< Joel 2 >

1 Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
Sunaţi din trâmbiţă în Sion şi sunaţi alarma pe muntele meu cel sfânt; să tremure toţi locuitorii ţării, pentru că ziua DOMNULUI vine, pentru că este aproape;
2 Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
O zi de întuneric şi de întunecime, o zi cu nori şi de întuneric gros; ca dimineaţa revărsată peste munţi; un popor mare şi puternic; nu a fost vreodată asemenea, nici nu va mai fi după el, în anii multor generaţii.
3 Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
Un foc mistuie înaintea lor; şi în spatele lor o flacără arde; ţara este ca grădina Edenului înaintea lor şi în spatele lor o pustie părăsită; da, şi nimic nu le va scăpa.
4 Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
Înfăţişarea lor este ca înfăţişarea cailor; şi ca nişte călăreţi, astfel vor alerga.
5 Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
Vor sări ca zgomotul carelor pe vârfurile munţilor, ca zgomotul flăcării de foc care mistuie miriştea, ca un popor puternic desfăşurat pentru bătălie.
6 Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
Înaintea feţei lor popoarele vor fi foarte îndurerate; toate feţele se vor înnegri.
7 Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
Ei vor alerga precum războinicii; vor urca pe zid ca bărbaţii de război; şi vor mărşălui fiecare pe căile lui şi nu vor rupe rândurile lor;
8 Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
Nici nu se împing unul pe altul; fiecare va merge pe cărarea lui; şi când vor cădea pe sabie, nu vor fi răniţi.
9 Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
Vor alerga încoace şi încolo în cetate; vor alerga pe zid, se vor cățăra pe case; ca un hoţ vor intra pe ferestre.
10 Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Pământul se va zgudui înaintea lor; cerurile vor tremura; soarele şi luna vor fi întunecate şi stelele îşi vor retrage strălucirea;
11 Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
Şi DOMNUL îşi va înălţa vocea înaintea armatei sale, pentru că tabăra lui este foarte mare, pentru că este puternic cel care împlineşte cuvântul său, pentru că ziua DOMNULUI este mare şi foarte înfricoşătoare; şi cine o poate suporta?
12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
De aceea chiar acum, spune DOMNUL, întoarceţi-vă la mine cu toată inima voastră şi cu post şi cu plâns şi cu jale;
13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
Şi sfâşiaţi-vă inima, şi nu hainele, şi întoarceţi-vă la DOMNUL Dumnezeul vostru, pentru că el este cu har şi milostiv, încet la mânie şi de o mare bunătate şi se pocăieşte de rău.
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
Cine ştie dacă el nu se va întoarce şi nu se va pocăi şi nu va lăsa o binecuvântare după el; un dar de mâncare şi un dar de băutură pentru DOMNUL Dumnezeul vostru?
15 Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
Sunaţi trâmbiţa în Sion, sfinţiţi un post, anunțați o adunare solemnă;
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
Adunaţi poporul, sfinţiţi adunarea, strângeţi pe bătrâni, adunaţi copiii şi pe cei care sug la sâni; să iasă mirele din camera lui şi mireasa din cămăruţa ei.
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
Preoţii, servitorii DOMNULUI, să plângă între portic şi altar şi să spună: Cruţă pe poporul tău, DOAMNE şi nu da moştenirea ta ocărârii, ca păgânii să stăpânească asupra lor, pentru a spune ei printre popoare: Unde este Dumnezeul lor?
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
Atunci DOMNUL va fi gelos pentru ţara lui şi va avea milă de poporul său.
19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
Da, DOMNUL va răspunde şi va spune poporului său: Iată, eu vă voi trimite grâne şi vin şi untdelemn şi vă veţi sătura cu ele; şi nu vă voi mai face de ocară printre păgâni;
20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
Ci voi îndepărta mult de la voi armata de la nord şi o voi alunga într-o ţară stearpă şi pustie, cu faţa spre marea de est şi cu spatele spre marea de vest, şi putoarea ei se va ridica şi mirosul ei urât se va urca, pentru că a făcut lucruri mari.
21 Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
Nu te teme, ţară; fii veselă şi bucură-te, pentru că DOMNUL va face lucruri mari.
22 Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
Nu vă temeţi, voi vite ale câmpului: pentru că păşunile pustiei înverzesc, pentru că pomul îşi poartă rodul, smochinul şi viţa îşi dau tăria.
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
Fiţi veseli, voi copii ai Sionului, şi bucuraţi-vă în DOMNUL Dumnezeul vostru, pentru că el v-a dat ploaia timpurie cu măsură şi va face să cadă pentru voi ploaia, ploaia timpurie şi ploaia târzie în luna întâi.
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
Şi ariile vor fi pline de grâu şi teascurile se vor revărsa de vin şi de untdelemn.
25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
Şi vă voi da înapoi anii pe care i-a mâncat lăcusta, muşiţa şi omida şi forfecarul, armata mea cea mare pe care am trimis-o printre voi.
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
Şi veţi mânca în abundenţă şi vă veţi sătura şi veţi lăuda numele DOMNULUI Dumnezeul vostru, care a lucrat minunat cu voi; şi poporul meu nu se va ruşina niciodată.
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
Şi veţi cunoaşte că sunt în mijlocul lui Israel şi că eu sunt DOMNUL Dumnezeul vostru şi niciun altul; şi poporul meu nu se va ruşina niciodată.
28 “Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
Şi după aceea se va întâmpla că voi turna duhul meu peste toată făptura; şi fiii voştri şi fiicele voastre vor profeţi, bătrânii voştri vor visa vise, tinerii voştri vor avea viziuni;
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
Şi de asemenea, în acele zile, voi turna duhul meu peste servitori şi peste servitoare.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
Şi voi arăta minuni în ceruri şi pe pământ: sânge şi foc şi stâlpi de fum.
31 A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
Soarele se va schimba în întuneric şi luna în sânge, înainte ca ziua cea mare şi înfricoşătoare a DOMNULUI să vină.
32 Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.
Şi se va întâmpla, că oricine va chema numele DOMNULUI va fi eliberat, pentru că în muntele Sionului şi în Ierusalim va fi eliberare, precum a spus DOMNUL, şi în rămăşiţa pe care DOMNUL o va chema.

< Joel 2 >