< Joel 2 >

1 Ẹ fun ìpè ní Sioni, ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi. Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì, nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá, nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
Bazūnējiet ar bazūni Ciānā, un lai skan stipri Manā svētā kalnā; lai visi zemes iedzīvotāji dreb, jo Tā Kunga diena nāk, jo tā ir tuvu:
2 Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀, ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri. Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá: àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé, ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.
Melna un tumša diena, apmākusies un miglaina diena. Kā rīta blāzma izplešas pār kalniem, tā liela un varena tauta, kāda nemūžam nav bijusi un pēc vairs nemūžam nebūs uz radu radiem.
3 Iná ń jó níwájú wọ́n; ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn. Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn, àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù; nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
Viņas priekšā rij uguns, un viņai nopakaļ deg liesma; zeme viņas priekšā ir kā Ēdenes dārzs, bet aiz viņas tukša posta vieta; neviens no tās nevar izbēgt.
4 Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin; wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun.
Viņu ģīmis ir kā zirgu ģīmis, un kā jātnieki, tāpat viņi skrien.
5 Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni wọn ń fo ní orí òkè bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ, bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.
Tie atlec pa kalnu virsgaliem, kā rati rīb, kā uguns liesma sprēgā, kas rugājus aprij, kā varena tauta, kas apbruņota uz karu.
6 Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀: gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
Viņu ieraudzīdami, ļaudis iztrūcinājās, visu vaigu sārtums nobāl.
7 Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára; wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun; olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀, wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
Tie skrien kā varoņi, kā kara vīri tie uzkāpj uz mūriem; un tie ikviens iet pa savu ceļu un neatkāpjās no savas tekas.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀; olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀, nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà wọn kì yóò gbọgbẹ́.
Tie nespiež viens otru, ikviens staigā savā kārtā, un jebšu krīt kara ieročos, tomēr tie netop aizturēti.
9 Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú; wọn yóò súré lórí odi, wọn yóò gùn orí ilé; wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.
Tie staigā pa pilsētu, tie skrien pa mūriem, tie iekāpj namos, tie nāk caur logiem iekšā kā zaglis.
10 Ayé yóò mì níwájú wọn; àwọn ọ̀run yóò wárìrì; oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn, àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Viņas priekšā dreb zeme, debess trīc, saule un mēnesis aptumšojās, un zvaigznes ierauj savu spožumu.
11 Olúwa yóò sì bú ramúramù jáde níwájú ogun rẹ̀: nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi; nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ; nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi; ara ta ni ó lè gbà á?
Un Tas Kungs paceļ Savu balsi Sava karaspēka priekšā, jo Viņa lēģeris ir varen liels, jo varens ir Viņa vārda izdarītājs, jo Tā Kunga diena ir liela un ļoti briesmīga, - kas to var panest?
12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi, àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”
Bet arī tagad Tas Kungs saka: atgriežaties pie Manis ar visu savu sirdi, un ar gavēšanu un ar raudāšanu un ar nožēlošanu.
13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya, kì í sì í ṣe aṣọ yín, ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
Un saplēšat savas sirdis un ne savas drēbes, un atgriežaties pie Tā Kunga, sava Dieva, jo viņš ir laipnīgs un sirdsžēlīgs, lēnprātīgs un no lielas žēlastības, un viņam ir žēl par to postu.
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà, kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀— àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu fún Olúwa Ọlọ́run yín?
Kas zin, varbūt ka Viņš atgriezīsies, un Viņam būs žēl, un atstās svētību aiz Sevis, ēdamu upuri un dzeramu upuri priekš Tā Kunga, jūsu Dieva!
15 Ẹ fún ìpè ní Sioni, ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́, ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
Bazūnējiet ar bazūni Ciānā, svētījiet gavēni, izsauciet sapulces dienu.
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ, ẹ ya ìjọ sí mímọ́; ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ, ẹ kó àwọn ọmọdé jọ, àti àwọn tí ń mú ọmú, jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀. Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀.
Sapulcinājiet ļaudis, svētījiet draudzi, sapulcinājiet vecajus, sasauciet bērniņus un zīdāmos pie krūtīm. Lai brūtgāns iet no sava kambara un brūte no savas vietas.
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa, sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ. Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa. Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn, tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí. Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé, ‘Ọlọ́run wọn ha da?’”
Starp priekšnamu un altāri lai raud priesteri, Tā Kunga sulaiņi, un lai saka: ak Kungs, žēlo Savus ļaudis un nenodod Savu mantību par nievāšanu, ka pagāni tos neapsmej! Kādēļ starp tautām būs sacīt: kur viņu Dievs?
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀, yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.
Tad Tas Kungs iekarsa Savas zemes pēc un saudzēja Savus ļaudis.
19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn, yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé: “Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun, àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn; Èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.
Un Tas Kungs atbildēja un sacīja uz Saviem ļaudīm: redzi, Es jums sūtīšu labību un vīnu un eļļu, ka jūs ar to topat pieēdināti, un Es jūs vairs nenodošu par nievāšanu starp pagāniem.
20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín, èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro, pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn, àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun. Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè, òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.” Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
Un Es atstādināšu tālu no jums to ziemeļnieku un to aizdzīšu sakaltušā un tukšā zemē, viņa priekšējus(pulkus) rīta jūrā un viņa pakaļējus(pulkus) vakara jūrā. Un viņa smarža kāps uz augšu, un viņa smirdums uzcelsies, jo viņš lielījās savos darbos.
21 Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀; jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀, nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá.
Nebīsties, zeme! Priecājies un esi līksma, jo Tas Kungs dara lielas lietas.
22 Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó, nítorí pápá oko aginjù ń rú. Nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́ àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
Nebīstaties, zvēri laukā! Jo ganības tuksnesī atkal nesīs jaunu zāli, jo koki nesīs savus augļus, vīna koks un vīģes koks izdos savu spēku.
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni, ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́, Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín, àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
Un Ciānas bērni, priecājaties un līksmojaties iekš Tā Kunga, sava Dieva! Jo Viņš jums dos taisnības mācītāju un jums sūtīs lietu, agro lietu un vēlo lietu kā papriekš.
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà; àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.
Un kloni būs pilni labības, un spaidi pārtecēs no vīna un eļļas.
25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín. Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
Tā Es jums atmaksāšu tos gadus, ko siseņi, vaboles un kukaiņi un kāpuri ir noēduši, Mans lielais karaspēks, ko Es jums biju sūtījis.
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò; ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
Un jūs ēdin ēdīsiet un pieēdīsities un slavēsiet Tā Kunga, sava Dieva, vārdu, kas brīnišķi jums ir darījis, un Mani ļaudis netaps kaunā ne mūžam.
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli, àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, àti pé kò sí ẹlòmíràn, ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.
Un jūs manīsiet, ka Es esmu Israēla vidū, un ka Es esmu Tas Kungs, jūsu Dievs, un cits neviens, un Mani ļaudis netaps kaunā ne mūžam.
28 “Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́, èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo; àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀, àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
Pēc tam tas notiks, ka Es Savu Garu izliešu pār visu miesu, un jūsu dēli un jūsu meitas sludinās praviešu mācību, jūsu vecaji sapņos sapņus, jūsu jaunekļi redzēs parādīšanas.
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin, àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin, ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
Arī pār kalpiem un pār kalponēm Es izliešu Savu Garu tanīs dienās.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun àti ní ayé, ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
Un Es darīšu brīnumus debesīs un zemes virsū, asinis un uguni un dūmu tvaiku.
31 A á sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
Saule taps pārvērsta par tumsību un mēnesis par asinīm, pirms nekā nāks Tā Kunga lielā un bijājamā diena.
32 Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà, nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu ní ìgbàlà yóò gbé wà, bí Olúwa ti wí, àti nínú àwọn ìyókù tí Olúwa yóò pè.
Un notiks, ka ikviens, kas Tā Kunga vārdu piesauks, taps izglābts. Jo Ciānas kalnā un Jeruzālemē būs glābšana, kā Tas Kungs ir runājis, un pie tiem atlikušiem būs tie, ko Tas Kungs aicinās.

< Joel 2 >