì ìpinnu! Nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ ní àfonífojì ìdájọ́.
[There will be] huge crowds of people in that Valley of Judgment. It will soon be the time that Yahweh [will punish them].
15 Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn, àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.
[At that time] there will be no light from the sun or moon, and the stars will not shine.
16 Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá, yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá; àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì. Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀, àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.
From Zion [Hill] in Jerusalem Yahweh will shout, and his voice will be like thunder, and his voice will cause the sky and the earth to shake. But Yahweh will protect [MET] his people; he will be like [MET] a strong wall behind which the people of Israel will be protected.
17 “Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi. Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́; àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.
[Yahweh says], “At that time, you Israeli people will know that I am Yahweh, your God. I live on Zion, my sacred hill. Jerusalem will be a sacred [city], and [soldiers from] other countries will never conquer it again.
18 “Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀, àwọn òkè kéékèèké yóò máa sàn fún wàrà; gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi. Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá, yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.
At that time, there will be vineyards covering [MTY] the hills, and [your cattle and goats on] those hills will produce plenty of milk. The streams in Judah will never dry up. And a stream will flow from my temple into the Acacia Valley [northeast of the Dead Sea].
19 Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro, Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro, nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda, ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
[The armies of] Egypt and Edom attacked the people of Judah and killed [MTY] many people who had not done anything that was wrong. So [now] those countries will become deserts,
20 Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé, àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.
but there will always be people living in Jerusalem and [in other places] in Judea.
21 Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.
[I], Yahweh, live on Zion [Hill in Jerusalem], and I will get revenge on the people [of Egypt and Edom] who killed [MTY] [many of my people].”

< Joel 3 >