< Joel 2 >

1 Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
در صهیون کرنا بنوازید و در کوه مقدس من صدا بلند کنید! تمامی ساکنان زمین بلرزندزیرا روز خداوند می‌آید و نزدیک است.۱
2 Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
روزتاریکی و ظلمت، روز ابرها و ظلمت غلیظ مثل فجر منبسط بر کوهها! امتی عظیم و قوی که مانندآن از ازل نبوده و بعد از این تا سالها و دهرهای بسیار نخواهد بود.۲
3 Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
پیش روی ایشان آتش می‌سوزاند و در عقب ایشان شعله ملتهب می‌گردد. پیش روی ایشان، زمین مثل باغ عدن ودر عقب ایشان، بیابان بایر است و نیز از ایشان احدی رهایی نمی یابد.۳
4 Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
منظر ایشان مثل منظراسبان است و مانند اسب‌سواران می‌تازند.۴
5 Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
مثل صدای ارابه‌ها بر قله کوهها جست و خیزمی کنند؛ مثل صدای شعله آتش که کاه رامی سوزاند؛ مانند امت عظیمی که برای جنگ صف بسته باشند.۵
6 Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
از حضور ایشان قوم هامی لرزند. تمامی رویها رنگ پریده می‌شود.۶
7 Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
مثل جباران می‌دوند، مثل مردان جنگی بر حصارهابرمی آیند و هر کدام به راه خود می‌آیند وطریقهای خود را تبدیل نمی کنند.۷
8 Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
بر یکدیگرازدحام نمی کنند، زیرا هرکس به راه خودمی خرامد. از میان حربه‌ها هجوم می‌آورند وصف های خود را نمی شکنند.۸
9 Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
بر شهرمی جهند، به روی حصارها می‌دوند، به خانه هابرمی آیند. مثل دزدان از پنجره‌ها داخل می شوند.۹
10 Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
از حضور ایشان زمین متزلزل وآسمانها مرتعش می‌شود؛ آفتاب و ماه سیاه می‌شوند و ستارگان نور خویش را باز می‌دارند.۱۰
11 Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
و خداوند آواز خود را پیش لشکر خویش بلند می‌کند، زیرا اردوی او بسیار عظیم است و آنکه سخن خود را بجا می‌آورد، قدیراست. زیرا روز خداوند عظیم و بی‌نهایت مهیب است و کیست که طاقت آن را داشته باشد.۱۱
12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
و لکن الان خداوند می‌گوید با تمامی دل وبا روزه و گریه و ماتم بسوی من بازگشت نمایید.۱۲
13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
و دل خود را چاک کنید نه رخت خویش را وبه یهوه خدای خود بازگشت نمایید زیرا که اورئوف و رحیم است و دیرخشم و کثیراحسان و ازبلا پشیمان می‌شود.۱۳
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
که می‌داند که شایدبرگردد و پشیمان شود و در عقب خود برکتی واگذارد، یعنی هدیه آردی و هدیه ریختنی برای یهوه خدای شما.۱۴
15 Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
در صهیون کرنا بنوازید وروزه را تعیین کرده، محفل مقدس را ندا کنید.۱۵
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
قوم را جمع کنید، جماعت را تقدیس نمایید، پیران و کودکان و شیرخوارگان را فراهم آورید. داماد از حجره خود و عروس از حجله خویش بیرون آیند.۱۶
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
کاهنانی که خدام خداوند هستنددر میان رواق و مذبح گریه کنند و بگویند: «ای خداوند بر قوم خویش شفقت فرما و میراث خویش را به عار مسپار، مبادا امت‌ها بر ایشان حکمرانی نمایند. چرا در میان قومها بگویند که خدای ایشان کجا است؟»۱۷
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
پس خداوند برای زمین خود به غیرت خواهد آمد و بر قوم خویش شفقت خواهد نمود.۱۸
19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
و خداوند قوم خود را اجابت نموده، خواهدگفت: «اینک من گندم و شیره و روغن را برای شمامی فرستم تا از آنها سیر شوید و شما را بار دیگردر میان امت‌ها عار نخواهم ساخت.۱۹
20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
و لشکرشمالی را از شما دور کرده، به زمین خشک ویران خواهم راند که مقدمه آن بر دریای شرقی وساقه‌اش بر دریای غربی خواهد بود و بوی بدش بلند خواهد شد و عفونتش برخواهد آمد زیراکارهای عظیم کرده است.»۲۰
21 Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
‌ای زمین مترس! وجد و شادی بنما زیرایهوه کارهای عظیم کرده است.۲۱
22 Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
‌ای بهایم صحرا مترسید زیرا که مرتع های بیابان سبز شد ودرختان میوه خود را آورد و انجیر و مو قوت خویش را دادند.۲۲
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
‌ای پسران صهیون در یهوه خدای خویش وجد و شادی نمایید، زیرا که باران اولین را به اندازه‌اش به شما داده است وباران اول و آخر را در وقت برای شما بارانیده است.۲۳
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
پس خرمن از گندم پر خواهد شد ومعصره‌ها از شیره و روغن لبریز خواهد گردید.۲۴
25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
و سالهایی را که ملخ و لنبه و سوس و سن یعنی لشکر عظیم من که بر شما فرستاده بودم خوردندبه شما رد خواهم نمود.۲۵
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
و غذای بسیارخورده، سیر خواهید شد و اسم یهوه خدای خودرا که برای شما کارهای عجیب کرده است، تسبیح خواهید خواند و قوم من تا به ابد خجل نخواهند شد.۲۶
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
و خواهید دانست که من در میان اسرائیل می‌باشم و من یهوه خدای شما هستم ودیگری نیست و قوم من خجل نخواهند شد تاابدالاباد.۲۷
28 “Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
و بعد از آن روح خود را بر همه بشر خواهم ریخت و پسران و دختران شما نبوت خواهندنمود و پیران شما و جوانان شما رویاها خواهنددید.۲۸
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
و در آن ایام روح خود را بر غلامان وکنیزان نیز خواهم ریخت.۲۹
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
و آیات را از خون وآتش و ستونهای دود در آسمان و زمین ظاهرخواهم ساخت.۳۰
31 A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
آفتاب به تاریکی و ماه به خون مبدل خواهند شد، پیش از ظهور یوم عظیم ومهیب خداوند.۳۱
32 Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.
و واقع خواهد شد هر‌که نام خداوند را بخواند نجات یابد زیرا در کوه صهیون و در اورشلیم چنانکه خداوند گفته است بقیتی خواهد بود و در میان باقی ماندگان آنانی که خداوند ایشان را خوانده است.۳۲

< Joel 2 >